< 1 Corinthians 1 >

1 Paulu, ẹni ti a pé láti jẹ́ aposteli Kristi Jesu nípa ìfẹ́ Ọlọ́run àti Sostene arákùnrin wa,
ⲁ̅ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⳿ⲡⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⲉⲧⲑⲁϩⲉⲙ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⳿ⲫⲟⲩⲱϣ ⳿ⲙⲫϯ ⲛⲉⲙ ⲥⲱⲥⲑⲉⲛⲏⲥ ⲡⲓⲥⲟⲛ.
2 Sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run ni Kọrinti, sí àwọn ti a sọ di mímọ́ nínú Kristi Jesu àti àwọn ti a pè láti jẹ́ mímọ́ pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ni ibikíbi ti ń pe orúkọ Olúwa wa Jesu Kristi ẹni ti ń ṣe Olúwa tiwọn àti ti àwa náà:
ⲃ̅⳿ⲛϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲑⲏⲉⲧϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⲕⲟⲣⲓⲛⲑⲟⲥ ⲛⲏⲉⲧⲁⲩⲧⲟⲩⲃⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲏⲉⲧⲑⲁϩⲉⲙ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉ⳿ⲫⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ϧⲉⲛ ⲙⲁⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲛⲧⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⳿ⲛⲧⲁⲛ.
3 Oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà fún yín láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa àti Olúwa wa tí í ṣe Jesu Kristi.
ⲅ̅⳿ⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⳿ⲧϩⲓⲣⲏⲛⲏ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲫϯ ⲡⲉⲛⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
4 Nígbà gbogbo ni mo ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run fún oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tó fi fún un yín nínú Kristi Jesu.
ⲇ̅ϯϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲡⲁⲛⲟⲩϯ ⳿ⲛⲥⲏⲟⲩ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲉⲧⲁⲩⲧⲏⲓϥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅.
5 Nítorí nínú rẹ̀ ni a ti sọ yín di ọlọ́rọ̀ nínú ọ̀rọ̀ sísọ yín gbogbo àti nínú ìmọ̀ yín gbogbo.
ⲉ̅ϫⲉ ϧⲉⲛ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲁⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ϧⲉⲛ ⲥⲁϫⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉⲙⲓ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
6 Nítorí ẹ̀rí wa nínú Kristi ni a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nínú yín.
ⲋ̅ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧⲁ ϯⲙⲉⲧⲙⲉⲑⲣⲉ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲧⲁϫⲣⲟ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
7 Nítorí náà ẹ̀yin kò ṣe aláìní nínú èyíkéyìí ẹ̀bùn ẹ̀mí, bí ẹ̀yin ṣe ń retí ìfarahàn Olúwa wa Jesu Kristi.
ⲍ̅ϩⲱⲥⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϣⲁⲧ ⲁⲛ ϧⲉⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲁ⳿ⲧϩⲏ ⳿ⲙⲡⲓϭⲱⲣⲡ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
8 Òun yóò sì mú yín dúró títí dé òpin, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ́ aláìlábùkù ní ọjọ́ Olúwa wa Jesu Kristi.
ⲏ̅ⲫⲁⲓ ⲉⲧⲉ ⲉϥ⳿ⲉⲧⲁϫⲣⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϣⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲁⲧⲁⲣⲓⲕⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲡ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
9 Ọlọ́run, nípasẹ̀ ẹni ti a pè yín sínú ìdàpọ̀ pẹ̀lú Ọmọ rẹ̀ Jesu Kristi Olúwa wa, jẹ́ Olóòtítọ́.
ⲑ̅⳿ϥⲉⲛϩⲟⲧ ⳿ⲛϫⲉ ⲫϯ ⲫⲏⲉⲧⲁϥⲑⲁϩⲉⲙ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉϯⲙⲉⲧ⳿ϣⲫⲏⲣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉϥϣⲏⲣⲓ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲡⲉⲛ⳪.
10 Mo bẹ̀ yín ẹ̀yin ara, ní orúkọ Olúwa wa Jesu Kristi, pé kí gbogbo yín fohùn ṣọ̀kan kí ó máa ṣe sí ìyapa láàrín yín, àti pé kí a lè ṣe yín pé ní inú àti ìmọ̀ kan náà.
ⲓ̅ϯϯϩⲟ ⲇⲉ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⲛⲁⲥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⳿ⲫⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ϩⲓⲛⲁ ⲟⲩⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ϩⲁⲛⲫⲱⲣϫ ϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛϣⲱⲡⲓ ⲇⲉ ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲥⲉⲃⲧⲱⲧ ϧⲉⲛ ⲟⲩϩⲏⲧ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲟⲩ⳿ⲅⲛⲱⲙⲏ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲧ.
11 Ẹ̀yin ará mi, àwọn kan láti ilé Kloe sọ di mí mọ̀ fún mi pé ìjà ń bẹ́ láàrín yín.
ⲓ̅ⲁ̅ⲁⲩⲧⲁⲙⲟⲓ ⲅⲁⲣ ⲉⲑⲃⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲛⲁ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲛⲁ⳿ⲭⲗⲟⲏⲥ ϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ϩⲁⲛ⳿ϣϭⲛⲏⲛ ϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
12 Ohun tí mo ń sọ ní pé, olúkúlùkù yín ń wí pé, “Èmí tẹ̀lé Paulu”; “Èmi tẹ̀lé Apollo”; òmíràn wí pé, “Èmi tẹ̀lé Kefa, Peteru”; àti ẹlòmíràn wí pé, “Èmi tẹ̀lé Kristi.”
ⲓ̅ⲃ̅ⲫⲁⲓ ⲇⲉ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϫⲉ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⲡⲓⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲙⲉⲛ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲫⲁ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲫⲁ ⲁⲡⲟⲗⲗⲱ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲫⲁ ⲕⲏⲫⲁ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲫⲁ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
13 Ǹjẹ́ a ha pín Kristi bí? Ṣé a kan Paulu mọ́ àgbélébùú fún un yín bí? Ǹjẹ́ a tẹ̀ yín bọ omi ní orúkọ Paulu bí?
ⲓ̅ⲅ̅ⲁⲩⲫⲉϣ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲙⲏ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲁⲩⲁϣϥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲓⲉ ⲁⲛ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϭⲓⲱⲙⲥ ⳿ⲉ⳿ⲫⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲩⲗⲟⲥ.
14 Inú mi dún púpọ̀ pé èmi kò tẹ ẹnikẹ́ni nínú yín bọ omi yàtọ̀ sí Krisipu àti Gaiusi.
ⲓ̅ⲇ̅ϯϣⲉⲡ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲡⲁⲛⲟⲩϯ ϫⲉ ⳿ⲙⲡⲓϯⲱⲙⲥ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⳿ⲉ⳿ⲕⲣⲓⲥⲡⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲅⲁⲓⲟⲥ.
15 Nítorí náà kò sí ẹni tí ó lè sọ pé òun ṣe ìtẹ̀bọmi ní orúkọ èmi fúnra ara mi.
ⲓ̅ⲉ̅ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ⲟⲩⲁⲓ ϫⲟⲥ ϫⲉ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛ ϭ- ⲓⲱⲙⲥ ⳿ⲉⲡⲁⲣⲁⲛ.
16 (Bẹ́ẹ̀ ni, mo tún tẹ ìdílé Stefana bọ omi; lẹ́yìn èyí, èmí kò rántí pé mo tẹ ẹnikẹ́ni bọ omi mọ́ níbikíbi).
ⲓ̅ⲋ̅ⲁⲓϯⲱⲙⲥ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲓⲕⲉⲏⲓ ⳿ⲛ⳿ⲥⲧⲉⲫⲁⲛⲁ ⲗⲟⲓⲡⲟⲛ ⳿ⲛϯ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲁⲛ ⲁⲓϯⲱⲙⲥ ⳿ⲛⲕⲉⲟⲩⲁⲓ.
17 Nítorí Kristi kò rán mi láti máa ṣe ìtẹ̀bọmi, ṣùgbọ́n ó rán mi láti máa wàásù ìyìnrere: kì í ṣe nípa ọgbọ́n ènìyàn, kí a máa ṣe sọ àgbélébùú Kristi dí aláìlágbára.
ⲓ̅ⲍ̅ⲛⲉⲧⲁϥⲧⲁⲟⲩⲟⲓ ⲅⲁⲣ ⲁⲛ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲉϯⲱⲙⲥ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲉϩⲓϣⲉⲛⲛⲟⲩϥⲓ ϧⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛⲥⲁϫⲓ ⲁⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙϣⲱⲡⲓ ⲉϥϣⲟⲩⲓⲧ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓ⳧ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
18 Nítorí pé òmùgọ̀ ni ọ̀rọ̀ àgbélébùú jẹ́ sí àwọn tí ń ṣègbé, ṣùgbọ́n fún àwa tí a ń gbàlà ó jẹ́ agbára Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲏ̅ⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓ⳧ ⳿ⲛⲧⲉⲛ ⲛⲏ ⲙⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁⲧⲁⲕⲟ ⲟⲩⲙⲉⲧⲥⲟϫ ⲡⲉ ⲛⲁⲛ ⲇⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ϧⲁ ⲛⲏⲉⲑⲛⲁⲛⲟϩⲉⲙ ⲟⲩϫⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲡⲉ.
19 Nítorí a tí kọ ọ́ pé: “Èmi yóò pa ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n run, òye àwọn olóye ni Èmi yóò sọ di asán.”
ⲓ̅ⲑ̅⳿ⲥ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ⲅⲁⲣ ϫⲉ ϯⲛⲁⲧⲁⲕⲟ ⳿ⲛ⳿ⲧⲥⲟⲫⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲥⲁⲃⲉⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲡ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲕⲁⲧϩⲏⲧ ϯⲛⲁϣⲟϣϥ.
20 Àwọn ọlọ́gbọ́n náà ha dá? Àwọn akọ̀wé náà ha dà? Àwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ ayé yìí ha dà? Ọlọ́run kò ha ti sọ ọgbọ́n ayé yìí di aṣiwèrè? (aiōn g165)
ⲕ̅ⲁϥⲑⲱⲛ ⲟⲩⲥⲁⲃⲉ ⲁϥⲑⲱⲛ ⲟⲩⲥⲁϧ ⲁϥⲑⲱⲛ ⲟⲩⲣⲉϥϧⲟⲧϧⲉⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓⲉⲛⲉϩ ⲙⲏ ⳿ⲙⲡⲉ ⲫϯ ⲉⲣ ⳿ⲧⲥⲟⲫⲓ⳿ⲁ ⲛ̇ⲧⲉ ⲡⲁⲓ ⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲥⲟϫ. (aiōn g165)
21 Nítorí pé, nínú ọgbọ́n Ọlọ́run, ayé kò le mọ̀ òun nípa ọgbọ́n àti ìṣeféfé wọn. Ó sì gba gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́ là nípa ìwàásù tí àwọn aráyé pè ní òmùgọ̀ àti ọ̀rọ̀ ọ yẹ̀yẹ́.
ⲕ̅ⲁ̅⳿ⲉⲡⲓⲇⲏ ⲅⲁⲣ ϧⲉⲛ ϯⲥⲟⲫⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⳿ⲙⲡⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲥⲟⲩⲉⲛ ⲫϯ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ϯⲥⲟⲫⲓ⳿ⲁ ⲁϥϯⲙⲁϯ ⳿ⲛϫⲉ ⲫϯ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ϯⲙⲉⲧⲥⲟϫ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲉⲛⲟϩⲉⲙ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲑⲛⲁϩϯ.
22 Nítorí pé àwọn Júù ń béèrè àmì, àwọn Helleni sí ń ṣàfẹ́rí ọgbọ́n,
ⲕ̅ⲃ̅ⲉⲡⲓⲇⲏ ⲛⲓⲕⲉⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲥⲉⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲛϩⲁⲛⲙⲏⲓⲛⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲟⲩⲉⲓⲛⲓⲛ ⲥⲉⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲟⲩⲥⲟⲫⲓ⳿ⲁ.
23 ṣùgbọ́n àwa ń wàásù Kristi ti a kàn mọ́ àgbélébùú, òkúta ìkọ̀sẹ̀ àwọn Júù àti òmùgọ̀ fún àwọn kèfèrí.
ⲕ̅ⲅ̅⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲇⲉ ⲧⲉⲛϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲙⲠⲭ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲁⲩⲁϣϥ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲙⲉⲛ ⲟⲩ⳿ⲥⲕⲁⲛⲇⲁⲗⲟⲛ ⲛⲱⲟⲩ ⲡⲉ ⲛⲓⲉⲑⲛⲟⲥ ⲇⲉ ⲟⲩⲙⲉⲧⲥⲟϫ ⲡⲉ.
24 Ṣùgbọ́n sí àwọn tí Ọlọ́run tí pè, àti àwọn Júù àti àwọn Giriki, Kristi ni agbára Ọlọ́run, àti ọgbọ́n Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲇ̅ⲛⲁⲛ ⲇⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ϧⲁ ⲛⲏⲉⲑⲛⲁⲛⲟϩⲉⲙ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲟⲩⲉⲓⲛⲓⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲟⲩϫⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲡⲉ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲥⲟⲫⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
25 Nítorí pé òmùgọ̀ Ọlọ́run jù ọgbọ́n ènìyàn lọ; àti aláìlera Ọlọ́run ni agbára jù ìlera ènìyàn lọ.
ⲕ̅ⲉ̅ϫⲉ ϯⲙⲉⲧⲥⲟϫ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⳿ⲥⲟⲓ ⳿ⲛⲥⲁⲃⲉ ⳿ⲉϩⲟⲧⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ϯⲙⲉⲧⲁⲥⲑⲏⲛⲏⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⳿ⲥⲟⲓ ⳿ⲛϫⲱⲣⲓ ⲉϩⲟⲧⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ.
26 Ará, ẹ kíyèsi ohun tí ẹ jẹ́ nígbà tí a pè yín. Kì í ṣe ọ̀pọ̀ yín jẹ ọlọ́gbọ́n nípa àgbékalẹ̀ ti ènìyàn, tàbí ọ̀pọ̀ nínú yín jẹ́ ènìyàn pàtàkì, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ọ̀pọ̀ nínú yín jẹ́ ọlọ́lá nípa ibi tí a gbé bí i.
ⲕ̅ⲋ̅⳿ⲁⲛⲁⲩ ⲅⲁⲣ ⳿ⲉⲡⲉⲧⲉⲛⲑⲱϩⲉⲙ ⲛⲁ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲥⲁⲃⲉ ⲕⲁⲧⲁ ⲥⲁⲣⲝ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛϫⲱⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲉⲩⲅⲉⲛⲏⲥ.
27 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tí yàn àwọn òmùgọ̀ ayé láti fi dààmú àwọn ọlọ́gbọ́n; Ọlọ́run sì ti yàn àwọn ohun aláìlera ayé láti fi dààmú àwọn ohun tí ó ni agbára.
ⲕ̅ⲍ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲛⲓⲥⲟϫ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲁϥⲥⲟⲧⲡⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲫϯ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥϯϣⲓⲡⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲥⲁⲃⲉⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲙⲉⲧϫⲱⲃ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲁϥⲥⲟⲧⲡⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲫϯ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥϯϣⲓⲡⲓ ⳿ⲛⲛⲓϫⲱⲣⲓ.
28 Àti àwọn ohun tí ayé tí kò ní ìyìn, àti àwọn ohun tí a kẹ́gàn, ni Ọlọ́run sì ti yàn, àní àwọn ohun tí kò sí, láti sọ àwọn ohun tí ó wà di asán.
ⲕ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲙⲉⲧⲁⲅⲉⲛⲏⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲏ ⲉⲧϣⲟϣϥ ⲁϥⲥⲟⲧⲡⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲫϯ ⲛⲉⲙ ⲛⲏ ⲉⲧⲉ⳿ⲛⲥⲉϣⲟⲡ ⲁⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥⲕⲱⲣϥ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧϣⲟⲡ.
29 Nítorí kí ó má ba à sí ẹnìkan tí yóò ṣògo níwájú rẹ̀.
ⲕ̅ⲑ̅ϩⲟⲡⲱⲥ ⳿ⲛⲧⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ⲥⲁⲣⲝ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϣⲟⲩϣⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲙⲫϯ.
30 Nítorí rẹ̀ ni ẹ̀yin ṣe wà nínú Kristi Jesu ẹni ti ó jásí ọgbọ́n fún wa láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run—èyí ń ni, òdodo, ìwà mímọ́ àti ìràpadà wa.
ⲗ̅⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϩⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲫⲏⲉⲧⲁϥϣⲱⲡⲓ ⲛⲁⲛ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲟⲫⲓ⳿ⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⲫϯ ⲟⲩⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲧⲟⲩⲃⲟ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲥⲱϯ.
31 Nítorí náà, bí a ti kọ ọ́ pé, “Ẹni ti ó bá ń ṣògo kí ó máa ṣògo nínú Olúwa.”
ⲗ̅ⲁ̅ϩⲓⲛⲁ ⲕⲁⲧⲁ ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ϫⲉ ⲡⲉⲧϣⲟⲩϣⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲙⲁⲣⲉϥϣⲟⲩϣⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϧⲉⲛ Ⲡ⳪.

< 1 Corinthians 1 >