< 1 Kings 12 >

1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
Tedy jechał Roboam do Sychem; bo w Sychem zebrał się był wszystek Izrael, aby go postanowili królem.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
I stało się, gdy usłyszał Jeroboam, syn Nabata, który był jeszcze w Egipcie; ( bo był uciekł przed królem Salomonem, i mieszkał Jeroboam w Egipcie.)
3 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
Tedy posłali i wezwali go. Przetoż przyszedłszy Jeroboam, i wszystko zgromadzenie Izraelskie, rzekli do Roboama, mówiąc:
4 “Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
Ojciec twój włożył na nas jarzmo ciężkie; ale ty teraz ulżyj nam niewoli srogiej ojca twego, i jarzma jego ciężkiego, które włożył na nas, a będziemyć służyli.
5 Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
Który im rzekł: Odejdźcie, a po trzech dniach wróćcie się do mnie. I odszedł lud.
6 Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
Tedy wszedł w radę król Roboam z starszymi, którzy stawali przed Salomonem, ojcem jego, za żywota jego, mówiąc: Co wy radzicie, jakąbym miał dać odpowiedź ludowi temu?
7 Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
Którzy mu odpowiedzieli, mówiąc: Jeźli dziś powolny będziesz ludowi temu, a posłuchasz ich, i dasz im odpowiedź, a będziesz mówił do nich słowa łagodne, będą sługami twymi po wszystkie dni.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
Ale on opuściwszy radę starszych, którą mu podali, wszedł w radę z młodzieńcami, którzy z nim wzrośli, a którzy stawali przed nim;
9 Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
I rzekł do nich: A wy co radzicie, abyśmy odpowiedzieli ludowi temu, który rzekł do mnie, mówiąc: Ulżyj jarzma, które włożył ojciec twój na nas?
10 Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
Tedy mu odpowiedzieli oni młodzieńcy, którzy z nim wzrośli, mówiąc: Tak odpowiesz temu ludowi, którzy mówili do ciebie, a rzekli: Ojciec twój włożył na nas jarzmo ciężkie, ale nam go ty ulżyj; tak rzeczesz do nich: Najmniejszy palec mój mięższy jest niż biodra ojca mego.
11 Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
Przetoż teraz ojciec mój kładł na was jarzmo ciężkie, ale ja przydam do jarzma waszego; ojciec mój karał was biczykami, ale ja was będę karał korbaczami.
12 Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
Przyszedł tedy Jeroboam, i wszystek lud do Roboama dnia trzeciego, jako był rozkazał król, mówiąc: Wróćcie się do mnie dnia trzeciego.
13 Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
I dał srogą odpowiedź król ludowi, opuściwszy radę starszych, którą mu byli dali,
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
A rzekł do nich według rady młodzieńców, mówiąc: Ojciec mój obciążał was jarzmem ciężkiem, ale ja przydam do jarzma waszego; ojciec mój karał was biczykami, ale ja was będę karał korbaczami.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
I nie usłuchał król ludu; bo była przyczyna od Pana, aby dosyć uczynił słowu swemu, które był powiedział Pan przez Achyjasza Sylonitczyka do Jeroboama, syna Nabatowego.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé, “Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi, ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese? Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli! Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn.
A gdy widział wszystek Izrael, że ich nie usłuchał król, odpowiedział lud królowi, tak mówiąc: Cóż my mamy za dział w Dawidzie? a co za dziedzictwo w synu Isajowym? Idź do namiotów swych, o Izraelu, a ty Dawidzie opatrz teraz dom twój. I rozeszli się Izraelczycy do namiotów swoich.
17 Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
A tak tylko nad synami Izraelskimi, którzy mieszkali w mieściech Judzkich, królował Roboam.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
I posłał król Roboam Adorama, który był poborcą, i ukamionował go wszystek Izrael, aż umarł; przetoż król Roboam, wsiadłszy co rychlej na wóz, uciekł do Jeruzalemu.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
A tak odstąpili Izraelczycy od domu Dawidowego, aż do dnia tego.
20 Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
I stało się, gdy usłyszał wszystek Izrael, że się wrócił Jeroboam, posławszy przyzwali go do zgromadzenia, i postanowili go królem nad wszystkim Izraelem. Nie zostało przy domu Dawidowym jedno samo pokolenie Judowe.
21 Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
A przyjechawszy Roboam do Jeruzalemu, zebrał wszystek dom Judowy, i pokolenie Benjaminowe, sto i ośmdziesiąt tysięcy mężów przebranych ku bojowi, aby walczyli z domem Izraelskim, ażeby przywrócone było królestwo Roboamowi, synowi Salomonowemu.
22 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
I stało się słowo Boże do Semejasza, męża Bożego, mówiąc:
23 “Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
Powiedz Roboamowi, synowi Salomonowemu, królowi Judzkiemu i wszystkiemu domowi Judowemu i Benjaminowemu, i innemu ludowi, mówiąc:
24 ‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.”’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Tak mówi Pan: Nie wychodźcie, ani walczcie z bracią swoją, synmi Izraelskimi; wróćcie się każdy do domu swego: albowiem odemnie się ta rzecz stała. I usłuchali rozkazania Pańskiego, a wrócili się, aby odeszli według słowa Pańskiego.
25 Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
Potem zbudował Jeroboam Sychem na górze Efraim, i mieszkał w nim, a stamtąd wyszedłszy pobudował Fanuel.
26 Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
I rzekł Jeroboam w sercu swem: Wnetby się wróciło królestwo do domu Dawidowego.
27 Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
Gdyby chadzał ten lud sprawować ofiary do domu Pańskiego do Jeruzalemu, i obróciłoby się serce ludu tego do pana swego, do Roboama, króla Judzkiego, a zabiwszy mię, wróciliby się do Roboama, króla Judzkiego.
28 Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
Przetoż naradziwszy się król, uczynił dwóch cielców złotych, i mówił do ludu: Dosycieście się nachodzili do Jeruzalemu; oto bogowie twoi, o Izraelu, którzy cię wywiedli z ziemi Egipskiej.
29 Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
I postawił jednego w Betel, a drugiego postawił w Dan.
30 Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
I było to pobudką do grzechu, bo chadzał lud do jednego z tych bogów aż do Dan,
31 Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
Uczynił też dom na wyżynach, i postanowił kapłany niektóre z pospólstwa, którzy nie byli z synów Lewiego.
32 Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
Nadto ustanowił Jeroboam święto uroczyste miesiąca ósmego, piętnastego dnia tegoż miesiąca, nakształt święta, które obchodzono w Judzie, i ofiarował na ołtarzu. Toż uczynił w Betel, ofiarując cielcom, które był uczynił; postanowił też kapłany w Betel na wyżynach, które był poczynił.
33 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.
I sprawował też ofiary na ołtarzu, który był uczynił w Betel, piętnastego dnia miesiąca ósmego, onegoż miesiąca, który był wymyślił w sercu swojem; i uczynił święto uroczyste synom Izraelskim, a przystąpił do ołtarza, aby kadził.

< 1 Kings 12 >