< 1 Corinthians 10 >
1 Nítorí èmi kò fẹ́ kí ẹ̀yin jẹ́ òpè si òtítọ́, ẹ̀yin arákùnrin ọ̀wọ́n, a kó gbọdọ̀ gbàgbé ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn wa nínú aginjù. Ọlọ́run ṣamọ̀nà wọn nípa rírán ìkùùkuu síwájú wọn, ó sì sìn wọ́n la omi Òkun pupa já.
ⲁ̅Ⲛ̇ϯⲟⲩⲉϣ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲧ⳿ⲉⲙⲓ ⲛⲁ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ϫⲉ ⲛⲉⲛⲓⲟϯ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲛⲁⲩⲭⲏ ϧⲁ ϯϭⲏⲡⲓ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲥⲓⲛⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲟⲙ.
2 A lè pe eléyìí ní ìtẹ̀bọmi ti Mose nínú ìkùùkuu àti nínú omi Òkun.
ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϭⲓⲱⲙⲥ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲉⲙⲱ⳿ⲩⲥⲏⲥ ϧⲉⲛ ϯϭⲏⲡⲓ ⲛⲉⲙ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲟⲙ.
3 Nípa iṣẹ́ ìyanu, gbogbo wọn jẹ oúnjẹ ẹ̀mí kan náà.
ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲧⲁⲓ⳿ϧⲣⲉ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⳿ⲙⲡⲛ̅ⲁ̅ⲧⲓⲕⲟⲛ ⲁⲩⲟⲩⲟⲙⲥ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
4 Wọ́n mu nínú omi tí Kristi fi fún wọn. Wọ́n mu omi ẹ̀mí láti inú àpáta tí ó ń tẹ̀lé wọn, àpáta náà ni Kristi. Ó wà pẹ̀lú wọn nínú aginjù náà, òun ni àpáta tí ń fi omi ẹ̀mí tu ọkàn lára.
ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲁⲓⲥⲱ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⳿ⲙⲡⲛ̅ⲁ̅ⲧⲓⲕⲟⲛ ⲁⲩⲥⲟϥ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲛⲁⲩⲥⲱ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲡⲛ̅ⲁ̅ⲧⲓⲕⲏ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲣⲁ ⲉⲥⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲥⲱⲟⲩ ϯⲡⲉⲧⲣⲁ ⲇⲉ ⲛⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲡⲉ.
5 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni inú Ọlọ́run kò dún sí; nítorí a pa wọ́n run nínú aginjù.
ⲉ̅ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲙⲡⲉ ⲫϯ ϯⲙⲁϯ ϧⲉⲛ ⲡⲟⲩϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲁⲩⲫⲱϣ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ϩⲓ ⳿ⲡϣⲁϥⲉ.
6 Àwọn nǹkan wọ̀nyí sì jásí àpẹẹrẹ fún àwa, kí a má ṣe ní ìfẹ́ sí àwọn ohun búburú gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn yìí ṣe ní ìfẹ́ si.
ⲋ̅ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⲁⲩϣⲱⲡⲓ ⲛⲁⲛ ⳿ⲛϩⲁⲛⲧⲩⲡⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲛⲧⲉⲛ⳿ϣⲧⲉⲙϣⲱⲡⲓ ⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲣⲉϥⲉⲣ⳿ⲉⲡⲓⲑⲩⲙⲓⲛ ⳿ⲛϩⲁⲛⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁ ⲛⲏ ⲉⲣ⳿ⲉⲡⲓⲑⲩⲙⲓⲛ.
7 Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe jẹ́ abọ̀rìṣà gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Àwọn ènìyàn náà jókòó láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì dìde dúró láti ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.”
ⲍ̅ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉⲛϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϣⲁⲙϣⲉ ⳿ⲓⲇⲱⲗⲟⲛ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧ⳿ⲥϧⲏ ⲟⲩⲧ ϫⲉ ⲁϥϩⲉⲙⲥⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲗⲁⲟⲥ ⳿ⲉⲟⲩⲱⲙ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉⲥⲱ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲧⲱⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲥⲱⲃⲓ.
8 Bẹ́ẹ̀ ni kí àwa kí ó má ṣe ṣe àgbèrè gẹ́gẹ́ bí àwọn mìíràn nínú wọn ti ṣe, tí ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé lẹgbẹ̀rún ènìyàn sì kú ní ọjọ́ kan.
ⲏ̅ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉⲛⲉⲣⲡⲟⲣⲛⲉⲩⲓⲛ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⳿ⲉⲁⲩⲉⲣⲡⲟⲣⲛⲉⲩⲓⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϩⲉⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⳿ⲛϫⲉ ⲕ̅ⲅ̅ ⳿ⲛϣⲟ.
9 Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin má ṣe dán Olúwa wò, gẹ́gẹ́ bí àwọn mìíràn nínú wọn ti dán an wò, tí a sì fi ejò run wọ́n.
ⲑ̅ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉⲛⲉⲣⲡⲓⲣⲁⲍⲓⲛ ⳿ⲙⲠⲭ̅ⲥ̅ ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⳿ⲉⲁⲩⲉⲣⲡⲓⲣⲁⲍⲓⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲧⲁⲕⲟ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓϩⲟϥ.
10 Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin kí ó má ṣe kùn, gẹ́gẹ́ bí àwọn mìíràn nínú wọ́n ṣe kùn, tí a sì ti ọwọ́ olùparun run wọ́n.
ⲓ̅ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉⲛⲉⲣ ⲣⲉⲣ⳿ⲭⲣⲉⲙⲣⲉⲙ ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⳿ⲉⲁⲩ⳿ⲭⲣⲉⲙⲣⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲧⲁⲕⲟ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲟⲧϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲉϥⲧⲁⲕⲟ.
11 Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣẹlẹ̀ sí wọn bí àpẹẹrẹ fún wa, a sì kọ̀wé wọn fún ìkìlọ̀ fún wa, àwa ẹni tí ìgbẹ̀yìn ayé dé bá. (aiōn )
ⲓ̅ⲁ̅ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲁⲩϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲧⲩⲡⲟⲥ ⳿ⲛⲛⲏ ⲁⲩ⳿ⲥϧⲏⲧⲟⲩ ⲇⲉ ⲛⲁⲛ ⲉⲩ⳿ⲥⲃⲱ ϧⲁ ⲛⲏ ⲉⲧⲁ ⳿ⲡϫⲱⲕ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓ⳿ⲉⲛⲉϩ ⲉⲣⲕⲁⲧⲁⲛⲧⲁⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ. (aiōn )
12 Nítorí náà, ẹni tí ó bá rò pé òun dúró, kí ó kíyèsára kí ó ma ba à ṣubú.
ⲓ̅ⲃ̅ϩⲱⲥⲧⲉ ⲫⲏⲉⲑⲙⲉⲩ⳿ⲓ ϫⲉ ⳿ϥⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧϥ ⲙⲁⲣⲉϥⲛⲁⲩ ⲙⲏⲡⲱⲥ ⳿ⲛⲧⲉϥϩⲉⲓ.
13 Kò sí ìdánwò kan tí ó ti bá yín, bí kò ṣe irú èyí tí ó mọ níwọ̀n fún ènìyàn, ṣùgbọ́n olódodo ni Ọlọ́run, ẹni ti kì yóò jẹ́ kí á dán an yín wò ju bí ẹ̀yin ti le gbà, ṣùgbọ́n tí yóò sì ṣe ọ̀nà àbáyọ pẹ̀lú nínú ìdánwò náà, kí ẹ̀yin ba à lè faradà á.
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲙⲡⲉ ⲡⲓⲣⲁⲥⲙⲟⲥ ⲧⲁϩⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⳿ⲉⲡⲓⲣⲁⲥⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲣⲱⲙⲓ ⳿ϥⲉⲛϩⲟⲧ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲫϯ ⲫⲏ ⲉⲧⲉ⳿ⲛ⳿ϥⲛⲁⲭⲁ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲁⲛ ⲉⲑⲣⲟⲩⲉⲣⲡⲓⲣⲁⲍⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲁⲗⲗⲁ ⲉϥ⳿ⲉϯⲧⲟⲧϥ ⲛⲉⲙⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲣⲁⲥⲙⲟⲥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ϣϫⲉⲙϫⲟⲙ ⳿ⲛϥⲁⲓ ϣⲁⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ.
14 Nítorí náà, ẹ̀yin olùfẹ́ ọ̀wọ́n, ẹ sá fún ìbọ̀rìṣà.
ⲓ̅ⲇ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲫⲁⲓ ⲛⲁⲙⲉⲛⲣⲁϯ ⲫⲱⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁ ϯⲙⲉⲧⲣⲉϥϣⲁⲙϣⲉ ⳿ⲓⲇⲱⲗⲟⲛ.
15 Èmi ń sọ̀rọ̀ bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn, ṣe ìdájọ́ fúnra rẹ̀ ohun tí mo sọ.
ⲓ̅ⲉ̅ⲁⲓϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛϩⲁⲛⲥⲁⲃⲉⲩ ⲙⲁϩⲁⲡ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲫⲏ⳿ⲉϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
16 Ǹjẹ́ ago ìdúpẹ́ nípasẹ̀ èyí tí a ń dúpẹ́ fún, kì í ha ṣe jíjẹ́ alábápín ìdàpọ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ Kristi bí? Àkàrà tí a bù, kì í ha ṣe jíjẹ́ alábápín nínú ara Kristi bi?
ⲓ̅ⲋ̅ⲡⲓⲁⲫⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲉⲩⲗⲟⲅⲓⲁ ⲫⲏⲉⲧⲉⲛ⳿ⲥⲙⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲙⲏ ϯⲙⲉⲧ⳿ϣⲫⲏⲣ ⲁⲛ ⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡ⳿ⲥⲛⲟϥ ⳿ⲙⲠⲭ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲱⲓⲕ ⳿ⲉⲧⲉⲛⲫⲱϣ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲙⲏ ϯⲙⲉⲧ⳿ϣⲫⲏⲣ ⲁⲛ ⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲡⲥⲱⲙⲁ ⳿ⲙⲠⲭ̅ⲥ.
17 Nítorí àkàrà kan ni ó ń bẹ, àwa tí a pọ̀ níye, tí a sì jẹ ara kan ń pín nínú àkàrà kan ṣoṣo.
ⲓ̅ⲍ̅ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲱⲓⲕ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲥⲱⲙⲁ ϧⲁ ⲛⲓⲙⲏϣ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲅⲁⲣ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲧⲉⲛϭⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲓⲱⲓⲕ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ.
18 Ẹ wo Israẹli nípa ti ara, àwọn tí ń jẹ ohun ẹbọ kò ha ṣe alábápín pẹpẹ bí?
ⲓ̅ⲏ̅⳿ⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲡⲓⲥ̅ⲗ̅ ⲕⲁⲧⲁ ⲥⲁⲣⲝ ⲙⲏ ⲛⲏ ⲁⲛ ⲉⲑⲟⲩⲱⲙ ⳿ⲛⲛⲓϣⲟⲩϣⲱⲟⲩϣⲓ ⲉⲧⲟⲓ ⳿ⲛ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲉⲡⲓⲙⲁ⳿ⲛⲉⲣϣⲱⲟⲩϣⲓ.
19 Ǹjẹ́ kí ni mo ń wí? Ṣé pé ohun tí a fi rú ẹbọ sí òrìṣà jẹ́ nǹkan kan tàbí pé òrìṣà jẹ́ nǹkan kan?
ⲓ̅ⲑ̅ⲟⲩ ϫⲉ ⲡⲉⲧϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϫⲉ ϣⲱⲧ ⳿ⲛ⳿ⲓⲇⲱⲗⲟⲛ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲓⲉ ϫⲉ ⲟⲩ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲡⲉ ⳿ⲓⲇⲱⲗⲟⲛ.
20 Rárá, ṣùgbọ́n ohun tí mo ń wí ni pé, ohun tí àwọn aláìkọlà fi ń rú ẹbọ wọn fi fun àwọn ẹ̀mí èṣù. Dájúdájú kì í ṣe ìrúbọ sí Ọlọ́run. Èmi kò sì fẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú yín so ara rẹ̀ pọ̀ mọ́ ẹ̀mí èṣù.
ⲕ̅ⲁⲗⲗⲁ ϫⲉ ⲛⲏⲉⲧⲟⲩϣⲱⲧ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲉⲑⲛⲟⲥ ⲁⲩϣⲱⲧ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓ⳿ⲓⲇⲱⲗⲟⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲫϯ ⲁⲛ ⳿ⲛϯⲟⲩⲉϣ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲇⲉ ⲁⲛ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲛⲛⲓⲇⲉⲙⲱⲛ.
21 Ẹ̀yin kò lè mu nínú ago tí Olúwa àti ago ti èṣù lẹ́ẹ̀kan náà; ẹ̀yin kò le ṣe àjọpín ní tábìlì Olúwa, àti ni tábìlì ẹ̀mí èṣù lẹ́ẹ̀kan náà.
ⲕ̅ⲁ̅⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲥⲱ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲁⲫⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲁⲫⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲇⲉⲙⲱⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉϭⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϯ⳿ⲧⲣⲁⲡⲉⲍⲁ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ⲛⲉⲙ ϯ⳿ⲧⲣⲁⲡⲉⲍⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲇⲉⲙⲱⲛ.
22 Kí ni ẹ̀ ń gbìyànjú láti ṣe? Àwa ha ń mú Olúwa jowú bí? Àwa ha ní agbára jù ú lọ bi?
ⲕ̅ⲃ̅ϣⲁⲛ ⲁⲛⲛⲁϯⲭⲟϩ ⳿ⲙⲠ⳪ ⲙⲏ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ϩⲁⲛϫⲱⲣⲓ ⳿ⲉϩⲟⲧⲉⲣⲟϥ.
23 “Ohun gbogbo ni o yẹ fún mi,” ṣùgbọ́n kì í ṣe ohun gbogbo ni ó ní èrè. “Ohun gbogbo ni ó yẹ fún mi,” ṣùgbọ́n kì í ṣe ohun gbogbo ni ń gbe ni rò.
ⲕ̅ⲅ̅⳿ⲥϣⲉ ⳿ⲛⲉⲣ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲛⲥⲉⲉⲣⲛⲟϥⲣⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲁⲛ ⲉⲝⲉⲥⲧⲓⲛ ⳿ⲉⲉⲣ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⲥⲉⲕⲱⲧ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲁⲛ.
24 Má ṣe ronú nípa ara rẹ̀ nìkan; ṣùgbọ́n kí olúkúlùkù máa wá rere ọmọnìkejì rẹ̀.
ⲕ̅ⲇ̅⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉ ⳿ϩⲗⲓ ⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲡⲉⲧⲉⲫⲱϥ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧϥ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲛⲥⲁ ⲫⲁ ⲡⲉϥ⳿ϣⲫⲏⲣ.
25 Jẹ ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá ń tà lọ́jà. Má ṣe gbìyànjú láti wádìí lọ́wọ́ ẹni tí ń tà á nítorí ẹ̀rí ọkàn.
ⲕ̅ⲉ̅ⲉⲛⲭⲁⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲟⲩϯ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲙⲁⲕⲉⲗⲗⲟⲥ ⲟⲩ⳿ⲟⲙⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϧⲟⲧϧⲉⲧ ⲁⲛ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ⲉⲑⲃⲉ ϯⲥⲩⲛⲏⲇⲏⲥⲓⲥ.
26 Nítorí “Ayé àti gbogbo nǹkan rere tí ń bẹ nínú rẹ̀, tí Olúwa ni wọ́n jẹ́.”
ⲕ̅ⲋ̅ⲫⲁ Ⲡ⳪ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ ⲛⲉⲙ ⲡⲉϥⲙⲟϩ.
27 Bí ẹnikẹ́ni tí kì í bá ṣe onígbàgbọ́ ba pè yín sí ibi àsè láti jẹun, bá a lọ. Gba ìpè rẹ̀ tí ó bá tẹ́ ọ lọ́rùn. Jẹ ohunkóhun tí ó bá pèsè sílẹ̀ fún àsè náà, má ṣe béèrè ohunkóhun nípa rẹ̀ nítorí ẹ̀rí ọkàn.
ⲕ̅ⲍ̅ⲓⲥϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲑⲛⲁϩϯ ⲑⲱϩⲉⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲱϣ ⲙⲁϣⲉ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲉⲛⲭⲁⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲟⲩⲛⲁⲭⲁⲩ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲟⲩ⳿ⲟⲙⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϧⲟⲧϧⲉⲧ ⲁⲛ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ⲉⲑⲃⲉ ϯⲥⲩⲛⲏⲇⲏⲥⲓⲥ.
28 Bí ẹnikẹ́ni bá sì kìlọ̀ fún un yín pé, “A ti fi ẹran yìí rú ẹbọ,” ẹ má ṣe jẹ́ ẹ nítorí ẹni ti o sọ fun ọ àti nítorí ẹ̀rí ọkàn.
ⲕ̅ⲏ̅⳿ⲉϣⲱⲡ ⲇⲉ ⲁⲣⲉϣⲁⲛ ⲟⲩⲁⲓ ϫⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ⲟⲩϣⲱⲧ ⳿ⲛ⳿ⲓⲇⲱⲗⲟⲛ ⲡⲉ ⲫⲁⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲟⲩⲱⲙ ⲉⲑⲃⲉ ⲫⲏⲉⲧⲁϥⲧⲁⲙⲱⲧⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⲉⲑⲃⲉ ϯⲥⲩⲛⲏⲇⲏⲥⲓⲥ.
29 Èmi ń sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀rí ọkàn ẹni tí ó sọ fún ọ kì í ṣe tirẹ̀. Nítorí kín ni a ó fi dá mi lẹ́jọ́ nítorí ẹ̀rí ọkàn ẹlòmíràn.
ⲕ̅ⲑ̅ϯϫⲱ ⲇⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩⲥⲩⲛⲏⲇⲏⲥⲓⲥ ⳿ⲛⲑⲱⲕ ⲁⲛ ⲧⲉ ⲁⲗⲗⲁ ⲑⲁ ⲡⲉⲕ⳿ϣⲫⲏⲣ ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⲧⲁⲙⲉⲧⲣⲉⲙϩⲉ ⲥⲉⲛⲁϯϩⲁⲡ ⳿ⲉⲣⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲕⲉⲥⲩⲛⲏⲇⲏⲥⲓⲥ.
30 Bí èmi ba fi ọpẹ́ jẹ ẹ́, èéṣe tí a fì ń sọ̀rọ̀ mi ní búburú nítorí ohun tí èmi dúpẹ́ fún.
ⲗ̅ⲓⲥϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϯϭⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ⲥⲉϫⲉⲟⲩ⳿ⲁ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲫⲏ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲉϯϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲱϥ.
31 Nítorí náà tí ẹ̀yin bá jẹ tàbí tí ẹ bá mu tàbí ohunkóhun tí ẹ̀yin bá sè, e máa ṣe gbogbo rẹ̀ fún ògo Ọlọ́run.
ⲗ̅ⲁ̅⳿ⲓⲧⲉ ⲟⲩⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲱⲙ ⳿ⲓⲧⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲱ ⳿ⲓⲧⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲓⲣⲓ ⳿ⲛⲕⲉϩⲱⲃ ⲁⲣⲓ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉ⳿ⲡϯⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲫϯ.
32 Nítorí náà, má ṣe jẹ́ òkúta ìkọ̀sẹ̀ tí ó lè gbé ẹlòmíràn ṣubú ìbá à ṣe Júù tàbí Giriki tàbí ìjọ Ọlọ́run.
ⲗ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ϣⲱⲡⲓ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲟⲓ ⳿ⲛⲁⲧ⳿ϭⲣⲟⲡ ⳿ⲛⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲟⲩⲉⲓⲛⲓⲛ ⲛⲉⲙ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
33 Bí mo ṣè n gbìyànjú láti tẹ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan lọ́rùn nínú gbogbo nǹkan tí mo bá ń ṣe láì wa ohun rere fún ara mi bí kò ṣe ti ènìyàn púpọ̀ kí ó lè ṣe é ṣe fún wọn láti le ní ìgbàlà.
ⲗ̅ⲅ̅ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲫⲣⲏϯ ϩⲱ ⲉⲧⲉ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϯⲣⲁⲛⲁϥ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲛϯⲕⲱϯ ⲁⲛ ⳿ⲛⲥⲁ ⲧⲁⲛⲟϥⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧ ⲁⲗⲗⲁ ⲑⲁ ⲛⲓⲙⲏϣ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉⲛⲟϩⲉⲙ.