< 1 John 5 >
1 Olúkúlùkù ẹni tí ó bá gbàgbọ́ pé Jesu ni Kristi, a bí i nípa ti Ọlọ́run: àti olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ràn. Ẹni tí ó bi nì, ó fẹ́ràn ẹni tí a bí nípasẹ̀ rẹ̀ pẹ̀lú.
Mindenki, aki hiszi, hogy Jézus a Krisztus, Istentől született, és mindenki, aki szereti az Atyát, a Fiút is szereti, aki tőle született.
2 Nípa èyí ni àwa mọ̀ pé àwa fẹ́ràn àwọn ọmọ Ọlọ́run, nígbà tí a bá fẹ́ràn Ọlọ́run, tí a sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́.
Abból ismerjük meg, hogy szeretjük Isten gyermekeit, hogyha Istent szeretjük, és parancsolatait megtartjuk.
3 Nítorí èyí ni ìfẹ́ Ọlọ́run, pé kí àwa pa òfin rẹ̀ mọ́: òfin rẹ̀ kò sì nira,
Mert az az Isten szeretete, hogy megtartjuk parancsolatait. Az ő parancsolatai pedig nem nehezek.
4 nítorí olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa tí Ọlọ́run, ó ṣẹ́gun ayé. Èyí sì ni ìṣẹ́gun tí ó ṣẹ́gun ayé, àní ìgbàgbọ́ wa.
Mindenki, aki Istentől született legyőzi a világot. A győzelem, amely legyőzte a világot: a mi hitünk.
5 Ta ni ẹni tí ó ṣẹ́gun ayé, bí kò ṣe ẹni tí ó gbàgbọ́ pé Ọmọ Ọlọ́run ni Jesu jẹ́?
Ki az, aki legyőzi a világot, ha nem az, aki hiszi, hogy Jézus az Isten Fia.
6 Èyí ni ẹni tí ó wá nípa omi àti ẹ̀jẹ̀, Jesu Kristi, kì í ṣe nípa omi nìkan, bí kò ṣe nípa omi àti ẹ̀jẹ̀. Àti pé Ẹ̀mí ni ó sì ń jẹ́rìí, nítorí pé òtítọ́ ni Ẹ̀mí.
Ő az a Jézus Krisztus, aki víz és vér által jött el. Nemcsak vízzel, hanem vízzel és vérrel. A Lélek pedig bizonyságot tesz Róla, mert a Lélek az igazság.
7 Nítorí pé àwọn mẹ́ta ni ó ń jẹ́rìí.
Hárman vannak, akik bizonyságot tesznek a mennyben: az Atya, az Ige és a Szentlélek és ez a három egy.
8 Ẹ̀mí, omi, àti ẹ̀jẹ̀: àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì wà ni ìṣọ̀kan.
És hárman vannak, akik bizonyságot tesznek a földön: a Lélek, a víz és a vér és ez a három is egy.
9 Bí àwa ba ń gba ẹ̀rí ènìyàn, ẹ̀rí Ọlọ́run tóbi jù: nítorí ẹ̀rí Ọlọ́run ni èyí pé, Ó tí jẹ́rìí ní ti Ọmọ rẹ̀.
Ha elfogadjuk az emberek bizonyságtételét, Isten bizonyságtétele nagyobb, mert Isten bizonyságtétele az, amellyel Fiáról tesz bizonyságot.
10 Ẹni tí ó bá gba Ọmọ Ọlọ́run gbọ́, ó ni ẹ̀rí nínú ara rẹ̀; ẹni tí kò bá gba Ọlọ́run gbọ́, ó ti mú un ni èké; nítorí kò gba ẹ̀rí náà gbọ́ tí Ọlọ́run jẹ́ ní ti Ọmọ rẹ̀.
Aki hisz Isten Fiában, abban megvan ez a bizonyságtétel. Aki nem hisz Istennek, hazuggá teszi őt, mert nem hisz abban a bizonyságtételben, amellyel Isten bizonyságot tett Fiáról.
11 Ẹ̀rí náà sì ni èyí pé Ọlọ́run fún wa ní ìyè àìnípẹ̀kun, ìyè yìí sì ń bẹ nínú Ọmọ rẹ̀. (aiōnios )
Ez a bizonyságtétel pedig az, hogy örök életet adott nekünk Isten. Ez az élet pedig az ő Fiában van. (aiōnios )
12 Ẹni tí ó bá ni Ọmọ, ó ni ìyè; ẹni tí kò bá sì ni Ọmọ Ọlọ́run, kò ní ìyè.
Akié a Fiú, azé az élet. Akiben nincs meg Isten Fia, az élet sincs meg abban.
13 Nǹkan wọ̀nyí ni mo kọ̀wé rẹ̀ sí yín, àní sí ẹ̀yin tí ó gba orúkọ Ọmọ Ọlọ́run gbọ́; kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé ẹ̀yin ní ìyè àìnípẹ̀kun, àní fún ẹ̀yin tí ó gba orúkọ Ọmọ Ọlọ́run gbọ́. (aiōnios )
Ezeket azért írtam nektek, akik hisztek Isten Fiának nevében, hogy tudjátok meg: örök életetek van. (aiōnios )
14 Èyí sì ni ìgboyà tí àwa ní níwájú rẹ̀, pé bí àwa bá béèrè ohunkóhun gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, ó ń gbọ́ tí wa.
Az az iránta való bizodalmunk, hogy ha kérünk valamit az ő akarata szerint, meghallgat minket.
15 Bí àwa bá sì mọ̀ pé ó ń gbọ́ tí wa, ohunkóhun tí àwa bá béèrè, àwa mọ̀ pé àwa rí ìbéèrè tí àwa ti béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ gbà.
Ha pedig tudjuk, hogy meghallgat bennünket, bármit kérünk, azt is tudjuk, hogy meg is adja azt, amit tőle kérünk.
16 Bí ẹnikẹ́ni bá rí arákùnrin rẹ̀ tí ń dẹ́ṣẹ̀ tí kì í ṣe sí ikú, òun yóò béèrè, Ọlọ́run yóò sì fún un ni ìyè, àní, fún àwọn tí ń dẹ́ṣẹ̀ tí kì í ṣe sí ikú. Ẹ̀ṣẹ̀ kan ń bẹ sì ikú, èmi kò wí pé ki òun gbàdúrà fún èyí.
Ha valaki látja, hogy atyjafia nem halálos bűnt követ el, könyörögjön érte, és életet fog adni annak, aki nem halálos bűnt követ el. Van halálos bűn. Nem az ilyen esetre mondom, hogy könyörögjön.
17 Gbogbo àìṣòdodo ni ẹ̀ṣẹ̀, ẹ̀ṣẹ̀ kan ń bẹ tí kì í ṣe sí ikú.
Minden gonoszság bűn, de van nem halálos bűn is.
18 Àwa mọ̀ pé ẹnikẹ́ni tí a bí nípa ti Ọlọ́run kì í dẹ́ṣẹ̀: ṣùgbọ́n ẹni tí a bí nípa tí Ọlọ́run a pa ara rẹ̀ mọ́, ẹni búburú kò ní lè fọwọ́ kàn án.
Tudjuk, hogy aki Istentől született nem vétkezik, hanem aki Istentől született vigyáz magára, és a gonosz meg sem érinti.
19 Àwa mọ̀ pé tí Ọlọ́run ni wá, àti gbogbo ayé ni ó wà lábẹ́ agbára ẹni búburú náà.
Tudjuk, hogy Istentől vagyunk, és az egész világ gonoszságban vesztegel.
20 Àwa sì mọ̀ pé Ọmọ Ọlọ́run dé, ó sì tí fi òye fún wa, kí àwa lè mọ ẹni tí í ṣe òtítọ́, àwa sì ń bẹ nínú ẹni tí í ṣe òtítọ́, àní, nínú Ọmọ rẹ̀, Jesu Kristi. Èyí ni Ọlọ́run òtítọ́, àti ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios )
De tudjuk azt is, hogy az Isten Fia eljött és képességet adott nekünk arra, hogy megismerjük az Igazat, és hogy mi az Igazban, az ő Fiában, a Jézus Krisztusban vagyunk. Ő az igaz Isten és az örök élet. (aiōnios )
21 Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú òrìṣà.
Gyermekeim, oltalmazzátok meg magatokat a bálványoktól. Ámen.