< 1 Kings 11 >
1 Solomoni ọba fẹ́ ọ̀pọ̀ àjèjì obìnrin yàtọ̀ sí ọmọbìnrin Farao, àwọn ọmọbìnrin Moabu, àti ti Ammoni, ti Edomu, ti Sidoni àti ti àwọn ọmọ Hiti.
Salamon király pedig megszerete sok idegen asszonyt, még pedig a Faraó leányán kivül a Moábiták, Ammoniták, Edomiták, Sídonbeliek és Hitteusok leányait,
2 Wọ́n wá láti orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ fẹ́ wọn níyàwó tàbí ní ọkọ, nítorí wọn yóò yí ọkàn yín padà sí òrìṣà wọn.” Síbẹ̀síbẹ̀ Solomoni fàmọ́ wọn ní ìfẹ́.
Olyan népek közül, a kik felől azt mondotta volt az Úr az Izráel fiainak: Ne menjetek hozzájok, és őket se engedjétek magatokhoz jőni, bizonyára az ő isteneik után hajtják a ti szíveteket. Ezekhez ragaszkodék Salamon szeretettel.
3 Ó sì ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin obìnrin, àwọn ọmọ ọba àti ọ̀ọ́dúnrún àlè, àwọn ìyàwó rẹ̀ sì yí i ní ọkàn padà.
És valának néki feleségei, hétszáz királynéasszony és háromszáz ágyas; és az ő feleségei elhajták az ő szívét.
4 Bí Solomoni sì ti di arúgbó, àwọn ìyàwó rẹ̀ sì yí i ní ọkàn padà sí ọlọ́run mìíràn, ọkàn rẹ̀ kò sì ṣe déédé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
És mikor megvénült Salamon, az ő feleségei elhajták az ő szívét az idegen istenek után, úgy hogy nem volt már az ő szíve tökéletes az Úrhoz, az ő Istenéhez, a mint az ő atyjának, Dávidnak szíve.
5 Solomoni tọ Aṣtoreti òrìṣà àwọn ará Sidoni lẹ́yìn, àti Moleki òrìṣà ìríra àwọn ọmọ Ammoni.
Mert Salamon követi vala Astoretet, a Sídonbeliek istenét, és Milkómot, az Ammoniták útálatos bálványát.
6 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe búburú níwájú Olúwa; kò sì tọ Olúwa lẹ́yìn ní pípé, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
És gonosz dolgot cselekedék Salamon az Úr szemei előtt, és nem követé olyan tökéletességgel az Urat, mint Dávid, az ő atyja.
7 Lórí òkè tí ń bẹ níwájú Jerusalẹmu, Solomoni kọ́ ibi gíga kan fún Kemoṣi, òrìṣà ìríra Moabu, àti fún Moleki, òrìṣà ìríra àwọn ọmọ Ammoni.
Akkor építe Salamon templomot Kámosnak, a Moábiták útálatos bálványának a hegyen, a mely Jeruzsálem átellenében van, és Moloknak, az Ammon fiai útálatos bálványának.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe bẹ́ẹ̀ fún gbogbo àwọn àjèjì obìnrin rẹ̀, ẹni tí ń sun tùràrí, tí wọ́n sì ń rú ẹbọ fún òrìṣà wọn.
És ekképen cselekedék Salamon mind az ő idegen feleségeivel, a kik az ő isteneiknek tömjéneztek és áldoztak.
9 Olúwa bínú sí Solomoni nítorí ọkàn rẹ̀ ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó ti fi ara hàn án lẹ́ẹ̀méjì.
Megharaguvék azért az Úr Salamonra, hogy elhajlott az ő szíve az Úrtól, Izráel Istenétől, a ki megjelent volt néki kétszer is,
10 Bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti kìlọ̀ fún Solomoni kí ó má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn, ṣùgbọ́n Solomoni kò pa àṣẹ Olúwa mọ́.
És azt parancsolta volt néki, hogy ne kövessen idegen isteneket, és mégsem őrizte meg az Úr parancsolatját.
11 Nítorí náà Olúwa wí fún Solomoni pé, “Nítorí bí ìwọ ti ṣe nǹkan yìí, tí ìwọ kò sì pa májẹ̀mú mi àti àṣẹ mi mọ́, tí mo ti pàṣẹ fún ọ, dájúdájú èmi yóò fa ìjọba ya kúrò lọ́wọ́ rẹ, èmi yóò sì fi fún ẹlòmíràn.
Monda azért az Úr Salamonnak: Miután ez történt veled, és nem őrizted meg az én szövetségemet és az én rendelésimet, a melyeket parancsoltam néked: elszakasztván elszakasztom tőled az országot, és adom a te szolgádnak.
12 Ṣùgbọ́n, nítorí Dafidi baba rẹ, Èmi kì yóò ṣe é ní ọjọ́ rẹ. Èmi yóò fà á ya kúrò lọ́wọ́ ọmọ rẹ.
Mindazáltal míg élsz, nem cselekeszem ezt Dávidért, a te atyádért; hanem a te fiadnak kezétől szakasztom el azt.
13 Síbẹ̀ èmi kì yóò fa gbogbo ìjọba náà ya, ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀yà kan fún ọmọ rẹ nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi, àti nítorí Jerusalẹmu tí èmi ti yàn.”
De nem szakasztom el az egész birodalmat; hanem egy nemzetséget adok a te fiadnak Dávidért, az én szolgámért és Jeruzsálemért, a melyet magamnak választottam.
14 Nígbà náà ni Olúwa gbé ọ̀tá kan dìde sí Solomoni, Hadadi ará Edomu ìdílé ọba ni ó ti wá ní Edomu.
És ellenséget támaszta az Úr Salamonra, az Edombeli Hadádot, a ki az Edombeli királyi nemből való vala.
15 Ó sì ṣe, nígbà tí Dafidi wà ní Edomu, Joabu olórí ogun sì gòkè lọ láti sin àwọn ọmọ-ogun Israẹli ti a pa lójú ogun, ó sì pa gbogbo ọkùnrin Edomu.
Mert mikor Dávid az Edomiták ellen ment volt, és Joáb, a sereg fővezére elment volt a megöletteknek temetésére, és levágott minden férfiú nemet Edomban, –
16 Nítorí Joabu àti gbogbo Israẹli sì dúró níbẹ̀ fún oṣù mẹ́fà, títí wọ́n fi pa gbogbo ọkùnrin Edomu run.
Mert hat hónapig volt ott Joáb az egész Izráellel, míg minden férfiúi nemet ki nem vesztett Edomban, -
17 Ṣùgbọ́n Hadadi sálọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ará Edomu tí wọ́n jẹ́ ìránṣẹ́ baba rẹ̀. Hadadi sì wà ní ọmọdé nígbà náà.
Akkor szaladott vala el Hadád és vele együtt valami Edomiták az ő atyjának szolgái közül ő vele, bemenvén Égyiptomba. Hadád pedig akkor még kis gyermek volt.
18 Wọ́n sì dìde kúrò ní Midiani, wọ́n sì lọ sí Parani. Nígbà náà ni wọ́n mú ènìyàn pẹ̀lú wọn láti Parani wá, wọ́n sì lọ sí Ejibiti, sọ́dọ̀ Farao ọba Ejibiti ẹni tí ó fún Hadadi ní ilé àti ilẹ̀, ó sì fún un ní oúnjẹ.
Kik felkelvén Midiánból, menének Páránba, és melléjök vévén a Páránbeli férfiak közül, bemenének Égyiptomba a Faraóhoz, az Égyiptombeli királyhoz, a ki házat ada néki, és ételt, italt szolgáltata néki, és jószágot is ada néki.
19 Inú Farao sì dùn sí Hadadi púpọ̀ tí ó fi fún un ní arábìnrin aya rẹ̀ ní aya, arábìnrin Tapenesi, ayaba.
Igen kedvében lőn azért Hadád a Faraónak, úgyannyira, hogy feleségül adá néki az ő feleségének hugát, Táfnes királyasszonynak hugát.
20 Arábìnrin Tapenesi bí ọmọkùnrin kan fún un tí à ń pe orúkọ rẹ̀ ní Genubati, ẹni tí Tapenesi tọ́ dàgbà ní ààfin ọba. Níbẹ̀ ni Genubati ń gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ Farao fúnra rẹ̀.
És a Táfnes huga szülé néki Génubátot, az ő fiát, és elválasztá azt Táfnes a Faraó házában, és Génubát ott volt a Faraó házában, a Faraó fiai között.
21 Nígbà tí ó sì wà ní Ejibiti, Hadadi sì gbọ́ pé Dafidi ti sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, àti pé Joabu olórí ogun sì ti kú pẹ̀lú. Nígbà náà ni Hadadi wí fún Farao pé, “Jẹ́ kí n lọ, kí èmi kí ó le padà sí ìlú mi.”
Mikor pedig Hadád meghallotta Égyiptomban, hogy Dávid elaludt az ő atyáival, és hogy Joáb is, a seregnek fővezére, meghalt, monda Hadád a Faraónak: Bocsáss el engem, hadd menjek el az én földembe.
22 Farao sì wí fún un pé, “Kí ni ìwọ ṣe aláìní níbí, tí ìwọ fi fẹ́ padà lọ sí ìlú rẹ?” Hadadi sì wí pé, “Kò sí nǹkan, ṣùgbọ́n sá à jẹ́ kí èmi kí ó lọ!”
És felele néki a Faraó: Mi nélkül szűkölködöl én nálam, hogy a te földedbe igyekezel menni? Felele az: Semmi nélkül nem szűkölködöm, de kérlek bocsáss el engem.
23 Ọlọ́run sì gbé ọ̀tá mìíràn dìde sí Solomoni, Resoni ọmọ Eliada, ẹni tí ó ti sá kúrò lọ́dọ̀ Hadadeseri olúwa rẹ̀, ọba Soba.
És támaszta az Isten néki más ellenséget is, Rézont, az Eljada fiát, a ki elfutott vala Hadadézertől, a Sóbabeli királytól, az ő urától.
24 Ó sì kó ènìyàn jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, ó sì di olórí ogun ẹgbẹ́ kan, nígbà tí Dafidi fi pa ogun Soba run; wọ́n sì lọ sí Damasku, wọ́n ń gbé ibẹ̀, wọ́n sì jẹ ọba ní Damasku.
És hadakozó férfiakat gyűjtött maga mellé, és ő vala a sereg hadnagya, mikor megölé őket Dávid; azután Damaskusba menvén ott lakának, és uralkodának Damaskusban.
25 Resoni sì jẹ́ ọ̀tá Israẹli ní gbogbo ọjọ́ Solomoni, ó ń pa kún ibi ti Hadadi ṣe. Bẹ́ẹ̀ ni Resoni jẹ ọba ní Siria, ó sì ṣòdì sí Israẹli.
És ellensége volt Izráelnek Salamonnak egész életében, a nyomorúságon kivül, a melyet Hadád szerze, és gyűlölte Izráelt, és uralkodott Siriában.
26 Bákan náà Jeroboamu ọmọ Nebati sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọba. Ó sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ Solomoni, ará Efraimu ti Sereda, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ opó, orúkọ rẹ̀ ni Serua.
Azután Jeroboám, a Nébát fia, Seredából való Efrateus, – a kinek anyja Sérua, egy özvegy asszony volt – a Salamon szolgája emelte fel kezét a király ellen.
27 Èyí sì ni ìdí tí ó fi ṣọ̀tẹ̀ sí ọba: Solomoni kọ́ Millo, ó sì di ẹ̀yà ìlú Dafidi baba rẹ̀.
Annak pedig, a miért felemelte kezét a király ellen, ez volt az oka: Mikor Salamon megépítette Millót, és berakatta az ő atyjának, a Dávid városának romlását;
28 Jeroboamu jẹ́ ọkùnrin alágbára, nígbà tí Solomoni sì rí bí ọ̀dọ́mọkùnrin náà ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ dáradára, ó fi í ṣe olórí iṣẹ́ ìrú ilé Josẹfu.
Jeroboám erős férfiú vala; és látván Salamon, hogy az ő szolgája az ő dolgában szorgalmatos, reá bízá a József háza gondviselésének egész terhét.
29 Ó sì ṣe, ní àkókò náà Jeroboamu ń jáde kúrò ní Jerusalẹmu. Wòlíì Ahijah ti Ṣilo sì pàdé rẹ̀ lójú ọ̀nà, ó sì wọ agbádá tuntun. Àwọn méjèèjì nìkan ni ó sì ń bẹ ní oko,
És történt ebben az időben, hogy mikor kiment egyszer Jeroboám Jeruzsálemből, találkozék az úton Ahijával, a Silóbeli prófétával, és rajta új köpönyeg volt, és csak ketten valának a mezőn együtt.
30 Ahijah sì gbá agbádá tuntun tí ó wọ̀ mú, ó sì fà á ya sí ọ̀nà méjìlá.
És megragadván Ahija az új ruhát, a mely azon volt, hasítá azt tizenkét részre.
31 Nígbà náà ni ó sọ fún Jeroboamu pé, “Mú ọ̀nà mẹ́wàá fún ara rẹ, nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Wò ó, èmi yóò fa ìjọba náà ya kúrò ní ọwọ́ Solomoni, èmi yóò sì fi ẹ̀yà mẹ́wàá fún ọ.
És monda Jeroboámnak: Vedd el magadnak a tíz részt; mert ezt mondja az Úr, Izráel Istene: Ímé elszakasztom ez országot Salamon kezétől, és néked adom a tíz nemzetséget;
32 Ṣùgbọ́n nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi àti nítorí Jerusalẹmu, ìlú tí mo ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, òun yóò ní ẹ̀yà kan.
Egy nemzetséget hagyok pedig ő nála az én szolgámért, Dávidért, és Jeruzsálem városáért, a melyet magamnak választottam az Izráel minden nemzetségei közül,
33 Èmi yóò ṣe èyí nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì ti sin Aṣtoreti òrìṣà àwọn ará Sidoni, Kemoṣi òrìṣà àwọn ará Moabu, àti Moleki òrìṣà àwọn ọmọ Ammoni, wọn kò sì rìn ní ọ̀nà mi, tàbí ṣe èyí tí ó dára lójú mi, tàbí pa àṣẹ àti òfin mi mọ́ bí Dafidi baba Solomoni ti ṣe.
Még pedig azért, mert elhagytak engem, és imádták Astoretet, a Sídonbeliek istenét, és Kámost, a Moábiták istenét, és Milkomot, az Ammon fiainak istenét, és nem jártak az én utaimban, hogy azt cselekedték volna, a mi tetszett volna az én szemeimnek: az én rendelésimet és végzéseimet, a mint Dávid, az ő atyja.
34 “‘Ṣùgbọ́n èmi kì yóò gba gbogbo ìjọba náà lọ́wọ́ Solomoni; èmi ti mú un jẹ́ olórí ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi, ẹni tí mo yàn, tí ó sì ti pa òfin mi àti àṣẹ mi mọ́.
De nem veszem el az egész birodalmat az ő kezétől, hanem akarom, hogy fejedelem legyen életének minden idejében, Dávidért az én szolgámért, a kit választottam; mivelhogy megőrizte az én parancsolatimat és rendeléseimet;
35 Èmi yóò gba ìjọba náà ní ọwọ́ ọmọ rẹ̀, èmi yóò sì fi ẹ̀yà mẹ́wàá fún ọ.
Hanem az ő fiának kezétől már elveszem a királyságot, és néked adom azt, tudniillik a tíz nemzetséget.
36 Èmi yóò fi ẹ̀yà kan fún ọmọ rẹ kí Dafidi ìránṣẹ́ mi lè máa ní ìmọ́lẹ̀ níwájú mi nígbà gbogbo ní Jerusalẹmu, ìlú tí mo ti yàn láti fi orúkọ mi síbẹ̀.
Az ő fiának pedig egy nemzetséget adok, hogy Dávidnak, az én szolgámnak legyen előttem szövétneke mindenkor Jeruzsálemben, a városban, a melyet magamnak választottam, hogy ott helyheztessem az én nevemet.
37 Ṣùgbọ́n ní ti ìwọ, Èmi yóò mú ọ, ìwọ yóò sì jẹ ọba lórí ohun gbogbo tí ọkàn rẹ ń fẹ́; ìwọ yóò jẹ ọba lórí Israẹli.
Téged pedig felveszlek, és uralkodol mindenekben a te lelkednek kívánsága szerint, és király lész az Izráelen.
38 Bí ìwọ bá ṣe gbogbo èyí tí mo pàṣẹ fún ọ, tí o sì rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú mi nípa pípa òfin àti àṣẹ mi mọ́, bí i Dafidi ìránṣẹ́ mi ti ṣe, Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò kọ́ ilé òtítọ́ fún ọ bí èyí tí mo kọ́ fún Dafidi, èmi yóò sì fi Israẹli fún ọ.
És ha te minden parancsolatimnak engedéndesz, és járándasz az én utaimban, és azt cselekedénded, a mi tetszik nékem, megőrizvén az én rendelésimet és parancsolatimat, a mint Dávid, az én szolgám cselekedett: én veled leszek, és építek néked állandó házat, a mint Dávidnak építettem, és néked adom az Izráelt.
39 Èmi yóò sì rẹ irú-ọmọ Dafidi sílẹ̀ nítorí èyí, ṣùgbọ́n kì í ṣe títí láé.’”
És megsanyargatom ezért a Dávid magvát: de még sem örökre.
40 Solomoni wá ọ̀nà láti pa Jeroboamu, ṣùgbọ́n Jeroboamu sálọ sí Ejibiti, sọ́dọ̀ Ṣiṣaki ọba Ejibiti, ó sì wà níbẹ̀ títí Solomoni fi kú.
Igyekezik vala pedig Salamon megölni Jeroboámot; ezért felkelvén Jeroboám, futa Égyiptomba, Sésákhoz, az Égyiptombeli királyhoz, és ott volt Égyiptomban, Salamon haláláig.
41 Ìyókù iṣẹ́ Solomoni àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ọgbọ́n rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ìṣe Solomoni bí?
Salamonnak egyéb dolgai pedig és minden cselekedetei, a melyeket cselekedett, és bölcsesége avagy nem írattattak-é meg a Salamon cselekedeteiről írott könyvben?
42 Solomoni sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu lórí gbogbo Israẹli ní ogójì ọdún.
Az az idő pedig, a melyben uralkodott Salamon Jeruzsálemben az egész Izráelen: negyven esztendő.
43 Nígbà náà ni Solomoni sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Rehoboamu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
És elaluvék Salamon az ő atyáival, és eltemetteték az ő atyjának, Dávidnak városában. És Roboám, az ő fia uralkodék helyette.