< 1 Kings 12 >

1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
HELE aku la o Rehoboama i Sekema, no ka mea, ua hele ka Iseraela a pau i Sekema e hooalii ia ia.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
Eia hoi kekahi, a lohe mai la o Ieroboama ke keiki a Nebata e noho ana ia ma Aigupita, (no ka mea, ua holo aku la ia mai ke alo aku o Solomona a ke alii, a noho no Ieroboama ma Aigupita; )
3 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
Hoouna aku la lakou a kii ia ia; a hele mai Ieroboama a me ke anaina a pau o ka Iseraela, a olelo aku la lakou ia Hehoboama, i aku la.
4 “Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
Ua hookaumaha mai la kou makuakane i ka makou auamo; ano hoi e hoomama oe i ka hana ehaeha a kou makuakane, a me ka auamo kaumaha ana i kau mai ai maluna o makou, alaila e malama aku makou ia oe.
5 Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
I mai la oia ia lakou, O hoi oukou i na la ekolu, alaila e hele hou mai io'u nei. Hoi aku la no hoi na kanaka.
6 Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
A kukakuka mai la o Rehoboama me na kanaka kahiko, ka poe i ku ma ke alo o Solomona kona makuakane, i kona wa e ola ana, ninau mai la, Pehea ia oukou e olelo mai ai e hai aku au i keia poe kanaka?
7 Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
Olelo aku la lakou ia ia, i aku la, Ina e hookahu oe no keia poe kanaka i keia la, a e malama ia lakou, a e hai aku ia lakou, me ka olelo i na huaolelo pono ia lakou, alaila lilo lakou i poe kauwa mau nau.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
Haalele ae la oia i ka olelo a ka poe kanaka kahiko, a lakou i haawi ai ia ia, a kukakuka mai la me na kanaka ui i nunui pu ae me ia, na mea i ku imua o kona alo:
9 Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
Olelo mai la hoi oia ia lakou, Heaha ka olelo a oukou e olelo mai ai, e hai aku ai kakou i keia poe kanaka, ka poe i olelo mai ia'u, i ka i aua mai, E hoomama oe i ka auamo a kou makuakane i kau mai ai maluna o makou?
10 Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
Olelo aku la hoi ia ia na kanaka ui i nunui pu ae me ia, i aku la, Penei oe e olelo aku ai i keia poe kanaka i olelo ae nei ia oe, i ka i ana'e, Ua hookaumaha mai la kou makuakane i ka makou auamo; aka, e hoomama mai oe ia mea ia makou; e olelo aku oe ia lakou peneia, E kela aku ka manoanoa o kuu limaiki i ko ka puhaka o ko'u makuakane.
11 Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
Eia hoi ua hooili ka ko'u makuakane i ka auamo kaumaha maluna o oukou, o hoouka hou aku au ma ka oukou auamo; ua hahau ko'u makuakane ia oukou me na huipa, aka, e hahau aku au ia oukou me na moohueloawa.
12 Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
Pela i hoi mai ai o Ieroboama a me ka poe kanaka a pau io Rehoboama la i ke kolu o ka la, e like me ka ke alii i hoomaopopo ai, i ka i ana mai, E hoi mai oukou io'u nei i ke kolu o ka la.
13 Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
Hai mai la ke alii i kanaka me ka oolea, a ua haalele aku i ka olelo a ka poe kanaka kahiko, a lakou i haawi aku ai ia ia;
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
A olelo mai la hoi ia lakou mamuli o ka olelo a na kanaka ui, i mai la, Ua hookaumaha ko'u makuakane i ka oukou auamo, aka, e hoouka hou aku au ma ka oukou auamo; ua hahau ko'u makuakane ia oukou me na huipa, aka, e hahau aku wau ia oukou me na moohueloawa.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
Aole hoi i hoolohe ke alii i kanaka, no ka mea, no ka Haku mai no ia, i hooko mai oia i kana olelo a Iehova i olelo mai ai ma ka lima o Ahiia no Silo, ia Ieroboama ke keiki a Nebata.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé, “Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi, ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese? Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli! Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn.
A ike ae la ka Iseraela a pau, i ka hoolohe ole mai o ke alii ia lakou, olelo aku la ka poe kanaka i ke alii, e i ana, Heaha ko makou kuleana iloko o Davida? aole hooilina iloko o ke keiki a Iese. I ko oukou mau halelewa, e ka Iseraela: ano hoi, e nana i kau ohana iho, e Davida. Pela i hoi ai ka Iseraela i ko lakou mau halelewa.
17 Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
A o na mamo a Iseraela e noho ana ma na kulanakauhale o Davida, ua alii ae la o Hehoboama maluna o lakou.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
Alaila hoouna ae la o Rehoboama ia Adorama, ka lunaauhau, a hailuku ka Iseraela a pau ia ia me na pohaku a make ia. Nolaila hele wikiwiki ae la o Rehoboama ke alii e ee ae i kona kaa, e holo i Ierusalema.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
Pela i kipi ai ka Iseraela i ka ohana a Davida a hiki i keia la.
20 Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
Eia kekahi, i ka lohe ana o ka Iseraela a pau, ua hoi mai o Ieroboama, kii aku la lakou ia ia e hele mai i ke anaina, a hooalii lakou ia ia maluna o ka Iseraela a pau. Aohe mea i hahai i ka ohana a Davida, o ka Iuda wale no.
21 Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
A hoi mai o Rehoboama i Ierusalema, hoakoakoa mai la oia i ka ohana a pau a Iuda, a me ka ohana a Beniamina, hookahi haneri me kanawalu tausani kanaka i waeia, na kanaka kaua, e kaua aku i ka ohana a Iseraela e hoihoi mai i ke aupuni ia Rehoboama ke keiki a Solomona.
22 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
Aka, hiki mai ka olelo a ke Akua, ia Semaia, ke kanaka o ke Akua, i mai la,
23 “Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
E olelo aku ia Rehoboama ke keiki a Solomona, ke alii o Iuda, a i ka ohana a pau a Iuda, a me Beniamina, a me ke koena o na kanaka, e i aku,
24 ‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.”’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Ke i mai nei Iehova penei, Mai pii aku oukou, aole hoi e kaua aku i ko oukou poe hoahanau na mamo a Iseraela, e hoi kela kanaka keia kanaka i kona hale iho, no ka mea, no'u aku nei keia mea. Hoolohe aku la lakou i ka olelo a ka Haku, a huli lakou e hoi e like me ka olelo a Iehova.
25 Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
Alaila kukulu ae la o Ieroboama ia Sekema ma ka mauna Eperaima, a noho ae la malaila; a hele aku malaila aku, a kukulu ae la ia Penuela.
26 Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
I iho la o Ieroboama iloko o kona naau, Ano, e hoi aku ai ke aupuni i ka ohana a Davida.
27 Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
Ina e pii ae keia poe kanaka e kaumaha ma ka hale o Iehova, ma Ierusalema, alaila e hoi ka naau o keia poe kanaka i ko lakou haku ia Rehoboama ke alii o Iuda, a e pepehi mai lakou ia'u, a e hoi hou aku ia Rehoboama i ke alii o Iuda.
28 Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
Nolaila kuka iho la ke alii, a hana i na keikibipi gula elua, a i mai la oia ia lakou, He nui ko oukou hele ana i Ierusalema: Eia hoi kou mau akua, e Iseraela, i lawe mai ia oe mai ka aina mai o Aigupita.
29 Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
Kukulu ae la hoi oia i kekahi ma Betela, a waiho aku hoi i kekahi ma Dana.
30 Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
Lilo ae la keia mea i hewa, no ka mea, ua hele ae la na kanaka imua o kekahi i Dana.
31 Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
Hana iho la oia i hale no na wahi kiekie, a hoolilo ae la i kekahi mau makaainana i poe kahuna, aole o ko na mamo a Levi.
32 Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
Hana iho la hoi o Ieroboama i ka ahaaina i ka walu o ka malama i ka umikumamalima o ka la, e like me ka ahaaina maloko o Iuda, a kaumaha aku la maluna o ke kuahu. Pela oia i hana'i ma Betela, e kaumaha ana no na keikibipi ana i hana'i; a hoonoho aku la oia ma Betela i na kahuna o na wahi kiekie ana i hana'i.
33 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.
Pela oia i kaumaha ai ma ke kuahu ana i hana'i ma Betela i ka umikumamalima o ka la o ka walu o ka mahina, ana i noonoo ai ma kona naau; a ua hoomaopopo i ka ahaaina na ka poe mamo a Iseraela, a ua kaumaha aku la maluna o ke kuahu, a kuni hoi i ka mea ala.

< 1 Kings 12 >