< 1 Corinthians 15 >
1 Ǹjẹ́ ará, èmi ń sọ ìyìnrere náà dí mí mọ̀ fún un yín, tí mo ti wàásù fún un yín, èyí tí ẹ̀yin pẹ̀lú ti gbá, nínú èyí tí ẹ̀yin sì dúró.
Now, my fellow believers, I want to remind you about the message about Christ that I preached to you. It is the message that you received and that you have continued to trust firmly.
2 Nípasẹ̀ ìyìnrere yìí ni a fi ń gbà yín là pẹ̀lú, bí ẹ̀yin bá di ọ̀rọ̀ ti mo ti wàásù fún yín mú ṣinṣin. Bí bẹ́ẹ̀ kọ̀, ẹ̀yin kàn gbàgbọ́ lásán.
If you keep on firmly [believing] this message that I preached to you, you will be saved {[God] will save you}. If you do not continue to believe it, your believing [in Christ] was (all for nothing/useless)!
3 Nítorí èyí tí mo rí gbà ṣáájú ohun gbogbo ní èmi pẹ̀lú ti fi lé e yín lọ́wọ́, bí Kristi ti kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìwé mímọ́ tí wí.
The most important part of the message that I received [from the Lord Jesus], and that I told you, was this: Christ died to [take away the guilt] of our sins, as the Scriptures [said that he would do].
4 Àti pé a sìnkú rẹ̀, àti pé ó jíǹde ní ọjọ́ kẹta gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ tí wí;
His [dead body] was buried {They buried his [body]}. On the third day [after that], [God] caused him to become alive again, as the Scriptures [said would happen].
5 àti pé ó farahàn Peteru, lẹ́yìn èyí, àwọn méjìlá.
After that, [Christ] was seen by {appeared to} Peter. Then he appeared to [eleven of] the [original] twelve [apostles].
6 Lẹ́yìn èyí, ó farahàn àwọn ará tí o jú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta lọ lẹ́ẹ̀kan náà; ọ̀pọ̀ nínú wọn wà títí fi di ìsinsin yìí, ṣùgbọ́n àwọn díẹ̀ ti sùn.
Later he was seen by {appeared to} more than 500 of our fellow believers. Most of those are still living, but some of them have died [EUP].
7 Lẹ́yìn èyí ni ó farahan Jakọbu; lẹ́yìn náà fún gbogbo àwọn aposteli.
Then he was seen by {appeared [to]} [his younger brother] James, [who became the leader of the congregation in Jerusalem]. Then he appeared to all of the apostles.
8 Àti níkẹyìn gbogbo wọn ó farahàn mí pẹ̀lú, bí ẹni tí a bí ṣáájú àkókò rẹ̀.
Finally, he was seen by {appeared to} me, but I became an apostle in a way that was very unusual [MET].
9 Nítorí èmi ni ẹni tí ó kéré jùlọ nínú àwọn aposteli, èmi ẹni tí kò yẹ láti pè ní aposteli, nítorí tí mo ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run.
The fact is, I [consider that I] am the least important of the apostles. I do not deserve to be an apostle, because I (persecuted God’s groups of believers/caused God’s groups of believers to suffer) [everywhere I went].
10 Ṣùgbọ́n nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run mo rí bí mo ti rí: oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tí a fi fún mi kò sì jẹ́ asán; ṣùgbọ́n mó ṣiṣẹ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ jú gbogbo wọn lọ, ṣùgbọ́n kì í ṣe èmi, bí kò ṣe oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí ó wà pẹ̀lú mi.
But it is because God acted kindly toward me in ways that I did not deserve that I became what I am now. And his acting kindly toward me produced a great result [LIT], which is that I worked harder [for Christ] than all the other apostles. But it was not that I [was working with my own ability]. Instead, God was helping me in a way I did not deserve.
11 Nítorí náà ìbá à ṣe èmí tàbí àwọn ni, èyí ní àwa wàásù, èyí ní ẹ̀yin sì gbàgbọ́.
So it does not matter whether it was I [who was preaching or whether it was the other apostles who were preaching]. We all preached [the same message], and that message is what you believed.
12 Ǹjẹ́ bí a bá wàásù Kristi pé ó tí jíǹde kúrò nínú òkú, èéha tí ṣe tí àwọn mìíràn nínú yín fi wí pé, àjíǹde òkú kò sí.
So now [let me ask you this]: Since [we] have all preached to you that Christ was raised again {that [God] caused Christ to become alive} after he died, (no one among you should be saying that [God] will not cause [believers] to become alive again after they die!/why do some of you say that [God] will not cause [believers] to become alive again after they die?) [RHQ]
13 Ṣùgbọ́n bí àjíǹde òkú kò sí, ǹjẹ́ Kristi kò jíǹde.
If [it is true that God] will not cause anyone to become alive again, that situation would mean that Christ was not raised from the dead {[he] did not cause Christ to become alive again}!
14 Bí Kristi kò bá sì jíǹde, ǹjẹ́ asán ni ìwàásù wà, asán sì ni ìgbàgbọ́ yín pẹ̀lú.
And if Christ was not raised from the dead {if [God] did not cause Christ to become alive again}, then what we preached to you was useless, and your believing [in Christ] is useless.
15 Ṣùgbọ́n jù bẹ́ẹ̀ lọ, a mú wa ni ẹlẹ́rìí èké fún Ọlọ́run; nítorí ti àwa jẹ́rìí Ọlọ́run pé ó jí Kristi dìde kúrò nínú òkú: ẹni tí òun kò jí dìde bí ó bá ṣe pé àwọn òkú kò jíǹde?
[If it is true that] no one will be raised from the dead {[that God] will not cause anyone to become alive again after he dies}, we [(exc)] have been guilty of lying to you about God, because we told you that God caused Christ to become alive again.
16 Nítorí pé bi á kò bá jí àwọn òkú dìde, ǹjẹ́ a kò jí Kristi dìde,
But if it were really true that no one who has died will be raised {that [God will] not cause anyone who has died to become alive} again, then Christ was not raised {[he] did not cause Christ to become alive} again either!
17 bí a kò bá sì jí Kristi dìde, asán ní ìgbàgbọ́ yín; ẹ̀yin wà nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín síbẹ̀.
If it were true that Christ was not raised {that [God] did not cause Christ to become alive} again after he died, you have believed in Christ for nothing, [because] God will still [punish] you for [MTY] your sins.
18 Ǹjẹ́ àwọn pẹ̀lú tí ó sùn nínú Kristi ṣègbé.
And those people who died [EUP] [while they were trusting] in Christ will go to hell. ()
19 Bí ó bá ṣe pé kìkì ayé yìí nìkan ní àwa ní ìrètí nínú Kristi, àwa jásí òtòṣì jùlọ nínú gbogbo ènìyàn.
In this life [many of us have suffered much for Christ] because we confidently expect [that he will reward us in heaven]. If we have confidently expected this in vain, people should pity us more than they pity anyone else!
20 Ǹjẹ́ nísinsin yìí Kristi tí jíǹde kúrò nínú òkú, ó sì dí àkọ́bí nínú àwọn tí ó sùn.
But [the truth is that] Christ has been raised from the dead {that [God] has caused Christ to live again after he had died}, and (that guarantees/because of that, it is certain) [MET] that he will also cause those [believers] who have died [EUP] to become alive again.
21 Nítorí ìgbà tí ó jẹ́ pé nípa ènìyàn ní ikú ti wá, nípa ènìyàn ní àjíǹde òkú sì ti wá pẹ̀lú.
What one man, [Adam, did affects us all]. We all die. Similarly, what one man—[Christ]—did [affects us(inc) all]: God will cause [all believers] to become alive again.
22 Nítorí bí gbogbo ènìyàn ti kú nínú Adamu, bẹ́ẹ̀ ní a ó sì sọ gbogbo ènìyàn dí alààyè nínú Kristi.
Because of what Adam did, all [of us who are descended] from him die. Similarly, because of what [Christ did], all of us who have a close relationship with him will be brought back to life {[God] will make alive all of us who have a close relationship with Christ}.
23 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ènìyàn ní ipá tirẹ̀: Kristi àkọ́bí; lẹ́yìn èyí àwọn tí ó jẹ́ tí Kristi ni wíwá rẹ̀.
But we must all take our turn. [God raised] Christ first [MET]. And when Christ returns, [God will cause] those who belong to Christ to become alive again.
24 Nígbà náà ni òpin yóò dé, nígbà tí ó bá ti fi ìjọba fún Ọlọ́run Baba, nígbà tí ó bá pa gbogbo àṣẹ àti gbogbo ọlá àti agbára run.
Then, after Christ has destroyed all [DOU] the evil powers that oppose God, [the world] will end. Then Christ will give to God, his Father, his kingdom to completely rule over it.
25 Nítorí ti òun gbọdọ̀ ti jẹ ọba kí òun to fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
You must realize that Christ must rule [here on earth] until he has completely defeated [MTY] all his enemies.
26 Ikú ní ọ̀tá ìkẹyìn tí a ó parun.
The last thing that [he] will get rid of is death. [But he certainly will get rid of death, which is like] an enemy [to us].
27 “Nítorí ó ti fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wí pé, “Ohun gbogbo ni á fi sí abẹ́ rẹ̀,” o dájú pé Ọlọ́run nìkan ṣoṣo ní kò sí ní abẹ́ rẹ̀, Òun ní ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ àkóso Kristi.
[In the Scriptures the Psalmist wrote that] God will cause everything to be under Christ’s [authority] [MTY]. But it is clear that the word ‘everything’ here does not include God, because God is the one who will cause everything to be under Christ’s [authority] [MTY].
28 Nígbà tí a bá sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀ tán, nígbà náà ni á ó fi ọmọ tìkára rẹ̀ pẹ̀lú sábẹ́ ẹni tí ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀, kí Ọlọ́run lè jásí ohun gbogbo nínú ohun gbogbo.
After everything is put under [the authority of] God’s Son, then Christ will put himself completely under [the authority of] God, the one who gave him that authority. Then God will be completely in control of everything [IDM], everywhere.
29 Ní báyìí, bí kò bá sí àjíǹde, kín ní ète àwọn ènìyàn tí wọn ń tẹ bọ omi nítorí òkú? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde rárá, nítorí kín ni a ṣe ń bamitiisi wọn nítorí wọn?
[Now think about this: Some among you] are being baptized (OR, are baptizing people) on behalf of those who died [before someone baptized them] (OR, who died [before they became believers]). If, [as some people say, believers] will not be raised [from the dead] {[God] will not cause [believers] to become alive again}, (what is the value in those people doing that?/there is no value in those people doing that!) [RHQ] If [God] will not cause any [believers] to become alive again, it is senseless to be baptized {baptize anyone} on behalf of someone who has died. [RHQ]
30 Nítorí kín ní àwa sì ṣe ń bẹ nínú ewu ni wákàtí gbogbo?
Furthermore, [if God will not cause us believers to become alive again], it is [RHQ] very foolish for me and the other apostles to be constantly [putting ourselves] in danger [because we tell people the gospel].
31 Mo sọ nípa ayọ̀ tí mo ní lórí yín nínú Kristi Jesu Olúwa wá pé, èmi ń kú lójoojúmọ́.
My fellow believers, every day I [am in danger of] being killed {people killing me}! That is as true as it is that I am pleased with you because of your close relationship with Christ Jesus our Lord.
32 Kí a wí bí ènìyàn, bí mo bá ẹranko jà ní Efesu, àǹfààní kín ni ó jẹ́ fún mi? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde, “Ẹ jẹ́ kí a máa jẹ, kí á máa mú; nítorí ní ọlá ni àwa ó kú.”
[If God will not cause us believers to become alive again after we die], (I will receive no benefit at all [from having opposed those who attacked me so strongly] in Ephesus [city]./what will I gain [from having opposed those who attacked me so strongly] in Ephesus [city]?) [RHQ] They were [fighting me like] wild beasts! If we [believers] will not be raised [from the dead] {If [God] will not cause us [believers] to live again}, we might as well say [as people often say]: “Tomorrow we are going to die, so we might as well enjoy now everything that we can. We might as well feast and get drunk!”
33 Kí a má tàn yín jẹ́, “Ẹgbẹ́ búburú bá ìwà rere jẹ́.”
Do not let [yourselves be deceived by those who say that God will not cause believers to live again] {Do not let [people who say that God will not cause believers to live again] deceive you}. If you associate with evil people [who say such things], they will (influence you to do evil things/destroy your good moral way of living).
34 Ẹ jí ìjí òdodo, kí ẹ má sì dẹ́ṣẹ̀; nítorí àwọn ẹlòmíràn kò ni imọ̀ Ọlọ́run, mo sọ èyí kí ojú ba à lè tiyín.
Start thinking correctly again [about these matters], as you should, and [stop your sinful behavior which has resulted from] your wrong thinking. [I say that] because [it seems that] some among you do not know God, and as a result they [are thinking wrongly]. I say that to make you ashamed.
35 Ṣùgbọ́n ẹnìkan yóò wí pé, “Báwo ni àwọn òkú yóò ṣe jíǹde? Irú ara wó ni wọn ó padà sí?”
But some of you are asking, “How will dead people be raised {How will [God] cause dead people to become alive} again? What kind of bodies will they have?”
36 Ìwọ aláìmòye, ohun tí ìwọ fúnrúgbìn kì í yè bí kò ṣe pé ó ba kú,
[Anyone who asks such questions is] foolish. You [know that] a seed that is planted in the ground must completely change its form [MET] before it sprouts.
37 àti èyí tí ìwọ fúnrúgbìn, kì í ṣe ara tí ń bọ̀ ni ìwọ fúnrúgbìn, ṣùgbọ́n èso lásán ni, ìbá à ṣe alikama, tàbí irú mìíràn.
A seed, such as a wheat seed, is very different from the plant that sprouts from it.
38 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fún ún ni ara bí o tí wù ú, àti fún olúkúlùkù irúgbìn ara tirẹ̀.
God gives everything that lives the form that he desires. He gives each seed its own form.
39 Gbogbo ẹran-ara kì í ṣe ẹran-ara kan náà, ṣùgbọ́n ọ̀tọ̀ ni ẹran-ara ti ènìyàn, ọ̀tọ̀ ni ẹran-ara ti ẹranko, ọ̀tọ̀ ní ti ẹja, ọ̀tọ̀ sì ní tí ẹyẹ.
[Similarly], people, animals, birds, and fish all have flesh, but each one has a different kind of flesh.
40 Ará ti òkè ọ̀run ń bẹ, ara ti ayé pẹ̀lú sì ń bẹ, ṣùgbọ́n ògo ti òkè ọ̀run ọ̀tọ̀, àti ògo ti ayé ọ̀tọ̀.
Also, there are angelic beings in heaven (OR, stars and planets in the sky), and there are people with bodies on the earth. The angelic beings (OR, stars and planets) are beautiful in one way, and people on earth are beautiful in a different way.
41 Ọ̀tọ̀ ni ògo ti oòrùn, ọ̀tọ̀ ni ògo ti òṣùpá, ọ̀tọ̀ sì ni ògo ti ìràwọ̀; ìràwọ̀ ṣá yàtọ̀ sí ìràwọ̀ ni ògo.
The sun is bright in one way, and the moon is bright in a different way, and the stars are bright in a different way. And even the various stars are different from each other in how bright they are.
42 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sí ni àjíǹde òkú. A gbìn ín ní ìdíbàjẹ́; a sí jì í dìde ni àìdíbàjẹ́.
And it is the same way [with our bodies. The bodies that we will have when God causes us] to live again after we die [will not be the same as the bodies that we have now] [MET]. [The bodies that we have now] will die and decay. [The new bodies that we will have] will never die.
43 A gbìn ín ni àìní ọlá, a sí jí i dìde ni ògo; a gbìn ín ni àìlera, a sì jí í dìde ní agbára.
We despise [the bodies that we have now], before we die. But our [new bodies] will be glorious. The [bodies that we have before we die] are weak. But our new bodies will be strong.
44 A gbìn ín ni, ara ẹran a sì jí i dìde ni ara ti ẹ̀mí. Bí ara ẹran bá ń bẹ, ara ẹ̀mí náà sì ń bẹ.
The bodies that we have before we die are natural bodies. But [our new bodies] will be ones that [God’s] Spirit ([controls/gives us]). Just like there are natural bodies, there are bodies that [God’s] Spirit [completely] controls (OR, makes alive).
45 Bẹ́ẹ̀ ní a si kọ ọ́ pé, “Adamu ọkùnrin ìṣáájú, alààyè ọkàn ni a dá a”; Adamu ìkẹyìn ẹ̀mí ìsọnidààyè.
[In the Scriptures] it is written {we read} that [when] the first man, Adam, [was created], he became a living human being. [Christ later also became a human being]. But [he is different from Adam, because he] became a person who gives us [spiritual] life.
46 Ṣùgbọ́n èyí tí í ṣe tí ẹ̀mí kọ ní ó kọ́kọ́ ṣáájú, bí kò ṣe èyí tí í ṣe tí ara ọkàn, lẹ́yìn náà èyí ti í ṣe ti ẹ̀mí.
But our bodies that God’s Spirit (will completely control/will give us) are not the first bodies that we have. We have our natural bodies first.
47 Ọkùnrin ìṣáájú ti inú erùpẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ẹni erùpẹ̀: ọkùnrin èkejì láti ọ̀run wá ni.
The first man, [Adam], was created {[God] created the first man, Adam} from the dust of the earth. But [Christ], the one who came later, came from heaven.
48 Bí ẹni erùpẹ̀ ti rí, irú bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí í ṣe erùpẹ̀: bí ẹni tí ọ̀run ti rí, irú bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí í ṣe tí ọ̀run.
Everyone on earth [has a body] like the first man on the earth had. And in heaven, [everyone will have a body like Christ], the man who came from heaven, has.
49 Bí àwa ti rú àwòrán ẹni erùpẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwa ó sì rú àwòrán ẹni ti ọ̀run.
And just like [God] gave us bodies like the first man on earth had, so we [believers will have bodies] like [Christ] has, who is now in heaven.
50 Ará, ǹjẹ́ èyí ní mo wí pé, ara àti ẹ̀jẹ̀ kò lè jogún ìjọba Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìdíbàjẹ́ kò lé jogún àìdíbàjẹ́.
My fellow believers, I want you to know that we [(inc)] [SYN] cannot go [to heaven, where] God rules [over everything], with our physical bodies, because our bodies [cannot last forever]. They will die and decay.
51 Kíyèsi í, ohun ìjìnlẹ̀ ni mo sọ fún un yín, gbogbo wá kì yóò sùn, ṣùgbọ́n gbogbo wá ní a ó paláradà.
But I will tell you something that [God] has not revealed [before]: [Some of] us [believers] will not die [EUP]. However, all of us will be changed {[God] will change all of us}.
52 Lọ́gán, ni ìṣẹ́jú kan, nígbà ìpè ìkẹyìn: nítorí ìpè yóò dún, a ó sì jí àwọn òkú dìde ní àìdíbàjẹ́, a ó sì pa wá láradà.
[It will happen] suddenly, as [fast as someone can] blink his eye [MET], when [we hear the sound of God’s] trumpet for the last time. When we hear that trumpet, all [the believers] who have died will come back to life and will have bodies that are changed {that [God] has changed}, bodies that will never decay.
53 Nítorí pé ara ìdíbàjẹ́ yìí kò lè ṣàìgbé ìdíbàjẹ́ wọ̀, àti ara kíkú yìí kò lè ṣàìgbé ara àìkú wọ̀.
And the [bodies of us who are alive at that time] will [also] be changed {And [God] will [also] change the [bodies of us who are alive at that time]}. These bodies of ours that die and decay must be transformed into [new bodies that] will never die; [it will be like someone] [MET] getting rid of [his old clothes] and putting on [new ones].
54 Ṣùgbọ́n nígbà tí ará ìdíbàjẹ́ yìí bá ti gbé àìdíbàjẹ́ wọ̀, ti ara kíkú yìí bá sí ti gbé àìkú wọ̀ bẹ́ẹ̀ tan, nígbà náà ni ọ̀rọ̀ ti a kọ yóò ṣẹ pé, “A gbé ikú mí ní ìṣẹ́gun.”
When that happens, what is written {what ([a prophet/Isaiah]) wrote} [in the Scriptures] will come true/happen: [God] will completely get rid of [MET] death. Our dying will no longer have any power to defeat us;
55 “Ikú, oró rẹ dà? Ikú, ìṣẹ́gun rẹ́ dà?” (Hadēs )
Death [APO] will not win a victory over us. Death will not be able to hurt us. (Hadēs )
56 Oró ikú ni ẹ̀ṣẹ̀; àti agbára ẹ̀ṣẹ̀ ni òfin.
It is because we sin [MET] [that we die, and it is because we] have God’s laws that we [know that we] have sinned.
57 Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ní fún Ọlọ́run ẹni tí ó fì ìṣẹ́gun fún wá nípa Olúwa wá Jesu Kristi!
But because of what our Lord Jesus Christ [has done], he enables us to be free [from having to obey God’s laws to be saved and to be free of being afraid to die]. We should thank God for that!
58 Nítorí náà ẹ̀yin ará mi olùfẹ́ ẹ máa dúró ṣinṣin, láìyẹsẹ̀, kí ẹ máa pọ̀ si í ní iṣẹ́ Olúwa nígbà gbogbo, ní ìwọ̀n bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé iṣẹ́ yin kì í ṣe asán nínú Olúwa.
So, my fellow believers whom I love, continue to hold strongly to [the things that you believe]. Do not let anything cause you to doubt them. Always be doing enthusiastically the work that the Lord [gives you]. And remember that the work that you do for the Lord is never (in vain/useless), [as it would be if God will not cause us to live again after we die].