< 1 Kings 10 >

1 Nígbà tí ayaba Ṣeba gbọ́ òkìkí Solomoni àti ì bà ṣe pọ̀ rẹ̀ ní ti orúkọ Olúwa, ó sì wá láti dán an wò pẹ̀lú ìbéèrè líle.
Et la reine de Saba ouït le nom de Salomon et le nom du Seigneur, et elle vint pour éprouver le roi en lui proposant des énigmes.
2 Ó sì wá sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ẹgbẹ́ èrò ńlá ńlá, pẹ̀lú ìbákasẹ tí ó ru tùràrí, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ wúrà, àti òkúta iyebíye, ó sì wá sí ọ̀dọ̀ Solomoni, ó sì bá a sọ gbogbo èyí tí ń bẹ ní ọkàn rẹ̀.
Elle entra dans Jérusalem avec une suite nombreuse, et des chameaux chargés de parfums et d'une immense quantité d'or et de pierres précieuses; elle fut introduite auprès de Salomon, et elle lui dit toutes les choses qu'il y avait en son cœur.
3 Solomoni sì dáhùn gbogbo ìbéèrè rẹ̀; kò sì sí èyí tí ó ṣòro fún ọba láti ṣàlàyé fún un.
Salomon l'éclaira sur toutes ses questions; il n'y eut pas une de ses questions à laquelle le roi négligeât de répondre.
4 Nígbà tí ayaba Ṣeba sì rí gbogbo ọgbọ́n Solomoni àti ààfin tí ó ti kọ́.
Et la reine de Saba vit toute la sagesse de Salomon, le palais qu'il avait bâti,
5 Oúnjẹ tí ó wà lórí i tábìlì rẹ̀, ìjókòó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti ìdúró àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti ìwọṣọ wọn, àwọn agbọ́tí rẹ̀, àti ẹbọ sísun tí ó sun ní ilé Olúwa, kò sì sí ẹ̀mí kan nínú rẹ̀ mọ́!
Les mets de sa table, les logements de ses serviteurs, la tenue de ses officiers, ses vêtements, ses échansons, et les holocaustes qu'il offrait dans le temple du Seigneur, et elle en fut hors d'elle-même.
6 Ó sì wí fún ọba pé, “Òtítọ́ ni ìròyìn tí mo gbọ́ ní orílẹ̀-èdè mi ní ti iṣẹ́ rẹ àti ọgbọ́n rẹ.
Et elle dit au roi Salomon: C'était la vérité qu'on m'avait dite en mon pays,
7 Ṣùgbọ́n èmi kò sì gba nǹkan wọ̀nyí gbọ́ títí ìgbà tí mo wá, tí mo sì fi ojú ara mi rí i. Sì kíyèsi i, a kò sọ ìdajì wọn fún mi; ìwọ sì ti fi ọgbọ́n àti ìrora kọjá òkìkí tí mo gbọ́.
Au sujet de ton éloquence et de ta sagesse; j'avais refusé de croire ce qu'on m'en avait rapporté, jusqu'à ce que je fusse venue moi-même et que j'eusse vu de mes yeux; et je reconnais qu'on ne m'avait point appris la moitié de ce qui réellement existe. Tu as beaucoup ajouté aux merveilles dont j'avais ouï parler chez moi.
8 Báwo ni inú àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe dùn tó! Báwo ni inú dídùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí wọ́n ń dúró níwájú rẹ nígbà gbogbo, tí wọ́n sì ń gbọ́ ọgbọ́n rẹ!
Heureuses tes femmes, heureux tes serviteurs qui sont toujours auprès de toi, et qui recueillent toute ta sagesse.
9 Ìbùkún ni fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó ní inú dídùn sí ọ, tí ó sì gbé ọ ka orí ìtẹ́ Israẹli. Nítorí tí Olúwa fẹ́ràn Israẹli títí láé, ni ó ṣe fi ọ́ jẹ ọba, láti ṣe ìdájọ́ àti òdodo.”
Béni soit le Seigneur ton Dieu qui s'est complu en toi, pour te donner le trône d'Israël, parce que le Seigneur Dieu aime ce peuple, et qu'il l'affermira pour toujours. Le Seigneur t'a fait leur roi pour que les jugements soient selon la justice et selon l'équité.
10 Ó sì fún ọba ní ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà, tùràrí olóòórùn dídùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, àti òkúta iyebíye. Kò sí irú ọ̀pọ̀lọpọ̀ tùràrí tí a mú wá tí ó dàbí irú èyí tí ayaba Ṣeba fi fún Solomoni ọba.
Elle donna à Salomon cent vingt talents d'or, et une immense quantité d'épices et de pierres précieuses. Il n'était jamais arrivé à Jérusalem autant d'épices que la reine de Saba en donna au roi Salomon.
11 (Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́-ọkọ̀ Hiramu tí ó mú wúrà láti Ofiri wá, wọ́n mú igi algumu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àti òkúta oníyebíye láti Ofiri wá.
Et le vaisseau d'Hiram qui avait transporté l'or d'Ophir, apporta une énorme quantité de bois rares et de pierres précieuses.
12 Ọba sì fi igi algumu náà ṣe òpó fún ilé Olúwa àti fún ààfin ọba, àti láti ṣe dùùrù pẹ̀lú àti ohun èlò orin olókùn fún àwọn akọrin. Irú igi algumu bẹ́ẹ̀ kò dé mọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò rí wọn títí di òní yìí.)
Et le roi fit avec les bois des balustrades pour le temple et le palais; puis, des lyres et des harpes pour les chanteurs. Il n'était jamais arrivé de tels bois rares en la terre promise, et l'on n'en avait vu nulle part avant ce jour-là.
13 Solomoni ọba sì fún ayaba Ṣeba ní gbogbo ìfẹ́ rẹ̀ àti ohun tí ó béèrè, yàtọ̀ sí èyí tí a fi fún un láti ọwọ́ Solomoni ọba wa. Nígbà náà ni ó yípadà, ó sì lọ sí ìlú rẹ̀, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Et le roi Salomon donna à la reine de Saba tout ce qu'elle voulut, tout ce qu'elle lui demanda, outre ce qu'il lui donna spontanément. Et elle s'en alla, et elle retourna en sa contrée avec tous ses serviteurs.
14 Ìwọ̀n wúrà tí Solomoni ń gbà ní ọdún kan sì jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà tálẹ́ǹtì wúrà,
Et le poids de l'or, qui arriva au roi Salomon en une année, fut de six cent soixante-six talents,
15 láìka èyí tí ó ń gbà lọ́wọ́ àwọn ajẹ́lẹ̀ àti àwọn oníṣòwò, àti ti gbogbo àwọn ọba Arabia, àti àwọn baálẹ̀ ilẹ̀.
Sans compter les tributs de ceux qui lui étaient soumis, marchands, rois de la rive gauche de l'Euphrate, ou princes de la terre promise.
16 Solomoni ọba sì ṣe igba asà wúrà lílù; ẹgbẹ̀ta ṣékélì wúrà ni ó lọ sí asà kan.
Et Salomon fit faire trois cents javelines d'or battu, chacune de trois cents sicles d'or,
17 Ó sì túnṣe ọ̀ọ́dúnrún asà wúrà lílù, pẹ̀lú òsùwọ̀n wúrà mẹ́ta tí ó tàn sí asà kọ̀ọ̀kan. Ọba sì kó wọn sí ilé igbó Lebanoni.
Et trois cents armures d'or battu, de trois mines d'or chacune; et il les consacra dans le palais de bois du Liban.
18 Nígbà náà ni ọba sì ṣe ìtẹ́ eyín erin ńlá kan, ó sì fi wúrà dídára bò ó.
Il fit faire aussi un grand trône d'ivoire, qu'il revêtit de lames d'or très fin.
19 Ìtẹ́ náà sì ní àtẹ̀gùn mẹ́fà, ẹ̀yìn rẹ̀ sì ṣe róbótó lókè. Ní ibi ìjókòó méjèèjì náà ni ìrọpá wà, pẹ̀lú kìnnìún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn.
On montait sur le trône par six degrés; il y avait des faces de taureaux derrière le trône, deux bras des deux côtés du siège et deux lions auprès des bras.
20 Kìnnìún méjìlá sì dúró níbi àtẹ̀gùn mẹ́fẹ̀ẹ̀fà, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní òpin àtẹ̀gùn kọ̀ọ̀kan, kò tí ì sí irú rẹ̀ ní ìjọba kan rí.
Il y avait douze lions sur les degrés, six à droite, six à gauche; on ne voyait rien de semblable dans aucun royaume.
21 Gbogbo ohun èlò mímu Solomoni ọba sì jẹ́ wúrà àti gbogbo ohun èlò ààfin igbó Lebanoni sì jẹ́ kìkì wúrà. Kò sí nǹkan kan tí a fi fàdákà ṣe, nítorí a kò ka fàdákà sí nǹkan kan ní gbogbo ọjọ́ Solomoni.
Et tous les vases dont se servait Salomon étaient d'or, ses baignoires étaient d'or; tous les meubles du palais de bois du Liban étaient d'or et de pièces rapportées. On n'y voyait point d'argent; car ce métal était compté pour rien du temps de Salomon;
22 Ọba sì ní ọkọ̀ Tarṣiṣi kan pẹ̀lú ọkọ̀ Hiramu ní Òkun. Ẹ̀ẹ̀kan ní ọdún mẹ́ta ni ọkọ̀ Tarṣiṣi ń dé, tí ó ń mú wúrà àti fàdákà, eyín erin àti ìnàkí àti ẹyẹ-ológe wá.
Et cela parce que Salomon avait un vaisseau de Tharsis à la mer, avec la flotte d'Hiram; tous les trois ans un vaisseau venait de Tharsis chargé d'or, d'argent et de pierres rares et travaillées.
23 Solomoni ọba sì pọ̀ ní ọrọ̀ àti ní ọgbọ́n ju gbogbo àwọn ọba ayé lọ.
Et Salomon fut grand en science et en richesses par-dessus tous les rois de la terre.
24 Gbogbo ayé sì ń wá ojú Solomoni láti gbọ́ ọgbọ́n tí Ọlọ́run ti fi sí i ní ọkàn.
Tous les rois de la terre demandèrent à le voir, et à entendre la sagesse que Dieu avait mise en son cœur.
25 Bí ọdún ṣe ń gorí ọdún olúkúlùkù àwọn tí ń wá sì ń mú ẹ̀bùn tirẹ̀ wá, ohun èlò fàdákà àti ohun èlò wúrà àti ẹ̀wù, àti tùràrí olóòórùn dídùn, ẹṣin àti ìbáaka.
Et, chaque année, ils lui apportaient tous des présents des vases d'or, des vêtements, de la myrrhe, des épices, des chevaux et des mules.
26 Solomoni sì kó kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jọ; ó sì ní ẹgbàáje kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin, tí ó fi pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ àti pẹ̀lú ọba ní Jerusalẹmu.
Salomon avait, pour ses chars, quatre mille cavales, et dix mille chevaux pour ses cavaliers; il les avait mis dans les villes des chars ou auprès de lui à Jérusalem, et il était chef de tous les rois depuis l'Euphrate jusqu'au territoire des Philistins et aux frontières de l'Égypte.
27 Ọba sì jẹ́ kí fàdákà pọ̀ ní Jerusalẹmu bí òkúta, àti igi kedari ni ó ṣe kí ó dàbí igi sikamore tí ń bẹ ní àfonífojì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Et le roi rendit à Jérusalem l'or et l'argent aussi communs que les pierres; il y amena autant de cèdres qu'il y a de mûriers dans les champs.
28 A mú àwọn ẹṣin wá fún Solomoni láti Ejibiti àti láti Kue, oníṣòwò ọba rà wọ́n láti Kue fún owó.
Salomon tirait des chevaux de l'Égypte; il y avait à Thécoé un marché royal, et on les allait prendre à Thécoé à prix d'argent.
29 Wọ́n ń mú kẹ̀kẹ́ kan gòkè láti Ejibiti wá fún ẹgbẹ̀ta ṣékélì fàdákà àti ẹṣin kan fún àádọ́jọ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún mú wọn wá fún ọba àwọn ọmọ Hiti àti ọba àwọn ọmọ Aramu.
L'attelage d'un char, venant d'Égypte, coûtait cent sicles d'argent et cinquante sicles par cheval. Il en était de même pour tous les rois des Hettéens et de la Syrie; ces achats venaient par mer.

< 1 Kings 10 >