< 1 John 4 >
1 Olùfẹ́, ẹ má ṣe gba gbogbo ẹ̀mí gbọ́, ṣùgbọ́n ẹ dán àwọn ẹ̀mí wò bí wọn ba ń ṣe tí Ọlọ́run, nítorí àwọn wòlíì èké púpọ̀ tí jáde lọ sínú ayé.
Milovaní, nepřijímejte lehkověrně všechno, co zní zbožně, ale napřed si ověřte, zda to pochází od Boha; vždyť kolem nás je mnoho falešných učitelů.
2 Èyí ni ẹ ó fi mọ Ẹ̀mí Ọlọ́run. Gbogbo ẹ̀mí tí ó ba jẹ́wọ́ pé, Jesu Kristi wá nínú ara, ti Ọlọ́run ni.
Zkušebním kamenem ať vám je, zda vyznávají, že se v Ježíši Kristu Bůh stal člověkem.
3 Gbogbo ẹ̀mí tí kò si jẹ́wọ́ pé Jesu Kristi wà nínú ara, kì í ṣe tí Ọlọ́run, èyí sì ni ẹ̀mí aṣòdì sí Kristi náà, tí ẹ̀yin ti gbọ́ pé ó ń bọ̀, àti nísinsin yìí ó sì tí de sínú ayé.
Kdo tuto skutečnost odmítá, nemluví v Božím jménu. Je na straně Kristova nepřítele, který už ve světě působí.
4 Ẹ̀yin ọmọ mi, ti Ọlọ́run ni yín, ẹ̀yin sì tí ṣẹ́gun wọn, nítorí ẹni tí ń bẹ nínú yin tóbi jú ẹni tí ń bẹ nínú ayé lọ.
Děti, váš život pramení z Boha, a proto odoláváte vlivu falešných učitelů. Váš zdroj je mocnější než jejich.
5 Tí ayé ni wọ́n, nítorí náà ni wọn ṣe ń sọ̀rọ̀ bí ẹni ti ayé, ayé sì ń gbọ́ tí wọn.
Oni jsou pravými dětmi své doby, proto říkají, co lidem vyhovuje a co lidé rádi slyší.
6 Ti Ọlọ́run ni àwa: ẹni tí ó bá mọ Ọlọ́run, ó ń gbọ́ tiwa; ẹni tí kì í ṣe ti Ọlọ́run kò ni gbọ́ ti wa. Nípa èyí ni àwa mọ ẹ̀mí òtítọ́, àti ẹ̀mí èké.
My jsme však děti Boží, a kdo to myslí s Bohem vážně, naslouchá nám. Naše svědectví vám pomůže spolehlivě odlišit pravdu od lži.
7 Olùfẹ́, ẹ jẹ́ kí a fẹ́ràn ara wa, nítorí ìfẹ́ ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; àti gbogbo ẹni tí ó bá ní ìfẹ́, a bí i nípa ti Ọlọ́run, ó sì mọ Ọlọ́run.
Přátelé, milujme se navzájem, protože láska pochází z Boha. Kdo rozdává lásku, dokazuje, že Boha zná a je jeho dítětem.
8 Ẹni tí kò bá ní ìfẹ́ kò mọ Ọlọ́run: nítorí pé ìfẹ́ ni Ọlọ́run.
Kdo nemiluje, neví o Bohu nic, protože Bůh je láska.
9 Nípa èyí ni a gbé fi ìfẹ́ Ọlọ́run hàn nínú wa, nítorí tí Ọlọ́run rán ọmọ bíbí rẹ̀ nìkan ṣoṣo sì ayé, kí àwa lè yè nípasẹ̀ rẹ̀.
Jak velice nás miluje, prokázal Bůh tím, že poslal na zem svého jediného Syna, aby se nám stal zdrojem života.
10 Nínú èyí ni ìfẹ́ wà, kì í ṣe pé àwa fẹ́ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n òun fẹ́ wá, ó sì rán Ọmọ rẹ̀ láti jẹ́ ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ wa.
Na počátku tedy stojí Boží láska a oběť, tam se rodí naše láska k Bohu.
11 Olùfẹ́, bí Ọlọ́run bá fẹ́ wa báyìí, ó yẹ kí a fẹ́ràn ara wa pẹ̀lú.
Jestliže nás Bůh tak miluje, zavazuje to i nás ke vzájemné lásce.
12 Ẹnikẹ́ni kò ri Ọlọ́run nígbà kan rí. Bí àwa bá fẹ́ràn ara wa, Ọlọ́run ń gbé inú wa, a sì mú ìfẹ́ rẹ̀ pé nínú wa.
Boha sice nevidíme, ale když se navzájem milujeme, působí mezi námi a jeho láska v nás nabývá přesvědčivosti.
13 Nípa èyí ni àwa mọ̀ pé àwa ń gbé inú rẹ̀, àti Òun nínú wa, nítorí tí ó ti fi Ẹ̀mí rẹ̀ fún wa.
Jenom Duch svatý nás může ujistit, že máme k Bohu pravý vztah.
14 Àwa tí rí, a sì jẹ́rìí pé Baba rán Ọmọ rẹ̀ láti jẹ́ Olùgbàlà fún aráyé.
Viděli jsme a dosvědčujeme, že Otec poslal Syna, aby zachránil svět.
15 Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ́wọ́ pé Jesu Ọmọ Ọlọ́run ni, Ọlọ́run ń gbé inú rẹ̀, àti òun nínú Ọlọ́run.
Kdo vyznává, že Ježíš je Boží Syn, otevřel se Božímu působení a je s ním zajedno.
16 Báyìí ni àwa mọ̀, tí a sì gba ìfẹ́ tí Ọlọ́run ní sí wa gbọ́. Ìfẹ́ ni Ọlọ́run; ẹni tí ó bá sì ń gbé inú ìfẹ́, ó ń gbé inú Ọlọ́run, àti Ọlọ́run nínú rẹ̀.
Známe Boží lásku a spoléháme na ni. Bůh je láska a ten, kdo miluje, zůstává s Bohem v živém spojení.
17 Nínú èyí ni a mú ìfẹ́ tí ó wà nínú wa pé, kí àwa bà á lè ni ìgboyà ní ọjọ́ ìdájọ́: nítorí pé bí òun tí rí, bẹ́ẹ̀ ni àwa sì rí ni ayé yìí.
Boží láska nám dává jistotu, že se nemusíme bát jeho soudu, protože se snažíme uvádět do života jeho lásku.
18 Ìbẹ̀rù kò sí nínú ìfẹ́; ṣùgbọ́n ìfẹ́ tí ó pé ń lé ìbẹ̀rù jáde; nítorí tí ìbẹ̀rù ni ìyà nínú. Ẹni tí ó bẹ̀rù kò pé nínú ìfẹ́.
Kde je láska, mizí strach; naše jednání je teprve tehdy ryzí, když nevyplývá ze strachu před trestem, ale z lásky.
19 Àwa fẹ́ràn rẹ̀ nítorí òun ni ó kọ́ fẹ́ràn wa.
Naše láska pramení z Boží lásky.
20 Bí ẹnikẹ́ni bá wí pé, “Èmi fẹ́ràn Ọlọ́run,” tí ó sì kórìíra arákùnrin rẹ̀, èké ni: nítorí ẹni tí kò fẹ́ràn arákùnrin rẹ̀ tí ó rí, báwo ni yóò tí ṣe lè fẹ́ràn Ọlọ́run tí òun kò rí?
Kdo staví na odiv svou lásku k Bohu a nenávidí bratra, klame druhé i sebe. Když nemiluje bratra, kterého má před očima, jak může milovat Boha, kterého nevidí?
21 Òfin yìí ni àwa sì rí gbà láti ọwọ́ rẹ̀ wá, pé ẹni tí ó bá fẹ́ràn Ọlọ́run kí ó fẹ́ràn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú.
Kristus nám řekl jednoznačně: Miluješ-li Boha, miluj bratra.