< 1 Kings 12 >

1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
Aa le nomb’e Sekeme añe t’i Rekhavame, ie fa niheo mb’e Sekeme mb’eo t’Israele iaby hañory aze ho mpanjaka.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
Ie amy zao, naho jinanji’ Iarovame ana’ i Nebate e Mitsraime añe—ie fa nitriban-day boak’ añatrefa’ i Se­lomò mpanjaka vaho nimoneñe e Mitsraime añe
3 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
le nañitrike naho nikoik’ aze iereo naho niheo mb’ amy Rekhavame mb’eo t’Iarovame rekets’ i valobohò’ Israeley, nanao ty hoe:
4 “Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
Nanoan-drae’o jokan-tsa­rererake; aa le hamaivaño ty fitoloñan-tsare­rerahan-drae’o, naho i joka mavesatse nampitarazoe’e anaiy, le hitoroñ’ azo zahay.
5 Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
Le hoe re am’ iereo: Misitaha telo andro heike, le mibaliha amako. Le nienga ondatio.
6 Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
Nisafiry amo androanavy nijohañe añatrefa’ i Selomò rae’e, ie mbe niveloñe, t’i Rekhavame, ami’ty hoe: Ino ty fanoroañe hatolo’ areo amako hamaleako ondatio?
7 Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
Le hoe ty nisaontsia’ iareo: Naho toe ho mpitoro’ ondatio irehe te anito hitoroña’o naho hihaoña’o vaho hisaon­tsia’o mora, le ho mpitoro’o nainai’e iereo.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
Fe nifarie’e ty safiry natolo’ o androanavio aze, vaho nandrambe ty fanoroa’ o ajalahy nindre nibey ama’e naho nijohañe añatrefa’eo.
9 Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
Fa hoe re am’ iereo: Akore ty safiri’ areo, hamalean-tika ondaty nisaontsy amako ami’ty hoe: Hamaivaño ty joka nampitarazoen-drae’o anaio?
10 Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
Aa le hoe ty asa’ o ajalahy nindre nibey ama’eo: Inao ty ho saon­tsie’o am’ondaty nisaontsy ama’o nanao ty hoe: Nanoen-drae’o mavesatse ty joka’ay, aa le hamaivaño ama’ay; Inao ty hilañona’o: Bey ta i fisafoan-draekoy ty anakikiko.
11 Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
Aa ndra t’ie nampijinien-draeko joka mavesatse, mbe ho tompeako ka o joka’ areoo; ie nandafa anahareo an-karavantsy, fa an-kalengo ka ty ihamofohako.
12 Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
Aa le nomb’ amy Rekhavame amy andro fahateloy t’Iarovame rekets’ ondaty iabio, ty amy saontsi’ i mpanjakaiy, vaho nanao ty hoe: Mibaliha amako ami’ty andro fahatelo.
13 Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
Le sinotra’ i mpanjakay ondatio, vaho napo’e i fanoroañe natolo’ o androana­vioy;
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
fa i fanoroa’ o ajalahioo ty nilañonà’e ami’ty hoe: Nanoen-draeko mavesatse ty joka’ areo, fe ho tovoñako o joka’ areoo, nandafa anahareo an-karavantsy ty raeko f’ie ho fofoheko an-kalengo.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
Aa le tsy hinao’ i mpanjakay ondatio; ie toe fandahara’ Iehovà, hampijadoñe i enta’ey, i tsi­nara’ Iehovà am-pità’ i Akià nte Silò am’ Iarovame, ana’ i Nebatey.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé, “Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi, ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese? Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli! Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn.
Aa ie nioni’ Israele iaby te tsy nihaoñe’ i mpanjakay, le hoe ty natoi’ ondatio amy mpanjakay: Ino ty anay amy Davide ao? Aman-dova amy ana’ Isaý hao zahay? Akia mb’an-kivoho’ areo ry Israele! Hajario i akiba’oy ry Davide. Aa le niavotse mb’ an-kiboho’ iareo mb’eo t’Israele.
17 Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
Fe mbe nifehe o ana’ Israele nimo­neñe amo rova’ Iehodaoo t’i Rekhavame.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
Nirahe’ i Rekhavame mpanjaka mb’eo, t’i Adorame, mpifeleke ty haba; f’ie finetsa’ Israele iaby vato le nihomake vaho nipitsike mb’ an-tsarete’e añe t’i Rekhavame nitson­demboke mb’e Ierosalaime mb’eo.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
Aa le niola amy anjomba’ i Davidey t’Israele pake henane.
20 Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
Ie amy zao, naho jinanji’ Israele iaby te tafampoly t’Iarovame, le nampisangitrife’ iereo mb’am-pivori-bey vaho nanoe’ iereo mpanjaka’ Israele iaby; leo raike tsy nañorike ty anjomba’ i Davide naho tsy Iehodà avao.
21 Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
Aa ie niheo mb’e Ierosalaime mb’eo t’i Rekhavame, le hene natonto’e ty anjomba’ Iehoda naho ty fifokoa’ i Beniamine, lahindefoñe soa-joboñe rai-hetse-tsi-valo-ale, hialy amy anjomba’ Israeley, hampolia’e amy Rekhavame ana’ i Selomò i fifeheañey.
22 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
Fe niheo amy Semaià, ondatin’ Añahare, ty tsaran’ Añahare nanao ty hoe:
23 “Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
Saon­tsio t’i Rekhavame, ana’ i Selomò mpanjaka’ Iehoday naho i anjomba’ Iehoda naho Beniamine iabiy vaho o ila’ ondatio, ty hoe;
24 ‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.”’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Hoe ty nafè’ Iehovà: Tsy hionjoñe mb’eo nahareo, tsy hialy amo ana’ Israele roahalahi’ areoo; songa mimpolia mb’an-kiboho’e añe, fa amako o raha zao. Aa le hinao’ iereo ty tsara’ Iehovà, vaho nimpoly, ty amy tsara’ Iehovày.
25 Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
Namboare’ Iarovame am-bohibohi’ i Efraime ao t’i Sekeme, le nimoneñe ao; vaho niavotse ama’e namboatse i Penoele.
26 Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
Le hoe ty fitsakorean-tro’ Iarovame, Himpoly amy anjomba’ i Davidey henane zao i fifeheañey,
27 Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
naho hionjomb’ amy anjomba’ Iehovà e Ierosalaimey ondatio hanao soroñe; le hitolik’ amy talè’ iareoy, homb’amy Rekhavame mpanjaka’ Iehoda ty arofo’ ondatio vaho havetra’ iareo iraho, ie himpoly mb’ an-dRekhavame mpanjaka’ Iehoda ao.
28 Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
Aa le nisafiry i mpanjakay, naho nandranjy bania volamena roe, vaho nanao ty hoe am’ondatio, Loho sarotse ty fionjona’ areo mb’e Ierosalaime mb’eo: ingo o ‘ndrahare’oo ry Israele, o ninday azo boak’ an-tane Mitsraimeo.
29 Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
Napo’e e Betele ao ty raike le napo’e e Dane ao ty raike.
30 Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
F’ie toe hakeo; amy te nionjoñe hitalaho ami’ty raik’ ama’e ondaty pake Daneo.
31 Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
Namboara’e kijà ka o haboañeo, vaho boak’ am’ ondaty tsotra iabio ty nanoe’e mpisoroñe fa tsy amo ana’ i Levio.
32 Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
Noriza’ Iarovame ty sabadidak’ ami’ty volam-paha-valo, ami’ty androm-paha-folo-lime ambi’ i volañey, hambañe amy sabadidake e Iehoday, ie nañenga amy kitreliy; izay ty e Betele ao, ie nanoa’e soroñe i bania namboare’e rey; vaho najado’e e Betele ao o mpisoro’ o toets’ abo namboare’eoo.
33 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.
Aa le niañambone mb’amy kitrely niranjie’e e Betele ao amy faha-folo-lime ambi’ i volam-paha-valoiy, i volañe nitsakorè’e an-tro’ey avao; le nañoriza’e sabadidake o ana’ Israeleo, vaho niañambone mb’amy kitrely fañemboha’ey.

< 1 Kings 12 >