< 1 Kings 1 >

1 Nígbà tí Dafidi ọba di arúgbó, ọjọ́ rẹ̀ sì pọ̀, ara rẹ̀ kò le è móoru bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n da ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ bò ó.
Hĩndĩ ĩrĩa Mũthamaki Daudi aakũrire na agatindĩka mĩaka-rĩ, ndaiguaga ũrugarĩ o na mamũhumbĩra na nguo.
2 Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí fún un pé, “Ẹ jẹ́ kí a wá ọ̀dọ́mọbìnrin wúńdíá kan kí ó dúró ti ọba, kì ó sì máa tọ́jú rẹ̀. Kí ó dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀ kí ara ọba olúwa wa lè móoru.”
Nĩ ũndũ ũcio ndungata ciake ikĩmwĩra atĩrĩ, “Reke tũcarie mũirĩtu mwĩthĩ gathirange, atungatagĩre mũthamaki na ũndũ wa kũmũmenyerera, na akomage hamwe nake nĩguo mũthamaki, mwathi witũ, aiguage ũrugarĩ.”
3 Nígbà náà ni wọ́n lọ jákèjádò ilẹ̀ Israẹli láti wá ọ̀dọ́mọbìnrin arẹwà, wọ́n sì rí Abiṣagi, ará Ṣunemu, wọ́n sì mú un wá sí ọ̀dọ̀ ọba.
Magĩetha mũirĩtu mũthaka Isiraeli guothe, makĩona Abishagi ũrĩa Mũshunami, na makĩmũrehe kũrĩ mũthamaki.
4 Ọmọbìnrin náà rẹwà gidigidi; ó sì ń ṣe ìtọ́jú ọba, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un, ṣùgbọ́n ọba kò sì bá a lòpọ̀.
Mũirĩtu ũcio aarĩ mũthaka mũno; nake akĩmenyerera mũthamaki na akĩmũtungatĩra, no mũthamaki ndaigana gũkoma nake.
5 Adonijah ẹni tí ìyá rẹ̀ ń ṣe Haggiti sì gbé ara rẹ̀ ga, ó sì wí pé, “Èmi yóò jẹ ọba.” Ó sì ṣètò kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin, pẹ̀lú àádọ́ta ọkùnrin láti máa sáré níwájú rẹ̀.
Na rĩrĩ, Adonija, ũrĩa nyina aarĩ Hagithu, akĩĩyumĩria, akiuga atĩrĩ, “Nĩ niĩ ngũtuĩka mũthamaki.” Nĩ ũndũ ũcio agĩthagathaga ngaari cia ita na mbarathi, na andũ mĩrongo ĩtano mathiiage matengʼerete marĩ mbere yake.
6 (Baba rẹ̀ kò bà á nínú jẹ́ rí nípa bíbéèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi hùwà báyìí?” Ó sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin, òun ni a bí lé Absalomu.)
(Ithe ndaamũkaanĩtie ũndũ, kana akamũũria atĩrĩ, “Wĩkĩte ũna na ũna nĩkĩ?” Ningĩ aarĩ mũndũ mũthaka mũno, na nĩwe waciarĩtwo thuutha wa Abisalomu.)
7 Adonijah sì gbèrò pẹ̀lú Joabu, ọmọ Seruiah àti Abiatari àlùfáà, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un.
Nake Adonija akĩrĩkanĩra na Joabu mũrũ wa Zeruia, na Abiatharu mũthĩnjĩri-Ngai, nao magĩtĩkĩra kũmũteithĩrĩria.
8 Ṣùgbọ́n Sadoku àlùfáà, Benaiah ọmọ Jehoiada, Natani wòlíì, Ṣimei àti ọ̀rẹ́ rẹ̀ Rei àti olórí ogun Dafidi ni kò darapọ̀ mọ́ Adonijah.
No Zadoku mũthĩnjĩri-Ngai, na Benaia mũrũ wa Jehoiada, na Nathani ũrĩa mũnabii, na Shimei, na Rei, na arangĩri arĩa a mwanya a Daudi matianyiitanĩire na Adonija.
9 Nígbà náà ni Adonijah fi àgùntàn àti màlúù àti ẹran ọ̀sìn tí ó sanra rú ẹbọ níbi Òkúta Soheleti tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ En-Rogeli. Ó sì pe gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ ọba, àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí wọ́n jẹ́ ìránṣẹ́ ọba.
Nake Adonija akĩruta igongona rĩa ngʼondu, na ngʼombe, na njaũ iria noru Ihiga-inĩ rĩa Zohelethu, hakuhĩ na Eni-Rogeli. Nake agĩĩta ariũ a ithe othe, na nĩo ariũ a mũthamaki, na andũ othe a Juda arĩa maarĩ anene a nyũmba ya ũthamaki,
10 Ṣùgbọ́n kò pe Natani wòlíì tàbí Benaiah tàbí àwọn olórí tàbí Solomoni arákùnrin rẹ̀.
no ndaigana gwĩta Nathani ũrĩa mũnabii, kana Benaia, kana arangĩri arĩa a mwanya, o na kana mũrũ wa ithe Solomoni.
11 Nígbà náà ni Natani béèrè lọ́wọ́ Batṣeba, ìyá Solomoni pé, “Ǹjẹ́ ìwọ kò gbọ́ pé Adonijah, ọmọ Haggiti ti jẹ ọba láìjẹ́ pé Dafidi olúwa wa mọ̀ sí i?
Nake Nathani akĩũria Bathisheba, nyina wa Solomoni atĩrĩ, “Nĩũiguĩte atĩ Adonija mũrũ wa Hagithu nĩatuĩkĩte mũthamaki, Daudi mwathi witũ atekũmenya?
12 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, jẹ́ kí èmi gbà ọ́ ní ìmọ̀ràn bí ìwọ ṣe lè gba ẹ̀mí rẹ là àti ẹ̀mí ọmọ rẹ Solomoni.
Na rĩrĩ, reke ngũtaare ũrĩa ũngĩhota kũhonokia muoyo waku na muoyo wa mũrũguo Solomoni.
13 Lọ sọ́dọ̀ Dafidi ọba, kí o sì wí fún un pé, ‘Olúwa mi ọba, ǹjẹ́ ìwọ kò búra fún ìránṣẹ́ rẹ pé, “Dájúdájú Solomoni ọmọ rẹ ni yóò jọba lẹ́yìn mi, yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ mi?” Èéṣe nígbà náà tí Adonijah fi jẹ ọba?’
Ũkĩra ũthiĩ kũrĩ Mũthamaki Daudi ũmwĩre atĩrĩ, ‘Mũthamaki mwathi wakwa, githĩ ndwehĩtire kũrĩ niĩ, ndungata yaku ũkĩnjĩĩra atĩrĩ: “Ti-itherũ Solomoni mũrũguo nĩwe ũgaatuĩka mũthamaki thuutha wakwa, na nĩwe ũgaikarĩra gĩtĩ gĩakwa gĩa ũthamaki”? Rĩu-rĩ, nĩ kĩĩ gĩtũmĩte Adonija atuĩke mũthamaki?’
14 Níwọ́n ìgbà tí ìwọ sì wà níbẹ̀, tí o sì ń bá ọba sọ̀rọ̀ èmi yóò wá, láti wádìí ohun tí o ti sọ.”
Ũrĩ o kũu ũkĩaria na mũthamaki, na niĩ njũke ndoonye kuo nĩguo njĩkĩre hinya ũguo ũkũmwĩra.”
15 Bẹ́ẹ̀ ni Batṣeba lọ rí ọba ní inú yàrá rẹ̀, ọba sì gbó gidigidi níbi tí Abiṣagi ará Ṣunemu ti ń ṣe ìránṣẹ́ fún ọba.
Nĩ ũndũ ũcio Bathisheba agĩthiĩ kuona mũthamaki ũcio mũkũrũ kanyũmba gake ga thĩinĩ, kũrĩa aatungatagĩrwo nĩ Abishagi ũrĩa Mũshunami.
16 Batṣeba sì tẹríba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba. Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?”
Bathisheba akĩinamĩrĩra, agĩturia ndu mbere ya mũthamaki. Nake mũthamaki akĩmũũria atĩrĩ, “Ũkwenda atĩa?”
17 Ó sì wí fún ọba pé, “Olúwa mi; ìwọ fúnra rẹ̀ fi Olúwa Ọlọ́run rẹ búra fún ìránṣẹ́ rẹ pé, ‘Solomoni ọmọ rẹ yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, yóò sì jókòó lórí ìtẹ́ mi.’
Akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mwathi wakwa, wee mwene nĩwehĩtire harĩ niĩ ndungata yaku na rĩĩtwa rĩa Jehova Ngai waku, ũkiuga atĩrĩ: ‘Solomoni mũrũguo nĩwe ũgaatuĩka mũthamaki thuutha wakwa, na nĩwe ũgaikarĩra gĩtĩ gĩakwa kĩa ũnene.’
18 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Adonijah ti di ọba, ìwọ, ọba olúwa mi kò sì mọ̀ nípa rẹ̀.
No rĩrĩ, Adonija nĩatuĩkĩte mũthamaki, na wee mũthamaki mwathi wakwa ndũmenyete ũhoro ũcio.
19 Òun sì ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ màlúù, àti ẹran tí ó ní ọ̀rá, àti àgùntàn rú ẹbọ, ó sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, àti Abiatari àlùfáà àti Joabu balógun, ṣùgbọ́n kò sì pe Solomoni ìránṣẹ́ rẹ.
Nĩarutĩte igongona inene rĩa ngʼombe nyingĩ, na njaũ noru, na ngʼondu, na ageeta ariũ a mũthamaki othe, na Abiatharu ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, na Joabu ũrĩa mũnene wa mbũtũ cia ita, no ndetĩte Solomoni ndungata yaku.
20 Olúwa mi ọba, ojú gbogbo Israẹli ń bẹ lára rẹ, láti mọ ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ olúwa mi ọba lẹ́yìn rẹ.
Mũthamaki mwathi wakwa, andũ a Isiraeli othe nĩwe macũthĩrĩirie, nĩguo ũmamenyithie nũũ ũgaikarĩra gĩtĩ kĩa ũnene thuutha waku wee mũthamaki, mwathi wakwa.
21 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tí olúwa mi ọba bá sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, wọn yóò sì ka èmi àti Solomoni sí ẹlẹ́ṣẹ̀.”
Kwaga ũguo-rĩ, rĩrĩa mũthamaki mwathi wakwa agaakoma ahurũke hamwe na maithe make, niĩ na mũrũ wakwa Solomoni tũgaatuuo ta andũ ageri ngero.”
22 Bí ó sì ti ń bá ọba sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Natani wòlíì sì wọlé.
Hĩndĩ ĩrĩa aaragia na mũthamaki, Nathani ũrĩa mũnabii agĩkinya.
23 Wọ́n sì sọ fún ọba pé, “Natani wòlíì wà níbí.” Ó sì lọ síwájú ọba, ó wólẹ̀, ó sì dojúbolẹ̀.
Nao makĩĩra mũthamaki atĩrĩ, “Mũnabii Nathani arĩ haha.” Nĩ ũndũ ũcio Nathani agĩthiĩ mbere ya mũthamaki, akĩinamĩrĩra, agĩturumithia ũthiũ thĩ.
24 Natani sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ, olúwa mi ọba, ti sọ pé Adonijah ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn rẹ àti pé òun ni yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ?
Nathani akĩũria atĩrĩ, “Wee mũthamaki mwathi wakwa-rĩ, nĩũtuĩte atĩ Adonija nĩwe ũgaatuĩka mũthamaki thuutha waku, na atĩ nĩwe ũgaikarĩra gĩtĩ gĩaku kĩa ũnene?
25 Ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ ní òní, ó sì ti rú ẹbọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ màlúù, àti ẹran ọlọ́ràá àti àgùntàn. Ó sì ti pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, balógun àti Abiatari àlùfáà. Nísìnsinyìí, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì wí pé, ‘Kí Adonijah ọba kí ó pẹ́!’
Ũmũthĩ nĩaikũrũkĩte na akaruta igongona inene rĩa ngʼombe nyingĩ, na njaũ noru, na ngʼondu. Na ageeta ariũ a mũthamaki othe, na anene a thigari othe, na Abiatharu ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai. Rĩu nĩ kũrĩa maraarĩa na makanyua marĩ hamwe nake, makiugaga atĩrĩ, ‘Mũthamaki Adonija arotũũra nginya tene!’
26 Ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́ rẹ, àti Sadoku àlùfáà, àti Benaiah ọmọ Jehoiada, àti Solomoni ìránṣẹ́ rẹ ni kò pè.
No rĩrĩ, niĩ ndungata yaku, na Zadoku ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, na Benaia mũrũ wa Jehoiada, na ndungata yaku Solomoni ndanatwĩta.
27 Ṣé nǹkan yìí ni olúwa mi ọba ti ṣe láìjẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ mọ ẹni tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ olúwa mi ọba lẹ́yìn rẹ?”
Ũndũ ũyũ-rĩ, nĩ mũthamaki mwathi wakwa wĩkĩte atamenyithĩtie ndungata ciake nũũ ũgũikarĩra gĩtĩ kĩa ũnene kĩa mũthamaki mwathi wakwa thuutha wake?”
28 Nígbà náà ni Dafidi ọba wí pé, “Pe Batṣeba wọlé wá.” Ó sì wá síwájú ọba, ó sì dúró níwájú rẹ̀.
Hĩndĩ ĩyo Mũthamaki Daudi akiuga atĩrĩ, “Ĩtai Bathisheba oke.” Nĩ ũndũ ũcio Bathisheba agĩũka harĩ mũthamaki, akĩrũgama mbere yake.
29 Ọba sì búra pé, “Dájúdájú bí Olúwa ti wà ẹni tí ó ti gbà mí kúrò nínú gbogbo wàhálà
Nake mũthamaki akĩĩhĩta, akiuga atĩrĩ: “O ta ũrĩa Jehova atũũraga muoyo, ũrĩa wanaahonokia kuuma mathĩĩna-inĩ mothe,
30 Lónìí dandan ni èmi yóò gbé ohun tí mo ti fi Olúwa Ọlọ́run Israẹli búra fún yọ pé, Solomoni ọmọ rẹ ni yóò jẹ ọba lẹ́yìn mi, àti pé yóò jókòó lórí ìtẹ́ mi ní ipò mi.”
ti-itherũ ũmũthĩ nĩguo ngũhingia ũrĩa ndehĩtire kũrĩ we na rĩĩtwa rĩa Jehova Ngai wa Isiraeli, ngĩkwĩra atĩrĩ: Solomoni mũrũguo nĩwe ũgaatuĩka mũthamaki thuutha wakwa, na nĩwe ũgaikarĩra gĩtĩ gĩakwa kĩa ũnene handũ hakwa.”
31 Nígbà náà ni Batṣeba tẹríba, ó sì kúnlẹ̀ níwájú ọba pé, “Kí olúwa mi Dafidi ọba kí ó pẹ́!”
Nake Bathisheba akĩinamĩrĩra, agĩturumithia ũthiũ thĩ, na agĩturia ndu mbere ya mũthamaki, akiuga atĩrĩ, “Mũthamaki mwathi wakwa Daudi arotũũra nginya tene!”
32 Dafidi ọba sì wí pé, “Ẹ pe Sadoku àlùfáà wọlé fún mi àti Natani wòlíì àti Benaiah ọmọ Jehoiada.” Nígbà tí wọ́n wá síwájú ọba,
Mũthamaki Daudi akiuga atĩrĩ, “Ĩtai Zadoku ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, na Nathani ũrĩa mũnabii, na Benaia mũrũ wa Jehoiada moke.” Rĩrĩa mookire mbere ya mũthamaki,
33 ọba sì wí fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn ìránṣẹ́ olúwa yín pẹ̀lú yín kí ẹ sì mú kí Solomoni ọmọ mi kí ó gun ìbáaka mi, kí ẹ sì mú un sọ̀kalẹ̀ wá sí Gihoni.
akĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi na ndungata cia mwathi wanyu na mũhaicie Solomoni mũrũ wakwa igũrũ rĩa nyũmbũ yakwa, mũmũikũrũkie nginya Gihoni.
34 Níbẹ̀ ni Sadoku àlùfáà àti Natani wòlíì yóò ti fi òróró yàn án ní ọba lórí Israẹli. Ẹ fọn fèrè, kí ẹ sì ké pé, ‘Kí Solomoni ọba kí ó pẹ́!’
Mũrĩ kũu, mũreke Zadoku ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai na Nathani ũrĩa mũnabii mamũitĩrĩrie maguta atuĩke mũthamaki wa Isiraeli. Ningĩ mũhuhe karumbeta, na mwanĩrĩre atĩrĩ, ‘Mũthamaki Solomoni arotũũra nginya tene!’
35 Nígbà náà ni kí ẹ sì gòkè pẹ̀lú rẹ̀, kí ó sì wá, kí ó sì jókòó sórí ìtẹ́ mi, kí ó sì jẹ ọba ní ipò mi. Èmi ti yàn án ní ọba lórí gbogbo Israẹli àti Juda.”
Ningĩ mũcooke mwambate nake, oke aikarĩre gĩtĩ gĩakwa kĩa ũnene, na athamake handũ hakwa. Nĩndĩmũthuurĩte aathanage Isiraeli na Juda.”
36 Benaiah ọmọ Jehoiada sì dá ọba lóhùn pé, “Àmín! Kí Olúwa Ọlọ́run olúwa mi ọba, kéde rẹ̀ bẹ́ẹ̀.
Benaia mũrũ wa Jehoiada agĩcookeria mũthamaki atĩrĩ, “Ameni! Jehova, Ngai wa mũthamaki mwathi wakwa arotũma gũtuĩke guo.
37 Bí Olúwa ti wà pẹ̀lú olúwa mi ọba, bẹ́ẹ̀ ni kí ó wà pẹ̀lú Solomoni kí ó lè mú kí ìjọba rẹ̀ pẹ́ ju ìtẹ́ olúwa mi Dafidi ọba lọ!”
O ta ũrĩa Jehova akoretwo arĩ hamwe na mũthamaki mwathi wakwa, aroikara hamwe na Solomoni na atũme wathani wake ũnenehe gũkĩra wathani wa mũthamaki mwathi wakwa Daudi!”
38 Nígbà náà ni Sadoku àlùfáà, Natani wòlíì, Benaiah ọmọ Jehoiada, àwọn ará Kereti àti Peleti sì sọ̀kalẹ̀ wá wọ́n sì gbé Solomoni gun ìbáaka Dafidi ọba wá sí Gihoni.
Tondũ ũcio Zadoku ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, na Nathani ũrĩa mũnabii, na Benaia mũrũ wa Jehoiada, hamwe na Akerethi na Apelethi, magĩikũrũka, makĩhaicia Solomoni nyũmbũ ya Mũthamaki Daudi, makĩmumagaria nginya Gihoni.
39 Sadoku àlùfáà sì mú ìwo òróró láti inú àgọ́, ó sì dà á sí Solomoni lórí. Nígbà náà ni wọ́n sì fọn fèrè, gbogbo àwọn ènìyàn sì ké pé, “Kí Solomoni ọba kí ó pẹ́!”
Zadoku ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai akĩruta rũhĩa rwa maguta kuuma hema-inĩ ĩrĩa nyamũre na agĩitĩrĩria Solomoni. Ningĩ makĩhuha karumbeta, nao andũ othe makĩanĩrĩra, makiuga atĩrĩ, “Mũthamaki Solomoni arotũũra nginya tene!”
40 Gbogbo ènìyàn sì gòkè tọ̀ ọ́ lẹ́yìn wọ́n ń fọn ìpè, wọ́n sì ń yọ ayọ̀ ńlá, tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ mì fún ìró wọn.
Andũ othe makĩambata mamũrũmĩrĩire, makĩhuhaga mĩtũrirũ me na gĩkeno kĩnene, nginya thĩ ĩgĩthingitha nĩ mũrurumo.
41 Adonijah àti gbogbo àwọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gbọ́ ọ́ bí wọ́n ti ń jẹun tán, wọ́n ń gbọ́ ìpè, Joabu sì wí pé, “Kí ní ìtumọ̀ gbogbo ariwo nínú ìlú yìí?”
Adonija na ageni othe arĩa maarĩ hamwe nake makĩigua mũrurumo ũcio rĩrĩa maarĩ hakuhĩ kũrĩĩkia iruga rĩao. Rĩrĩa maiguire mũgambo wa karumbeta, Joabu akĩũria atĩrĩ, “Inegene rĩu rĩothe rĩrĩ itũũra-inĩ nĩ rĩa kĩĩ?”
42 Bí ó sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Jonatani ọmọ Abiatari àlùfáà sì dé, Adonijah sì wí pé, “Wọlé wá, ọkùnrin yíyẹ ìwọ gbọdọ̀ mú ìròyìn rere wá.”
O akĩaragia-rĩ, Jonathani mũrũ wa Abiatharu ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai agĩkinya. Adonija akĩmwĩra atĩrĩ, “Toonya thĩinĩ. Mũndũ wa bata tawe no nginya akorwo nĩ ũhoro mwega aatũrehere.”
43 Jonatani sì dáhùn, ó sì wí fún Adonijah pé, “Lóòótọ́ ni olúwa wa Dafidi ọba, fi Solomoni jẹ ọba.
Jonathani agĩcookia atĩrĩ; “Aca ti ũguo! Mũthamaki Daudi mwathi witũ nĩatuĩte Solomoni mũthamaki.
44 Ọba sì ti rán Sadoku àlùfáà, Natani wòlíì, Benaiah ọmọ Jehoiada àti àwọn ará Kereti àti Peleti pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì ti gbé e gun ìbáaka ọba,
Mũthamaki nĩoimagarĩtie Solomoni hamwe na Zadoku ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, na Nathani ũrĩa mũnabii, na Benaia mũrũ wa Jehoiada, na Akerethi na Apelethi, na nĩmahaicĩtie Solomoni nyũmbũ ya mũthamaki,
45 Sadoku àlùfáà àti Natani wòlíì ti fi òróró yàn án ní ọba ní Gihoni. Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gòkè wá pẹ̀lú ayọ̀, ìlú sì ń hó pẹ̀lú rẹ̀. Èyí ni ariwo tí ẹ̀yin ń gbọ́.
na rĩrĩ, Zadoku ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, na Nathani ũrĩa mũnabii nĩmamũitĩrĩirie maguta kũu Gihoni atuĩke mũthamaki. Kuuma hau nĩmambatĩte makiugagĩrĩria, narĩo itũũra rĩothe rĩkamaamũkĩria. Rĩu nĩrĩo inegene rĩrĩa mũraigua.
46 Solomoni sì ti jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀.
O na ningĩ, Solomoni nĩaikarĩire gĩtĩ gĩake kĩa ũnene gĩa ũthamaki.
47 Àwọn ìránṣẹ́ ọba sì ti tún wá láti bá olúwa wa Dafidi ọba yọ̀, wí pé, ‘Kí Ọlọ́run rẹ̀ mú orúkọ Solomoni lókìkí ju tirẹ̀ lọ àti kí ìtẹ́ rẹ̀ kí ó pọ̀ ju tirẹ̀ lọ!’ Ọba sì tẹ ara rẹ̀ ba lórí ibùsùn rẹ̀,
Ningĩ atongoria a ũthamaki nĩmokĩte gũcookeria Mũthamaki Daudi, mwathi witũ, ngaatho, makoiga atĩrĩ: ‘Ngai waku arotũma rĩĩtwa rĩa Solomoni rĩgĩe na ngumo gũkĩra rĩaku, naguo ũthamaki wake ũroneneha gũkĩra waku!’ Nake mũthamaki nĩainamĩrĩra na aakĩgooca arĩ o gĩtanda-inĩ,
48 ọba sì wí pé, ‘Ògo ni fún Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó ti jẹ́ kí ojú mi rí ẹnìkan tí ó jókòó lórí ìtẹ́ mi lónìí.’”
oiga atĩrĩ, ‘Jehova Ngai wa Isiraeli arogoocwo, ũrĩa wĩtĩkĩrĩtie maitho makwa meyonere mwana ũmwe wakwa agĩikarĩra gĩtĩ gĩakwa kĩa ũnene ũmũthĩ.’”
49 Nígbà náà ni gbogbo àwọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ Adonijah dìde ní ìdágìrì, wọ́n sì túká.
Hĩndĩ ĩyo ageni othe a Adonija makĩmaka, magĩũkĩra, magĩĩthiĩra, o mũndũ na njĩra yake.
50 Ṣùgbọ́n Adonijah sì bẹ̀rù Solomoni, ó lọ, ó sì di ìwo pẹpẹ mú.
No rĩrĩ, Adonija, nĩ ũndũ wa gwĩtigĩra Solomoni, agĩthiĩ akĩĩnyiitĩrĩra hĩa cia kĩgongona.
51 Nígbà náà ni a sì sọ fún Solomoni pé, “Adonijah bẹ̀rù Solomoni ọba, ó sì di ìwo pẹpẹ mú, Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí ọba Solomoni búra fún mi lónìí pé, òun kì yóò fi idà pa ìránṣẹ́ rẹ̀.’”
Hĩndĩ ĩyo Solomoni akĩmenyithio atĩrĩ, “Adonija nĩaretigĩra Mũthamaki Solomoni, na nĩenyiitĩrĩire hĩa cia kĩgongona. Aroiga atĩrĩ, ‘Mũthamaki Solomoni nĩehĩte harĩ niĩ ũmũthĩ anjĩĩre atĩ ndekũũraga ndungata yake na rũhiũ rwa njora.’”
52 Solomoni sì dáhùn pé, “Bí ó bá fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ ẹni ọ̀wọ̀, irun orí rẹ̀ kan kì yóò sì bọ́ sílẹ̀; ṣùgbọ́n bí a bá rí búburú kan ní ọwọ́ rẹ̀ òun yóò kú.”
Solomoni agĩcookia atĩrĩ, “Angĩona atĩ nĩ mũndũ wagĩrĩire, gũtirĩ rũcuĩrĩ rwake rwa mũtwe rũkaagũa thĩ; no angĩoneka na ũũru no agaakua.”
53 Nígbà náà ni Solomoni ọba rán àwọn ènìyàn, wọ́n sì mú un sọ̀kalẹ̀ láti ibi pẹpẹ wá. Adonijah sì wá, ó sì foríbalẹ̀ fún Solomoni ọba, Solomoni sì wí pé, “Lọ ilé rẹ.”
Ningĩ Mũthamaki Solomoni agĩtũma andũ, nao makĩmũikũrũkia kuuma kĩgongona-inĩ. Adonija akĩinamĩrĩra harĩ Mũthamaki Solomoni, nake Solomoni akĩmwĩra atĩrĩ, “Inũka gwaku mũciĩ.”

< 1 Kings 1 >