< 1 Corinthians 6 >
1 Bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá ni èdè-àìyedè sí ẹnìkejì rẹ̀, ó ha gbọdọ̀ lọ pè é lẹ́jọ́ níwájú àwọn aláìṣòótọ́ bí, bí kò ṣe níwájú àwọn ènìyàn mímọ́?
ⲁ̅ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲁⲓ ⲛⲁⲉⲣⲧⲟⲗⲙⲁⲛ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛⲧⲉϥ ⲟⲩϩⲱⲃ ⲟⲩⲧⲱϥ ⲛⲉⲙ ⲡⲉϥ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲉϭⲓϩⲁⲡ ϩⲓ ⲛⲓⲣⲉϥϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⲟⲩⲟϩ ϩⲓ ⲛⲓⲁⲅⲓⲟⲥ ⲁⲛ.
2 Ṣé ẹ̀yin kò mọ̀ pé àwọn ẹni mímọ́ ni yóò ṣe ìdájọ́ ayé? Ǹjẹ́ bí ó ba ṣe ìpàṣẹ yín ni a o ti ṣe ìdájọ́ ayé, kín ni ìdí tí ẹ kò fi yanjú àwọn ọ̀rọ̀ kéékèèké wọ̀nyí láàrín ara yín.
ⲃ̅ϣⲁⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛⲓⲁⲅⲓⲟⲥ ⲉⲑⲛⲁϯ ϩⲁⲡ ⳿ⲉⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲓⲥϫⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲉⲩⲛⲁϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲁⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⲁⲛ ϫⲉ ⳿ⲛϩⲁⲛⲕⲟⲩϫⲓ ⳿ⲙⲙⲁ ⳿ⲛϯϩⲁⲡ.
3 Ẹ kò mọ̀ pé àwa ni a ó ṣe ìdájọ́ àwọn angẹli ní? Mélòó mélòó àwọn nǹkan tó wà nínú ayé yìí.
ⲅ̅⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲉⲛⲛⲁϯϩⲁⲡ ⳿ⲉϩⲁⲛⲁⲅⲅⲉⲗⲟⲥ ⲙⲏⲧⲓⲅⲉ ϩⲁⲛ⳿ϩⲃⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓⲃⲓⲟⲥ.
4 Nítorí náà, bí ẹ̀yin bá ni aáwọ̀ lórí ọ̀rọ̀ yìí, ǹjẹ́ ẹ ó yàn láti gba ìdájọ́ lọ́dọ̀ àwọn tí ìgbé ayé wọn ń di gígàn nínú ìjọ.
ⲇ̅ⲉϣⲱⲡ ⲙⲉⲛ ⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛⲧⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛϩⲁⲛⲙⲁ⳿ⲛϯϩⲁⲡ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓⲃⲓⲟⲥ ⲛⲏⲉⲧϣⲏϣ ϧⲉⲛ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓ⳿ⲁ ⲛⲁⲓ ⲙⲁ⳿ⲧϩⲉⲙⲥⲱⲟⲩ.
5 Mo sọ èyí kí ojú lè tì yín. Ṣé ó ṣe é ṣe kí a máa rín ẹnìkan láàrín yín tí ó gbọ́n níwọ̀n láti ṣe ìdájọ́ èdè-àìyedè láàrín àwọn onígbàgbọ́?
ⲉ̅ⲉⲓϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲉⲩ⳿ϫⲫⲓⲟ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛⲥⲁⲃⲉ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲉⲣⲇⲓ⳿ⲁ⳿ⲕⲣⲓⲛⲓⲛ ⲟⲩⲧⲉ ⲡⲉϥⲥⲟⲛ.
6 Ṣùgbọ́n dípò èyí, arákùnrin kan ń pe arákùnrin kejì lẹ́jọ́ sí ilé ẹjọ́ níwájú àwọn aláìgbàgbọ́.
ⲋ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲟⲩⲥⲟⲛ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲥⲟⲛ ⲉϥϭⲓϩⲁⲡ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲁⲓ ϩⲓ ⲛⲓⲁⲑⲛⲁϩϯ.
7 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àbùkù ni fún un yín pátápátá pé ẹ̀yin ń bá ara yín ṣe ẹjọ́. Kín ní ṣe tí ẹ kò kúkú gba ìyà? Kín ló dé tí ẹ kò kúkú gba ìrẹ́jẹ kí ẹ sì fi i sílẹ̀ bẹ́ẹ̀?
ⲍ̅ϩⲏⲇⲏ ⲙⲉⲛ ϩⲟⲗⲱⲥ ⲟⲩⲑⲉⲃⲓⲟ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲡⲉ ϫⲉ ⲟⲩⲟⲛⲧⲉⲧⲉⲛ ϩⲁⲡ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲟⲩⲧⲱⲧⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⲛⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲏⲟⲩ ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⲥⲉϭⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⲁⲛ ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⲥⲉϥⲱϫⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ.
8 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ń jẹ ni ní ìyà, ẹ sì ń rẹ́ ni jẹ. Ẹ̀yin si ń ṣe èyí sí àwọn arákùnrin yín.
ⲏ̅ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲉⲧϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲧϥⲱϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲁⲓ ⳿ⲛⲛⲉⲧⲉⲛ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ.
9 Ẹ̀yin kò mọ̀ pé àwọn aláìṣòótọ́ kì í yóò jogún ìjọba Ọlọ́run? Kí a máa tàn yín jẹ; kì í ṣe àwọn àgbèrè, tàbí àwọn abọ̀rìṣà, tàbí àwọn panṣágà, tàbí àwọn ọkùnrin tí ń ṣe ìṣe obìnrin tàbí àwọn ọkùnrin tí ń ba ara wọn lòpọ̀
ⲑ̅ϣⲁⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛⲓⲣⲉϥϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲥⲉⲛⲁⲉⲣ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲥⲱⲣⲉⲙ ϫⲉ ⲟⲩⲇⲉ ⲡⲟⲣⲛⲟⲥ ⲟⲩⲇⲉ ⲣⲉϥϣⲁⲙϣⲉ ⳿ⲓⲇⲱⲗⲟⲛ ⲟⲩⲇⲉ ⲛⲱⲓⲕ ⲟⲩⲇⲉ ⲙⲁⲗⲁⲕⲟⲥ ⲟⲩⲇⲉ ⲣⲉϥⲉⲛⲕⲟⲧ ⲛⲉⲙ ϩⲱⲟⲩⲧ.
10 tàbí àwọn olè, tàbí àwọn wọ̀bìà, tàbí àwọn ọ̀mùtí, tàbí àwọn apẹ̀gàn, tàbí àwọn alọ́nilọ́wọ́gbà ni yóò jogún ìjọba Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲟⲩⲇⲉ ⲣⲉϥϭⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⲟⲩⲇⲉ ⲣⲉϥϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⲟⲩⲇⲉ ⲣⲉϥⲑⲓϧⲓ ⲟⲩⲇⲉ ⲣⲉϥϯϣⲱϣ ⲟⲩⲇⲉ ⲣⲉϥϩⲱⲗⲉⲙ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲥⲉⲛⲁⲉⲣ⳿ⲕⲗⲏ ⲣⲟⲛⲟⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲁⲛ.
11 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹlòmíràn nínú yín sì tí jẹ́ rí; ṣùgbọ́n a ti sọ yín di mímọ́, ṣùgbọ́n a ti dá yín láre ni orúkọ Jesu Kristi Olúwa, àti nípa Ẹ̀mí Mímọ́ Ọlọ́run wa.
ⲓ̅ⲁ̅ⲕⲉ ⲧⲁⲩⲧⲁ ⲛⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⲡⲉ ⲁⲗⲗⲁ ⲁⲩϫⲉⲕⲉⲙ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲁⲗⲗⲁ ⲁⲩⲧⲟⲩⲃⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲁⲗⲗⲁ ⲁⲩ⳿ⲑⲙⲁⲓ⳿ⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲛⲉⲙ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡⲛ̅ⲁ̅ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲛⲛⲟⲩϯ.
12 “Ohun gbogbo ní ó tọ́ fún mi,” ṣùgbọ́n kì í ṣe ohun gbogbo ni ó ní èrè. “Ohun gbogbo ni ó yẹ fún mi,” ṣùgbọ́n èmi kì yóò jẹ́ kí ohunkóhun ṣe olórí fun mi.
ⲓ̅ⲃ̅⳿ⲉⲝⲉⲥⲧⲓⲛ ⲛⲏⲓ ⳿ⲉⲉⲣϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⲥⲉⲉⲣⲛⲟϥⲣⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲁⲛ ⲉⲝⲉⲥⲧⲓⲛ ⲛⲏⲓ ⳿ⲉⲉⲣϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲛⲛⲉ⳿ϣ ⳿ϩⲗⲓ ⲓⲣⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲉⲣϣⲓϣⲓ.
13 “Oúnjẹ fún inú àti inú fún oúnjẹ,” ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò fi òpin sí méjèèjì, ara kì í ṣe fún ìwà àgbèrè ṣíṣe, ṣùgbọ́n fún Olúwa, àti Olúwa fún ara náà.
ⲓ̅ⲅ̅ⲛⲓ⳿ϧⲣⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲁⲩⲭⲏ ⳿ⲛϯⲛⲉϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ϯⲛⲉϫⲓ ⳿ⲛⲛⲓ⳿ϧⲣⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲑⲁⲓ ⲇⲉ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲕⲉⲭⲱⲟⲩⲛⲓ ⲫϯ ⲛⲁⲕⲟⲣϥⲟⲩ ⲡⲓⲥⲱⲙⲁ ⲇⲉ ⲛⲁϥⲭⲏ ⳿ⲛϯ ⲡⲟⲣⲛⲓⲁ ⲁⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲙⲠ⳪ ⲟⲩⲟϩ Ⲡ⳪ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲱⲙⲁ.
14 Nínú agbára rẹ̀, Ọlọ́run jí Olúwa dìde kúrò nínú òkú bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni yóò jí àwa náà dìde.
ⲓ̅ⲇ̅ⲫϯ ⲇⲉ ⲁϥⲧⲟⲩⲛⲟⲥ ⲡⲉⲛ⳪ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ϩⲱⲛ ⲉϥ⳿ⲉⲧⲟⲩⲛⲟⲥⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲧⲉϥϫⲟⲙ.
15 Ṣé ẹ kò tilẹ̀ mọ̀ pé ara yín gan an jẹ́ ẹ̀yà ara Kristi fún ara rẹ̀? Ǹjẹ́ tí ó ba jẹ́ bẹ́ẹ̀, ǹjẹ́ ó yẹ kí ń mú ẹ̀yà ara Kristi kí ń fi ṣe ẹ̀yà ara àgbèrè bí? Kí a má rí i!
ⲓ̅ⲉ̅⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲙⲁ ϩⲁⲛⲙⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲛⲉ ⳿ⲛⲧⲁⲱⲗⲓ ⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲛⲓⲙⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲛⲧⲁⲁⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲉⲗⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲟⲣⲛⲏ ⳿ⲛⲛⲉⲥϣⲱⲡⲓ.
16 Tàbí ẹ kò mọ̀ pé bí ẹnìkan bá so ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ àgbèrè ó jẹ́ ara kan pẹ̀lú rẹ̀? Nítorí a tí kọ ọ́ wí pé, “Àwọn méjèèjì yóò sì di ara kan.”
ⲓ̅ⲋ̅ϣⲁⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲫⲏ ⲉⲧⲧⲱⲙⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉϯⲡⲟⲣⲛⲏ ⲟⲩⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⲡⲉ ⲉⲩ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⲅⲁⲣ ⲡⲉϫⲁϥ ⳿ⲙⲡⲃ̅ ⲉⲩⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ.
17 Ṣùgbọ́n ẹni ti ó dàpọ̀ mọ́ Olúwa di ẹ̀mí kan náà pẹ̀lú rẹ̀.
ⲓ̅ⲍ̅ⲫⲏⲇⲉ ⲉⲧⲧⲱⲙⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲠ⳪ ⲟⲩⲡⲛ̅ⲁ̅ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⲡⲉ.
18 Ẹ máa sá fún àgbèrè. Gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ènìyàn ń dá wà lóde ara, ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè ń ṣe sí ara òun tìkára rẹ̀.
ⲓ̅ⲏ̅ⲫⲱⲧ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲛϯⲡⲟⲣⲛⲓⲁ ⲛⲟⲃⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲉ ⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⲛⲁⲁⲓϥ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲱⲙⲁ ⲫⲏ ⲇⲉ ⲉⲧⲉⲣⲡⲟⲣⲛⲉⲩⲓⲛ ⲁϥⲉⲣⲛⲟⲃⲓ ⳿ⲉⲡⲉϥⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲙⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
19 Tàbí, ẹ̀yin kò mọ̀ pé ara yín ni tẹmpili Ẹ̀mí Mímọ́, ti ń bẹ nínú yín, ti ẹ̀yin ti gbà lọ́wọ́ Ọlọ́run? Ẹ̀yin kì í ṣe ti ara yín,
ⲓ̅ⲑ̅ϣⲁⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲙⲁ ⲟⲩⲉⲣⲫⲉⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲡⲛ̅ⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⲡⲉ ⲫⲏ ⲉⲧϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲫⲏ ⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛϭⲓⲧϥ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲫϯ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲫⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ.
20 nítorí a ti rà yín ni iye kan. Nítorí náà ẹ yìn Ọlọ́run lógo nínú ara yín, àti nínú ẹ̀mí yín, tì í ṣe ti Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲁⲩϣⲉⲡ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲁ ⲟⲩⲧⲓⲙⲏ ⲙⲁⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲫϯ ϧⲉⲛ ⲛⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲙⲁ.