< 1 Corinthians 9 >

1 Èmi kò ha ni òmìnira bí? Èmi kò ha ń ṣe aposteli bí? Èmi kò ha ti rí Jesu Olúwa bí? Ẹ̀yìn ha kọ́ ní èrè iṣẹ́ mi nínú Olúwa bí?
ⲁ̅ⲙⲏ ⲁⲛⲅ̅ⲟⲩⲣⲙ̅ϩⲉ ⲁⲛ. ⲙⲏ ⲁⲛⲅ̅ⲟⲩⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⲁⲛ. ⲙⲏ ⲙ̅ⲡⲓⲛⲁⲩ ⲉⲓ̅ⲥ̅ ⲡⲉⲛϫⲟⲉⲓⲥ. ⲙⲏ ⲛ̅ⲧⲱⲧⲛ̅ ⲁⲛ ⲡⲉ ⲡⲁϩⲱⲃ ϩⲙ̅ⲡϫⲟⲉⲓⲥ.
2 Ní ìrònú àwọn ẹlòmíràn, èmi kì í ṣe aposteli. Dájúdájú aposteli ni mo jẹ́ fún un yín, tí n kì bá ṣe fún àwọn ẹlòmíràn. Nítorí èdìdì iṣẹ́ aposteli mi ni ẹ̀yin jẹ́ nínú Olúwa.
ⲃ̅ⲉϣϫⲉⲁⲛⲅ̅ⲟⲩⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⲁⲛ ⲛ̅ϩⲉⲛⲕⲟⲟⲩⲉ. ⲁⲗⲗⲁ ⲁⲛⲅ̅ⲟⲩⲁ ⲛⲏⲧⲛ̅. ⲧⲉⲥⲫⲣⲁⲅⲓⲥ ⲅⲁⲣ ⲛ̅ⲧⲁⲙⲛ̅ⲧⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⲛ̅ⲧⲱⲧⲛ̅ ⲡⲉ ϩⲙ̅ⲡϫⲟⲉⲓⲥ.
3 Èyí ni ìdáhùn mi sí àwọn tí ń béèrè ẹ̀tọ́ aposteli mi.
ⲅ̅ⲧⲁⲓ̈ ⲧⲉ ⲧⲁⲁⲡⲟⲗⲟⲅⲓⲁ ⲛ̅ⲛⲉⲧⲁⲛⲁⲕⲣⲓⲛⲉ ⲙ̅ⲙⲟⲓ̈.
4 Ṣé a kò ní ẹ̀tọ́ láti máa jẹ àti láti máa mu bí?
ⲇ̅ⲙⲏ ⲙⲛ̅ⲧⲁⲛⲧⲉⲝⲟⲩⲥⲓⲁ ⲛ̅ⲟⲩⲱⲙ ϩⲓⲥⲱ.
5 Ṣé àwa kò ní ẹ̀tọ́ láti máa mú ìyàwó tí í ṣe onígbàgbọ́ káàkiri gẹ́gẹ́ bí àwọn aposteli mìíràn? Àti bí arákùnrin Olúwa, àti Kefa.
ⲉ̅ⲙⲏ ⲙⲛ̅ⲧⲁⲛⲧⲉⲝⲟⲩⲥⲓⲁ ⲉⲧⲣⲉⲩⲥⲱⲛⲉ ⲛ̅ⲥϩⲓⲙⲉ ⲟⲩⲁϩⲥ̅ ⲛ̅ⲥⲱⲛ ⲛ̅ⲑⲉ ⲛ̅ⲛ̅ⲕⲉⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⲙⲛ̅ⲛⲉⲥⲛⲏⲩ ⲙ̅ⲡϫⲟⲉⲓⲥ ⲁⲩⲱ ⲕⲏⲫⲁⲥ.
6 Ṣé èmi nìkan àti Barnaba, àwa kò ha ní agbára láti máa ṣiṣẹ́ bọ́ ara wa ni?
ⲋ̅ϫⲛ̅ⲙ̅ⲙⲟⲛ ⲁⲛⲟⲕ ⲙⲁⲩⲁⲁⲧ ⲙⲛ̅ⲃⲁⲣⲛⲁⲃⲁⲥ ⲙⲛ̅ⲧⲁⲛⲧⲉⲝⲟⲩⲥⲓⲁ ⲙ̅ⲙⲁⲩ ⲉⲧⲙ̅ⲣ̅ϩⲱⲃ.
7 Ta ni ó ṣíṣẹ́ ológun tí ó sanwó ara rẹ̀? Ta ní gbin ọgbà àjàrà tí kì í jẹ nínú èso rẹ̀? Tàbí ta ní ń bọ ọ̀wọ́ ẹran tí kì í sí ì jẹ nínú wàrà ọ̀wọ́ ẹran?
ⲍ̅ⲛⲓⲙ ⲡⲉ ⲉϣⲁϥⲣ̅ⲙⲁⲧⲟⲓ̈ ϩⲛ̅ⲛⲉϥⲟⲯⲱⲛⲓⲟⲛ ⲙ̅ⲙⲓⲛ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲉⲛⲉϩ. ⲛⲓⲙ ⲡⲉϣⲁϥⲧⲱϭⲉ ⲛ̅ⲟⲩⲙⲁ ⲛ̅ⲉⲗⲟⲟⲗⲉ ⲛϥ̅ⲧⲙ̅ⲟⲩⲱⲙ ⲙ̅ⲡⲉϥⲕⲁⲣⲡⲟⲥ. ⲛⲓⲙ ⲡⲉϣⲁϥⲙⲟⲟⲛⲉ ⲛ̅ⲟⲩⲟϩⲉ ⲛϥ̅ⲧⲙ̅ⲟⲩⲱⲙ ⲙ̅ⲡⲉϥⲉⲣⲱⲧⲉ.
8 Èmi ha sọ nǹkan wọ̀nyí bí ènìyàn? Tàbí òfin kò wí bákan náà bì?
ⲏ̅ⲙⲏ ⲕⲁⲧⲁⲣⲱⲙⲉ ⲉⲓ̈ϫⲱ ⲛ̅ⲛⲁⲓ̈. ⲏ̅ ⲙⲉⲣⲉⲡⲕⲉⲛⲟⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲛⲁⲓ̈.
9 Nítorí nínú òfin tí Ọlọ́run fún Mose, ni a tí kọ ọ́ pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu.” Ǹjẹ́ màlúù ni Ọlọ́run n ṣe ìtọ́jú rẹ̀ bi?
ⲑ̅ϥⲥⲏϩ ⲅⲁⲣ ϩⲙ̅ⲡⲛⲟⲙⲟⲥ ⲙ̅ⲙⲱⲩ̈ⲥⲏⲥ ϫⲉ ⲛ̅ⲛⲉⲕϣⲃⲧ̅ⲟⲩⲙⲁⲥⲉ ⲉϥϩⲓ. ⲙⲏ ⲡⲣⲟⲟⲩϣ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ ⲡⲉ ϩⲁⲛⲉϩⲟⲟⲩ
10 Dájúdájú ó sọ eléyìí fún wa pé, nítorí wa ni a ṣe kọ̀wé yìí kí ẹni tí ń tulẹ̀ lè máa tulẹ̀ ní ìrètí àti ẹni tí ń pakà lè ni ìrètí láti ní ìpín nínú ìkórè.
ⲓ̅ϫⲛ̅ⲉϥϫⲱ ⲙ̅ⲙⲟⲥ ⲉⲧⲃⲏⲏⲧⲛ̅. ⲛ̅ⲧⲁⲩⲥⲁϩϥ̅ ⲅⲁⲣ ⲉⲧⲃⲏⲏⲧⲛ̅ ϫⲉ ϣ̅ϣⲉ ⲉⲡⲉⲧⲥⲕⲁⲓ̈ ⲉⲥⲕⲁⲓ̈ ⲉϫⲛ̅ⲟⲩϩⲉⲗⲡⲓⲥ. ⲁⲩⲱ ⲡⲉⲧϩⲓ ⲉϫⲛ̅ⲟⲩϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⲉⲧⲣⲉϥⲙⲉⲧⲉⲭⲉ.
11 Bí àwa ti fún irúgbìn ohun ti ẹ̀mí sínú ọkàn yín, ohun ńlá ha ni bí àwa ó ba ká ohun ti yín tí ṣe ti ara?
ⲓ̅ⲁ̅ⲉϣϫⲉⲁⲛⲟⲛ ⲁⲛϫⲟ ⲛⲏⲧⲛ̅ ⲛ̅ⲛⲉⲡⲛⲉⲩⲙⲁⲧⲓⲕⲟⲛ ⲟⲩⲛⲟϭ ⲡⲉ. ⲉϣϫⲉⲁⲛⲟⲛ ⲡⲉⲧⲛⲁⲱϩⲥ̅ ⲛ̅ⲛⲉⲧⲛ̅ⲥⲁⲣⲕⲓⲕⲟⲛ.
12 Bí àwọn ẹlòmíràn bá ní ẹ̀tọ́ tí ìrànlọ́wọ́ sì wá láti ọ̀dọ̀ yín, àwa ha kọ́ ni ó tọ́ sí jù? Ṣùgbọ́n àwa kò lo agbára yìí ṣùgbọ́n àwa faradà ohun gbogbo, kí àwa má ba à ṣe ìdènà fún ìyìnrere Kristi.
ⲓ̅ⲃ̅ⲉϣϫⲉⲟⲩⲛ̅ϩⲉⲛⲕⲟⲟⲩⲉ ⲙⲉⲧⲉⲭⲉ ⲉⲧⲉⲧⲛ̅ⲉⲝⲟⲩⲥⲓⲁ. ⲛ̅ϩⲟⲩⲟ ϭⲉ ⲁⲛ ⲁⲛⲟⲛ. ⲁⲗⲗⲁ ⲙ̅ⲡⲛ̅ⲭⲣⲱ ⲛ̅ⲧⲉⲉⲓⲉⲝⲟⲩⲥⲓⲁ. ⲁⲗⲗⲁ ⲉⲛϥⲓ ϩⲁϩⲱⲃ ⲛⲓⲙ ϫⲉⲕⲁⲁⲥ ⲉⲛⲛⲉⲛϯ ⲛ̅ⲟⲩϫⲣⲟⲡ ⲙ̅ⲡⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⲙ̅ⲡⲉⲭ̅ⲥ̅·
13 Ǹjẹ́ ó yé e yín pé Ọlọ́run sọ fún àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili pé kí wọ́n mú oúnjẹ tàbí àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n mú wá fún òun, láti fi ṣe ìtọ́jú ara wọn? Àti àwọn tí ń dúró tí pẹpẹ wọn a máa ṣe àjọpín pẹ̀lú pẹpẹ.
ⲓ̅ⲅ̅ⲛ̅ⲧⲉⲧⲛ̅ⲥⲟⲟⲩⲛ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛⲉⲧⲣ̅ϩⲱⲃ ⲉⲛⲉⲣⲡⲏⲩⲉ ⲉⲩⲟⲩⲱⲙ ⲉⲃⲟⲗ ϩⲛ̅ⲛⲁⲡⲣ̅ⲡⲉ. ⲛⲉⲧⲥⲣⲟϥⲧ̅ ⲉⲡⲉⲑⲩⲥⲓⲁⲥⲧⲏⲣⲓⲟⲛ ⲉϣⲁⲩⲡⲱϣ ⲉϫⲱⲟⲩ ⲙⲛ̅ⲡⲉⲑⲩⲥⲓⲁⲥⲧⲏⲣⲓⲟⲛ.
14 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi àṣẹ lélẹ̀ pé, àwọn tí ń wàásù ìyìnrere kí wọn sì máa jẹ́ nípa ìyìnrere.
ⲓ̅ⲇ̅ⲧⲁⲓ̈ ⲧⲉ ⲑⲉ ⲉⲛⲧⲁⲡϫⲟⲉⲓⲥ ⲧⲟϣⲥ̅ ⲛ̅ⲛⲉⲧⲧⲁϣⲉⲟⲉⲓϣ ⲙ̅ⲡⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⲉⲱⲛϩ̅ ⲉⲃⲟⲗ ⲙ̅ⲡⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ.
15 Síbẹ̀síbẹ̀ n kò ì tí ì lo irú àwọn ẹ̀tọ́ wọ̀nyí rí. Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì kọ ìwé yìí láti fi sọ fún un yín pé, mo fẹ́ bẹ̀rẹ̀ sí í gbà irú nǹkan bẹ̀ ẹ́ lọ́wọ́ yín. Kí a sọ òtítọ́, ó sàn fún mi láti kú sínú ebi ju pé kí n sọ ògo tí mo ní láti wàásù nù.
ⲓ̅ⲉ̅ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ⲙ̅ⲡⲓⲭⲣⲱ ⲛ̅ⲗⲁⲁⲩ ⲛ̅ⲛⲁⲓ̈. ⲛ̅ⲧⲁⲓ̈ⲥⲉϩⲛⲁⲓ̈ ⲇⲉ ⲁⲛ ϫⲉ ⲉⲩⲉϣⲱⲡⲉ ⲛ̅ⲧⲉⲉⲓϩⲉ ⲛ̅ϩⲏⲧ. ⲛⲁⲛⲟⲩⲥ ⲅⲁⲣ ⲛⲁⲓ̈ ⲉⲧⲣⲁⲙⲟⲩ ⲉϩⲟⲩⲉⲡⲁϣⲟⲩϣⲟⲩ ⲉⲧⲉⲙⲛ̅ⲗⲁⲁⲩ ⲛⲁϣⲧⲣⲉϥϣⲱⲡⲉ ⲉϥϣⲟⲩⲉⲓⲧ.
16 Nítorí pé bí mo ti ń wàásù ìyìnrere, kì í ṣe ohun tí mo lè máa ṣògo lè. Èmi kò tilẹ̀ le è ṣe é ní, kí a tilẹ̀ sọ pé mo fẹ́ kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Ègbé ni fún mi tí mo bá kọ̀ láti wàásù ìyìnrere.
ⲓ̅ⲋ̅ⲉⲓ̈ϣⲁⲛⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲍⲉ ⲅⲁⲣ ⲛ̅ⲟⲩϣⲟⲩϣⲟⲩ ⲛⲁⲓ̈ ⲁⲛ ⲡⲉ. ⲟⲩϩⲧⲟⲣ ⲅⲁⲣ ⲉⲣⲟⲓ̈ ⲡⲉ ⲟⲩⲟⲓ̈ ⲅⲁⲣ ⲛⲁⲓ̈ ⲡⲉ ⲉⲓ̈ϣⲁⲛⲧⲙ̅ⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲍⲉ.
17 Tó bá jẹ́ pé mò ń wàásù tinútinú mi, mo ní èrè kan, ṣùgbọ́n tí ń kò bá ṣe tinútinú mi, a ti fi iṣẹ́ ìríjú lé mi lọ́wọ́.
ⲓ̅ⲍ̅ⲉϣϫⲉⲉϩⲛⲁⲓ̈ ⲇⲉ ⲉⲓ̈ⲉⲓⲣⲉ ⲙ̅ⲡⲁⲓ̈ ⲟⲩⲛ̅ⲧⲁⲓ̈ ⲙ̅ⲙⲁⲩ ⲛⲟⲩⲃⲉⲕⲉ. ⲉϣϫⲉⲛ̅ϩⲛⲁⲓ̈ ⲇⲉ ⲁⲛ ⲉⲓ̈ⲉ ⲛ̅ⲧⲁⲩⲧⲁⲛϩⲟⲩⲧ ⲉⲩⲟⲓⲕⲟⲛⲟⲙⲓⲁ.
18 Ní irú ipò báyìí, kín ni ẹ rò pé yóò jẹ èrè mi ni láti jẹ́? Èrè mi ní àgbàyanu ayọ̀ tí mo ń rí gbà nípa ìwàásù ìyìnrere láìgba owó lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, láìbéèrè ẹ̀tọ́ mi lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni.
ⲓ̅ⲏ̅ⲁϣ ϭⲉ ⲡⲉ ⲡⲁⲃⲉⲕⲉ ϫⲉⲕⲁⲁⲥ ⲡⲉ ⲉⲓ̈ⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲍⲉ ⲧⲁⲕⲁⲡⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⲛ̅ⲟⲩⲉϣ ⲛ̅ϫⲟ ⲉⲃⲟⲗ ⲉⲣⲟϥ ⲉⲧⲙ̅ⲧⲣⲁⲉⲓⲣⲉ ⲙ̅ⲡⲁϩⲧⲟⲣ ϩⲙ̅ⲡⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ·
19 Bí mo ti jẹ́ òmìnira tí ń kò sì darapọ̀ mọ́ ẹnikẹ́ni, mo sọ ara mi di ẹrú lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn, láti lè jèrè ọ̀pọ̀lọpọ̀ sí i.
ⲓ̅ⲑ̅ⲉⲓ̈ⲟ ⲅⲁⲣ ⲛ̅ⲣⲙ̅ϩⲉ ϩⲛ̅ϩⲱⲃ ⲛⲓⲙ ⲁⲓ̈ⲁⲁⲧ ⲛ̅ϩⲙ̅ϩⲁⲗ ⲛ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲙ ϫⲉ ⲉⲓ̈ⲉϯϩⲏⲩ ⲙ̅ⲡⲉϩⲟⲩⲟ.
20 Nígbà tí mó wà lọ́dọ̀ àwọn Júù, mo dàbí ọ̀kan nínú wọn, kí wọn ba à lè tẹ́tí sí ìwàásù ìyìnrere mi àti ki n le jèrè wọn fún Kristi. Nígbà tí mo bá wà láàrín àwọn tó wà lábẹ́ òfin èmi kì í bá wọn jiyàn rárá (bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò sí lábẹ́ òfin), kí èmi lè jèrè àwọn ti ń bẹ lábẹ́ òfin.
ⲕ̅ⲁⲓ̈ϣⲱⲡⲉ ⲛ̅ⲛ̅ⲓ̈ⲟⲩⲇⲁⲓ̈ ϩⲱⲥ ⲓ̈ⲟⲩⲇⲁⲓ̈ ϫⲉ ⲉⲓ̈ⲉϯϩⲏⲩ ⲛ̅ⲛ̅ⲓ̈ⲟⲩⲇⲁⲓ̈. ⲁⲓ̈ϣⲱⲡⲉ ⲛ̅ⲛⲉⲧϩⲁⲡⲛⲟⲙⲟⲥ ϩⲱⲥ ⲉⲓ̈ϩⲁⲡⲛⲟⲙⲟⲥ ⲉⲛϯϣⲟⲟⲡ ⲁⲛ ⲁⲛⲟⲕ ϩⲁⲡⲛⲟⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲉⲓ̈ⲉϯϩⲏⲩ ⲛ̅ⲛⲉⲧϩⲁⲡⲛⲟⲙⲟⲥ.
21 Nígbà tí mo bá wà láàrín àwọn tí kò sí lábẹ́ òfin, èmi náà yóò dàbí ẹni tí kò sí lábẹ́ òfin (èmi kì í ṣe aláìlófin sí Ọlọ́run, ṣùgbọ́n èmí ń bẹ lábẹ́ òfin Kristi), kí èmi le jèrè àwọn tí kò sí lábẹ́ òfin.
ⲕ̅ⲁ̅ⲁⲓ̈ϣⲱⲡⲉ ⲛ̅ⲛ̅ⲁⲛⲟⲙⲟⲥ ϩⲱⲥ ⲁⲛⲟⲙⲟⲥ ⲉⲁⲛⲅ̅ⲟⲩⲁⲛⲟⲙⲟⲥ ⲁⲛ ⲙ̅ⲡⲛⲟⲩⲧⲉ. ⲁⲗⲗⲁ ⲉⲁⲛⲅ̅ⲟⲩⲉⲛⲛⲟⲙⲟⲥ ⲙ̅ⲡⲉⲭ̅ⲥ̅ ϫⲉ ⲉⲓ̈ⲉϯϩⲏⲩ ⲛ̅ⲛ̅ⲁⲛⲟⲙⲟⲥ.
22 Nígbà tí mo bá wà láàrín àwọn aláìlera, èmi náà yóò di aláìlera, kí èmi lé jèrè àwọn aláìlera. Mo di ohun gbogbo fún gbogbo ènìyàn, kí èmi ba à lè gba díẹ̀ là lábẹ́ bí ó ti wù kí ó rí.
ⲕ̅ⲃ̅ⲁⲓ̈ϣⲱⲡⲉ ⲛ̅ⲛ̅ϭⲱⲃ ϩⲱⲥ ϭⲱⲃ ϫⲉ ⲉⲓ̈ⲉϯϩⲏⲩ ⲛ̅ⲛ̅ϭⲱⲃ. ⲁⲓ̈ⲣ̅ⲥⲙⲟⲧ ⲛⲓⲙ ⲙⲛ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲙ ϫⲉⲕⲁⲥ ⲡⲁⲛⲧⲱⲥ ⲉⲓ̈ⲉⲧⲟⲩϫⲉϩⲟⲓ̈ⲛⲉ.
23 Èmi sì ń ṣe ohun gbogbo nítorí ti ìyìnrere, kí èmi kí ó lè jẹ́ alábápín nínú rẹ̀ pẹ̀lú yín.
ⲕ̅ⲅ̅ⲉⲉⲓ̈ⲉⲓⲣⲉ ⲇⲉ ⲛ̅ⲛⲁⲓ̈ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲉⲧⲃⲉⲡⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ϫⲉ ⲉⲓ̈ⲉϣⲱⲡⲉ ⲛⲁϥ ⲛ̅ⲕⲟⲓⲛⲱⲛⲟⲥ·
24 Ẹ̀yin kò mọ̀ pé, olúkúlùkù ẹni tí ó ní ipa nínú eré ìje ni ó máa ń sáré, ṣùgbọ́n ẹnìkan ṣoṣo ni ń gba ipò ẹ̀bùn tí ó ga jù. Nítorí náà, ẹ sá eré ìje yín kí ẹ ba à le borí.
ⲕ̅ⲇ̅ⲛ̅ⲧⲉⲧⲛ̅ⲥⲟⲟⲩⲛ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛⲉⲧⲡⲏⲧ ϩⲙ̅ⲡⲉⲥⲧⲁⲇⲓⲟⲛ. ⲥⲉⲡⲏⲧ ⲙⲉⲛ ⲧⲏⲣⲟⲩ. ⲟⲩⲁ ⲇⲉ ⲡⲉϣⲁϥϫⲓⲡⲉⲕⲗⲟⲙ. ⲡⲱⲧ ⲛ̅ⲧⲉⲓ̈ϩⲉ ϫⲉ ⲉⲧⲉⲧⲛⲉⲧⲁϩⲟ.
25 Gbogbo ẹni tí ó ń sáré ìje a máa lọ nínú ìsẹ́ra-ẹni tí ó lágbára. Wọ́n ń ṣe èyí láti gba adé ìdíbàjẹ́. Ṣùgbọ́n àwa ń sá eré ìje tiwa láti fi gba adé ọ̀run àìdíbàjẹ́ láéláé.
ⲕ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲇⲉ ⲛⲓⲙ ⲉⲧⲁⲅⲱⲛⲓⲍⲉ ϣⲁϥⲉⲅⲕⲣⲁⲧⲉⲩⲉ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲉϩⲱⲃ ⲛⲓⲙ ⲛⲏ ⲙⲉⲛ ϫⲉ ⲉⲩⲉϫⲓ ⲛ̅ⲟⲩⲕⲗⲟⲙ ⲉϣⲁϥⲧⲁⲕⲟ. ⲁⲛⲟⲛ ⲇⲉ ⲛ̅ⲟⲩⲁⲧⲧⲁⲕⲟ.
26 Nítorí náà, mo ń sá eré ìje lọ sójú àmì, kì í ṣe bí ẹni ti kò dá lójú. Mò ń jà kí n lè borí, kì í ṣe bí ẹni tí ń bá afẹ́fẹ́ jà.
ⲕ̅ⲋ̅ⲁⲛⲟⲕ ϭⲉ ⲉⲓ̈ⲡⲏⲧ ⲛ̅ⲧⲉⲓ̈ϩⲉ ϩⲱⲥ ϩⲛ̅ⲟⲩϩⲱⲡ ⲁⲛ. ⲉⲓ̈ⲡⲩⲕⲧⲉⲩⲉ ⲛ̅ⲧⲉⲓ̈ϩⲉ ϩⲱⲥ ⲉⲛⲉⲉⲓ̈ϩⲓⲟⲩⲉ ⲁⲛ ⲉⲡⲁⲏⲣ.
27 Ṣùgbọ́n èmi ń kó ara mi ní ìjánu, mo sì ń mú un wá sí abẹ́ ìtẹríba, pé lẹ́yìn tí mo ti wàásù fún àwọn ẹlòmíràn, nítorí ohunkóhun, kí èmi fún rara mi má ṣe di ẹni ìtanù fún ẹ̀bùn náà.
ⲕ̅ⲍ̅ⲁⲗⲗⲁ ϯⲱϥⲉ ⲙ̅ⲡⲁⲥⲱⲙⲁ ϯⲉⲓⲣⲉ ⲙ̅ⲙⲟϥ ⲛ̅ϩⲙ̅ϩⲁⲗ. ⲙⲏⲡⲱⲥ ⲉⲓ̈ⲧⲁϣⲉⲟⲉⲓϣ ⲛ̅ϩⲉⲛⲕⲟⲟⲩⲉ ⲧⲁϣⲱⲡⲉ ⲁⲛⲟⲕ ⲛ̅ϫⲟⲟⲩⲧ·

< 1 Corinthians 9 >