< 1 Kings 10 >

1 Nígbà tí ayaba Ṣeba gbọ́ òkìkí Solomoni àti ì bà ṣe pọ̀ rẹ̀ ní ti orúkọ Olúwa, ó sì wá láti dán an wò pẹ̀lú ìbéèrè líle.
A królowa z Saby usłyszawszy sławę o Salomonie i o imieniu Pańskiem przyjechała, aby go doświadczyła w zagadkach.
2 Ó sì wá sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ẹgbẹ́ èrò ńlá ńlá, pẹ̀lú ìbákasẹ tí ó ru tùràrí, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ wúrà, àti òkúta iyebíye, ó sì wá sí ọ̀dọ̀ Solomoni, ó sì bá a sọ gbogbo èyí tí ń bẹ ní ọkàn rẹ̀.
I wjechała do Jeruzalemu z wielkim bardzo pocztem, z wielbłądami niosącemi rzeczy wonne, i złota bardzo wiele, i kamienia drogiego, a przyszedłszy do Salomona mówiła do niego o wszystkiem, co miała w sercu swojem.
3 Solomoni sì dáhùn gbogbo ìbéèrè rẹ̀; kò sì sí èyí tí ó ṣòro fún ọba láti ṣàlàyé fún un.
Ale jej odpowiedział Salomon na jej wszystkie słowa; nie było nic skrytego przed królem, na coby jej nie odpowiedział.
4 Nígbà tí ayaba Ṣeba sì rí gbogbo ọgbọ́n Solomoni àti ààfin tí ó ti kọ́.
Przetoż widząc królowa z Saby wszystkę mądrość Salomonową, i dom, który był zbudował,
5 Oúnjẹ tí ó wà lórí i tábìlì rẹ̀, ìjókòó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti ìdúró àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti ìwọṣọ wọn, àwọn agbọ́tí rẹ̀, àti ẹbọ sísun tí ó sun ní ilé Olúwa, kò sì sí ẹ̀mí kan nínú rẹ̀ mọ́!
Także potrawy stołu jego, i siadania sług jego, i stawania służących mu, i szaty ich, i podczasze jego, i wschody, po których wstępował do domu Pańskiego, zdumiała się bardzo;
6 Ó sì wí fún ọba pé, “Òtítọ́ ni ìròyìn tí mo gbọ́ ní orílẹ̀-èdè mi ní ti iṣẹ́ rẹ àti ọgbọ́n rẹ.
I rzekła do króla: Prawdziwać to mowa, którąm słyszała w ziemi mojej o sprawach twoich, i o mądrości twojej;
7 Ṣùgbọ́n èmi kò sì gba nǹkan wọ̀nyí gbọ́ títí ìgbà tí mo wá, tí mo sì fi ojú ara mi rí i. Sì kíyèsi i, a kò sọ ìdajì wọn fún mi; ìwọ sì ti fi ọgbọ́n àti ìrora kọjá òkìkí tí mo gbọ́.
Alem nie wierzyła powieściom onym, ażem sama przyjechawszy oglądała to oczyma swemi. Ale mi tego nie powiedziano i połowy. Większa jest mądrość i dobroć twoja niżeli sława, którąm słyszała.
8 Báwo ni inú àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe dùn tó! Báwo ni inú dídùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí wọ́n ń dúró níwájú rẹ nígbà gbogbo, tí wọ́n sì ń gbọ́ ọgbọ́n rẹ!
Błogosławieni mężowie twoi, błogosławieni słudzy twoi, którzy zawsze przed tobą stoją, i słuchają mądrości twojej.
9 Ìbùkún ni fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó ní inú dídùn sí ọ, tí ó sì gbé ọ ka orí ìtẹ́ Israẹli. Nítorí tí Olúwa fẹ́ràn Israẹli títí láé, ni ó ṣe fi ọ́ jẹ ọba, láti ṣe ìdájọ́ àti òdodo.”
Niechże będzie Pan, Bóg twój, błogosławiony, który cię sobie upodobał, aby cię posadził na stolicy Izraelskiej, przeto iż Pan umiłował Izraela na wieki, i postanowił cię królem, abyś czynił sąd i sprawiedliwość.
10 Ó sì fún ọba ní ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà, tùràrí olóòórùn dídùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, àti òkúta iyebíye. Kò sí irú ọ̀pọ̀lọpọ̀ tùràrí tí a mú wá tí ó dàbí irú èyí tí ayaba Ṣeba fi fún Solomoni ọba.
I dała królowi sto i dwadzieścia talentów złota, i rzeczy wonnych bardzo wiele, i kamienia drogiego. Nie przyszło nigdy potem tak wiele wonnych rzeczy, jako dała królowa z Saby królowi Salomonowi.
11 (Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́-ọkọ̀ Hiramu tí ó mú wúrà láti Ofiri wá, wọ́n mú igi algumu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àti òkúta oníyebíye láti Ofiri wá.
Nadto okręty Hirama, które przynosiły złoto z Ofir, przyniosły z Ofir drzewa almugimowego bardzo wiele i kamienia drogiego.
12 Ọba sì fi igi algumu náà ṣe òpó fún ilé Olúwa àti fún ààfin ọba, àti láti ṣe dùùrù pẹ̀lú àti ohun èlò orin olókùn fún àwọn akọrin. Irú igi algumu bẹ́ẹ̀ kò dé mọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò rí wọn títí di òní yìí.)
I poczynił król z drzewa almugimowego wschody do domu Pańskiego, i do domu królewskiego, i harfy, i lutnie śpiewakom; a nigdy nie przywożono takiego drzewa almugimowego, ani widziano aż do dnia tego.
13 Solomoni ọba sì fún ayaba Ṣeba ní gbogbo ìfẹ́ rẹ̀ àti ohun tí ó béèrè, yàtọ̀ sí èyí tí a fi fún un láti ọwọ́ Solomoni ọba wa. Nígbà náà ni ó yípadà, ó sì lọ sí ìlú rẹ̀, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Król także Salomon dał królowej z Saby wszystko, czego chciała i czego żądała, oprócz tego, co jej dał z dobrej woli ręką królewską. Potem odjechawszy, wróciła się do ziemi swojej, ona i słudzy jej.
14 Ìwọ̀n wúrà tí Solomoni ń gbà ní ọdún kan sì jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà tálẹ́ǹtì wúrà,
A była waga onego złota, które przychodziło Salomonowi na każdy rok, sześć set sześćdziesiąt i sześć talentów złota,
15 láìka èyí tí ó ń gbà lọ́wọ́ àwọn ajẹ́lẹ̀ àti àwọn oníṣòwò, àti ti gbogbo àwọn ọba Arabia, àti àwọn baálẹ̀ ilẹ̀.
Oprócz tego, co przychodziło od kupców i z handlu tych, którzy rzeczami wonnemi kupczyli, i od wszystkich królów Arabskich, i książąt ziemi.
16 Solomoni ọba sì ṣe igba asà wúrà lílù; ẹgbẹ̀ta ṣékélì wúrà ni ó lọ sí asà kan.
Przetoż uczynił król Salomon dwieście tarczy ze złota ciągnionego, sześć set syklów złota wychodziło na każdą tarczą;
17 Ó sì túnṣe ọ̀ọ́dúnrún asà wúrà lílù, pẹ̀lú òsùwọ̀n wúrà mẹ́ta tí ó tàn sí asà kọ̀ọ̀kan. Ọba sì kó wọn sí ilé igbó Lebanoni.
Przytem trzy sta puklerzy ze złota ciągnionego, trzy grzywny złota odważył na każdy puklerz. I schował je król w domu lasu Libanowego.
18 Nígbà náà ni ọba sì ṣe ìtẹ́ eyín erin ńlá kan, ó sì fi wúrà dídára bò ó.
Uczynił także król stolicę wielką z kości słoniowej, i powlókł ją szczerem złotem.
19 Ìtẹ́ náà sì ní àtẹ̀gùn mẹ́fà, ẹ̀yìn rẹ̀ sì ṣe róbótó lókè. Ní ibi ìjókòó méjèèjì náà ni ìrọpá wà, pẹ̀lú kìnnìún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn.
Sześć stopni było u onej stolicy, a wierzch okrągły był na stolicy z tyłu; i poręcze były z obudwu stron siedzenia, a dwa lwy stały u poręczy;
20 Kìnnìún méjìlá sì dúró níbi àtẹ̀gùn mẹ́fẹ̀ẹ̀fà, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní òpin àtẹ̀gùn kọ̀ọ̀kan, kò tí ì sí irú rẹ̀ ní ìjọba kan rí.
A dwanaście lwów stało na onych sześciu stopniach z obu stron. Nie było nic takiego urobiono w żadnych królestwach.
21 Gbogbo ohun èlò mímu Solomoni ọba sì jẹ́ wúrà àti gbogbo ohun èlò ààfin igbó Lebanoni sì jẹ́ kìkì wúrà. Kò sí nǹkan kan tí a fi fàdákà ṣe, nítorí a kò ka fàdákà sí nǹkan kan ní gbogbo ọjọ́ Solomoni.
Nadto wszystkie naczynia, z których pijał król Salomon, były złote, także i wszystkie naczynia domu lasu Libanowego były z szczerego złota; nic nie było ze srebra, ani go miano w jakiej cenie za dni Salomonowych.
22 Ọba sì ní ọkọ̀ Tarṣiṣi kan pẹ̀lú ọkọ̀ Hiramu ní Òkun. Ẹ̀ẹ̀kan ní ọdún mẹ́ta ni ọkọ̀ Tarṣiṣi ń dé, tí ó ń mú wúrà àti fàdákà, eyín erin àti ìnàkí àti ẹyẹ-ológe wá.
Albowiem okręty królewskie były na morzu z okrętami Hiramowemi: raz we trzy lata wracały się okręty z morza, przynosząc złoto i srebro, kości słoniowe, i koczkodany, i pawie.
23 Solomoni ọba sì pọ̀ ní ọrọ̀ àti ní ọgbọ́n ju gbogbo àwọn ọba ayé lọ.
A tak uwielmożniony jest król Salomon nad wszystkie króle ziemskie bogactwy i mądrością.
24 Gbogbo ayé sì ń wá ojú Solomoni láti gbọ́ ọgbọ́n tí Ọlọ́run ti fi sí i ní ọkàn.
Przetoż wszyscy obywatele ziemi pragnęli widzieć Salomona, aby słuchali mądrości jego, którą był dał Bóg w serce jego.
25 Bí ọdún ṣe ń gorí ọdún olúkúlùkù àwọn tí ń wá sì ń mú ẹ̀bùn tirẹ̀ wá, ohun èlò fàdákà àti ohun èlò wúrà àti ẹ̀wù, àti tùràrí olóòórùn dídùn, ẹṣin àti ìbáaka.
I przynosił mu każdy dary swe, naczynia srebrne i naczynia złote, i szaty, i zbroje, i rzeczy wonne, konie, i muły, a to na każdy rok.
26 Solomoni sì kó kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jọ; ó sì ní ẹgbàáje kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin, tí ó fi pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ àti pẹ̀lú ọba ní Jerusalẹmu.
Tak iż nazgromadzał Salomon wozów, i jezdnych, a miał tysiąc i czterysta wozów, i dwanaście tysięcy jezdnych, które rozsadził po miastach wozów, i przy sobie w Jeruzalemie.
27 Ọba sì jẹ́ kí fàdákà pọ̀ ní Jerusalẹmu bí òkúta, àti igi kedari ni ó ṣe kí ó dàbí igi sikamore tí ń bẹ ní àfonífojì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀.
I złożył król srebra w Jeruzalemie tak wiele, jako kamienia, a ceder jako sykomorów, których na polu rośnie bardzo wiele.
28 A mú àwọn ẹṣin wá fún Solomoni láti Ejibiti àti láti Kue, oníṣòwò ọba rà wọ́n láti Kue fún owó.
Przywodzono też konie Salomonowi z Egiptu, i towary rozliczne; bo kupcy królewscy brali towary rozliczne za pewne pieniądze.
29 Wọ́n ń mú kẹ̀kẹ́ kan gòkè láti Ejibiti wá fún ẹgbẹ̀ta ṣékélì fàdákà àti ẹṣin kan fún àádọ́jọ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún mú wọn wá fún ọba àwọn ọmọ Hiti àti ọba àwọn ọmọ Aramu.
A wychodził i przychodził cug woźników z Egiptu za sześć set srebrników, a koń za sto i pięćdziesiąt. A tak wszyscy królowie Hetejscy, i królowie Syryjscy z rąk ich koni dostawali.

< 1 Kings 10 >