< 1 Corinthians 14 >

1 Ẹ máa lépa ìfẹ́, ki ẹ sí máa fi ìtara ṣàfẹ́rí ẹ̀bùn tí í ṣe ti Ẹ̀mí, ṣùgbọ́n ki ẹ kúkú lé máa sọtẹ́lẹ̀.
ⲁ̅ϬⲞϪⲒ ⲚⲤⲀϮⲀⲄⲀⲠⲎ ⲬⲞϨ ⲆⲈ ⲈⲚⲒⲠⲚⲀⲦⲒⲔⲞⲚ ⲘⲀⲖⲖⲞⲚ ⲆⲈ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲠⲢⲞⲪⲎ ⲦⲈⲨⲒⲚ.
2 Nítorí ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ní èdè àìmọ̀, kò bá ènìyàn sọ̀rọ̀ bì ko ṣe Ọlọ́run: nítorí kó sí ẹni tí ó gbọ́; ṣùgbọ́n nípá ti Ẹ̀mí ó ń sọ ohun ìjìnlẹ̀.
ⲃ̅ⲠⲈⲦⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲪⲖⲀⲤ ⲈϤⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲀⲚ ⲀⲖⲖⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲘⲘⲞⲚ ϨⲖⲒ ⲄⲀⲢ ⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲢⲞϤ ϦⲈⲚⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀϪⲈ ϤⲤⲀϪⲒ ⲚϨⲀⲚⲘⲨⲤⲦⲎ ⲢⲒⲞⲚ.
3 Ṣùgbọ́n ẹni tí ń sọtẹ́lẹ̀ ń ba àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ fún ìmúdúró, àti ìgbaniníyànjú, àti ìtùnú.
ⲅ̅ⲪⲎ ⲆⲈ ⲈⲦⲈⲢⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲈⲨⲒⲚ ⲀϤⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲚⲞⲨⲔⲰⲦ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲚⲞⲘϮ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲐⲰⲦ ⲚϨⲎⲦ.
4 Ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ni èdè àìmọ̀ ń fi ẹsẹ̀ ara rẹ̀ mulẹ̀; ṣùgbọ́n ẹni ti ń sọtẹ́lẹ̀ ń fi ẹsẹ̀ ìjọ múlẹ̀.
ⲇ̅ⲠⲈⲦⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲪⲖⲀⲤ ⲀϤⲔⲰⲦ ⲘⲘⲞϤ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲪⲎ ⲆⲈ ⲈⲦⲈⲢⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲈⲨⲒⲚ ⲀϤⲔⲰⲦ ⲚⲞⲨⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ.
5 Ṣùgbọ́n ìbá wù mí ki gbogbo yín lè máa sọ onírúurú èdè, ṣùgbọ́n kí ẹ kúkú máa sọtẹ́lẹ̀, ẹni tí ń sọtẹ́lẹ̀ pọ̀ jú ẹni ti ń fèdèfọ̀ lọ, bi kọ ṣe pé ó bá ń ṣe ìtumọ̀, kí ìjọ bá à lè kọ́ ẹ̀kọ́.
ⲉ̅ϮⲞⲨⲈϢ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲆⲈ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲖⲀⲤ ⲘⲀⲖⲖⲞⲚ ⲆⲈ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲈⲢⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲈⲨⲒⲚ ⲚⲀⲀ ⲠⲈⲦⲈⲢⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲈⲨⲒⲚ ⲆⲈ ⲈϨⲞⲦⲈ ⲠⲈⲦⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲪⲖⲀⲤ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲒⲘⲎⲦⲒ ⲚⲦⲈϤⲈⲢⲘⲈⲚⲈⲨⲒⲚ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϮⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ϬⲒ ⲚⲞⲨⲔⲰⲦ.
6 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ará, bí mo bá wá sí àárín yín, tí mo sì ń sọ̀rọ̀ ní èdè àìmọ̀, èrè kín ni èmi yóò jẹ́ fún yin, bi ko ṣe pé mo bá ń bá yín sọ̀rọ̀, yálà nípa ìṣípayá, tàbí ìmọ̀ tàbí nípá ìsọtẹ́lẹ̀, tàbí nípa ẹ̀kọ́?
ⲋ̅ϮⲚⲞⲨ ⲆⲈ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲒϢⲀⲚⲒ ϨⲀⲢⲰⲦⲈⲚ ⲈⲒⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲖⲀⲤ ⲞⲨ ⲚϨⲎⲞⲨ ⲠⲈϮⲚⲀⲦⲎⲒϤ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲀⲒϢⲦⲈⲘⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲰⲦⲈⲚ ϦⲈⲚⲞⲨϬⲰⲢⲠ ⲈⲂⲞⲖ ⲒⲈ ϦⲈⲚⲞⲨⲈⲘⲒ ⲒⲈ ϦⲈⲚⲞⲨⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲒⲀ ⲒⲈ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲂⲰ.
7 Bẹ́ẹ̀ ní pẹ̀lú àwọn nǹkan tí kò ní ẹ̀mí tí ń dún, ìbá à ṣe fèrè tàbí dùùrù bí kò ṣe pé ìyàtọ̀ bá wà nínú wọn, a ó tí ṣe mọ ohùn tí fèrè tàbí tí dùùrù ń wí?
ⲍ̅ⲞⲘⲰⲤ ⲚⲒⲀⲦⲮⲨⲬⲎ ⲈⲨϮ ⲚⲦⲞⲨⲤⲘⲎ ⲒⲦⲈ ⲞⲨⲤⲎⲂⲒ ⲚϪⲰ ⲒⲦⲈ ⲞⲨⲔⲨⲐⲀⲢⲀ ⲀⲨϢⲦⲈⲘϢⲒⲂϮ ⲚⲦⲞⲨⲤⲘⲎ ⲠⲰⲤ ⲤⲈⲚⲀⲈⲘⲒ ⲈⲠⲈⲦⲞⲨϪⲰ ⲘⲘⲞϤ ⲒⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲞⲨⲈⲢⲔⲨⲐⲀⲢⲒⲌⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ.
8 Nítorí pé bi ohùn ìpè kò bá dájú, ta ni yóò múra fún ogun?
ⲏ̅ⲔⲈ ⲄⲀⲢ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲢⲈϢⲀⲚ ⲞⲨⲤⲀⲖⲠⲒⲄⲜ ϮⲚⲞⲨⲤⲘⲎ ⲈⲤⲞⲨⲞⲚϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲀⲚ ⲚⲒⲘ ⲈⲐⲚⲀϢⲤⲈⲂⲦⲰⲦϤ ⲈⲠⲠⲞⲖⲈⲘⲞⲤ.
9 Bẹ́ẹ̀ sí ni ẹ̀yin, bí kò ṣe pé ẹ̀yin bá ń fi ahọ́n yín sọ̀rọ̀ tí ó yé ni, a ó ti ṣe mọ ohun ti ẹ ń wí? Nítorí pé ẹ̀yin yóò kàn máa sọ̀rọ̀ si afẹ́fẹ́ lásán.
ⲑ̅ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ϨⲰⲦⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲪⲖⲀⲤ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲢⲈϢⲦⲈⲘϪⲈ ⲞⲨⲤⲀϪⲒ ⲈϤⲞⲨⲞⲚϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲠⲰⲤ ⲤⲈⲚⲀⲈⲘⲒ ⲈⲠⲈⲦⲈⲚϪⲰ ⲘⲘⲞϤ ⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲄⲀⲢ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲤⲀϪⲒ ⲈⲠⲀⲎⲢ.
10 Ó lé jẹ́ pé onírúurú ohùn èdè ní ń bẹ ní ayé, kò sí ọ̀kan tí kò ní ìtumọ̀.
ⲓ̅ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚϢⲖⲰⲖ ⲚⲤⲘⲎ ϦⲈⲚⲠⲀⲒⲔⲞⲤⲘⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲘⲞⲚ ϨⲖⲒ ⲈϤⲞⲒ ⲚⲀⲦⲤⲘⲎ.
11 Ǹjẹ́ bí èmí kò mọ ìtumọ̀ ohùn èdè náà, èmí ó jásí aláìgbédè sí ẹni tí ń sọ̀rọ̀, ẹni tí ń sọ̀rọ̀ yóò sí jásí aláìgbédè sí mi.
ⲓ̅ⲁ̅ⲈϢⲰⲠ ⲀⲒϢⲦⲈⲘⲈⲘⲒ ⲈⲦϪⲞⲘ ⲚⲦⲈϮⲤⲘⲎ ϮⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲈⲒⲞⲒ ⲘⲂⲀⲢⲂⲀⲢⲞⲤ ⲚⲦⲞⲦϤ ⲘⲠⲈⲦⲤⲀϪⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈⲦⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲎⲒ ϤⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲈϤⲞⲒ ⲘⲂⲀⲢⲂⲀⲢⲞⲤ ⲚⲦⲞⲦ.
12 Bẹ́ẹ̀ sì ní ẹ̀yin, bí ẹ̀yin ti ní ìtara fún ẹ̀bùn Ẹ̀mí, ẹ máa ṣe àfẹ́rí àti máa pọ̀ sí i fún ìdàgbàsókè ìjọ.
ⲓ̅ⲃ̅ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ϨⲰⲦⲈⲚ ⲈⲠⲒⲆⲎ ⲦⲈⲦⲈⲚⲞⲒ ⲚⲢⲈϤⲬⲞϨ ⲚⲚⲒⲠⲚⲀⲦⲒⲔⲞⲚ ⲈⲠⲔⲰⲦ ⲚⲦⲈϮⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ⲔⲰϮ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲦⲈⲚⲈⲢϨⲞⲨⲞ.
13 Nítorí náà jẹ́ ki ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ni èdè àìmọ̀ gbàdúrà ki ó lè máa ṣe ìtumọ̀ ohun tí ó sọ.
ⲓ̅ⲅ̅ⲈⲐⲂⲈⲪⲀⲒ ⲠⲈⲦⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲪⲖⲀⲤ ⲘⲀⲢⲈϤⲦⲰⲂϨ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤⲈⲢⲘⲈⲚⲈⲨⲒⲚ.
14 Nítorí bí èmi bá ń gbàdúrà ní èdè àìmọ̀, ẹ̀mí mi ni ń gbàdúrà, ṣùgbọ́n ọkàn mi jẹ́ aláìléso.
ⲓ̅ⲇ̅ⲈϢⲰⲠ ⲄⲀⲢ ⲀⲒϢⲀⲚⲦⲰⲂϨ ϦⲈⲚⲪⲖⲀⲤ ⲠⲀⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲠⲈⲦⲦⲰⲂϨ ⲠⲀϨⲎⲦ ⲆⲈ ϤⲞⲒ ⲚⲀⲦⲞⲨⲦⲀϨ.
15 Ǹjẹ́ kín ni èmi yóò ṣe? Èmi yóò fi ẹ̀mí mi gbàdúrà, èmi yóò sí fi òye mi gbàdúrà pẹ̀lú; Èmi yóò fi ẹ̀mí mi kọrin, èmi yóò sí fi òye mi kọrin pẹ̀lú.
ⲓ̅ⲉ̅ⲞⲨ ϪⲈ ⲠⲈϮⲚⲀⲀⲒϤ ϮⲚⲀⲦⲰⲂϨ ϦⲈⲚⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀϮⲚⲀⲦⲰⲂϨ ⲆⲈ ⲞⲚ ϦⲈⲚⲠⲒⲔⲈϨⲎⲦ ϮⲚⲀⲈⲢⲮⲀⲖⲒⲚ ϦⲈⲚⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀϮⲚⲀⲈⲢⲮⲀⲖⲒⲚ ⲆⲈ ⲞⲚ ϦⲈⲚⲠⲒⲔⲈϨⲎⲦ.
16 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ìwọ bá yin Ọlọ́run nípa ẹ̀mí, báwo ni ẹni tí ń bẹ ni ipò òpè yóò ṣe ṣe “Àmín” si ìdúpẹ́ rẹ, nígbà tí kò mọ ohun tí ìwọ wí?
ⲓ̅ⲋ̅ⲒⲈ ⲘⲘⲞⲚ ⲀⲔϢⲀⲚⲤⲘⲞⲨ ϦⲈⲚⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲠⲈⲦϪⲰⲔ ⲘⲪⲘⲀ ⲘⲠⲒⲒⲆⲒⲰⲦⲎⲤ ⲈⲂⲞⲖ ⲠⲰⲤ ϤⲚⲀϪⲈ ⲠⲒⲀⲘⲎⲚ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲈⲔϢⲈⲠϨⲘⲞⲦ ⲈⲠⲒⲆⲎ ⲠⲈⲦⲈⲔϪⲰ ⲘⲘⲞϤ ϤⲈⲘⲒ ⲈⲢⲞϤ ⲀⲚ.
17 Nítorí ìwọ dúpẹ́ gidigidi nítòótọ́, ṣùgbọ́n a kó fi ẹsẹ̀ ẹnìkejì rẹ múlẹ̀.
ⲓ̅ⲍ̅ⲚⲐⲞⲔ ⲄⲀⲢ ⲘⲈⲚ ⲔⲀⲖⲰⲤ ⲔϢⲈⲠϨⲘⲞⲦ ⲀⲖⲖⲀ ⲠⲒⲔⲈⲞⲨⲀⲒ ϤⲔⲎⲦ ⲀⲚ.
18 Mó dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run tí èmi ń fọ onírúurú èdè ju gbogbo yín lọ.
ⲓ̅ⲏ̅ϮϢⲈⲠϨⲘⲞⲦ ⲚⲦⲈⲚ ⲪⲚⲞⲨϮ ϪⲈ ϮⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲪⲖⲀⲤ ⲘⲀⲖⲖⲞⲚ ⲈϨⲞⲦⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ⲦⲎⲢⲞⲨ.
19 Ṣùgbọ́n mo fẹ́ kí n kúkú fi ọkàn mi sọ ọ̀rọ̀ márùn-ún ni inú ìjọ, kí n lè kọ́ àwọn ẹlòmíràn ju ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọ̀rọ̀ ni èdè àìmọ̀.
ⲓ̅ⲑ̅ⲀⲖⲖⲀ ϮⲞⲨⲰϢ ⲈϪⲈ ⲈⲚⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲠⲀⲔⲀϮ ϦⲈⲚϮⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲀⲈⲢⲔⲀⲦⲎⲬⲒⲚ ⲚϨⲀⲚⲔⲈⲬⲰⲞⲨⲚⲒ ⲈϨⲞⲦⲈ ⲞⲨⲐⲂⲀ ⲚⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲪⲖⲀⲤ.
20 Ará, ẹ má ṣe jẹ ọmọdé ni òye, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ ọmọdé ní àrankàn, ṣùgbọ́n ni òye ẹ jẹ́ àgbà.
ⲕ̅ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲘⲠⲈⲢⲈⲢⲀⲖⲞⲨ ϦⲈⲚⲚⲈⲦⲈⲚⲔⲀϮ ⲀⲖⲖⲀ ⲀⲢⲒⲀⲖⲞⲨ ϦⲈⲚϮⲔⲀⲔⲒⲀ ⲚϨⲢⲎⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚⲚⲈⲦⲈⲚⲔⲀϮ ϢⲰⲠⲒ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚϪⲎ ϪⲈⲂⲞⲖ.
21 A tí kọ ọ́ nínú òfin pé, “Nípa àwọn aláhọ́n mìíràn àti elétè àjèjì ní èmi ó fi ba àwọn ènìyàn yìí sọ̀rọ̀; síbẹ̀ wọn kì yóò gbọ́ tèmi,”
ⲕ̅ⲁ̅ⲤⲤϦⲎⲞⲨⲦ ⲄⲀⲢ ϨⲒ ⲪⲚⲞⲘⲞⲤ ϪⲈ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲔⲈⲖⲀⲤ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚⲔⲈⲤⲪⲞⲦⲞⲨ ϮⲚⲀⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘ ⲠⲀⲒⲖⲀⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲞⲚ ⲚⲚⲞⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲚⲤⲰⲒ ⲠⲈϪⲈ ⲠϬⲞⲒⲤ.
22 Nítorí náà àwọn ahọ́n jásí àmì kan, kì í ṣe fún àwọn tí ó gbàgbọ́, bí kò ṣe fún àwọn aláìgbàgbọ́: ṣùgbọ́n ìsọtẹ́lẹ̀ kì í ṣe fún àwọn tí kò gbàgbọ́ bí kò ṣe fún àwọn tí ó gbàgbọ́.
ⲕ̅ⲃ̅ϨⲰⲤⲦⲈ ⲚⲒⲖⲀⲤ ⲚⲀⲨⲬⲎ ⲈⲨⲘⲎⲒⲚⲒ ⲚⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀϨϮ ⲀⲚ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲒⲀⲐⲚⲀϨϮ ϮⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲒⲀ ⲆⲈ ⲚⲀⲤⲬⲎ ⲚⲚⲒⲀⲐⲚⲀϨϮ ⲀⲚ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀϨϮ.
23 Ǹjẹ́ bí gbogbo ìjọ bá péjọ sí ibi kan, tí gbogbo wọn sí ń fi èdè fọ̀, bí àwọn tí ó jẹ́ aláìlẹ́kọ̀ọ́ àti aláìgbàgbọ́ bá wọlé wá, wọn kí yóò ha wí pé ẹ̀yin ń ṣe òmùgọ̀?
ⲕ̅ⲅ̅ⲈϢⲰⲠ ⲞⲨⲚ ⲀⲤϢⲀⲚⲒ ⲈⲨⲘⲀ ⲚϪⲈϮⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ⲦⲎⲢⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲤⲈⲤⲀϪⲒ ⲦⲎⲢⲞⲨ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲖⲀⲤ ⲚⲤⲈⲒ ⲆⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲒⲆⲒⲰⲦⲎⲤ ⲒⲈ ϨⲀⲚⲀⲐⲚⲀϨϮ ⲘⲎ ⲤⲈⲚⲀϪⲞⲤ ⲀⲚ ϪⲈ ⲀⲢⲈ ⲚⲀⲒ ⲖⲞⲂⲒ.
24 Ṣùgbọ́n bí gbogbo yín bá ń sọtẹ́lẹ̀, ti ẹnìkan tí kò gbàgbọ́ tàbí tí ko ni ẹ̀kọ́ bá wọlé wá, gbogbo yin ní yóò fi òye ẹ̀ṣẹ̀ yé e, gbogbo yin ní yóò wádìí rẹ̀.
ⲕ̅ⲇ̅ⲈϢⲰⲠ ⲆⲈ ⲈⲨⲈⲢⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲈⲨⲒⲚ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲚⲦⲈϤⲒ ⲆⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲚϪⲈⲞⲨⲀⲐⲚⲀϨϮ ⲒⲈ ⲞⲨⲒⲆⲒⲰⲦⲎⲤ ⲤⲈⲚⲀⲤⲀϨⲰϤ ⲚϪⲈⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲤⲈⲚⲀϦⲈⲦϦⲰⲦϤ ⲚϪⲈⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ.
25 Bẹ́ẹ̀ ní a ó sì fi àṣírí ọkàn rẹ̀ hàn; bẹ́ẹ̀ ni òun ó sì dojúbolẹ̀, yóò sí sin Ọlọ́run yóò sì sọ pé, “Nítòótọ́ Ọlọ́run ń bẹ láàrín yín!”
ⲕ̅ⲉ̅ⲚⲎ ⲈⲦϨⲎⲠ ⲚⲦⲈⲠⲈϤϨⲎⲦ ⲤⲈⲚⲀⲞⲨⲞⲚϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ϤⲚⲀϨⲒⲦϤ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲈϤϨⲞ ⲚⲦⲈϤⲞⲨⲰϢⲦ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲈϤⲞⲨⲰⲚϨ ⲈⲂⲞⲖ ϪⲈ ⲞⲚⲦⲰⲤ ⲪⲚⲞⲨϮ ϢⲞⲠ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ.
26 Ǹjẹ́ èéha ti ṣe, kín ni àwa yóò sọ ẹ̀yin ará? Nígbà tí ẹ̀yin péjọpọ̀, tí olúkúlùkù yín ni Saamu kan tàbí ẹ̀kọ́ kan, èdè kan, ìfihàn kan àti ìtumọ̀ kan. Ẹ máa ṣe ohun gbogbo láti gbé ìjọ ró.
ⲕ̅ⲋ̅ⲞⲨ ϪⲈ ⲠⲈ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲈϢⲰⲠ ⲀⲢⲈⲦⲈⲚϢⲀⲚⲐⲰⲞⲨϮ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲠⲒⲞⲨⲀⲒ ⲞⲨⲞⲚⲦⲀϤ ⲚⲞⲨⲮⲀⲖⲘⲞⲤ ⲘⲘⲀⲨ ⲞⲨⲞⲚⲦⲀϤ ⲚⲞⲨⲤⲂⲰ ⲞⲨⲞⲚⲦⲀϤ ⲚⲞⲨϬⲰⲢⲠ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞⲚⲦⲀϤ ⲚⲞⲨⲀⲤⲠⲒ ⲚⲖⲀⲤ ⲞⲨⲞⲚⲦⲀϤ ⲚⲞⲨⲈⲢⲘⲎⲚⲒⲀ ϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲘⲀⲢⲞⲨϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲔⲰⲦ.
27 Bí ẹnìkan bá fi èdè fọ̀, kí ó jẹ ènìyàn méjì, tàbí bí ó pọ̀ tán, kí ó jẹ́ mẹ́ta, kí ó sọ̀rọ̀ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan, kí ẹnìkan sì túmọ̀ rẹ̀.
ⲕ̅ⲍ̅ⲒⲦⲈ ⲠⲈⲦⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲪⲖⲀⲤ ⲔⲀⲦⲀ ⲂⲂ ⲒⲈ ⲠⲒϨⲞⲨⲞ ⲄⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲘⲈⲢⲞⲤ ⲈⲪⲞⲨⲀⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲀⲢⲈ ⲞⲨⲀⲒ ⲈⲢⲘⲈⲚⲈⲨⲒⲚ.
28 Ṣùgbọ́n bí kò bá sí ògbufọ̀, kí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ nínú ìjọ; sì jẹ́ kí ó máa bá ara rẹ̀ àti Ọlọ́run sọ̀rọ̀.
ⲕ̅ⲏ̅ⲈϢⲰⲠ ⲆⲈ ⲚⲞⲨⲈⲢⲘⲈⲚⲈⲨⲦⲎⲤ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲘⲀⲢⲈϤⲬⲀⲢⲰϤ ϦⲈⲚϮⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ⲘⲀⲢⲈϤⲤⲀϪⲒ ⲆⲈ ⲞⲨⲦⲰϤ ⲚⲈⲘ ⲪⲚⲞⲨϮ.
29 Jẹ́ kí àwọn wòlíì méjì tàbí mẹ́ta sọ̀rọ̀, ki àwọn ìyókù sì wòye ìtumọ̀ ohun tí a sọ.
ⲕ̅ⲑ̅ⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲆⲈ ⲂⲒⲈ ⲄⲘⲀⲢⲞⲨⲤⲀϪⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲔⲈⲬⲰⲞⲨⲚⲒ ⲘⲀⲢⲞⲨⲈⲢⲆⲒⲀⲔⲢⲒⲚⲒⲚ.
30 Bí a bá sì fi ohunkóhun hàn ẹni tí ó jókòó níbẹ̀, jẹ́ kí ẹni tí ó kọ́ sọ̀rọ̀ ṣáájú dákẹ́.
ⲗ̅ⲈϢⲰⲠ ⲆⲈ ⲀⲢⲈϢⲀⲚ ⲞⲨϬⲰⲢⲠ ⲈⲂⲞⲖ ϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲔⲈⲞⲨⲀⲒ ⲈϤϨⲈⲘⲤⲒ ⲠⲒϨⲞⲨⲒⲦ ⲘⲀⲢⲈϤⲬⲀⲢⲞϤ.
31 Nítorí gbogbo yín lè sọtẹ́lẹ̀ ni ọ̀kọ̀ọ̀kan, kí gbogbo yín lè kọ́ ẹ̀kọ́, kí a lè tu gbogbo yín nínú.
ⲗ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲄⲀⲢ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲔⲀⲦⲀ ⲞⲨⲀⲒ ⲞⲨⲀⲒ ⲈⲈⲢⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲈⲨⲒⲚ ⲦⲎⲢⲞⲨ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲤⲈϬⲒⲤⲂⲰ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲤⲈϪⲈⲘⲚⲞⲘϮ ⲦⲎⲢⲞⲨ.
32 Ẹ̀mí àwọn wòlíì a sí máa tẹríba fún àwọn wòlíì.
ⲗ̅ⲃ̅ⲚⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲦⲈⲚⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ϢⲀⲨϬⲚⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲚⲒⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ.
33 Nítorí Ọlọ́run kì í ṣe Ọlọ́run ohun rúdurùdu, ṣùgbọ́n ti àlàáfíà. Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ nínú gbogbo ìjọ ènìyàn mímọ́.
ⲗ̅ⲅ̅ⲪⲚⲞⲨϮ ⲄⲀⲢ ⲪⲀ ⲪⲰⲢϪ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲀⲖⲖⲀ ⲪⲀ ⲦϨⲒⲢⲎⲚⲎ ⲠⲈ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲈⲦϢⲞⲠ ϦⲈⲚⲚⲒⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲚⲦⲈⲚⲎ ⲈⲐⲞⲨⲀⲂ.
34 Jẹ́ ki àwọn obìnrin yín dákẹ́ nínú ìjọ, nítorí a kò fi fún wọn láti sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí wọn wà lábẹ́ ìtẹríba, gẹ́gẹ́ bí òfin pẹ̀lú ti wí.
ⲗ̅ⲇ̅ⲚⲒϨⲒⲞⲘⲒ ⲘⲀⲢⲞⲨⲬⲀⲢⲰⲞⲨ ϦⲈⲚϮⲈⲔⲔⲖⲎ ⲤⲒⲀ ⲚⲤⲈⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲚⲰⲞⲨ ⲀⲚ ⲈⲤⲀϪⲒ ⲀⲖⲖⲀ ⲘⲀⲢⲞⲨϬⲚⲈϪⲰⲞⲨ ⲔⲀⲦⲀ ⲪⲢⲎϮ ⲈⲦⲈ ⲠⲒⲔⲈⲚⲞⲘⲞⲤ ϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ.
35 Bí wọ́n bá sì fẹ́ mọ̀ nípa ohunkóhun, kí wọn béèrè lọ́wọ́ ọkọ wọn ní ilé; nítorí ohun ìtìjú ni fún àwọn obìnrin láti máa sọ̀rọ̀ nínú ìjọ.
ⲗ̅ⲉ̅ⲒⲤϪⲈ ⲆⲈ ⲤⲈⲞⲨⲰϢ ⲈⲈⲘⲒ ⲈⲞⲨϨⲰⲂ ⲘⲀⲢⲞⲨϢⲈⲚ ⲚⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ϦⲈⲚⲚⲞⲨⲎⲒ ⲞⲨϢⲰϢ ⲄⲀⲢ ⲠⲈ ⲚⲞⲨⲤϨⲒⲘⲒ ⲈⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚϮⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ.
36 Kín ni? Ṣe lọ́dọ̀ yín ní ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ti jáde ni, tàbí ẹ̀yin nìkan ni o tọ̀ wá?
ⲗ̅ⲋ̅ϢⲀⲚ ⲈⲦⲀ ⲠⲤⲀϪⲒ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲒⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲐⲎⲚⲞⲨ ϢⲀⲚ ⲈⲦⲀϤⲪⲞϨ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ.
37 Bí ẹnikẹ́ni bá ró ará rẹ̀ pé òun jẹ́ wòlíì, tàbí òun jẹ́ ẹni tí ó ní ẹ̀bùn ẹ̀mí, jẹ́ kí nǹkan wọ̀nyí ti mo kọ sí yin yé e dájú pé òfin Olúwa ni wọ́n.
ⲗ̅ⲍ̅ⲒⲤϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲀⲒ ⲈϤⲘⲈⲨⲒ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲞⲨⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲠⲈ ⲒⲈ ⲞⲨⲠⲚⲀⲦⲒⲔⲞⲤ ⲠⲈ ⲘⲀⲢⲈϤⲈⲘⲒ ⲈⲚⲎ ⲈϮⲤϦⲀⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϪⲈ ⲞⲨⲈⲚⲦⲞⲖⲎ ⲚⲦⲈⲠϬⲞⲒⲤ ⲦⲈ.
38 Ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá fi ojú fo èyí dá, òun fúnra rẹ̀ ní a ó fi ojú fò dá.
ⲗ̅ⲏ̅ⲒⲤϪⲈ ⲆⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲀⲒ ⲈϤⲞⲒ ⲚⲀⲦⲈⲘⲒ ⲤⲈⲞⲒ ⲚⲀⲦⲈⲘⲒ ⲈⲢⲞϤ.
39 Nítorí náà ará, ẹ máa fi ìtara ṣàfẹ́rí láti sọtẹ́lẹ̀, kí ẹ má sì ṣe dánilẹ́kun láti fi èdè fọ̀.
ⲗ̅ⲑ̅ϨⲰⲤⲦⲈ ⲚⲀⲤⲚⲎⲞⲨ ⲬⲞϨ ⲈⲈⲢⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲈⲨⲒⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈⲢⲦⲀϨⲚⲞ ⲈⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲖⲀⲤ.
40 Ẹ máa ṣe ohun gbogbo tẹ̀yẹtẹ̀yẹ àti lẹ́sẹẹsẹ.
ⲙ̅ϨⲰⲂ ⲆⲈ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲘⲀⲢⲞⲨϢⲰⲠⲒ ⲈⲨⲔⲰⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲨⲐⲎϢ.

< 1 Corinthians 14 >