< 1 Corinthians 15 >

1 Ǹjẹ́ ará, èmi ń sọ ìyìnrere náà dí mí mọ̀ fún un yín, tí mo ti wàásù fún un yín, èyí tí ẹ̀yin pẹ̀lú ti gbá, nínú èyí tí ẹ̀yin sì dúró.
Ngakho, bazalwane, ngilazisa ivangeli engalitshumayeza lona, lani elalemukelayo, njalo elimi kulo,
2 Nípasẹ̀ ìyìnrere yìí ni a fi ń gbà yín là pẹ̀lú, bí ẹ̀yin bá di ọ̀rọ̀ ti mo ti wàásù fún yín mú ṣinṣin. Bí bẹ́ẹ̀ kọ̀, ẹ̀yin kàn gbàgbọ́ lásán.
njalo elisindiswa ngalo; uba libambelela elizwini levangeli engalitshumayela kini, ngaphandle kokuthi lakholwa ize.
3 Nítorí èyí tí mo rí gbà ṣáájú ohun gbogbo ní èmi pẹ̀lú ti fi lé e yín lọ́wọ́, bí Kristi ti kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìwé mímọ́ tí wí.
Ngoba ngalinika okokuqala lokho engakwemukelayo lami, ukuthi uKristu wafa ngenxa yezono zethu, njengokwemibhalo;
4 Àti pé a sìnkú rẹ̀, àti pé ó jíǹde ní ọjọ́ kẹta gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ tí wí;
lokuthi wangcwatshwa; lokuthi wavuswa kwabafileyo ngosuku lwesithathu, njengokwemibhalo;
5 àti pé ó farahàn Peteru, lẹ́yìn èyí, àwọn méjìlá.
lokuthi wabonakala kuKefasi, emva kwalokho kwabalitshumi lambili;
6 Lẹ́yìn èyí, ó farahàn àwọn ará tí o jú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta lọ lẹ́ẹ̀kan náà; ọ̀pọ̀ nínú wọn wà títí fi di ìsinsin yìí, ṣùgbọ́n àwọn díẹ̀ ti sùn.
emva kwalokho wabonakala ngesikhathi sinye kubazalwane abedlula amakhulu amahlanu, ubunengi babo basekhona kuze kube lamuhla, kodwa labanye sebalala;
7 Lẹ́yìn èyí ni ó farahan Jakọbu; lẹ́yìn náà fún gbogbo àwọn aposteli.
emva kwalokho wabonakala kuJakobe, emva kwalokho wabonakala kubaphostoli bonke;
8 Àti níkẹyìn gbogbo wọn ó farahàn mí pẹ̀lú, bí ẹni tí a bí ṣáájú àkókò rẹ̀.
lekucineni kwabo bonke wabonakala lakimi njengozelwe ngesikhathi esingaqondanga.
9 Nítorí èmi ni ẹni tí ó kéré jùlọ nínú àwọn aposteli, èmi ẹni tí kò yẹ láti pè ní aposteli, nítorí tí mo ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run.
Ngoba mina ngingomncinyanyana kubaphostoli, engingafanele ukuthiwa ngumphostoli, ngoba ngazingela ibandla likaNkulunkulu.
10 Ṣùgbọ́n nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run mo rí bí mo ti rí: oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tí a fi fún mi kò sì jẹ́ asán; ṣùgbọ́n mó ṣiṣẹ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ jú gbogbo wọn lọ, ṣùgbọ́n kì í ṣe èmi, bí kò ṣe oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí ó wà pẹ̀lú mi.
Kodwa ngomusa kaNkulunkulu ngiyikho lokho engiyikho khona, lomusa wakhe okimi kawubanga yize; kodwa ngitshikatshike okwengezelelwe kulabo bonke, kanti kungesimi, kodwa ngumusa kaNkulunkulu olami.
11 Nítorí náà ìbá à ṣe èmí tàbí àwọn ni, èyí ní àwa wàásù, èyí ní ẹ̀yin sì gbàgbọ́.
Ngakho loba kuyimi, loba kuyibo, ngokunjalo siyatshumayela langokunjalo lakholwa.
12 Ǹjẹ́ bí a bá wàásù Kristi pé ó tí jíǹde kúrò nínú òkú, èéha tí ṣe tí àwọn mìíràn nínú yín fi wí pé, àjíǹde òkú kò sí.
Kodwa uba uKristu etshunyayelwa ukuthi uvusiwe kwabafileyo, batsho njani abanye phakathi kwenu ukuthi kakukho ukuvuka kwabafileyo?
13 Ṣùgbọ́n bí àjíǹde òkú kò sí, ǹjẹ́ Kristi kò jíǹde.
Kodwa uba kungekho ukuvuka kwabafileyo, kavuswanga laye uKristu;
14 Bí Kristi kò bá sì jíǹde, ǹjẹ́ asán ni ìwàásù wà, asán sì ni ìgbàgbọ́ yín pẹ̀lú.
uba-ke uKristu engavuswanga, ngakho ukutshumayela kwethu kuyize, lokholo lwenu lalo luyize.
15 Ṣùgbọ́n jù bẹ́ẹ̀ lọ, a mú wa ni ẹlẹ́rìí èké fún Ọlọ́run; nítorí ti àwa jẹ́rìí Ọlọ́run pé ó jí Kristi dìde kúrò nínú òkú: ẹni tí òun kò jí dìde bí ó bá ṣe pé àwọn òkú kò jíǹde?
Lathi futhi sificwa singabafakazi bamanga bakaNkulunkulu, ngoba safakaza ngoNkulunkulu ukuthi wamvusa uKristu, angamvusanga, uba-ke abafileyo bengavuswa.
16 Nítorí pé bi á kò bá jí àwọn òkú dìde, ǹjẹ́ a kò jí Kristi dìde,
Ngoba uba abafileyo bengavuswa, kavuswanga laye uKristu;
17 bí a kò bá sì jí Kristi dìde, asán ní ìgbàgbọ́ yín; ẹ̀yin wà nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín síbẹ̀.
njalo uba uKristu engavuswanga, ukholo lwenu luyize; lisesezonweni zenu.
18 Ǹjẹ́ àwọn pẹ̀lú tí ó sùn nínú Kristi ṣègbé.
Ngakho lalabo abalele bekuKristu sebabhubha.
19 Bí ó bá ṣe pé kìkì ayé yìí nìkan ní àwa ní ìrètí nínú Kristi, àwa jásí òtòṣì jùlọ nínú gbogbo ènìyàn.
Uba singabathembela kuKristu kule impilo kuphela, singabalosizi kulabo bonke abantu.
20 Ǹjẹ́ nísinsin yìí Kristi tí jíǹde kúrò nínú òkú, ó sì dí àkọ́bí nínú àwọn tí ó sùn.
Kodwa khathesi-ke uKristu uvusiwe kwabafileyo, waba yisithelo sokuqala sabaleleyo.
21 Nítorí ìgbà tí ó jẹ́ pé nípa ènìyàn ní ikú ti wá, nípa ènìyàn ní àjíǹde òkú sì ti wá pẹ̀lú.
Ngoba lokhu ngomuntu ukufa kweza, langomuntu ukuvuka kwabafileyo kweza.
22 Nítorí bí gbogbo ènìyàn ti kú nínú Adamu, bẹ́ẹ̀ ní a ó sì sọ gbogbo ènìyàn dí alààyè nínú Kristi.
Ngoba njengalokhu kuAdamu bonke bayafa, ngokunjalo futhi kuKristu bonke bazakwenziwa baphile.
23 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ènìyàn ní ipá tirẹ̀: Kristi àkọ́bí; lẹ́yìn èyí àwọn tí ó jẹ́ tí Kristi ni wíwá rẹ̀.
Kodwa ngulowo lalowo ngesakhe isigaba; isithelo sokuqala uKristu, besekusiba ngabakaKristu ekufikeni kwakhe,
24 Nígbà náà ni òpin yóò dé, nígbà tí ó bá ti fi ìjọba fún Ọlọ́run Baba, nígbà tí ó bá pa gbogbo àṣẹ àti gbogbo ọlá àti agbára run.
besekusiba yikuphela, lapho esenikela umbuso kuNkulunkulu, uYise, lalapho esenze kwaphela konke ukubusa labo bonke ubukhosi lamandla.
25 Nítorí ti òun gbọdọ̀ ti jẹ ọba kí òun to fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ngoba umele yena ukubusa, aze abeke zonke izitha ngaphansi kwenyawo zakhe.
26 Ikú ní ọ̀tá ìkẹyìn tí a ó parun.
Isitha sokucina esizachithwa yikufa.
27 “Nítorí ó ti fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wí pé, “Ohun gbogbo ni á fi sí abẹ́ rẹ̀,” o dájú pé Ọlọ́run nìkan ṣoṣo ní kò sí ní abẹ́ rẹ̀, Òun ní ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ àkóso Kristi.
Ngoba izinto zonke uzehlisele ngaphansi kwenyawo zakhe. Kodwa nxa esithi izinto zonke zehlisiwe, kusobala ukuthi ungaphandle kwazo yena ozehlisileyo izinto zonke ngaphansi kwakhe.
28 Nígbà tí a bá sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀ tán, nígbà náà ni á ó fi ọmọ tìkára rẹ̀ pẹ̀lú sábẹ́ ẹni tí ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀, kí Ọlọ́run lè jásí ohun gbogbo nínú ohun gbogbo.
Nxa izinto zonke sezehlisiwe ngaphansi kwakhe, khona layo iNdodana ngokwayo izazehlisa ngaphansi kwalowo owehlisela zonke izinto ngaphansi kwayo, ukuze uNkulunkulu abe yikho konke kukho konke.
29 Ní báyìí, bí kò bá sí àjíǹde, kín ní ète àwọn ènìyàn tí wọn ń tẹ bọ omi nítorí òkú? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde rárá, nítorí kín ni a ṣe ń bamitiisi wọn nítorí wọn?
Pho, bazakwenzani ababhabhathizelwa abafileyo uba abafileyo bengavuki isibili? Kungani babhabhathizelwa abafileyo na?
30 Nítorí kín ní àwa sì ṣe ń bẹ nínú ewu ni wákàtí gbogbo?
Kungani lathi sisengozini ihola ngehola?
31 Mo sọ nípa ayọ̀ tí mo ní lórí yín nínú Kristi Jesu Olúwa wá pé, èmi ń kú lójoojúmọ́.
Ngiyafa usuku ngosuku, ngiyaqinisa ngokuzincoma ngani engilakho kuKristu Jesu iNkosi yethu.
32 Kí a wí bí ènìyàn, bí mo bá ẹranko jà ní Efesu, àǹfààní kín ni ó jẹ́ fún mi? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde, “Ẹ jẹ́ kí a máa jẹ, kí á máa mú; nítorí ní ọlá ni àwa ó kú.”
Uba ngokwabantu ngalwa lezilo eEfesu, nzuzo bani kimi, uba abafileyo bengavuki? Asidle sinathe, ngoba kusasa siyafa.
33 Kí a má tàn yín jẹ́, “Ẹgbẹ́ búburú bá ìwà rere jẹ́.”
Lingakhohliswa; ukwejwayelana lababi kuyonakalisa izimilo ezinhle.
34 Ẹ jí ìjí òdodo, kí ẹ má sì dẹ́ṣẹ̀; nítorí àwọn ẹlòmíràn kò ni imọ̀ Ọlọ́run, mo sọ èyí kí ojú ba à lè tiyín.
Vusani ingqondo ngokulunga njalo lingoni; ngoba abanye balokungamazi uNkulunkulu; ngikhulumela ukuthi libe lenhloni.
35 Ṣùgbọ́n ẹnìkan yóò wí pé, “Báwo ni àwọn òkú yóò ṣe jíǹde? Irú ara wó ni wọn ó padà sí?”
Kodwa omunye uzakuthi: Abafileyo bavuswa njani? Njalo beza lomzimba onjani?
36 Ìwọ aláìmòye, ohun tí ìwọ fúnrúgbìn kì í yè bí kò ṣe pé ó ba kú,
Siphukuphuku, lokho okuhlanyelayo wena, kakwenziwa kuphile ngaphandle kokuthi kufe;
37 àti èyí tí ìwọ fúnrúgbìn, kì í ṣe ara tí ń bọ̀ ni ìwọ fúnrúgbìn, ṣùgbọ́n èso lásán ni, ìbá à ṣe alikama, tàbí irú mìíràn.
lalokho okuhlanyelayo, kawuhlanyeli umzimba ozakuba khona, kodwa uhlamvu oluze, mhlawumbe, olwebele kumbe olokunye nje;
38 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fún ún ni ara bí o tí wù ú, àti fún olúkúlùkù irúgbìn ara tirẹ̀.
kodwa uNkulunkulu uyinika umzimba njengokuthanda kwakhe, lakuleyo laleyo yenhlanyelo owayo umzimba.
39 Gbogbo ẹran-ara kì í ṣe ẹran-ara kan náà, ṣùgbọ́n ọ̀tọ̀ ni ẹran-ara ti ènìyàn, ọ̀tọ̀ ni ẹran-ara ti ẹranko, ọ̀tọ̀ ní ti ẹja, ọ̀tọ̀ sì ní tí ẹyẹ.
Inyama yonke kayisinyamanye; kodwa enye yinyama yabantu, lenye yinyama yenyamazana, lenye eyenhlanzi, lenye eyezinyoni.
40 Ará ti òkè ọ̀run ń bẹ, ara ti ayé pẹ̀lú sì ń bẹ, ṣùgbọ́n ògo ti òkè ọ̀run ọ̀tọ̀, àti ògo ti ayé ọ̀tọ̀.
Ikhona lemizimba yezulwini, lemizimba yemhlabeni; kodwa inkazimulo yezulu ingenye, leyemhlabeni ingenye.
41 Ọ̀tọ̀ ni ògo ti oòrùn, ọ̀tọ̀ ni ògo ti òṣùpá, ọ̀tọ̀ sì ni ògo ti ìràwọ̀; ìràwọ̀ ṣá yàtọ̀ sí ìràwọ̀ ni ògo.
Enye yinkazimulo yelanga, lenye yinkazimulo yenyanga, lenye yinkazimulo yezinkanyezi; ngoba inkanyezi yehlukile kwenye inkanyezi enkazimulweni.
42 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sí ni àjíǹde òkú. A gbìn ín ní ìdíbàjẹ́; a sí jì í dìde ni àìdíbàjẹ́.
Kunjalo-ke ukuvuka kwabafileyo. Kuhlanyelwa ekuboleni, kuyavuswa kungekho ekuboleni;
43 A gbìn ín ni àìní ọlá, a sí jí i dìde ni ògo; a gbìn ín ni àìlera, a sì jí í dìde ní agbára.
kuhlanyelwa ekudelweni, kuvuswe enkazimulweni; kuhlanyelwa ebuthakathakeni, kuvuswe emandleni;
44 A gbìn ín ni, ara ẹran a sì jí i dìde ni ara ti ẹ̀mí. Bí ara ẹran bá ń bẹ, ara ẹ̀mí náà sì ń bẹ.
kuhlanyelwa umzimba wemvelo, kuvuswe umzimba womoya. Kukhona umzimba wemvelo, njalo kukhona umzimba womoya.
45 Bẹ́ẹ̀ ní a si kọ ọ́ pé, “Adamu ọkùnrin ìṣáájú, alààyè ọkàn ni a dá a”; Adamu ìkẹyìn ẹ̀mí ìsọnidààyè.
Langokunjalo kulotshiwe ukuthi: Umuntu wokuqala uAdamu waba ngumphefumulo ophilayo; uAdamu wokucina ngumoya ophilisayo.
46 Ṣùgbọ́n èyí tí í ṣe tí ẹ̀mí kọ ní ó kọ́kọ́ ṣáájú, bí kò ṣe èyí tí í ṣe tí ara ọkàn, lẹ́yìn náà èyí ti í ṣe ti ẹ̀mí.
Kodwa okokuqala kakusikho okomoya, kodwa okwemvelo, besekusiza okomoya.
47 Ọkùnrin ìṣáájú ti inú erùpẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ẹni erùpẹ̀: ọkùnrin èkejì láti ọ̀run wá ni.
Umuntu wokuqala wavela emhlabeni, ungowomhlabathi; umuntu wesibili uyiNkosi evela ezulwini.
48 Bí ẹni erùpẹ̀ ti rí, irú bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí í ṣe erùpẹ̀: bí ẹni tí ọ̀run ti rí, irú bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí í ṣe tí ọ̀run.
Njengoba enjalo owomhlabathi, banjalo labo abomhlabathi; lanjengoba enjalo owezulwini, banjalo labo abezulwini;
49 Bí àwa ti rú àwòrán ẹni erùpẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwa ó sì rú àwòrán ẹni ti ọ̀run.
futhi njengoba sibelesimo sowomhlabathi, lathi sizakuba lesimo sowezulwini.
50 Ará, ǹjẹ́ èyí ní mo wí pé, ara àti ẹ̀jẹ̀ kò lè jogún ìjọba Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìdíbàjẹ́ kò lé jogún àìdíbàjẹ́.
Kodwa ngitsho lokhu, bazalwane, ukuthi inyama legazi kungelidle ilifa lombuso kaNkulunkulu; lokubola kakulidli ilifa lokungaboli.
51 Kíyèsi í, ohun ìjìnlẹ̀ ni mo sọ fún un yín, gbogbo wá kì yóò sùn, ṣùgbọ́n gbogbo wá ní a ó paláradà.
Khangelani, ngilitshela imfihlo: Kasiyikulala sonke, kodwa sizaphendulwa sonke,
52 Lọ́gán, ni ìṣẹ́jú kan, nígbà ìpè ìkẹyìn: nítorí ìpè yóò dún, a ó sì jí àwọn òkú dìde ní àìdíbàjẹ́, a ó sì pa wá láradà.
ngesikhatshana, ngokucwayiza kwelihlo, ekukhaleni kophondo lokucina; ngoba uphondo luzakhala, labafileyo bazavuswa bengelakubola, lathi sizaphendulwa.
53 Nítorí pé ara ìdíbàjẹ́ yìí kò lè ṣàìgbé ìdíbàjẹ́ wọ̀, àti ara kíkú yìí kò lè ṣàìgbé ara àìkú wọ̀.
Ngoba lokhu okubolayo kumele ukwembatha ukungaboli, lalokho okufayo kwembathe ukungafi.
54 Ṣùgbọ́n nígbà tí ará ìdíbàjẹ́ yìí bá ti gbé àìdíbàjẹ́ wọ̀, ti ara kíkú yìí bá sí ti gbé àìkú wọ̀ bẹ́ẹ̀ tan, nígbà náà ni ọ̀rọ̀ ti a kọ yóò ṣẹ pé, “A gbé ikú mí ní ìṣẹ́gun.”
Nxa-ke lokho okubolayo sekwembethe ukungaboli, lalokho okufayo sekwembethe ukungafi, kuzakwenzeka ngalesosikhathi ilizwi elilotshiweyo lokuthi: Ukufa kuginyiwe ekunqobeni.
55 “Ikú, oró rẹ dà? Ikú, ìṣẹ́gun rẹ́ dà?” (Hadēs g86)
Lungaphi, kufa, udonsi lwakho? Kungaphi, ngcwaba, ukunqoba kwakho? (Hadēs g86)
56 Oró ikú ni ẹ̀ṣẹ̀; àti agbára ẹ̀ṣẹ̀ ni òfin.
Lodonsi lokufa yisono; lamandla esono ngumlayo.
57 Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ní fún Ọlọ́run ẹni tí ó fì ìṣẹ́gun fún wá nípa Olúwa wá Jesu Kristi!
Kodwa kabongwe uNkulunkulu osinika ukunqoba ngeNkosi yethu uJesu Kristu.
58 Nítorí náà ẹ̀yin ará mi olùfẹ́ ẹ máa dúró ṣinṣin, láìyẹsẹ̀, kí ẹ máa pọ̀ si í ní iṣẹ́ Olúwa nígbà gbogbo, ní ìwọ̀n bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé iṣẹ́ yin kì í ṣe asán nínú Olúwa.
Ngakho, bazalwane bami abathandekayo, manini, linganyikinyeki, lengezelelwe emsebenzini weNkosi kokuphela, lazi ukuthi ukutshikatshika kwenu kakusilo ize eNkosini.

< 1 Corinthians 15 >