< 1 Kings 12 >

1 Rehoboamu sì lọ sí Ṣekemu, nítorí gbogbo Israẹli ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.
Forsothe Roboam cam in to Sichem; for al Israel was gaderid thidur to make hym kyng.
2 Nígbà tí Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó wà ní Ejibiti síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Solomoni ọba, ó sì wà ní Ejibiti.
`And sotheli Jeroboam, sone of Nabath, whanne he was yit in Egipt, and fledde fro the face of kyng Salomon, turnede ayen fro Egipt, for the deeth of Salomon was herd;
3 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jeroboamu, òun àti gbogbo ìjọ Israẹli sì lọ sọ́dọ̀ Rehoboamu, wọ́n sì wí fún un pé,
and thei senten, and clepiden hym. Therfor Jeroboam cam, and al the multitude of Israel, and thei spaken to Roboam,
4 “Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”
and seiden, Thi fadir puttide hardeste yok on vs, therfor abate thou a litil now of the hardest comaundement of thi fadir, and of the greuousiste yok which he puttide on vs, and we schulen serue to thee.
5 Rehoboamu sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.
Which Roboam seide to hem, Go ye `til to the thridde dai, and turne ye ayen to me.
6 Nígbà náà ni Rehoboamu ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbàgbà tí ń dúró níwájú Solomoni baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láààyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”
And whanne the puple hadde go, kyng Roboam took counsel with the eldere men, that stoden bifor Salomon, his fadir, while he lyuyde yit; and Roboam seide, What counsel yyue ye to me, that Y answere to the puple?
7 Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò máa ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”
Whiche seiden to hym, If thou obeiest to dai to this puple, and seruest this puple, and yyuest stide to her axyng, and spekist to hem liyte wordis, thei schulen be seruauntis to thee in alle daies.
8 Ṣùgbọ́n Rehoboamu kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.
Which Roboam forsook the counsel of elde men, which thei yauen to hym, and took yonge men, that weren nurschid with hym, and stoden nyy him;
9 Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, ‘Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀’?”
and he seide to hem, What counsel yyue ye to me, that Y answere to this puple, that seiden to me, Make thou esyere the yok which thi fadir puttide on vs?
10 Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.
And the yonge men, that weren nurschid with hym, seiden to hym, Thus speke thou to this puple, that spaken to thee, and seiden, Thi fadir made greuouse oure yok, releeue thou vs; thus thou schalt speke to hem, My leest fyngur is grettere than the bak of my fader;
11 Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàṣán nà yín, Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
and now my fadir puttide on you a greuouse yok, forsothe Y schal adde on youre yok; my fadir beet you with scourgis, forsothe Y schal bete you with scorpiouns.
12 Jeroboamu àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Rehoboamu ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”
Therfor Jeroboam, and al the puple, cam to Roboam, in the thridde dai, as the kyng spak, seiynge, Turne ye ayen to me in the thridde dai.
13 Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbàgbà fún un,
And the kyng answeride harde thingis to the puple, while the counsel of eldere men was forsakun, which thei hadden youe to hym;
14 Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo, èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i, baba mi fi pàṣán nà yín èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”
and he spak to hem bi the counsel of yonge men, and seide, My fadir made greuouse youre yok, forsothe Y schal adde to youre yok; my fadir beet you with scourgis, forsothe Y schal bete you with scorpiouns.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jeroboamu ọmọ Nebati láti ẹnu Ahijah ará Ṣilo ṣẹ.
And the kyng assentide not to the puple, for the Lord hadde turned awey, `ether hadde wlatid hym, that the Lord schulde reise his word, which he hadde spoke in the hond of Ahias of Silo to Jeroboam, sone of Nabath.
16 Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé, “Ìpín wo ni àwa ní nínú Dafidi, ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jese? Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Israẹli! Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dafidi!” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli padà sí ilé wọn.
Therfor the puple siy, that the kyng nolde here hem; and the puple answeride to the kyng, and seide, What part is to vs in Dauid, ether what eritage in the sone of Ysay? Israel, turne thou ayen in to thi tabernaclis; now, Dauid, se thou thin hows. And Israel yede in to hise tabernaclis.
17 Ṣùgbọ́n fún ti àwọn ọmọ Israẹli tí ń gbé nínú ìlú Juda, Rehoboamu jẹ ọba lórí wọn síbẹ̀.
Forsothe Roboam regnede on the sones of Israel, whiche euere dwelliden in the citees of Juda.
18 Ọba Rehoboamu rán Adoniramu jáde, ẹni tí ó wà ní ìkáwọ́ iṣẹ́ onírúurú, ṣùgbọ́n gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa. Ọba Rehoboamu, gbìyànjú láti dé inú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì sálọ sí Jerusalẹmu.
Therfore kyng Roboam sente Adhuram, that was on the tributis; and al the puple of Israel stonyde hym, and he was deed.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí ilé Dafidi títí di òní yìí.
Forsothe kyng Roboam stiede hastili on the chare, and fledde in to Jerusalem; and Israel departide fro the hows of Dauid, til in to present dai.
20 Nígbà tí gbogbo Israẹli sì gbọ́ pé Jeroboamu ti padà dé, wọ́n ránṣẹ́, wọ́n sì pè é wá sí àjọ, wọ́n sì fi jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli. Kò sí ẹnìkan tí ó tọ ilé Dafidi lẹ́yìn bí kò ṣe kìkì ẹ̀yà Juda nìkan.
Forsothe it was doon, whanne al Israel hadde herd that Jeroboam turnede ayen, thei senten, and clepiden hym, whanne the cumpany was gaderid togidere, and thei maden hym kyng on al Israel; and no man suede the hows of Dauid, outakun the lynage aloone of Juda.
21 Nígbà tí Rehoboamu sì dé sí Jerusalẹmu, ó kó gbogbo ilé Juda jọ, àti ẹ̀yà Benjamini; ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ènìyàn tí a yàn, tí wọ́n ń ṣe ológun, láti bá ilé Israẹli jà àti láti mú ìjọba náà padà bọ̀ sọ́dọ̀ Rehoboamu, ọmọ Solomoni.
Forsothe Roboam cam to Jerusalem, and gaderide al the hows of Juda, and the lynage of Beniamyn, an hundrid and fourescore thousynde of chosun men and weriours, that thei schulden fiyte ayens the hows of Israel, and schulden brynge ayen the rewme to Roboam, sone of Solomon.
22 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Ṣemaiah ènìyàn Ọlọ́run wá wí pé,
Forsothe the word of God was made to Semeia, the man of God, and seide,
23 “Sọ fún Rehoboamu, ọmọ Solomoni, ọba Juda àti fún gbogbo ilé Juda àti ti Benjamini, àti fún àwọn ènìyàn tókù wí pé,
Speke thou to Roboam, sone of Salomon, the kyng of Juda, and to al the hows of Juda and of Beniamyn, and to the residue of the puple, and seie thou, The Lord seith thes thingis,
24 ‘Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Israẹli. Kì olúkúlùkù yín padà sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.”’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
Ye schulen not stie, nether ye schulen fiyte ayens youre britheren, the sones of Israel; `a man turne ayen in to his hows, for this word is doon of me. Thei herden the word of the Lord, and thei turneden ayen fro the iurney, as the Lord comaundide to hem.
25 Nígbà náà ni Jeroboamu kọ́ Ṣekemu ní òkè Efraimu, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Penieli.
Forsothe Jeroboam bildide Sichem, in the hil of Effraym, and dwellide there; and he yede out fro thennus, and bildide Phanuel.
26 Jeroboamu rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsin yìí sí ilé Dafidi.
And Jeroboam seide in his herte, Now the rewme schal turne ayen to the hows of Dauid,
27 Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Rehoboamu ọba Juda. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Rehoboamu ọba Juda lọ.”
if this puple stieth to Jerusalem, that it make sacrifices in the hows of the Lord in Jerusalem; and the herte of this puple schal turne to her lord, Roboam, kyng of Juda; and thei schulen sle me, and schulen turne ayen to hym.
28 Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọrọ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Israẹli, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Ejibiti wá.”
And by counsel thouyt out, he made tweyne goldun caluys, and seide to hem, Nyle ye stie more in to Jerusalem; Israel, lo! thi goddis, that ledden thee out of the lond of Egipt.
29 Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Beteli, àti èkejì ní Dani.
And he settide oon in Bethel, and the tother in Dan.
30 Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dani láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.
And this word was maad to Israel in to synne; for the puple yede til in to Dan, to worschipe the calf.
31 Jeroboamu sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Lefi.
And Jeroboam made templis in hiye placis, and `he made preestis of the laste men of the puple, that weren not of the sones of Leuy.
32 Jeroboamu sì dá àsè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àsè tí ó wà ní Juda, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Beteli, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Beteli.
And he ordeynede a solempne dai in the eiythe monethe, in the fiftenthe dai of the monethe, bi the licnesse of solempnyte which was halewid in Juda. And he stiede, and made in lijk maner an auter in Bethel, that he schulde offre to the calues, whiche he hadde maad; and he ordeynede in Bethel preestis of the hiye places, whiche he hadde maad.
33 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Beteli. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.
And he styede on the auter, which he hadde bildid in Bethel, in the fiftenthe day of the eiythe monethe, which he hadde feyned of his herte; and he made solempnyte to the sones of Israel, and he stiede on the auter, that he schulde brenne encence.

< 1 Kings 12 >