< 1 Corinthians 9 >

1 Èmi kò ha ni òmìnira bí? Èmi kò ha ń ṣe aposteli bí? Èmi kò ha ti rí Jesu Olúwa bí? Ẹ̀yìn ha kọ́ ní èrè iṣẹ́ mi nínú Olúwa bí?
ⲁ̅Ⲙⲏ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲟⲩⲣⲉⲙϩⲉ ⲁⲛ ⲙⲏ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲟⲩⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⲁⲛ ⲙⲏ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲡⲉⲛ⳪ ⳿ⲙⲡⲓⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲙⲏ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ ⲡⲉ ⲡⲁϩⲱⲃ ϧⲉⲛ Ⲡ⳪.
2 Ní ìrònú àwọn ẹlòmíràn, èmi kì í ṣe aposteli. Dájúdájú aposteli ni mo jẹ́ fún un yín, tí n kì bá ṣe fún àwọn ẹlòmíràn. Nítorí èdìdì iṣẹ́ aposteli mi ni ẹ̀yin jẹ́ nínú Olúwa.
ⲃ̅ⲓⲥϫⲉ ϯⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⲁⲛ ⳿ⲛϩⲁⲛⲕⲉⲭⲱⲟⲩⲛⲓ ⲁⲗⲗⲁ ϯⲟⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϯ⳿ⲥ⳿ⲫⲣⲁⲅⲓⲥ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲁⲙⲉⲧⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲡⲉ ϧⲉⲛ Ⲡ⳪.
3 Èyí ni ìdáhùn mi sí àwọn tí ń béèrè ẹ̀tọ́ aposteli mi.
ⲅ̅ⲧⲁⲁⲡⲟⲗⲟⲅⲓⲁ ⳿ⲛⲛⲏ ⲉⲧϧⲟⲧϧⲉⲧ ⳿ⲙⲙⲟⲓ ⲑⲁⲓ ⲧⲉ.
4 Ṣé a kò ní ẹ̀tọ́ láti máa jẹ àti láti máa mu bí?
ⲇ̅ⲙⲏ ⳿ⲙⲙⲟⲛⲧⲉⲛ ⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲉⲟⲩⲱⲙ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉⲥⲱ.
5 Ṣé àwa kò ní ẹ̀tọ́ láti máa mú ìyàwó tí í ṣe onígbàgbọ́ káàkiri gẹ́gẹ́ bí àwọn aposteli mìíràn? Àti bí arákùnrin Olúwa, àti Kefa.
ⲉ̅ⲙⲏ ⲟⲩⲟⲛⲧⲉⲛ ⲉⲣϣⲓϣⲓ ⲉⲑⲣⲉ ⲟⲩⲥⲱⲛⲓ ⳿ⲛ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲥⲱⲛ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲙ⳿ⲡⲥⲉⲡⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ⲛⲉⲙ ⲕⲏⲫⲁ.
6 Ṣé èmi nìkan àti Barnaba, àwa kò ha ní agbára láti máa ṣiṣẹ́ bọ́ ara wa ni?
ⲋ̅ϣⲁⲛ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧ ⲛⲉⲙ ⲃⲁⲣⲛⲁⲃⲁⲥ ⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛⲧⲉⲛ ⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲉ⳿ϣⲧⲉⲙⲉⲣϩⲱⲃ.
7 Ta ni ó ṣíṣẹ́ ológun tí ó sanwó ara rẹ̀? Ta ní gbin ọgbà àjàrà tí kì í jẹ nínú èso rẹ̀? Tàbí ta ní ń bọ ọ̀wọ́ ẹran tí kì í sí ì jẹ nínú wàrà ọ̀wọ́ ẹran?
ⲍ̅ⲛⲓⲙ ⳿ⲉϣⲁϥⲉⲣⲙⲁⲧⲟⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛⲟⲩϥ ⳿ⲛⲟⲯⲱⲛⲓⲟⲛ ⲉⲛⲉϩ ⲛⲓⲙ ⳿ⲉϣⲁϥϭⲟ ⳿ⲛⲟⲩⲓⲁϩⲁⲗⲟⲗⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲁϥⲟⲩⲱⲙ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲉϥⲟⲩⲧⲁϩ ⲓⲉ ⲛⲓⲙ ⳿ⲉϣⲁϥⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲟϩⲓ ⳿ⲛ⳿ⲉⲥⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙⲟⲩⲱⲙ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲡⲉⲣⲱϯ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲟϩⲓ.
8 Èmi ha sọ nǹkan wọ̀nyí bí ènìyàn? Tàbí òfin kò wí bákan náà bì?
ⲏ̅ⲙⲏ ⲁⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲓ ⲕⲁⲧⲁ ⲣⲱⲙⲓ ϣⲁⲛ ⲡⲓⲕⲉⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⳿ϥϫⲱ ⳿ⲛⲛⲁⲓ ⲁⲛ.
9 Nítorí nínú òfin tí Ọlọ́run fún Mose, ni a tí kọ ọ́ pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu.” Ǹjẹ́ màlúù ni Ọlọ́run n ṣe ìtọ́jú rẹ̀ bi?
ⲑ̅⳿ⲥ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ⲅⲁⲣ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲙⲙⲱ⳿ⲩⲥⲏⲥ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲉⲕϯ ⲥⲁⲭⲟⲗ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲉⲛ ⲉϩⲉ ⲉϥϩⲓ ⲙⲏ ⲁⲥⲉⲣⲙⲉⲗⲓⲛ ⳿ⲙⲫϯ ϧⲁ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲱⲟⲩ.
10 Dájúdájú ó sọ eléyìí fún wa pé, nítorí wa ni a ṣe kọ̀wé yìí kí ẹni tí ń tulẹ̀ lè máa tulẹ̀ ní ìrètí àti ẹni tí ń pakà lè ni ìrètí láti ní ìpín nínú ìkórè.
ⲓ̅ϣⲁⲛ ⲡⲁⲛⲧⲱⲥ ⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲉⲑⲃⲏ ⲧⲉⲛ ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲥϧⲏⲧⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⲉⲑⲃⲏⲧⲉⲛ ϫⲉ ⳿ⲥⲉⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫⲏ ⲉⲧ⳿ⲥⲭⲁⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲥⲭⲁⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏ ⲉⲧϩⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥⲉⲣϩⲉⲗⲡⲓⲥ ⳿ⲉϭⲓ.
11 Bí àwa ti fún irúgbìn ohun ti ẹ̀mí sínú ọkàn yín, ohun ńlá ha ni bí àwa ó ba ká ohun ti yín tí ṣe ti ara?
ⲓ̅ⲁ̅ⲓⲥϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲁⲛⲥⲓϯ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛⲛⲓⲡⲛ̅ⲁ̅ⲧⲓⲕⲟⲛ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⲡⲉ ⲉϣⲱⲡ ⲁⲛϣⲁⲛⲱⲥϧ ⳿ⲛⲛⲉⲧⲉⲛⲥⲁⲣⲕⲓⲕⲟⲛ.
12 Bí àwọn ẹlòmíràn bá ní ẹ̀tọ́ tí ìrànlọ́wọ́ sì wá láti ọ̀dọ̀ yín, àwa ha kọ́ ni ó tọ́ sí jù? Ṣùgbọ́n àwa kò lo agbára yìí ṣùgbọ́n àwa faradà ohun gbogbo, kí àwa má ba à ṣe ìdènà fún ìyìnrere Kristi.
ⲓ̅ⲃ̅ⲓⲥϫⲉ ϩⲁⲛⲕⲉⲭⲱⲟⲩⲛⲓ ⲉⲧϭⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲉⲧⲉⲛⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲭⲣⲁⲥⲑⲉ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲉⲣϣⲓϣⲓ ⲁⲗⲗⲁ ⲧⲉⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲛ⳿ϣⲧⲉⲙϯ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛ⳿ϭⲣⲟⲡ ⳿ⲙⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ. ̅.
13 Ǹjẹ́ ó yé e yín pé Ọlọ́run sọ fún àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili pé kí wọ́n mú oúnjẹ tàbí àwọn ẹ̀bùn tí wọ́n mú wá fún òun, láti fi ṣe ìtọ́jú ara wọn? Àti àwọn tí ń dúró tí pẹpẹ wọn a máa ṣe àjọpín pẹ̀lú pẹpẹ.
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛⲏ ⲉⲧⲉⲣϩⲱⲃ ⳿ⲉⲛⲓⲉⲣⲫⲏⲟⲩ⳿ⲓ ϣⲁⲩⲟⲩⲱⲙ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲁ ⲡⲓⲉⲣⲫⲉⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲏ ⲉⲑⲙⲏⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲙⲁ⳿ⲛⲉⲣϣⲱⲟⲩϣⲓ ϣⲁⲩⲫⲱϣ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲁⲩ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲙⲁ⳿ⲛⲉⲣϣⲱⲟⲩϣⲓ.
14 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi àṣẹ lélẹ̀ pé, àwọn tí ń wàásù ìyìnrere kí wọn sì máa jẹ́ nípa ìyìnrere.
ⲓ̅ⲇ̅ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ϩⲱϥ Ⲡ⳪ ⲁϥⲑⲱϣ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲙⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⳿ⲉⲱⲛϧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ.
15 Síbẹ̀síbẹ̀ n kò ì tí ì lo irú àwọn ẹ̀tọ́ wọ̀nyí rí. Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì kọ ìwé yìí láti fi sọ fún un yín pé, mo fẹ́ bẹ̀rẹ̀ sí í gbà irú nǹkan bẹ̀ ẹ́ lọ́wọ́ yín. Kí a sọ òtítọ́, ó sàn fún mi láti kú sínú ebi ju pé kí n sọ ògo tí mo ní láti wàásù nù.
ⲓ̅ⲉ̅⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲓⲉⲣ⳿ⲭⲣⲁⲥⲑⲉ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛⲛⲁⲓ ⲛⲉⲧⲁⲓ⳿ⲥϧⲉ ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⲁⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧ ⲛⲁⲛⲉⲥ ⲅⲁⲣ ⲛⲏⲓ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⳿ⲉⲙⲟⲩ ⲓⲉ ⲡⲁϣⲟⲩϣⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ϣⲟⲩⲱϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
16 Nítorí pé bí mo ti ń wàásù ìyìnrere, kì í ṣe ohun tí mo lè máa ṣògo lè. Èmi kò tilẹ̀ le è ṣe é ní, kí a tilẹ̀ sọ pé mo fẹ́ kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Ègbé ni fún mi tí mo bá kọ̀ láti wàásù ìyìnrere.
ⲓ̅ⲋ̅⳿ⲉϣⲱⲡ ⲅⲁⲣ ⲁⲓϣⲁⲛϩⲓϣⲉⲛⲛⲟⲩϥⲓ ⳿ⲛⲟⲩϣⲟⲩϣⲟⲩ ⲛⲏⲓ ⲁⲛ ⲡⲉ ⲟⲩⲁⲛⲁⲅⲕⲏ ⲅⲁⲣ ⲉⲧⲭⲏ ϩⲓϫⲱⲓ ⲟⲩⲟⲓ ⲅⲁⲣ ⲛⲏⲓ ⲉϣⲱⲡ ⲁⲓ⳿ϣⲧⲉⲙϩⲓϣⲉⲛⲛⲟⲩϥⲓ.
17 Tó bá jẹ́ pé mò ń wàásù tinútinú mi, mo ní èrè kan, ṣùgbọ́n tí ń kò bá ṣe tinútinú mi, a ti fi iṣẹ́ ìríjú lé mi lọ́wọ́.
ⲓ̅ⲍ̅ⲓⲥϫⲉ ⲅⲁⲣ ⲁⲓ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲫⲁⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲛⲏⲓ ⲓⲉ ⲟⲩⲟⲛϯ ⲃⲉⲭⲉ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲓⲥϫⲉ ⳿ⲉ⳿ϩⲛⲏⲓ ⲁⲛ ⲓⲉ ⲟⲩⲟⲓⲕⲟⲛⲟⲙⲓⲁ ⲡⲉⲧⲁⲩⲧⲉⲛϩⲟⲩⲧ ⳿ⲉⲣⲟⲥ.
18 Ní irú ipò báyìí, kín ni ẹ rò pé yóò jẹ èrè mi ni láti jẹ́? Èrè mi ní àgbàyanu ayọ̀ tí mo ń rí gbà nípa ìwàásù ìyìnrere láìgba owó lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, láìbéèrè ẹ̀tọ́ mi lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni.
ⲓ̅ⲏ̅ⲁϣ ⲟⲩⲛ ⲡⲉ ⲡⲁⲃⲉⲭⲉ ϩⲓⲛⲁ ⲉⲓϩⲓϣⲉⲛⲛⲟⲩϥⲓ ⳿ⲛⲧⲁⲭⲁ ⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⲁⲧ⳿ϭⲛⲉ ⲇⲁⲡⲁⲛⲏ ⳿ⲉ⳿ϣⲧⲉⲙⲉⲣ⳿ⲭⲣⲁⲥⲑⲉ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲉⲣϣⲓϣⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ.
19 Bí mo ti jẹ́ òmìnira tí ń kò sì darapọ̀ mọ́ ẹnikẹ́ni, mo sọ ara mi di ẹrú lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn, láti lè jèrè ọ̀pọ̀lọpọ̀ sí i.
ⲓ̅ⲑ̅ⲉⲓⲟⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲣⲉⲙϩⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁⲓⲁⲓⲧ ⳿ⲙⲃⲱⲕ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁϫⲉⲙϩⲏⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲓϩⲟⲩ⳿ⲟ.
20 Nígbà tí mó wà lọ́dọ̀ àwọn Júù, mo dàbí ọ̀kan nínú wọn, kí wọn ba à lè tẹ́tí sí ìwàásù ìyìnrere mi àti ki n le jèrè wọn fún Kristi. Nígbà tí mo bá wà láàrín àwọn tó wà lábẹ́ òfin èmi kì í bá wọn jiyàn rárá (bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò sí lábẹ́ òfin), kí èmi lè jèrè àwọn ti ń bẹ lábẹ́ òfin.
ⲕ̅ⲁⲓϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁϫⲉⲙϩⲏⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲁⲓϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲛⲏ ⲉⲧⲭⲏ ϧⲁ ⳿ⲫⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲉⲓⲭⲏ ϧⲁ ⳿ⲫⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲛϯⲭⲏ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲁⲛ ϧⲁ ⳿ⲫⲛⲟⲙⲟⲥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁϫⲉⲙϩⲏⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧⲭⲏ ϧⲁ ⳿ⲫⲛⲟⲙⲟⲥ.
21 Nígbà tí mo bá wà láàrín àwọn tí kò sí lábẹ́ òfin, èmi náà yóò dàbí ẹni tí kò sí lábẹ́ òfin (èmi kì í ṣe aláìlófin sí Ọlọ́run, ṣùgbọ́n èmí ń bẹ lábẹ́ òfin Kristi), kí èmi le jèrè àwọn tí kò sí lábẹ́ òfin.
ⲕ̅ⲁ̅ⲁⲓϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲁⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲉ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲟⲩⲁⲛⲟⲙⲟⲥ ⲁⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲁⲗⲗⲁ ⲉⲓⲭⲏ ϧⲁ ⳿ⲫⲛⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲙⲠⲭ̅ⲥ̅ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁϫⲉⲙϩⲏⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲛⲟⲙⲟⲥ.
22 Nígbà tí mo bá wà láàrín àwọn aláìlera, èmi náà yóò di aláìlera, kí èmi lé jèrè àwọn aláìlera. Mo di ohun gbogbo fún gbogbo ènìyàn, kí èmi ba à lè gba díẹ̀ là lábẹ́ bí ó ti wù kí ó rí.
ⲕ̅ⲃ̅ⲁⲓϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧϣⲱⲛⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲉϥϣⲱⲛⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁϫⲉⲙϩⲏⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧϣⲱⲛⲓ ⲁⲓϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲛⲣⲏϯ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϩⲓⲛⲁ ⲡⲁⲛⲧⲱⲥ ⳿ⲛⲧⲁⲛⲟϩⲉⲙ ⳿ⲛϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ.
23 Èmi sì ń ṣe ohun gbogbo nítorí ti ìyìnrere, kí èmi kí ó lè jẹ́ alábápín nínú rẹ̀ pẹ̀lú yín.
ⲕ̅ⲅ̅ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⲧⲏⲣⲟⲩ ϯ⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲉⲣⲟϥ.
24 Ẹ̀yin kò mọ̀ pé, olúkúlùkù ẹni tí ó ní ipa nínú eré ìje ni ó máa ń sáré, ṣùgbọ́n ẹnìkan ṣoṣo ni ń gba ipò ẹ̀bùn tí ó ga jù. Nítorí náà, ẹ sá eré ìje yín kí ẹ ba à le borí.
ⲕ̅ⲇ̅⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛⲏⲉⲧϭⲟϫⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲥⲧⲁⲇⲓⲟⲛ ⲥⲉϭⲟϫⲓ ⲙⲉⲛ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲟⲩⲁⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉϣⲁϥϭⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲃⲁⲓ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲇⲉ ϭⲟϫⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲧⲁϩⲟ.
25 Gbogbo ẹni tí ó ń sáré ìje a máa lọ nínú ìsẹ́ra-ẹni tí ó lágbára. Wọ́n ń ṣe èyí láti gba adé ìdíbàjẹ́. Ṣùgbọ́n àwa ń sá eré ìje tiwa láti fi gba adé ọ̀run àìdíbàjẹ́ láéláé.
ⲕ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲇⲉ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲉⲣⲁⲅⲱⲛⲓⲍⲉⲥⲑⲉ ϣⲁϥ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲏ ⲙⲉⲛ ⲟⲩⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉϭⲓ ⳿ⲛⲟⲩ⳿ⲭⲗⲟⲙ ⲉϥⲛⲁⲧⲁⲕⲟ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲇⲉ ⲟⲩⲁⲧⲧⲁⲕⲟ.
26 Nítorí náà, mo ń sá eré ìje lọ sójú àmì, kì í ṣe bí ẹni ti kò dá lójú. Mò ń jà kí n lè borí, kì í ṣe bí ẹni tí ń bá afẹ́fẹ́ jà.
ⲕ̅ⲋ̅⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ϯϭⲟϫⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ϩⲱⲥ ϧⲉⲛ ⲟⲩϩⲱⲡ ⲁⲛ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ϯϯ ϩⲱⲥ ⲉⲓϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⲁⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲁⲏⲣ.
27 Ṣùgbọ́n èmi ń kó ara mi ní ìjánu, mo sì ń mú un wá sí abẹ́ ìtẹríba, pé lẹ́yìn tí mo ti wàásù fún àwọn ẹlòmíràn, nítorí ohunkóhun, kí èmi fún rara mi má ṣe di ẹni ìtanù fún ẹ̀bùn náà.
ⲕ̅ⲍ̅ⲁⲗⲗⲁ ϯⲱϥⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲥⲱⲙⲁ ⲟⲩⲟϩ ϯⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲙⲃⲱⲕ ⲙⲏⲡⲱⲥ ⳿ⲉⲁⲓϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲛϩⲁⲛⲕⲉ ⲭⲱⲟⲩⲛⲓ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϩⲱ ⳿ⲛⲥⲉϫⲉⲙⲧ ⲉⲓⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲇⲟⲕⲓⲙⲟⲥ.

< 1 Corinthians 9 >