< 1 Kings 12 >

1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
Rehoboamu nĩathiire Shekemu, nĩgũkorwo andũ a Isiraeli othe nĩmathiĩte kuo makamũtue mũthamaki.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
Rĩrĩa Jeroboamu mũrũ wa Nebati aiguire ũhoro ũcio (aarĩ o Misiri, kũrĩa oorĩire eherere Mũthamaki Solomoni), akiuma Misiri, akĩinũka.
3 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
Nĩ ũndũ ũcio andũ a Isiraeli magĩtũmanĩra Jeroboamu, nake Jeroboamu hamwe na kĩũngano gĩothe gĩa Isiraeli magĩthiĩ kũrĩ Rehoboamu makĩmwĩra atĩrĩ:
4 “Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
“Thoguo nĩatũigĩrĩire icooki iritũ, no rĩu tũhũthĩrie wĩra ũcio mũritũ na icooki rĩu iritũ rĩrĩa aatũigĩrĩire, na nĩtũrĩgũtungatagĩra.”
5 Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
Rehoboamu akĩmacookeria atĩrĩ, “Thiĩi mũgaacooka kũrĩ niĩ thuutha wa mĩthenya ĩtatũ.” Nĩ ũndũ ũcio andũ magĩĩthiĩra.
6 Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
Thuutha ũcio Mũthamaki Rehoboamu akĩhooya kĩrĩra kũrĩ athuuri arĩa maatungatagĩra ithe Solomoni rĩrĩa aarĩ muoyo. Akĩmooria atĩrĩ, “Mũngĩndaara njookerie andũ aya atĩa?”
7 Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Ũmũthĩ ũngĩĩtĩkĩra gũtuĩka ndungata ya andũ aya na ũmatungatĩre, na ũmacookerie na njĩra njagĩrĩru-rĩ, megũtũũra marĩ ndungata ciaku hĩndĩ ciothe.”
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
No Rehoboamu akĩregana na ũtaaro ũrĩa athuuri acio maamũheire, na akĩhooya kĩrĩra kuuma kũrĩ aanake a riika rĩake, arĩa maamũtungatagĩra.
9 Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
Akĩmooria atĩrĩ, “Inyuĩ mũngĩndaara atĩa? Andũ aya maranjĩĩra atĩ, ‘Tũhũthĩrie icooki rĩrĩa thoguo aatũigĩrĩire’ Ingĩmacookeria atĩa?”
10 Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
Aanake acio a riika rĩake makĩmũcookeria atĩrĩ, “Cookeria andũ acio makwĩrĩte atĩ, ‘Thoguo nĩatũigĩrĩire icooki iritũ, nowe tũhũthĩrie icooki rĩu,’ ũmeere atĩrĩ, ‘kaara gakwa ka mũira nĩ gatungu gũkĩra njohero ya baba.
11 Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
Baba aamũigĩrĩire icooki iritũ; niĩ nĩngũrĩritũhia makĩria. Baba aamũhũũraga na iboko; no niĩ ndĩrĩmũhũũraga na tũngʼaurũ.’”
12 Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
Thuutha wa mĩthenya ĩtatũ Jeroboamu na andũ othe magĩcooka kũrĩ Rehoboamu, o ta ũrĩa mũthamaki oigĩte atĩrĩ, “Mũgaacooka kũrĩ niĩ thuutha wa mĩthenya ĩtatũ.”
13 Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
Mũthamaki agĩcookeria andũ acio ũhoro ehĩte mũno. Akĩregana na ũtaaro ũrĩa aaheetwo nĩ athuuri,
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
akĩrũmĩrĩra ũtaaro wa aanake, akiuga atĩrĩ, “Baba nĩamũritũhĩirie icooki, no niĩ nĩngũrĩritũhia makĩria. Baba aamũhũũraga na iboko; niĩ ndĩrĩmũhũũraga na tũngʼaurũ.”
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
Nĩ ũndũ ũcio mũthamaki ndaigana gũthikĩrĩria andũ acio, tondũ maũndũ macio meekĩkire moimĩte kũrĩ Jehova, nĩguo kiugo kĩhingio kĩrĩa Jehova eerire Jeroboamu mũrũ wa Nebati na kanua ka Ahija ũrĩa Mũshiloni.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé, “Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi, ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese? Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli! Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn.
Rĩrĩa andũ othe a Isiraeli moonire atĩ mũthamaki ũcio nĩarega kũmathikĩrĩria, magĩcookeria mũthamaki atĩrĩ: “Tũrĩ na igai rĩrĩkũ harĩ Daudi, na nĩ gĩcunjĩ kĩrĩkũ tũrĩ nakĩo harĩ mũrũ wa Jesii? Cooka hema-inĩ ciaku wee Isiraeli! Wee Daudi-rĩ, menyerera nyũmba yaku wee mwene.” Nĩ ũndũ ũcio andũ othe a Isiraeli makĩinũka.
17 Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
No andũ a Isiraeli arĩa maatũũraga matũũra-inĩ ma Juda-rĩ, Rehoboamu agĩthiĩ na mbere kũmathamakĩra.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
Mũthamaki Rehoboamu agĩtũma Adoniramu ũrĩa warĩ mũrũgamĩrĩri wa andũ arĩa maarutithagio wĩra na hinya, no andũ a Isiraeli makĩmũhũũra na mahiga nyuguto, agĩkua. No Rehoboamu agĩĩthara, akĩhaica ngaari-inĩ yake ya ita, akĩũrĩra Jerusalemu.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
Nĩ ũndũ ũcio andũ a Isiraeli matũire maremeire nyũmba ya Daudi nginya ũmũthĩ.
20 Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
Rĩrĩa andũ a Isiraeli othe maaiguire atĩ Jeroboamu nĩacookete kuuma bũrũri wa Misiri, makĩmũtũmanĩra oke kĩũngano-inĩ, na makĩmũtua mũthamaki wa Isiraeli guothe. Mũhĩrĩga wa Juda noguo wiki warũmĩrĩire nyũmba ya Daudi.
21 Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
Rĩrĩa Rehoboamu aakinyire Jerusalemu, akĩũngania andũ othe a nyũmba ya Juda na a mũhĩrĩga wa Benjamini andũ 180,000 a kũrũa mbaara nĩgeetha makarũe na nyũmba ya Isiraeli, nĩguo macookerie Rehoboamu mũrũ wa Solomoni ũthamaki.
22 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
No rĩrĩ, kiugo kĩa Ngai gĩgĩkinyĩra Shemaia mũndũ wa Ngai akĩĩrwo atĩrĩ:
23 “Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
“Thiĩ wĩre Rehoboamu mũrũ wa Solomoni mũthamaki wa Juda, na nyũmba ya Juda yothe o na ya Benjamini na andũ arĩa angĩ othe, ũmeere atĩrĩ,
24 ‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.”’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
‘Jehova ekuuga ũũ: Tigai kwambata mũkahũũrane na ariũ a ithe wanyu, andũ a Isiraeli. O mũndũ wanyu wothe nĩacooke mũciĩ, nĩgũkorwo nĩ niĩ njĩkĩte ũndũ ũyũ.’” Nĩ ũndũ ũcio magĩathĩkĩra kiugo kĩa Jehova, magĩcooka mũciĩ o ta ũrĩa Jehova aathanĩte.
25 Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
Nake Jeroboamu akĩirigĩra itũũra rĩa Shekemu na rũthingo rwa hinya thĩinĩ wa bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma wa Efiraimu, agĩtũũra kuo. Kuuma kũu agĩthiĩ agĩaka itũũra rĩa Penieli.
26 Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
Jeroboamu agĩĩciiria atĩrĩ, “Ũthamaki wahota gũcookerera nyũmba ya Daudi.
27 Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
Andũ aya mangĩambata mathiĩ makarute magongona hekarũ-inĩ ya Jehova kũu Jerusalemu-rĩ, nĩmagacooka gwathĩkĩra mwathi wao Rehoboamu mũthamaki wa Juda. Nĩmakanjũraga na macookerere Mũthamaki Rehoboamu.”
28 Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
Thuutha wa kũhooya ũtaaro, mũthamaki nĩathondekire mĩhianano ĩĩrĩ ya njaũ cia thahabu. Akĩĩra andũ atĩrĩ, “Ũhoro wa kwambataga Jerusalemu nĩũkũmũritũhĩra mũno. Atĩrĩrĩ Isiraeli, ici ngai cianyu, iria ciamũrutire bũrũri wa Misiri.”
29 Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
Mũhianano ũmwe akĩũiga Betheli, na ũrĩa ũngĩ akĩũiga Dani.
30 Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
Naguo ũndũ ũyũ ũgĩtuĩka mehia; nĩgũkorwo andũ nĩmathiiaga o nginya Dani kũhooya mũhianano ũrĩa warĩ kũu.
31 Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
Jeroboamu nĩaakire mahooero kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru, na agĩthuura athĩnjĩri-ngai a kuuma kũrĩ andũ a mĩthemba yothe, o na gũtuĩka matiarĩ Alawii.
32 Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
Akĩambĩrĩria gĩathĩ mũthenya wa ikũmi na ĩtano mweri-inĩ wa ĩnana, ũtuĩke ta gĩathĩ kĩrĩa kĩagomanagwo Juda, na akĩrutĩra magongona kĩgongona-inĩ. Eekire ũguo kũu Betheli, akĩrutĩra mĩhianano ĩyo ya njaũ aathondekete magongona. Ningĩ kũu Betheli akĩiga athĩnjĩri-ngai kũndũ kũu gũtũũgĩru aathondekete.
33 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.
Mũthenya wa ikũmi na ĩtano mweri-inĩ wa ĩnana, mweri ũrĩa eethuurĩire we mwene, akĩruta magongona kĩgongona-inĩ kĩrĩa aakĩte kũu Betheli. Nĩ ũndũ ũcio akĩambĩrĩria gĩathĩ kĩu nĩ ũndũ wa andũ a Isiraeli, na akĩambata kĩgongona-inĩ kũruta magongona.

< 1 Kings 12 >