< 1 Corinthians 15 >
1 Ǹjẹ́ ará, èmi ń sọ ìyìnrere náà dí mí mọ̀ fún un yín, tí mo ti wàásù fún un yín, èyí tí ẹ̀yin pẹ̀lú ti gbá, nínú èyí tí ẹ̀yin sì dúró.
Przyjaciele, chciałbym wam teraz przypomnieć dobrą nowinę, którą przekazałem wam, którą przyjęliście, której jesteście wierni,
2 Nípasẹ̀ ìyìnrere yìí ni a fi ń gbà yín là pẹ̀lú, bí ẹ̀yin bá di ọ̀rọ̀ ti mo ti wàásù fún yín mú ṣinṣin. Bí bẹ́ẹ̀ kọ̀, ẹ̀yin kàn gbàgbọ́ lásán.
i która daje wam zbawienie—o ile trzymacie się tego, co wam głosiłem. Chyba że uwierzyliście na próżno…
3 Nítorí èyí tí mo rí gbà ṣáájú ohun gbogbo ní èmi pẹ̀lú ti fi lé e yín lọ́wọ́, bí Kristi ti kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìwé mímọ́ tí wí.
Na samym początku przekazałem wam to, co sam przyjąłem, mianowicie że Chrystus umarł za nasze grzechy—zgodnie z zapowiedziami Pisma,
4 Àti pé a sìnkú rẹ̀, àti pé ó jíǹde ní ọjọ́ kẹta gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ tí wí;
że został pogrzebany, że trzeciego dnia zmartwychwstał—również zgodnie z Pismem,
5 àti pé ó farahàn Peteru, lẹ́yìn èyí, àwọn méjìlá.
i że ukazał się Piotrowi, a następnie pozostałym Dwunastu.
6 Lẹ́yìn èyí, ó farahàn àwọn ará tí o jú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta lọ lẹ́ẹ̀kan náà; ọ̀pọ̀ nínú wọn wà títí fi di ìsinsin yìí, ṣùgbọ́n àwọn díẹ̀ ti sùn.
Później widziało Go równocześnie pięciuset wierzących, z których większość jeszcze żyje—niektórzy jednak już zmarli.
7 Lẹ́yìn èyí ni ó farahan Jakọbu; lẹ́yìn náà fún gbogbo àwọn aposteli.
Potem Jezus ukazał się Jakubowi i wszystkim innym apostołom.
8 Àti níkẹyìn gbogbo wọn ó farahàn mí pẹ̀lú, bí ẹni tí a bí ṣáájú àkókò rẹ̀.
Na samym końcu, jakby najmniej godnemu, ukazał się także mnie.
9 Nítorí èmi ni ẹni tí ó kéré jùlọ nínú àwọn aposteli, èmi ẹni tí kò yẹ láti pè ní aposteli, nítorí tí mo ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run.
Jestem bowiem najmniejszym z apostołów i nie powinienem nawet używać tego tytułu, gdyż prześladowałem kościół Boga.
10 Ṣùgbọ́n nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run mo rí bí mo ti rí: oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tí a fi fún mi kò sì jẹ́ asán; ṣùgbọ́n mó ṣiṣẹ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ jú gbogbo wọn lọ, ṣùgbọ́n kì í ṣe èmi, bí kò ṣe oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí ó wà pẹ̀lú mi.
Tylko dzięki Jego łasce jestem więc tym, kim jestem—a łaska ta przyniosła owoce. Trudziłem się o wiele bardziej niż inni—oczywiście nie ja sam, zawsze bowiem Bóg wspierał mnie swoją łaską.
11 Nítorí náà ìbá à ṣe èmí tàbí àwọn ni, èyí ní àwa wàásù, èyí ní ẹ̀yin sì gbàgbọ́.
Zresztą czy ja, czy inni, i tak głosimy tę samą dobrą nowinę, w którą wy uwierzyliście.
12 Ǹjẹ́ bí a bá wàásù Kristi pé ó tí jíǹde kúrò nínú òkú, èéha tí ṣe tí àwọn mìíràn nínú yín fi wí pé, àjíǹde òkú kò sí.
Skoro więc głosimy zmartwychwstanie Chrystusa, to dlaczego niektórzy z was twierdzą, że coś takiego jak zmartwychwstanie w ogóle nie istnieje?
13 Ṣùgbọ́n bí àjíǹde òkú kò sí, ǹjẹ́ Kristi kò jíǹde.
Jeśli nie istnieje, to i Chrystus nie zmartwychwstał.
14 Bí Kristi kò bá sì jíǹde, ǹjẹ́ asán ni ìwàásù wà, asán sì ni ìgbàgbọ́ yín pẹ̀lú.
A jeśli On nie zmartwychwstał, to głoszenie dobrej nowiny nie ma sensu—i również wasza wiara jest pozbawiona podstaw.
15 Ṣùgbọ́n jù bẹ́ẹ̀ lọ, a mú wa ni ẹlẹ́rìí èké fún Ọlọ́run; nítorí ti àwa jẹ́rìí Ọlọ́run pé ó jí Kristi dìde kúrò nínú òkú: ẹni tí òun kò jí dìde bí ó bá ṣe pé àwọn òkú kò jíǹde?
W takiej sytuacji okazujemy się fałszywymi świadkami, bo twierdzimy, że Bóg ożywił z martwych Chrystusa. A nie mógł tego zrobić, skoro umarli nie zmartwychwstają.
16 Nítorí pé bi á kò bá jí àwọn òkú dìde, ǹjẹ́ a kò jí Kristi dìde,
Jeśli umarli nie mogą powstać z martwych, Chrystus też nie zmartwychwstał.
17 bí a kò bá sì jí Kristi dìde, asán ní ìgbàgbọ́ yín; ẹ̀yin wà nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín síbẹ̀.
A jeśli On nie ożył, niepotrzebnie Mu uwierzyliście i, co za tym idzie, nadal jesteście obciążeni waszymi grzechami.
18 Ǹjẹ́ àwọn pẹ̀lú tí ó sùn nínú Kristi ṣègbé.
Ci zaś wierzący, którzy już zmarli, poszli na potępienie.
19 Bí ó bá ṣe pé kìkì ayé yìí nìkan ní àwa ní ìrètí nínú Kristi, àwa jásí òtòṣì jùlọ nínú gbogbo ènìyàn.
Jeżeli nasza nadzieja w Chrystusie dotyczy tylko tego ziemskiego życia, to jesteśmy najbardziej godni pożałowania ze wszystkich ludzi.
20 Ǹjẹ́ nísinsin yìí Kristi tí jíǹde kúrò nínú òkú, ó sì dí àkọ́bí nínú àwọn tí ó sùn.
Lecz Chrystus naprawdę zmartwychwstał—jako pierwszy z umarłych!
21 Nítorí ìgbà tí ó jẹ́ pé nípa ènìyàn ní ikú ti wá, nípa ènìyàn ní àjíǹde òkú sì ti wá pẹ̀lú.
Skoro śmierć przyszła na świat z powodu człowieka—Adama, to również zmartwychwstanie przyjdzie przez Człowieka—Chrystusa.
22 Nítorí bí gbogbo ènìyàn ti kú nínú Adamu, bẹ́ẹ̀ ní a ó sì sọ gbogbo ènìyàn dí alààyè nínú Kristi.
Z powodu Adama wszyscy umierają, ale dzięki Chrystusowi wszyscy zmartwychwstaną.
23 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ènìyàn ní ipá tirẹ̀: Kristi àkọ́bí; lẹ́yìn èyí àwọn tí ó jẹ́ tí Kristi ni wíwá rẹ̀.
Każdy we właściwym czasie: najpierw powstał z martwych Chrystus, w czasie Jego powrotu ożyją natomiast ci, którzy do Niego należą.
24 Nígbà náà ni òpin yóò dé, nígbà tí ó bá ti fi ìjọba fún Ọlọ́run Baba, nígbà tí ó bá pa gbogbo àṣẹ àti gbogbo ọlá àti agbára run.
Potem nastąpi koniec i Chrystus przekaże królestwo Bogu Ojcu, a wszelkie władze i potęgi przestaną istnieć.
25 Nítorí ti òun gbọdọ̀ ti jẹ ọba kí òun to fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
Chrystus ma bowiem panować do czasu, aż wszyscy Jego przeciwnicy padną u Jego stóp.
26 Ikú ní ọ̀tá ìkẹyìn tí a ó parun.
Ostatnim pokonanym wrogiem będzie śmierć.
27 “Nítorí ó ti fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wí pé, “Ohun gbogbo ni á fi sí abẹ́ rẹ̀,” o dájú pé Ọlọ́run nìkan ṣoṣo ní kò sí ní abẹ́ rẹ̀, Òun ní ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ àkóso Kristi.
Bóg poddał bowiem wszystko władzy Chrystusa—oczywiście wszystko oprócz siebie samego, bo to On jest Tym, który poddał wszystko Chrystusowi.
28 Nígbà tí a bá sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀ tán, nígbà náà ni á ó fi ọmọ tìkára rẹ̀ pẹ̀lú sábẹ́ ẹni tí ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀, kí Ọlọ́run lè jásí ohun gbogbo nínú ohun gbogbo.
Gdy więc już wszystko zostanie poddane Synowi Bożemu, wtedy także On przekaże władzę Ojcu, który dał Mu wszystko we władanie. Odtąd Bóg będzie obecny we wszystkich i będzie panował nad wszystkim.
29 Ní báyìí, bí kò bá sí àjíǹde, kín ní ète àwọn ènìyàn tí wọn ń tẹ bọ omi nítorí òkú? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde rárá, nítorí kín ni a ṣe ń bamitiisi wọn nítorí wọn?
Co robią ci, którzy przyjmują chrzest za zmarłych? Jeśli umarli w ogóle nie powstaną do życia, to jaki jest sens tego, co robią?
30 Nítorí kín ní àwa sì ṣe ń bẹ nínú ewu ni wákàtí gbogbo?
A my? Po co ciągle narażamy się na niebezpieczeństwa?
31 Mo sọ nípa ayọ̀ tí mo ní lórí yín nínú Kristi Jesu Olúwa wá pé, èmi ń kú lójoojúmọ́.
Przyjaciele—moja dumo w Chrystusie Jezusie, naszym Panu!—wiecie przecież, że codziennie ryzykuję życie.
32 Kí a wí bí ènìyàn, bí mo bá ẹranko jà ní Efesu, àǹfààní kín ni ó jẹ́ fún mi? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde, “Ẹ jẹ́ kí a máa jẹ, kí á máa mú; nítorí ní ọlá ni àwa ó kú.”
Po co, jak niewolnik na arenie, walczyłem z dzikimi bestiami w Efezie? Jeśli umarli nie zmartwychwstają, to: „Jedzmy i pijmy, bo jutro czeka nas śmierć!”
33 Kí a má tàn yín jẹ́, “Ẹgbẹ́ búburú bá ìwà rere jẹ́.”
Nie dajcie się oszukać! „Złe towarzystwo prowadzi do rozwiązłości”.
34 Ẹ jí ìjí òdodo, kí ẹ má sì dẹ́ṣẹ̀; nítorí àwọn ẹlòmíràn kò ni imọ̀ Ọlọ́run, mo sọ èyí kí ojú ba à lè tiyín.
Opamiętajcie się i przestańcie grzeszyć! Niektórzy z was w ogóle nie znają Boga! Mówię to, aby was zawstydzić.
35 Ṣùgbọ́n ẹnìkan yóò wí pé, “Báwo ni àwọn òkú yóò ṣe jíǹde? Irú ara wó ni wọn ó padà sí?”
Ktoś może zapytać: „Jak umarli zmartwychwstaną? W jakich ciałach?”.
36 Ìwọ aláìmòye, ohun tí ìwọ fúnrúgbìn kì í yè bí kò ṣe pé ó ba kú,
Niemądry człowieku! Żeby jakaś roślina wyrosła, najpierw musi zginąć ziarno, które zostało rzucone w ziemię.
37 àti èyí tí ìwọ fúnrúgbìn, kì í ṣe ara tí ń bọ̀ ni ìwọ fúnrúgbìn, ṣùgbọ́n èso lásán ni, ìbá à ṣe alikama, tàbí irú mìíràn.
Nie siejesz przecież tego, co ma wyrosnąć, ale rzucasz w ziemię ziarno tej rośliny, na przykład pszenicy lub czegoś innego.
38 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fún ún ni ara bí o tí wù ú, àti fún olúkúlùkù irúgbìn ara tirẹ̀.
A Bóg, zgodnie ze swoją wolą, daje mu nową postać—każdemu rodzajowi ziarna inną.
39 Gbogbo ẹran-ara kì í ṣe ẹran-ara kan náà, ṣùgbọ́n ọ̀tọ̀ ni ẹran-ara ti ènìyàn, ọ̀tọ̀ ni ẹran-ara ti ẹranko, ọ̀tọ̀ ní ti ẹja, ọ̀tọ̀ sì ní tí ẹyẹ.
Dotyczy to nie tylko roślin. Inne ciała mają ludzie, inne zwierzęta, inne ptaki, a jeszcze inne ryby.
40 Ará ti òkè ọ̀run ń bẹ, ara ti ayé pẹ̀lú sì ń bẹ, ṣùgbọ́n ògo ti òkè ọ̀run ọ̀tọ̀, àti ògo ti ayé ọ̀tọ̀.
Są ciała niebieskie i ciała ziemskie—każde z nich ma inne piękno.
41 Ọ̀tọ̀ ni ògo ti oòrùn, ọ̀tọ̀ ni ògo ti òṣùpá, ọ̀tọ̀ sì ni ògo ti ìràwọ̀; ìràwọ̀ ṣá yàtọ̀ sí ìràwọ̀ ni ògo.
Słońce ma swój blask, inne światło daje jednak księżyc, a jeszcze inne gwiazdy. A nawet one różnią się między sobą.
42 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sí ni àjíǹde òkú. A gbìn ín ní ìdíbàjẹ́; a sí jì í dìde ni àìdíbàjẹ́.
Podobnie jest ze zmartwychwstaniem. Posiane jest ciało śmiertelne, a zmartwychwstanie ciało nieśmiertelne.
43 A gbìn ín ni àìní ọlá, a sí jí i dìde ni ògo; a gbìn ín ni àìlera, a sì jí í dìde ní agbára.
Posiane jest ciało materialne—słabe i sprawiające wiele kłopotów,
44 A gbìn ín ni, ara ẹran a sì jí i dìde ni ara ti ẹ̀mí. Bí ara ẹran bá ń bẹ, ara ẹ̀mí náà sì ń bẹ.
a zmartwychwstanie ciało duchowe—pełne mocy i wspaniałe! Istnieją bowiem ciała materialne i ciała duchowe.
45 Bẹ́ẹ̀ ní a si kọ ọ́ pé, “Adamu ọkùnrin ìṣáájú, alààyè ọkàn ni a dá a”; Adamu ìkẹyìn ẹ̀mí ìsọnidààyè.
Pismo mówi: „Adam, pierwszy człowiek, stał się istotą mającą życie”. Ale ostatni „Adam”—czyli Jezus—stał się duchem dającym życie!
46 Ṣùgbọ́n èyí tí í ṣe tí ẹ̀mí kọ ní ó kọ́kọ́ ṣáájú, bí kò ṣe èyí tí í ṣe tí ara ọkàn, lẹ́yìn náà èyí ti í ṣe ti ẹ̀mí.
Najpierw przyszedł ten, który miał ciało ziemskie. Potem dopiero przyszedł Ten, który ma ciało duchowe.
47 Ọkùnrin ìṣáájú ti inú erùpẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ẹni erùpẹ̀: ọkùnrin èkejì láti ọ̀run wá ni.
Adam, pierwszy człowiek, przyszedł z ziemi. Jezus, drugi Człowiek, przyszedł z nieba.
48 Bí ẹni erùpẹ̀ ti rí, irú bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí í ṣe erùpẹ̀: bí ẹni tí ọ̀run ti rí, irú bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí í ṣe tí ọ̀run.
Ci, którzy żyją na ziemi, mają ciało podobne do Adama, człowieka z ziemi. Ci jednak, którzy należą do nieba, otrzymają ciała podobne do Jezusa, Człowieka z nieba.
49 Bí àwa ti rú àwòrán ẹni erùpẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwa ó sì rú àwòrán ẹni ti ọ̀run.
Teraz jesteśmy podobni do ziemskiego Adama, ale będziemy podobni do niebiańskiego Chrystusa.
50 Ará, ǹjẹ́ èyí ní mo wí pé, ara àti ẹ̀jẹ̀ kò lè jogún ìjọba Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìdíbàjẹ́ kò lé jogún àìdíbàjẹ́.
Zapewniam was, przyjaciele, że nikt nie wejdzie do królestwa Bożego w ludzkim, śmiertelnym ciele—to, co jest doczesne, nie może bowiem stać się częścią tego, co jest wieczne.
51 Kíyèsi í, ohun ìjìnlẹ̀ ni mo sọ fún un yín, gbogbo wá kì yóò sùn, ṣùgbọ́n gbogbo wá ní a ó paláradà.
Pragnę wam jednak zdradzić wspaniałą tajemnicę: Nie wszyscy umrzemy, ale wszyscy otrzymamy nowe ciała.
52 Lọ́gán, ni ìṣẹ́jú kan, nígbà ìpè ìkẹyìn: nítorí ìpè yóò dún, a ó sì jí àwọn òkú dìde ní àìdíbàjẹ́, a ó sì pa wá láradà.
Stanie się to w jednej chwili, w mgnieniu oka, przy dźwięku ostatniej trąby. Gdy ona zabrzmi, zmarli powstaną do życia w nieśmiertelnych ciałach, a my, żywi, również otrzymamy nowe ciała.
53 Nítorí pé ara ìdíbàjẹ́ yìí kò lè ṣàìgbé ìdíbàjẹ́ wọ̀, àti ara kíkú yìí kò lè ṣàìgbé ara àìkú wọ̀.
Bo to, co jest doczesne i śmiertelne, musi zostać zastąpione tym, co wieczne i nieśmiertelne.
54 Ṣùgbọ́n nígbà tí ará ìdíbàjẹ́ yìí bá ti gbé àìdíbàjẹ́ wọ̀, ti ara kíkú yìí bá sí ti gbé àìkú wọ̀ bẹ́ẹ̀ tan, nígbà náà ni ọ̀rọ̀ ti a kọ yóò ṣẹ pé, “A gbé ikú mí ní ìṣẹ́gun.”
Gdy więc nasze doczesne i śmiertelne ciała przemienią się w ciała wieczne i nieśmiertelne, wypełnią się słowa Pisma: „Zwycięstwo pochłonęło śmierć.
55 “Ikú, oró rẹ dà? Ikú, ìṣẹ́gun rẹ́ dà?” (Hadēs )
Gdzie jest triumf śmierci? Gdzie jest jej żądło?”. (Hadēs )
56 Oró ikú ni ẹ̀ṣẹ̀; àti agbára ẹ̀ṣẹ̀ ni òfin.
Żądłem, którym śmierć zaatakowała ludzi, jest grzech, a Prawo ujawniło siłę grzechu.
57 Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ní fún Ọlọ́run ẹni tí ó fì ìṣẹ́gun fún wá nípa Olúwa wá Jesu Kristi!
Dziękujmy jednak Bogu za to, że posłał Jezusa Chrystusa, naszego Pana, i pozwolił nam odnieść zwycięstwo!
58 Nítorí náà ẹ̀yin ará mi olùfẹ́ ẹ máa dúró ṣinṣin, láìyẹsẹ̀, kí ẹ máa pọ̀ si í ní iṣẹ́ Olúwa nígbà gbogbo, ní ìwọ̀n bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé iṣẹ́ yin kì í ṣe asán nínú Olúwa.
Moi kochani przyjaciele, bądźcie wytrwali i nieugięci, nieustannie oddani pracy dla Pana. I pamiętajcie, że wasz wysiłek jest cenny w Jego oczach i nie pójdzie na marne.