< 1 Corinthians 2 >

1 Nígbà tí èmí tọ̀ yín wá, ẹ̀yin ará, kì í ṣe nípa ọ̀rọ̀ gíga àti ọgbọ́n gíga ni mo fi bá yín sọ̀rọ̀, nígbà tí èmi ń sọ̀rọ̀ ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run fún un yín.
ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲚⲞⲔ ϨⲰ ⲈⲦⲀⲒⲒ ϨⲀⲢⲰⲦⲈⲚ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲚⲈⲦⲀⲒⲒ ⲀⲚ ⲔⲀⲦⲀ ⲞⲨϬⲒⲤⲒ ⲚⲦⲈⲞⲨⲤⲀϪⲒ ⲒⲈ ⲞⲨⲤⲞⲪⲒⲀ ⲀⲒⲦⲀⲘⲞ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲈⲠⲒⲘⲨⲤⲦⲎⲢⲒⲞⲚ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
2 Èmi ti pinnu láti má mọ ohunkóhun nígbà ti mo wà láàrín yín bí kò ṣe Jesu Kristi, ẹni tí a kàn mọ́ àgbélébùú.
ⲃ̅ⲘⲠⲒϮϨⲀⲠ ⲄⲀⲢ ⲈⲈⲘⲒ ⲈϨⲖⲒ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲪⲀⲒ ⲀⲨⲀϢϤ.
3 Èmi sì tọ̀ yín wá ni àìlera, àti ní ẹ̀rù, àti ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwárìrì.
ⲅ̅ⲀⲚⲞⲔ ϨⲰ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲈⲦⲀⲤⲐⲈⲚⲎⲤ ⲚⲈⲘ ⲞⲨϨⲞϮ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲤⲐⲈⲢⲦⲈⲢ ⲈⲚⲀϢⲰϤ ⲀⲒⲒ ϨⲀⲢⲰⲦⲈⲚ.
4 Ìwàásù mi àti ẹ̀kọ́ mi, kì í ṣe nípa ọgbọ́n ènìyàn àti ọ̀rọ̀ tí a fi ń yí ènìyàn lọ́kàn padà, bí kò ṣe nípa ìfihàn agbára Ẹ̀mí.
ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲀⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘ ⲠⲀϨⲒⲰⲒϢ ⲚⲀϤϦⲈⲚ ϨⲀⲚⲐⲰⲦ ⲚϨⲎⲦ ⲀⲚ ⲚⲦⲈϨⲀⲚⲤⲀϪⲒ ⲚⲤⲞⲪⲒⲀ ⲚⲢⲰⲘⲒ ⲀⲖⲖⲀ ϦⲈⲚⲞⲨⲰⲚϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲦⲈⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲈⲘ ⲞⲨϪⲞⲘ.
5 Kí ìgbàgbọ́ yín kí ó má ṣe dúró lórí ọgbọ́n ènìyàn, ṣùgbọ́n kí ó dúró lórí agbára Ọlọ́run.
ⲉ̅ϨⲒⲚⲀ ⲠⲈⲦⲈⲚⲚⲀϨϮ ⲚⲦⲈϤϢⲦⲈⲘϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲞⲪⲒⲀ ⲚⲢⲰⲘⲒ ⲀⲖⲖⲀ ϦⲈⲚⲞⲨϪⲞⲘ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
6 Ṣùgbọ́n àwa ń sọ̀rọ̀ ọgbọ́n láàrín àwọn tí a pè, ṣùgbọ́n kì í ṣe ọgbọ́n ti ayé yìí tàbí ti àwọn olórí ayé yìí, èyí tí yóò di asán. (aiōn g165)
ⲋ̅ⲞⲨⲤⲞⲪⲒⲀ ⲆⲈ ⲠⲈⲦⲈⲚⲤⲀϪⲒ ⲘⲘⲞⲤ ϦⲈⲚⲚⲎ ⲈⲦϪⲎⲔ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲤⲞⲪⲒⲀ ⲆⲈ ⲚⲐⲀ ⲠⲀⲒⲈⲚⲈϨ ⲀⲚ ⲦⲈ ⲞⲨⲆⲈ ⲚⲐⲀ ⲚⲒⲀⲢⲬⲰⲚ ⲀⲚ ⲚⲦⲈⲠⲀⲒⲈⲚⲈϨ ⲚⲀⲒ ⲈⲐⲚⲀⲔⲰⲢϤ. (aiōn g165)
7 Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa ń sọ̀rọ̀ ọgbọ́n ti Ọlọ́run tó fi ara sin, ọgbọ́n tí ó ti fi ara pamọ́, èyí tí Ọlọ́run ti lànà sílẹ̀ ṣáájú ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé fún ògo wa. (aiōn g165)
ⲍ̅ⲀⲖⲖⲀ ⲞⲨⲤⲞⲪⲒⲀ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲦⲈⲚⲤⲀϪⲒ ⲘⲘⲞⲤ ϦⲈⲚⲞⲨⲘⲨⲤⲦⲎⲢⲒⲞⲚ ⲐⲎ ⲈⲦϨⲎⲠ ⲐⲎ ⲈⲦⲀϤⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲚⲐⲀϢⲤ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ϦⲀϪⲰⲞⲨ ⲚⲚⲒⲈⲚⲈϨ ⲈⲨⲰⲞⲨ ⲚⲀⲚ. (aiōn g165)
8 Èyí ti ẹnikẹ́ni nínú àwọn aláṣẹ ayé yìí kò mọ̀. Ìbá ṣe pé wọ́n mọ̀ ọ́n, wọn kì bá tún kan Olúwa ògo mọ́ àgbélébùú. (aiōn g165)
ⲏ̅ⲐⲎ ⲈⲦⲈ ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ⲚⲚⲒⲀⲢⲬⲰⲚ ⲚⲦⲈⲠⲀⲒⲈⲚⲈϨ ⲤⲞⲨⲰⲚⲤ ⲈⲚⲈⲀⲨⲤⲞⲨⲰⲚⲤ ⲄⲀⲢ ⲚⲀⲨⲚⲀⲈϢ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲚⲦⲈⲠⲰⲞⲨ ⲀⲚ ⲠⲈ. (aiōn g165)
9 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Ojú kò tí ì rí, etí kò tí í gbọ́, kò sì ọkàn ènìyàn tí ó tí í mọ̀ ohun tí Ọlọ́run tí pèsè sílẹ̀ fún àwọn tí o fẹ́ ẹ.”
ⲑ̅ⲀⲖⲖⲀ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲤϦⲎⲞⲨⲦ ϪⲈ ⲚⲎ ⲈⲦⲈ ⲘⲠⲈ ⲂⲀⲖ ⲚⲀⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲆⲈ ⲘⲠⲈ ⲘⲀϢϪ ⲤⲞⲐⲘⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲞⲨϢⲈ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲠϨⲎⲦ ⲚⲢⲰⲘⲒ ⲚⲎ ⲈⲦⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲤⲈⲂⲦⲰⲦⲞⲨ ⲚⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀⲘⲈⲚⲢⲒⲦϤ.
10 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fi í hàn fún wa nípasẹ̀ Ẹ̀mí rẹ̀. Ẹ̀mí á máa wádìí ohun gbogbo, kódà àwọn àṣírí Ọlọ́run tó jinlẹ̀ jùlọ.
ⲓ̅ⲀⲚⲞⲚ ⲆⲈ ⲀϤϬⲞⲢⲠⲞⲨ ⲚⲀⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲄⲀⲢ ϤϦⲞⲦϦⲈⲦ ⲚⲈⲚⲬⲀⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲦϢⲎⲔ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
11 Ta ni nínú ènìyàn tí ó mọ èrò ọkàn ènìyàn kan, bí kò ṣe ẹ̀mí ènìyàn tí ó wà nínú rẹ̀? Bákan náà, kò sí ẹni ti ó mọ àwọn èrò Ọlọ́run, bí kò ṣe Ẹ̀mí Ọlọ́run fúnra rẹ̀.
ⲓ̅ⲁ̅ⲚⲒⲘ ⲄⲀⲢ ϦⲈⲚⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲈⲦⲤⲰⲞⲨⲚ ⲚⲚⲀ ⲠⲒⲢⲰⲘⲒ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲦⲈⲠⲒⲢⲰⲘⲒ ⲈⲦϢⲞⲠ ⲚϦⲎⲦϤ ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲞⲚ ⲚⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲘⲠⲈ ϨⲖⲒ ⲈⲘⲒ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
12 Àwa kò gbà ẹ̀mí ti ayé yìí, bí kò ṣe Ẹ̀mí ẹni tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wa, kí a lè ní òye ohun tí Ọlọ́run fi fún wa lọ́fẹ̀ẹ́.
ⲓ̅ⲃ̅ⲀⲚⲞⲚ ⲆⲈ ⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲦⲈⲠⲀⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲀⲚ ⲠⲈⲦⲀⲚϬⲒⲦϤ ⲀⲖⲖⲀ ⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲠⲒⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲚⲞⲨϮ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲚⲈⲘⲒ ⲈⲚⲎ ⲈⲦⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲦⲎⲒⲦⲞⲨ ⲚⲀⲚ ⲚϨⲘⲞⲦ.
13 Èyí ni àwa ń wí, kì í ṣe èyí tí a ń kọ nípa ọ̀rọ̀ ọgbọ́n ènìyàn, ṣùgbọ́n èyí tí Ẹ̀mí Mímọ́ fi ń kọ ènìyàn, èyí tí a ń fi ohun Ẹ̀mí wé ohun Ẹ̀mí.
ⲓ̅ⲅ̅ⲈⲦⲈ ⲚⲀⲒ ⲚⲈⲈⲦⲈⲚⲤⲀϪⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲘⲈⲦⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲚⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲀⲚ ⲚⲦⲈϨⲀⲚⲤⲀϪⲒ ⲚⲤⲞⲪⲒⲀ ⲀⲖⲖⲀ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲘⲈⲦⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ ⲚⲦⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈⲚⲈⲢⲤⲨⲚⲔⲢⲒⲚⲒⲚ ⲚϨⲀⲚⲠⲚⲀⲦⲒⲔⲞⲚ ⲚⲚⲒⲠⲚⲀⲦⲒⲔⲞⲤ.
14 Ṣùgbọ́n ènìyàn nípa ti ara kò gba ohun ti Ẹ̀mí Ọlọ́run wọ̀n-ọn-nì, nítorí pé wèrè ni wọ́n jásí fún un, òun kò sì le mọ̀ wọ́n, nítorí nípa tí Ẹ̀mí ní a fi ń wádìí wọn.
ⲓ̅ⲇ̅ⲠⲒⲮⲨⲬⲒⲔⲞⲤ ⲆⲈ ⲚⲢⲰⲘⲒ ⲘⲠⲀϤϢⲈⲠ ⲚⲀ ⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲢⲞϤ ⲞⲨⲘⲈⲦⲤⲞϪ ⲄⲀⲢ ⲚⲀϤ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲘⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲘⲘⲞϤ ⲈⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲀⲨϦⲞⲦϦⲈⲦ ⲘⲘⲞϤ ⲠⲚⲀⲦⲒⲔⲞⲤ.
15 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó wà nípa ti ẹ̀mí ń wádìí ohun gbogbo, ṣùgbọ́n kò sí ẹnikẹ́ni tí í wádìí rẹ̀.
ⲓ̅ⲉ̅ⲠⲒⲠⲚⲀⲦⲒⲔⲰⲤ ⲆⲈ ⲚⲐⲞϤ ϢⲀϤϦⲈⲦϦⲈⲦ ⲚⲈⲚⲬⲀⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲘⲠⲀⲢⲈ ϨⲖⲒ ϢϦⲈⲦϦⲰⲦϤ.
16 “Nítorí ta ni ó mọ ọkàn Olúwa, ti yóò fi máa kọ́ Ọ?” Ṣùgbọ́n àwa ní inú Kristi.
ⲓ̅ⲋ̅ⲚⲒⲘ ⲄⲀⲢ ⲠⲈⲦⲀϤⲈⲘⲒ ⲈⲠϨⲎⲦ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲈⲘⲘⲞⲚ ⲚⲒⲘ ⲈⲐⲚⲀϢⲦⲤⲀⲂⲞϤ ⲀⲚⲞⲚ ⲆⲈ ⲠϨⲎⲦ ⲘⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲠⲈⲦⲈⲘⲘⲞⲚ.

< 1 Corinthians 2 >