< 1 Corinthians 2 >

1 Nígbà tí èmí tọ̀ yín wá, ẹ̀yin ará, kì í ṣe nípa ọ̀rọ̀ gíga àti ọgbọ́n gíga ni mo fi bá yín sọ̀rọ̀, nígbà tí èmi ń sọ̀rọ̀ ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run fún un yín.
A ja gdym przyszedł do was, bracia! nie przyszedłem z wyniosłością mowy albo mądrości, opowiadając wam świadectwo Boże.
2 Èmi ti pinnu láti má mọ ohunkóhun nígbà ti mo wà láàrín yín bí kò ṣe Jesu Kristi, ẹni tí a kàn mọ́ àgbélébùú.
Albowiem nie osądziłem za rzecz potrzebną, co inszego umieć między wami, tylko Jezusa Chrystusa, i to onego ukrzyżowanego.
3 Èmi sì tọ̀ yín wá ni àìlera, àti ní ẹ̀rù, àti ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwárìrì.
I byłem ja u was w słabości i w bojaźni i w strachu wielkim,
4 Ìwàásù mi àti ẹ̀kọ́ mi, kì í ṣe nípa ọgbọ́n ènìyàn àti ọ̀rọ̀ tí a fi ń yí ènìyàn lọ́kàn padà, bí kò ṣe nípa ìfihàn agbára Ẹ̀mí.
A mowa moja i kazanie moje nie było w powabnych mądrości ludzkiej słowach, ale w okazaniu ducha i mocy,
5 Kí ìgbàgbọ́ yín kí ó má ṣe dúró lórí ọgbọ́n ènìyàn, ṣùgbọ́n kí ó dúró lórí agbára Ọlọ́run.
Aby się wiara wasza nie gruntowała na mądrości ludzkiej, ale na mocy Bożej.
6 Ṣùgbọ́n àwa ń sọ̀rọ̀ ọgbọ́n láàrín àwọn tí a pè, ṣùgbọ́n kì í ṣe ọgbọ́n ti ayé yìí tàbí ti àwọn olórí ayé yìí, èyí tí yóò di asán. (aiōn g165)
A mądrość mówimy między doskonałymi; ale mądrość nie tego świata, ani książąt tego świata, którzy giną; (aiōn g165)
7 Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa ń sọ̀rọ̀ ọgbọ́n ti Ọlọ́run tó fi ara sin, ọgbọ́n tí ó ti fi ara pamọ́, èyí tí Ọlọ́run ti lànà sílẹ̀ ṣáájú ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé fún ògo wa. (aiōn g165)
Ale mówimy mądrość Bożą w tajemnicy, która jest zakryta, którą Bóg przeznaczył przed wieki ku chwale naszej, (aiōn g165)
8 Èyí ti ẹnikẹ́ni nínú àwọn aláṣẹ ayé yìí kò mọ̀. Ìbá ṣe pé wọ́n mọ̀ ọ́n, wọn kì bá tún kan Olúwa ògo mọ́ àgbélébùú. (aiōn g165)
Której żaden z książąt tego świata nie poznał; bo gdyby byli poznali, nigdy by Pana chwały nie ukrzyżowali; (aiōn g165)
9 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Ojú kò tí ì rí, etí kò tí í gbọ́, kò sì ọkàn ènìyàn tí ó tí í mọ̀ ohun tí Ọlọ́run tí pèsè sílẹ̀ fún àwọn tí o fẹ́ ẹ.”
Ale opowiadamy, jako napisano: Czego oko nie widziało i ucho nie słyszało i na serce ludzkie nie wstąpiło, co nagotował Bóg tym, którzy go miłują.
10 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fi í hàn fún wa nípasẹ̀ Ẹ̀mí rẹ̀. Ẹ̀mí á máa wádìí ohun gbogbo, kódà àwọn àṣírí Ọlọ́run tó jinlẹ̀ jùlọ.
Ale nam to Bóg objawił przez Ducha swojego; albowiem duch wszystkiego się bada, i głębokości Bożych.
11 Ta ni nínú ènìyàn tí ó mọ èrò ọkàn ènìyàn kan, bí kò ṣe ẹ̀mí ènìyàn tí ó wà nínú rẹ̀? Bákan náà, kò sí ẹni ti ó mọ àwọn èrò Ọlọ́run, bí kò ṣe Ẹ̀mí Ọlọ́run fúnra rẹ̀.
Bo któż z ludzi wie, co jest w człowieku, tylko duch człowieczy, który w nim jest? Także też i tego, co jest w Bogu, nikt nie wie, tylko Duch Boży.
12 Àwa kò gbà ẹ̀mí ti ayé yìí, bí kò ṣe Ẹ̀mí ẹni tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wa, kí a lè ní òye ohun tí Ọlọ́run fi fún wa lọ́fẹ̀ẹ́.
Aleśmy my nie przyjęli ducha świata, lecz Ducha, który jest z Boga, abyśmy wiedzieli, które rzeczy nam są od Boga darowane;
13 Èyí ni àwa ń wí, kì í ṣe èyí tí a ń kọ nípa ọ̀rọ̀ ọgbọ́n ènìyàn, ṣùgbọ́n èyí tí Ẹ̀mí Mímọ́ fi ń kọ ènìyàn, èyí tí a ń fi ohun Ẹ̀mí wé ohun Ẹ̀mí.
O których też mówimy, nie temi słowy, których ludzka mądrość naucza, ale których Duch Święty naucza, do duchownych rzeczy duchowne stosując.
14 Ṣùgbọ́n ènìyàn nípa ti ara kò gba ohun ti Ẹ̀mí Ọlọ́run wọ̀n-ọn-nì, nítorí pé wèrè ni wọ́n jásí fún un, òun kò sì le mọ̀ wọ́n, nítorí nípa tí Ẹ̀mí ní a fi ń wádìí wọn.
Ale cielesny człowiek nie pojmuje tych rzeczy, które są Ducha Bożego; albowiem mu są głupstwem i nie może ich poznać, przeto iż duchownie bywają rozsądzone.
15 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó wà nípa ti ẹ̀mí ń wádìí ohun gbogbo, ṣùgbọ́n kò sí ẹnikẹ́ni tí í wádìí rẹ̀.
Aleć duchowny rozsądza wszystko; lecz sam od nikogo nie bywa rozsądzony.
16 “Nítorí ta ni ó mọ ọkàn Olúwa, ti yóò fi máa kọ́ Ọ?” Ṣùgbọ́n àwa ní inú Kristi.
Albowiem któż poznał zmysł Pański? Któż go będzie uczył? Ale my zmysł Chrystusowy mamy.

< 1 Corinthians 2 >