< 1 Corinthians 7 >

1 Ní báyìí, nítorí àwọn ohun tí ẹ ṣe kọ̀wé: Ó dára fún ọkùnrin kí ó máa ṣe ni ìdàpọ̀ pẹ̀lú obìnrin.
ⲁ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲛⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲥϧⲏⲧⲟⲩ ⲛⲏⲓ ⲛⲁⲛⲉⲥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉ⳿ϣⲧⲉⲙϭⲓ ⲛⲉⲙ ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ.
2 Ṣùgbọ́n nítorí àgbèrè pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ kí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan gbéyàwó tirẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni kí obìnrin kọ̀ọ̀kan ní ọkọ tirẹ̀.
ⲃ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲛⲓⲡⲟⲣⲛⲓⲁ ⲇⲉ ⲙⲁⲣⲉ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲭⲁ ⲧⲉϥ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲛⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⲙⲁⲣⲉ ϯⲟⲩ⳿ⲓ ϯⲟⲩ⳿ⲓ ⲭⲁ ⲡⲉⲥϩⲁⲓ ⲛⲁⲥ.
3 Kí ọkùnrin kí ó fi gbogbo ẹ̀tọ́ ìyàwó rẹ̀ fún ún, kí ìyàwó fi gbogbo ẹ̀tọ́ ọkọ fún ọkọ rẹ̀.
ⲅ̅ⲡⲓϩⲁⲓ ⲙⲁⲣⲉϥϯ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲟⲛ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲙⲁⲣⲉⲥϯ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲣⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲉⲥϩⲁⲓ.
4 Aya kò láṣẹ lórí ara rẹ̀ mọ́, ara rẹ̀ ti di ti ọkọ rẹ̀. Bákan náà ni ọkùnrin tí ó gbéyàwó kò ní àṣẹ lórí ara rẹ̀ mọ́, ara rẹ̀ ti di ti ìyàwó rẹ̀.
ⲇ̅ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛⲧⲉⲥ ⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲥⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲙⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲓϩⲁⲓ ⲡⲉ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲟⲛ ⲡⲓⲕⲉϩⲁⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛⲧⲉϥ ⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲙⲡⲉϥⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲙⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲁⲗⲗⲁ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲧⲉ.
5 Nítorí náà, ẹ má ṣe fi àwọn ẹ̀tọ́ tọkọtaya wọ̀nyí dun ara yín, bí kò ṣe nípa ìfìmọ̀ṣọ̀kan, kí ẹ̀yin lè fi ara yín fún àwẹ̀ àti àdúrà, kí ẹ̀yin sì tún jùmọ̀ pàdé, lẹ́yìn ìgbà náà, wọ́n gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ ara wọn kí Satani má ba à dán wọn wò nítorí àìlèmáradúró wọn.
ⲉ̅⳿ⲙⲡⲉⲣϥⲉϫ ⲛⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⲁⲣⲏⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲟⲩϯⲙⲁϯ ⳿ⲡⲣⲟⲥ ⲟⲩⲥⲏⲟⲩ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲥⲣⲱϥⲧ ⳿ⲉϯ⳿ⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲏ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲁⲗⲓⲛ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲓ ⲉⲩⲙⲁ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ⳿ⲡⲥⲁⲧⲁⲛⲁⲥ ⲉⲣⲡⲓⲣⲁⲍⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⲉⲑⲃⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲙⲉⲧⲁⲧⲑⲱⲧ⳿ⲛϩⲏⲧ.
6 Mo sọ èyí fún un yín bí ìmọ̀ràn ní kì í ṣe bí àṣẹ.
ⲋ̅ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲕⲁⲧⲁ ⲟⲩⲥⲩⲛ⳿ⲅⲛⲱⲙⲏ ⲕⲁⲧⲁ ⲟⲩⲁϩⲥⲁϩⲛⲓ ⲁⲛ.
7 Ó wù mí kí olúkúlùkù dàbí èmi, ṣùgbọ́n gbogbo ènìyàn kò le jẹ́ bákan náà, Ọlọ́run fún olúkúlùkù ènìyàn ní ẹ̀bùn tirẹ̀, ọ̀kan bí irú èyí àti èkejì bí irú òmíràn.
ⲍ̅ϯⲟⲩⲱϣ ⲇⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲣⲏϯ ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲟⲩⲛⲟⲧⲉϥ ⲟⲩ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲫϯ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲙⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲕⲉⲟⲩⲁⲓ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲕⲉⲣⲏϯ.
8 Nítorí náà, mo wí fún àwọn àpọ́n àti opó pé, ó sàn kí wọ́n kúkú wà gẹ́gẹ́ bí èmi tí wà.
ⲏ̅ϯϫⲱ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲛⲏ ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲟⲩϭⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲭⲏⲣⲁ ϫⲉ ⲛⲁⲛⲉⲥ ⲛⲱⲟⲩ ⲁⲩϣⲁⲛϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲣⲏϯ.
9 Ṣùgbọ́n bí wọ́n kò bá lè mú ara dúró, kí wọ́n gbéyàwó tàbí kí wọ́n fẹ́ ọkọ, nítorí pé ó sàn láti gbéyàwó jù láti ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ lọ.
ⲑ̅ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ ⲥⲉⲛⲁ⳿ϣⲉⲣⲉⲅⲕⲣⲁⲧⲉⲩⲉⲥⲑⲉ ⲁⲛ ⲙⲁⲣⲟⲩϭⲓ ⲛⲁⲛⲉⲥ ⲅⲁⲣ ⳿ⲉϭⲓ ⲉϩⲟⲧⲉ ⳿ⲛⲥⲉϭⲓ ⳿ⲭⲣⲱⲙ.
10 Àwọn ti ó ti gbéyàwó àti àwọn tí ó lọ́kọ, ni mo fẹ́ pa á láṣẹ fún kì í ṣe láti ọ̀dọ̀ mi ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa: “Obìnrin kò gbọdọ̀ kọ́ fi ọkọ rẹ̀ sílẹ̀.”
ⲓ̅ⲛⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲁⲩϭⲓ ϯϩⲟⲛϩⲉⲛ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲁⲛ ⲁⲗⲗⲁ Ⲡ⳪ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲥ⳿ϣⲧⲉⲙⲫⲱⲣϫ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲡⲉⲥϩⲁⲓ.
11 Ṣùgbọ́n tí ó bá fi ọkọ rẹ̀ sílẹ̀; jẹ́ kí ó wà láìní ọkọ mọ́, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, kí ó bá ọkọ rẹ̀ làjà, kí ọkọ kí ó má ṣe aya rẹ̀ sílẹ̀.
ⲓ̅ⲁ̅ⲕⲁⲛ ⲉϣⲱⲡ ⲁⲥϣⲁⲛⲫⲱⲣϫ ⲙⲁⲣⲉⲥⲟϩⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲉϣⲉⲛ ϭⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲙⲁⲣⲉⲥϩⲱⲧⲡ ⳿ⲉⲡⲉⲥϩⲁⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓϩⲁⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙⲭⲁ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ.
12 Mo fẹ́ fi àwọn ìmọ̀ràn kan kún ún fún un yín, kì í ṣe àṣẹ láti ọ̀dọ̀ Olúwa. Bí arákùnrin bá fẹ́ aya tí kò gbàgbọ́, tí aya náà sá á fẹ́ dúró tí ọkọ náà, ọkọ náà tí í ṣe onígbàgbọ́ kò gbọdọ̀ kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
ⲓ̅ⲃ̅⳿ⲡⲥⲉⲡⲓ ⲇⲉ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲁⲛⲟⲕ Ⲡ⳪ ⲁⲛ ϫⲉ ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲥⲟⲛ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛⲧⲉϥ ⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲁⲑⲛⲁϩϯ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲑⲁⲓ ⲉⲥϯ ⲙⲁϯ ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲛⲉⲙⲁϥ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉϥⲭⲁⲥ ⳿ⲛⲥⲱϥ.
13 Tí ó bá sì jẹ́ obìnrin ló fẹ́ ọkọ tí kò gbàgbọ́, ṣùgbọ́n tí ọkọ náà ń fẹ́ kí obìnrin yìí dúró tí òun, aya náà kò gbọdọ̀ kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
ⲓ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛⲧⲁⲥ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲟⲩϩⲁⲓ ⳿ⲛⲁⲑⲛⲁϩϯ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲁⲓ ⲉϥϯⲙⲁϯ ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲛⲉⲙⲁⲥ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉⲥⲭⲁ ⲡⲓϩⲁⲓ ⳿ⲛⲥⲱⲥ.
14 Nítorí pé ó ṣe é ṣe kí a lè mú ọkọ tí kò gba Kristi gbọ́ súnmọ́ Ọlọ́run nípa aya tí í ṣe onígbàgbọ́, a sì le mú ìyàwó tí kò gba Kristi gbọ́ súnmọ́ Ọlọ́run nípa ọkọ tí í ṣe onígbàgbọ́. Bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, àwọn ọmọ wọn yóò jẹ́ aláìmọ́. Ṣùgbọ́n bí wọn kò bá kọ ara wọn sílẹ̀, ó ṣe é ṣe kí àwọn ọmọ wọn di mímọ́.
ⲓ̅ⲇ̅ⲁϥⲧⲟⲩⲃⲟ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓϩⲁⲓ ⳿ⲛⲁⲑⲛⲁϩϯ ϧⲉⲛ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥⲧⲟⲩⲃⲟ ⳿ⲛϫⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲁⲑⲛⲁϩϯ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲥⲟⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ϩⲁⲣⲁ ⲛⲉⲧⲉⲛϣⲏⲣⲓ ⲥⲉϭⲁϧⲉⲙ ϯⲛⲟⲩ ⲇⲉ ⲥⲉⲟⲩⲁⲃ.
15 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin tí i ṣe aláìgbàgbọ́ náà bá fẹ́ láti lọ, jẹ́ kí ó máa lọ. Arákùnrin tàbí arábìnrin náà kò sí lábẹ́ ìdè mọ́; Ọlọ́run ti pè wá láti gbé ní àlàáfíà.
ⲓ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲓⲥϫⲉ ⲡⲓⲁⲑⲛⲁϩϯ ⲛⲁⲫⲱⲣϫ ⲙⲁⲣⲉϥⲫⲱⲣϫ ⳿ⲛ⳿ϥⲟⲓ ⳿ⲙⲃⲱⲕ ⲁⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲥⲟⲛ ⲓⲉ ϯⲥⲱⲛⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲫϯ ⲇⲉ ⲁϥⲑⲁϩⲉⲙ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲟⲩϩⲓⲣⲏⲛⲏ.
16 Báwo ni ẹ̀yin aya ṣe le mọ̀ pé bóyá ẹ̀yin ni yóò gba ọkọ yín là? Bákan náà ni a lè wí nípa ọkọ tí í ṣe onígbàgbọ́ pé, kò sí ìdánilójú pé aya aláìgbàgbọ́ le yípadà láti di onígbàgbọ́ nípa dídúró ti ọkọ.
ⲓ̅ⲋ̅ⲁⲣⲉ⳿ⲉⲙⲓ ⲅⲁⲣ ⲑⲱⲛ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ϫⲉ ⲁⲣⲏⲟⲩ ⲧⲉⲣⲁ⳿ϣⲛⲟϩⲉⲙ ⳿ⲙⲡⲉϩⲁⲓ ⲓⲉ ⲁⲕⲥⲱⲟⲩⲛ ⲑⲱⲛ ⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ϫⲉ ⲁⲣⲏⲟⲩ ⳿ⲭⲛⲁ⳿ϣⲛⲟϩⲉⲙ ⳿ⲛⲧⲉⲕ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ.
17 Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí olúkúlùkù máa gbé ìgbé ayé tí Ọlọ́run ń fẹ́ yín fún, àti nínú èyí tí Olúwa pè é sí. Ìlànà àti òfin mi fún gbogbo ìjọ ni èyí.
ⲓ̅ⲍ̅⳿ⲓⲙⲏϯ ⳿ⲉⲡⲓⲣⲏϯ ⲉⲧⲁ Ⲡ⳪ ⲑⲁϣϥ ⳿ⲙⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁ ⲫϯ ⲑⲁϩⲉⲙ ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲙⲁⲣⲉϥⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲟⲛ ⳿ⲉϯⲟⲩⲁϩⲥⲁϩⲛⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
18 Ǹjẹ́ ọkùnrin kan ha ti kọlà nígbà tí a pè é? Kí ó má sì ṣe di aláìkọlà. Ǹjẹ́ ọkùnrin kan ha ti kọlà nígbà tí a pè é? Kí ó ma ṣe kọlà.
ⲓ̅ⲏ̅ⲁⲩⲑⲁϩⲉⲙ ⲟⲩⲁⲓ ⲉϥⲥⲟⲩⲃⲏⲧ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉϥⲥⲉⲕ ϯⲙⲉⲧⲁⲧⲥⲉⲃⲓ ⲛⲁϥ ⲁⲩⲑⲁϩⲉⲙ ⲟⲩⲁⲓ ϧⲉⲛ ϯⲙⲉⲧⲁⲧⲥⲉⲃⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉϥⲥⲟⲩⲃⲏⲧϥ.
19 Ìkọlà kò jẹ́ nǹkan àti àìkọlà kò jẹ́ nǹkan, bí kò ṣe pípa òfin Ọlọ́run mọ́.
ⲓ̅ⲑ̅⳿ⲡⲥⲉⲃⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ϩⲗⲓ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ϯⲙⲉⲧⲁⲧⲥⲉⲃⲓ ⳿ϩⲗⲓ ⲧⲉ ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲓⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲛⲓⲉⲛⲧⲟⲗⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
20 Ó yẹ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan máa ṣe iṣẹ́ tí ó ń ṣe tẹ́lẹ̀, kí Ọlọ́run tó pé é sínú ìgbàgbọ́ nínú Kristi.
ⲕ̅ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲑⲱϩⲉⲙ ⲉⲧⲁⲩⲑⲁϩⲙⲉϥ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲙⲁⲣⲉϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ.
21 Ǹjẹ́ ẹrú ni ọ́ bí nígbà ti a pè ọ́? Má ṣe kà á sí. Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá le di òmìnira, kúkú ṣe èyí nì.
ⲕ̅ⲁ̅ⲁⲩⲑⲁϩⲙⲉⲕ ⲉⲕⲟⲓ ⳿ⲙⲃⲱⲕ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉⲥⲉⲣⲙⲉⲗⲓ ⲛ ⲛⲁⲕ ⲁⲗⲗⲁ ⲓⲥϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟⲕ ⳿ⲉⲉⲣⲣⲉⲙϩⲉ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⲁⲣⲓⲟⲩ⳿ⲓ.
22 Tí ó bá jẹ́ ẹrú, ti Olúwa sì pé ọ, rántí pé Kristi ti sọ ọ́ di òmìnira kúrò lọ́wọ́ agbára búburú ti ẹ̀ṣẹ̀. Tí ó bá sì ti pé ọ̀ nítòótọ́ tí ó sì ti di òmìnira, ó ti di ẹrú Kristi.
ⲕ̅ⲃ̅ⲡⲓⲃⲱⲕ ⲅⲁⲣ ⲉⲧⲁⲩⲑⲁϩⲙⲉϥ ϧⲉⲛ Ⲡ⳪ ⲟⲩⲁⲡⲉⲗⲉⲩⲑⲉⲣⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ⲡⲉ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲟⲛ ⲡⲓⲣⲉⲙϩⲉ ⲉⲧⲁⲩⲑⲁϩⲙⲉϥ ⲟⲩⲃⲱⲕ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲡⲉ.
23 A sì ti rà yín ní iye kan, nítorí náà ẹ má ṣe di ẹrú ènìyàn.
ⲕ̅ⲅ̅ⲁⲩϣⲉⲡ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲁ ⲟⲩⲧⲓⲙⲏ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲉⲣⲃⲱⲕ ⳿ⲛⲛⲓⲣⲱⲙⲓ.
24 Ará, jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn, nínú èyí tí a pè é, kí ó dúró nínú ọ̀kan náà pẹ̀lú Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲇ̅ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲛⲁ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲫⲏ ⲉⲧⲁⲩⲑⲁϩⲙⲉϥ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ϧⲉⲛ ⲫⲁⲓ ⲙⲁⲣⲉϥϣⲱⲡⲓ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲫϯ.
25 Ṣùgbọ́n nípa ti àwọn wúńdíá, èmi kò ní àṣẹ kankan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n mo wí fún yín ní ìdájọ́ bí ẹni tí ó rí àánú Olúwa gbà láti jẹ́ olódodo.
ⲕ̅ⲉ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲛⲓⲡⲁⲣⲑⲉⲛⲟⲥ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛϯ ⲟⲩⲁϩⲥⲁϩⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲧⲉⲛ Ⲡ⳪ ⲟⲩ⳿ⲅⲛⲱⲙⲏ ⲇⲉ ⲡⲉϯϯ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϩⲱⲥ ⳿ⲉⲁⲩⲛⲁⲓ ⲛⲏⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ Ⲡ⳪ ⲉⲑⲣⲓϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲧⲟⲥ.
26 Nítorí náà mo rò pé èyí dára nítorí wàhálà ìsinsin yìí, èyí nì ni pé o dára fún ènìyàn kí ó wà bí o ṣe wà.
ⲕ̅ⲋ̅ϯⲙⲉⲩ⳿ⲓ ⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲛⲁⲛⲉ ⲫⲁⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥϣⲱⲡⲓ ⲉⲑⲃⲉ ϯⲁⲛⲁⲅⲕⲏ ⲉⲧϣⲟⲡ ϫⲉ ⲛⲁⲛⲉⲥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⲉⲑⲣⲉϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ.
27 Ǹjẹ́ ó ti ṣe ẹlẹ́rìí láti fẹ́ ìyàwó. Ẹ má ṣe kọ ara yín sílẹ̀, nítorí èyí tí mo wí yìí. Ṣùgbọ́n tí o kò bá sì tí ìgbéyàwó, tàbí fẹ́ ọkọ, má ṣe sáré láti ṣe bẹ́ẹ̀ lákokò yìí.
ⲕ̅ⲍ̅⳿ⲕⲥⲟⲛϩ ⳿ⲉ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲃⲟⲗⲕ ⳿ⲕⲃⲏⲗ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ.
28 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá gbé ìyàwó ìwọ kò dẹ́ṣẹ̀, bí a bá gbé wúńdíá ní ìyàwó òun kò dẹ́ṣẹ̀. Ṣùgbọ́n irú àwọn tí ó bá gbé ìyàwó yóò dojúkọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàhálà nípa ti ara, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ dá a yín sí.
ⲕ̅ⲏ̅ⲕⲁⲛ ⲉϣⲱⲡ ⲁⲕϣⲁⲛϭⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲕⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉϣⲱⲡ ⲁⲥϣⲁⲛϭⲓ ⳿ⲛϫⲉ ϯⲡⲁⲣⲑⲉⲛⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲉⲥⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ⲉⲩ⳿ⲉϭⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲟⲩϩⲟϫϩⲉϫ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ. ⳿.
29 Òun ti mo ń wí ará, ni pé kúkúrú ni àkókò, láti ìsinsin yìí lọ, ẹni tí ó ni aya kí ó dàbí ẹni tí kò ní rí;
ⲕ̅ⲑ̅⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ϯϯ⳿ⲁⲥⲟ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲛⲁ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲡⲥⲏⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲱⲣϥ ⲡⲉ ⲧⲟⲗⲟⲓⲡⲟⲛ ϩⲓⲛⲁ ⲛⲏ ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛⲧⲟⲩ ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲥⲉⲉⲣ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛ ⲛⲏ ⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛⲧⲱⲟⲩ.
30 àwọn tí ń sọkún, bí ẹni pé wọn kò sọkún rí, àti àwọn tí ń yọ̀ bí ẹni pé wọn kò yọ̀ rí, àti àwọn tí ń rà bí ẹni pé wọn kò ní rí,
ⲗ̅ⲛⲏ ⲉⲧⲣⲓⲙⲓ ϩⲱⲥ ⳿ⲛⲥⲉⲣⲓⲙⲓ ⲁⲛ ⲛⲏ ⲉⲧⲣⲁϣⲓ ϩⲱⲥ ⳿ⲛⲥⲉⲣⲁϣⲓ ⲁⲛ ⲛⲏ ⲉⲧϣⲱⲡ ϩⲱⲥ ⳿ⲛⲥⲉ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⲁⲛ.
31 àti àwọn tó ń lo ohun ayé yìí, bí ẹni tí kò ṣe àṣejù nínú wọn: nítorí ìgbà ayé yìí ń kọjá lọ.
ⲗ̅ⲁ̅ⲛⲏ ⲉⲧⲉⲣ⳿ⲭⲣⲁⲥⲑⲉ ⳿ⲙⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ϩⲱⲥ ⳿ⲛⲥⲉⲉⲣⲕⲁⲧⲁ⳿ⲭⲣⲁⲥⲑⲉ ⲁⲛ ⳿ϥⲛⲁⲥⲓⲛⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓ⳿ⲥⲭⲏⲙⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ.
32 Nínú gbogbo nǹkan tí ẹ bá ń ṣe ni mo tí fẹ́ kí ẹ sọ ara yín di òmìnira lọ́wọ́ àníyàn. Ọkùnrin tí kò ní ìyàwó le lo àkókò rẹ̀ láti fi ṣiṣẹ́ fún Olúwa, yóò sì má ronú bí ó ti ṣe le tẹ́ Olúwa lọ́rùn.
ⲗ̅ⲃ̅ϯⲟⲩⲉϣ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲇⲉ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲧⲣⲱⲟⲩϣ ⲫⲏ ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲉϥϭⲓ ⲁϥϥⲓⲣⲱⲟⲩϣ ϧⲁ ⲛⲁ Ⲡ⳪ ϫⲉ ⲡⲱⲥ ⳿ϥⲣⲁⲛⲁϥ ⳿ⲙⲠ⳪.
33 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ó bá tí ṣe ìgbéyàwó kò le ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí ó ní láti ronú àwọn nǹkan rẹ̀ nínú ayé yìí àti bí ó ti ṣe le tẹ́ aya rẹ̀ lọ́rùn,
ⲗ̅ⲅ̅ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲁϥϭⲓ ⲁϥϥⲓⲣⲱⲟⲩϣ ϧⲁ ⲛⲁ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲡⲱⲥ ⳿ϥⲛⲁⲣⲁⲛⲁⲥ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ.
34 dájúdájú, ìfẹ́ rẹ̀ pín sí ọ̀nà méjì. Bákan náà ló rí fún obìnrin tí a gbé ní ìyàwó àti wúńdíá. Obìnrin tí kò bá tí ì délé ọkọ a máa tọ́jú ohun tí ṣe ti Olúwa, kí òun lè jẹ́ mímọ́ ní ara àti ní ẹ̀mí. Ṣùgbọ́n ọmọbìnrin tí a bá ti gbé níyàwó, a máa ṣe ìtọ́jú ohun tí ṣe ti ayé, bí yóò ti ṣe le tẹ́ ọkọ rẹ̀ lọ́rùn.
ⲗ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥⲫⲏϣ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲉⲧⲁⲥϭⲓ ⲛⲉⲙ ϯⲡⲁⲣⲑⲉⲛⲟⲥ ⲑⲏ ⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲥϭⲓ ⲁⲥϥⲓⲣⲱⲟⲩϣ ϧⲁ ⲛⲁ Ⲡ⳪ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲥϣⲱⲡⲓ ⲉⲥⲟⲩⲁⲃ ϧⲉⲛ ⲡⲉⲥⲥⲱⲙⲁ ⲛⲉⲙ ⲡⲉⲥⲡⲛ̅ⲁ̅ ⲑⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲁⲥϭⲓ ⲁⲥϥⲓⲣⲱⲟⲩϣ ϧⲁ ⲛⲁ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲡⲱⲥ ⳿ⲥⲛⲁⲣⲁⲛⲁϥ ⳿ⲙⲡⲉⲥϩⲁⲓ.
35 Mo ń sọ èyí fún àǹfààní ara yín kì í ṣe láti dá yín lẹ́kun ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin lè gbé ní ọ̀nà tí ó tọ́ kí ẹ sì lè máa sin Olúwa láìsí ìyapa ọkàn.
ⲗ̅ⲉ̅ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲉⲧⲉⲣⲛⲟϥⲣⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲟⲩⲭⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛⲟⲩϩⲁϫⲓ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲁⲗⲗⲁ ϫⲉ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲧⲉⲛ⳿ⲥⲭⲏⲙⲁ ϣⲱⲡⲓ ⲉϥⲥⲟⲩⲃⲏⲧ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲙⲧⲟⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲠ⳪ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲉⲧ ⲁⲧϭⲓ⳿ϩⲣⲁϥ.
36 Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá rò pé òun kò ṣe ohun tí ó yẹ sí wúńdíá rẹ̀ ti ìpòùngbẹ rẹ si pọ si, bí ó bá sí tọ́ bẹ́ẹ̀, jẹ́ kí ó ṣe bí ó tí fẹ́, òun kò dẹ́ṣẹ̀, jẹ́ kí wọn gbé ìyàwó.
ⲗ̅ⲋ̅ⲓⲥϫⲉ ⲇⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲁⲓ ⲙⲉⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉϭⲓϣⲓⲡⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲧⲉϥⲡⲁⲣⲑⲉⲛⲟⲥ ⲉϣⲱⲡ ⲁϥϣⲁⲛⲉⲣⲁⲕⲙⲏ ⳿ⲛϩⲟⲩⲟ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲁⲓ ⲡⲉⲧⲉ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥϣⲱⲡⲓ ⲡⲉⲧⲉϩⲛⲁϥ ⲙⲁⲣⲉϥⲁⲓϥ ⳿ⲛ⳿ϥⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ⲁⲛ ⲙⲁⲣⲟⲩϭ ⲓ.
37 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó dúró ṣinṣin ni ọkàn rẹ̀, tí kò ní àìgbọdọ̀ má ṣe, ṣùgbọ́n tí ó ní agbára lórí ìfẹ́ ara rẹ̀, tí ó sì ti pinnu ní ọkàn rẹ̀ pé, òun ó pa wúńdíá ọmọbìnrin òun mọ́, yóò ṣe rere.
ⲗ̅ⲍ̅ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲧ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ϧⲉⲛ ⲡⲉϥϩⲏⲧ ⲉϥⲧⲁϫⲣⲏⲟⲩⲧ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ⲁⲛⲁⲅⲕⲏ ⲧⲟⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲟⲩⲟⲛⲧⲉϥ ⲉⲣϣⲓϣⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲉⲧⲉϩⲛⲁϥ ⳿ⲙⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲁⲓ ⲁϥϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲙⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϧⲉⲛ ⲡⲉϥϩⲏⲧ ⳿ⲉⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲧⲉϥⲡⲁⲣⲑⲉⲛⲟⲥ ⲕⲁⲗⲱⲥ ⳿ϥⲛⲁⲁⲓⲥ.
38 Bẹ́ẹ̀ sì ní ẹni tí ó fi wúńdíá ọmọbìnrin fún ni ní ìgbéyàwó, ó ṣe rere; ṣùgbọ́n ẹni tí kò fi fún ni ní ìgbéyàwó ṣe rere jùlọ.
ⲗ̅ⲏ̅ϩⲱⲥⲧⲉ ⲫⲏⲉⲧϯ ⳿ⲛⲧⲉϥⲡⲁⲣⲑⲉⲛⲟⲥ ⲉⲩⲅⲁⲙⲟⲥ ⲕⲁⲗⲱⲥ ⳿ϥⲣⲁ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏ ⲉⲧⲉ⳿ⲛ⳿ϥϯ ⳿ⲛⲑⲱϥ ⲁⲛ ⲟⲩϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲕⲁⲗⲱⲥ ⲡⲉⲧⲉ⳿ϥⲛⲁⲁⲓϥ.
39 A fi òfin dé obìnrin níwọ̀n ìgbà tí òun pẹ̀lú ọkọ rẹ̀ wà láààyè, bí ọkọ rẹ̀ bá kú, ó ní òmìnira láti ṣe ìgbéyàwó pẹ̀lú ọkùnrin mìíràn, tí ó bá wù ú ó sì gbọdọ̀ jẹ́ ti Olúwa.
ⲗ̅ⲑ̅ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲉⲥ ⲥⲱⲛϩ ⳿ⲉⲡⲉⲥϩⲁⲓ ⳿ⲉⲫⲟⲥⲟⲛ ⳿ⲭⲣⲟⲛⲟⲛ ⲉϥⲟⲛϧ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲥϩⲁⲓ ⲉϣⲱⲡ ⲇⲉ ⲁϥϣⲁⲛⲉⲛⲕⲟⲧ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲥϩⲁⲓ ⲟⲩⲣⲉⲙϩⲏ ⲧⲉ ⳿ⲉϭⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉϩⲛⲁⲥ ⲙⲟⲛⲟⲛ ϧⲉⲛ Ⲡ⳪.
40 Ṣùgbọ́n nínú èrò tèmi obìnrin náà yóò ní ayọ̀ púpọ̀, tí kò bá ṣe ìgbéyàwó mìíràn mọ́. Mo sì rò pé mo ń fún un yín ní ìmọ̀ràn láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Ọlọ́run nígbà tí mo ń sọ nǹkan wọ̀nyí.
ⲙ̅ⲱⲟⲩ⳿ⲛⲓⲁⲧⲥ ⲇⲉ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲁⲥϣⲁⲛⲟϩⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲕⲁⲧⲁ ⲧⲁ⳿ⲅⲛⲱⲙⲏ ϯⲙⲉⲩ⳿ⲓ ⲇⲉ ϩⲱ ϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲡⲛ̅ⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧ.

< 1 Corinthians 7 >