< 1 Kings 12 >

1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
Şi Roboam a mers la Sihem, pentru că tot Israelul venise la Sihem să îl facă împărat.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
Şi s-a întâmplat, când Ieroboam, fiul lui Nebat, care era încă în Egipt, a auzit despre aceasta, (fiindcă el fugise din prezenţa împăratului Solomon şi Ieroboam locuia în Egipt),
3 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
Că ei au trimis şi l-au chemat. Şi Ieroboam şi toată adunarea lui Israel au venit şi i-au vorbit lui Roboam, spunând:
4 “Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
Tatăl tău ne-a făcut jugul apăsător; de aceea acum, fă servirea apăsătoare a tatălui tău şi jugul lui cel greu pe care l-a pus asupra noastră, mai uşor, şi noi îţi vom servi.
5 Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
Şi el le-a spus: Plecaţi pentru încă trei zile, apoi veniţi din nou la mine. Şi poporul a plecat.
6 Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
Şi împăratul Roboam s-a consultat cu bătrânii, care stătuseră în picioare înaintea lui Solomon, tatăl său, pe când el încă trăia şi a spus: Cum mă sfătuiţi voi să răspund acestui popor?
7 Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
Şi ei i-au vorbit, spunând: Dacă vei fi un servitor al acestui popor în această zi şi le vei servi şi le vei răspunde şi vei vorbi cuvinte bune către ei, atunci ei vor fi servitorii tăi pentru totdeauna.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
Dar el a părăsit sfatul bătrânilor, pe care i l-au dat şi s-a sfătuit cu tinerii care crescuseră împreună cu el şi care stăteau în picioare înaintea lui;
9 Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
Şi le-a spus: Ce sfat ne daţi voi ca să putem răspunde acestui popor, care mi-a vorbit, zicând: Uşurează jugul pe care tatăl tău l-a pus asupra noastră?
10 Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
Şi tinerii care crescuseră cu el i-au vorbit, spunând: Astfel să vorbeşti acestui popor care ţi-a vorbit, spunând: Tatăl tău a îngreunat jugul nostru, dar tu uşurează-ni-l; astfel să le spui: Degetul meu cel mic va fi mai gros decât coapsele tatălui meu.
11 Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
Şi acum, dacă tatăl meu v-a încărcat cu un jug greu, eu voi adăuga la jugul vostru: tatăl meu v-a pedepsit cu bice, dar eu vă voi pedepsi cu scorpioni.
12 Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
Astfel Ieroboam şi tot poporul au venit la Roboam a treia zi, precum împăratul rânduise, spunând: Veniţi din nou la mine a treia zi.
13 Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
Şi împăratul a răspuns poporului cu asprime şi a părăsit sfatul pe care i-l dăduseră bătrânii;
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
Şi le-a vorbit după sfatul tinerilor, spunând: Tatăl meu a îngreunat jugul vostru, dar eu voi adăuga la jugul vostru; tatăl meu de asemenea v-a pedepsit cu bice, dar eu vă voi pedepsi cu scorpioni.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
De aceea împăratul nu a dat ascultare poporului; deoarece cauza era de la DOMNUL, ca să îşi poată împlini spusa pe care DOMNUL o vorbise prin Ahiia şilonitul lui Ieroboam, fiul lui Nebat.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé, “Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi, ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese? Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli! Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn.
Astfel, când tot Israelul a văzut că împăratul nu le-a dat ascultare, poporul a răspuns împăratului, zicând: Ce parte avem noi în David? Nici nu avem o moştenire în fiul lui Isai; la corturile tale, Israele; acum vezi-ţi de casa ta, Davide. Astfel Israel a plecat la corturile sale.
17 Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
Dar cât despre copiii lui Israel care locuiau în cetăţile lui Iuda, Roboam a domnit peste ei.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
Atunci împăratul Roboam a trimis pe Adoram, care era peste taxă; şi tot Israelul l-a împroşcat cu pietre, încât el a murit. De aceea împăratul Roboam s-a grăbit să se urce în carul său, pentru a fugi la Ierusalim.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
Astfel Israel s-a răzvrătit împotriva casei lui David până în această zi.
20 Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
Şi s-a întâmplat, când tot Israelul a auzit că Ieroboam s-a întors, că au trimis şi l-au chemat la adunare şi l-au făcut împărat peste tot Israelul; nu era nimeni care urma casa lui David, decât singur tribul lui Iuda.
21 Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
Şi când Roboam a venit la Ierusalim, el a adunat toată casa lui Iuda, cu tribul lui Beniamin, o sută optzeci de mii de oameni aleşi, care erau războinici, pentru a lupta împotriva casei lui Israel, pentru a aduce împărăţia din nou la Roboam, fiul lui Solomon.
22 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
Dar cuvântul lui Dumnezeu a venit la Şemaia, omul lui Dumnezeu, spunând:
23 “Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
Vorbeşte-i lui Roboam, fiul lui Solomon, împăratul lui Iuda, şi întregii case a lui Iuda şi a lui Beniamin şi rămăşiţei poporului, spunând:
24 ‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.”’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Astfel spune DOMNUL: Să nu vă urcaţi, nici să nu luptaţi împotriva fraţilor voştri, copiii lui Israel; întoarceţi-vă fiecare om la casa lui, pentru că acest lucru este de la mine. Ei au dat ascultare cuvântului DOMNULUI şi s-au întors să plece, conform cuvântului DOMNULUI.
25 Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
Atunci Ieroboam a construit Sihemul în muntele Efraim şi a locuit acolo; şi a ieşit de acolo şi a construit Penuelul.
26 Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
Şi Ieroboam a spus în inima sa: Acum împărăţia se va întoarce la casa lui David;
27 Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
Dacă acest popor urcă pentru a aduce sacrificiu în casa DOMNULUI la Ierusalim, atunci inima acestui popor se va întoarce din nou la domnul lor, la Roboam, împăratul lui Iuda, şi pe mine mă vor ucide şi se vor întoarce la Roboam, împăratul lui Iuda.
28 Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
De aceea împăratul s-a sfătuit şi a făcut doi viţei de aur şi le-a spus: Este prea mult pentru voi să urcaţi la Ierusalim: iată, Israele, dumnezeii tăi care te-au scos din ţara Egiptului.
29 Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
Şi a pus pe unul în Betel şi pe celălalt l-a pus în Dan.
30 Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
Şi acest lucru a devenit un păcat; fiindcă poporul a mers să se închine înaintea unuia, până la Dan.
31 Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
Şi el a făcut o casă a înălţimilor şi a făcut preoţi din cei mai de jos oameni, care nu erau dintre fiii lui Levi.
32 Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
Şi Ieroboam a rânduit o sărbătoare în luna a opta, în ziua a cincisprezecea a lunii, ca sărbătoarea care este în Iuda, şi a oferit pe altar. Astfel a făcut el în Betel, sacrificând viţeilor pe care îi făcuse; şi a aşezat în Betel pe preoţii înălţimilor pe care el le făcuse.
33 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.
Astfel el a oferit pe altarul pe care îl făcuse în Betel în ziua a cincisprezecea a lunii a opta, în luna pe care el o plănuise din inima lui; şi a rânduit o sărbătoare pentru copiii lui Israel; şi a oferit pe altar şi a ars tămâie.

< 1 Kings 12 >