< 1 John 3 >
1 Ẹ wo irú ìfẹ́ tí Baba fi fẹ́ wa, tí a fi ń pè wá ní ọmọ Ọlọ́run; bẹ́ẹ̀ ni a sá à jẹ́. Nítorí èyí ni ayé kò ṣe mọ̀ wá, nítorí tí kò mọ̀ ọ́n.
Подивіться, яку дивовижну любов проявив до нас Отець, щоб ми були названі Божими дітьми! І ми [справді Його діти]! Світ не знає нас тому, що не пізнав Його.
2 Olùfẹ́, ọmọ Ọlọ́run ni àwa ń ṣe nísinsin yìí, a kò ì tí i fihàn bí àwa ó ti rí: àwa mọ̀ pé, nígbà tí òun ba farahàn, àwa yóò dàbí rẹ̀; nítorí àwa yóò rí i, àní bí òun tí rí.
Любі, тепер ми Божі діти. І те, ким станемо, ще не явилося, але ми знаємо, що коли Він з’явиться, то ми станемо подібними до Нього, тому що ми побачимо Його Таким, Яким Він є.
3 Olúkúlùkù ẹni tí ó ba sì ní ìrètí yìí nínú rẹ̀, ń wẹ ara rẹ̀ mọ́, àní bí òun ti mọ́.
Кожен, хто має цю надію в Христа, очищує себе, як і Він є чистий.
4 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń dẹ́ṣẹ̀, ó ń rú òfin pẹ̀lú, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ni rírú òfin.
Кожен, хто чинить гріх, чинить і беззаконня, бо гріх є беззаконням.
5 Ẹ̀yin sì mọ̀ pé, òun farahàn láti mu ẹ̀ṣẹ̀ kúrò; ẹ̀ṣẹ̀ kò sì ṣí nínú rẹ̀.
Ви знаєте, що Христос явився, щоб усунути наші гріхи, а в Ньому гріха немає.
6 Ẹnikẹ́ni tí ó ba ń gbé inú rẹ̀ kì í dẹ́ṣẹ̀; ẹnikẹ́ni tí ó bá sì ń dẹ́ṣẹ̀ kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni kò mọ̀ ọ́n.
Кожен, хто залишається в Ньому, не грішить. А кожен, хто грішить, не бачив Його й навіть не пізнав Його.
7 Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín, ẹni tí ó bá ń ṣe òdodo, ó jásí olódodo, gẹ́gẹ́ bí òun tí jẹ olódodo.
Діточки, нехай ніхто не вводить вас в оману. Хто чинить правду, той праведний, як і Він праведний.
8 Ẹni tí ó ba ń dẹ́ṣẹ̀ tí èṣù ni; nítorí láti àtètèkọ́ṣe ni èṣù ti ń dẹ́ṣẹ̀. Nítorí èyí ni Ọmọ Ọlọ́run ṣe farahàn, kí ó lè pa iṣẹ́ èṣù run.
Хто чинить гріх, той від диявола, тому що диявол грішить від початку. Тому Син Божий і явився, щоб зруйнувати діла диявола.
9 Ẹnikẹ́ni tí a ti ipa Ọlọ́run bí, kì í dẹ́ṣẹ̀; nítorí tí irú rẹ̀ ń gbé inú rẹ̀, kò sì lè dẹ́ṣẹ̀ nítorí pé a ti ti ipa Ọlọ́run bí i.
Кожен, хто народжений від Бога, не робить гріха, тому що Боже насіння перебуває в ньому. Він не може грішити, оскільки народжений від Бога.
10 Nínú èyí ni àwọn ọmọ Ọlọ́run ń farahàn, àti àwọn ọmọ èṣù; ẹnikẹ́ni tí kò ba ń ṣe òdodo, àti ẹni tí kò fẹ́ràn arákùnrin rẹ̀ kì í ṣe ti Ọlọ́run.
Так можна виявити, хто є Божими дітьми і хто є дітьми диявола: кожен, хто не чинить праведності й не любить свого брата, – не від Бога.
11 Nítorí èyí ni iṣẹ́ tí ẹ̀yin tí gbọ́ ni àtètèkọ́ṣe, pé ki àwa fẹ́ràn ara wa.
Такою є звістка, яку ви чули від початку: ми повинні любити одне одного.
12 Kì í ṣe bí Kaini, tí í ṣe ẹni búburú, tí o sì pa arákùnrin rẹ̀. Nítorí kín ni ó sì ṣe pa á? Nítorí tí iṣẹ́ tirẹ̀ jẹ́ búburú ṣùgbọ́n tí arákùnrin rẹ̀ sì jẹ́ òdodo.
Не так, як Каїн, який був від лукавого й вбив свого брата. А чому ж він його вбив? Тому що його діла були лихі, а діла його брата – праведні.
13 Kì ẹnu má ṣe yà yín, ẹ̀yin ará mi, bí ayé bá kórìíra yín.
Брати, не дивуйтеся, якщо світ ненавидить вас.
14 Àwa mọ̀ pé àwa tí rékọjá láti inú ikú sínú ìyè, nítorí tí àwa fẹ́ràn àwọn ará. Ẹni tí kò ba ni ìfẹ́, ó ń gbé inú ikú.
Ми знаємо, що вже перейшли від смерті до життя, бо ми любимо братів, а той, хто не любить, залишається мертвим.
15 Ẹnikẹ́ni tí ó ba kórìíra arákùnrin rẹ̀ apànìyàn ni, ẹ̀yin sì mọ́ pé kò sí apànìyàn tí ó ni ìyè àìnípẹ̀kun láti máa gbé inú rẹ̀. (aiōnios )
Кожен, хто ненавидить свого брата, є вбивцею, а ви знаєте, що жоден вбивця немає в собі вічного життя. (aiōnios )
16 Nípa èyí ni àwa mọ ìfẹ́ nítorí tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ lélẹ̀ fún wa, ó sì yẹ kí àwa fi ẹ̀mí wa lélẹ̀ fún àwọn ará.
Отак ми пізнали любов: Христос віддав за нас своє життя. Тож і ми повинні віддавати своє життя за братів.
17 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ni ohun ìní ayé, tí ó sì ri arákùnrin rẹ̀ tí ó ṣe aláìní, tí ó sì sé ìlẹ̀kùn ìyọ́nú rẹ̀ mọ́ ọn, báwo ni ìfẹ́ Ọlọ́run ṣe ń gbé inú rẹ̀?
Якщо хтось має багатства світу, дивиться на потребу свого брата та є байдужим до нього, то як Божа любов може залишатися в ньому?
18 Ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ má ṣe jẹ́ kí a fi ọ̀rọ̀ tàbí ahọ́n fẹ́ràn, bí kò ṣe ni ìṣe àti ní òtítọ́.
Діточки, любімо не словом і язиком, але ділом і правдою.
19 Àti nípa èyí ni àwa ó mọ̀ pé àwa jẹ́ ti òtítọ́, àti pé àwa ó sì fi ọkàn ara wa balẹ̀ níwájú rẹ̀.
Так ми розуміємо, що походимо від правди, і перед Ним заспокоїмо наше серце.
20 Nínú ohunkóhun tí ọkàn wa bá ń dá wa lẹ́bi; nítorí pé Ọlọ́run tóbi ju ọkàn wa lọ, ó sì mọ ohun gbogbo.
Навіть якщо наше серце засуджує нас, Бог величніший за наше серце й знає все.
21 Olùfẹ́, bí ọkàn wa kò bá dá wa lẹ́bi, ǹjẹ́ àwa ni ìgboyà níwájú Ọlọ́run?
Любі, якщо наше серце [нас] не засуджує, то ми маємо сміливість перед Богом
22 Àti ohunkóhun tí àwa bá béèrè, ni àwa ń rí gbà lọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí tí àwa ń pa òfin rẹ̀ mọ́, àwa sì ń ṣe àwọn nǹkan tí ó dára lójú rẹ̀.
і чого тільки не попросимо [в Нього] – отримаємо, бо ми дотримуємося Його заповідей і робимо те, що Йому до вподоби.
23 Èyí sì ni òfin rẹ̀, pé kí àwa gba orúkọ Jesu Kristi Ọmọ rẹ̀ gbọ́, kí a sì fẹ́ràn ara wá gẹ́gẹ́ bí ó tí fi òfin fún wa.
І це Його заповідь, щоб ми вірили в ім’я Його Сина, Ісуса Христа, і любили одне одного, як Він доручив нам.
24 Ẹni tí ó bá sì pa òfin rẹ̀ mọ́ ń gbé inú rẹ̀, àti òun nínú rẹ̀. Àti nípa èyí ni àwa mọ̀ pé ó ń gbé inú wa, nípa Ẹ̀mí tí ó fi fún wa.
Той, хто дотримується Його заповідей, залишається в Бозі, а Бог – у ньому. І те, що Він залишається в нас, пізнаємо від Духа, Якого Він нам дав.