< 1 Chronicles 9 >

1 Gbogbo Israẹli ni a kọ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá nínú ìwé àwọn ọba Israẹli. Àwọn ènìyàn Juda ni a kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli nítorí àìṣòótọ́ wọn.
Och hele Israel vardt räknad, och si, de äro uppskrifne i Israels och Juda Konungars bok, och nu bortförde till Babel för sina missgerningars skull;
2 Nísinsin yìí, àwọn tí ó kọ́kọ́ tún tẹ̀dó lórí ohun ìní wọn ní ìlú wọn ni díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa.
De som tillförene bodde på sina ägor och städer, nämliga Israel, Prester, Leviter och de Nethinim.
3 Àwọn tí ó wá láti Juda láti Benjamini àti láti Efraimu àti Manase tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu jẹ́:
Men i Jerusalem bodde någre af Juda barn, någre af BenJamins barn, någre af Ephraims och Manasse barn;
4 Uttai ọmọ Ammihudu, ọmọ Omri, ọmọ Imri, ọmọ Bani, ìran ọmọ Peresi ọmọ Juda.
Nämliga utaf Perez barn, Juda sons, var Athai, Ammihuds son, Omri sons, Imri sons, Bani sons;
5 Àti nínú ará Ṣilo: Asaiah àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Men af Siloni, Asaja förste sonen, och hans andre söner.
6 Ní ti ará Sera: Jeueli. Àwọn ènìyàn láti Juda sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́wàá.
Af Serahs barn, Jeguel och deras bröder, sexhundrad och niotio.
7 Àti nínú àwọn ọmọ Benjamini ni: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Hodafiah; ọmọ Hasenuah;
Af BenJamins barn, Sallu, Mesullams son, Hodavia sons, Hassenua sons,
8 Ibinaiah ọmọ Jerohamu; Ela ọmọ Ussi, ọmọ Mikri; àti Meṣullamu ọmọ Ṣefatia; ọmọ Reueli, ọmọ Ibinijah.
Och Jibneja, Jerohams son. Och Ela, Ussi son, Michri sons, och Mesullam, Sephatia son, Reguels sons, Jibneja sons;
9 Àwọn ènìyàn láti Benjamini gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ ọ́ nínú ìran wọn nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó dín mẹ́rìnlélógójì. Gbogbo àwọn ọkùnrin yí jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé.
Dertill deras bröder uti deras ätter, niohundrad och sex och femtio. Alle desse männerna voro höfvitsmän för fäderna uti deras fäders hus.
10 Ní ti àwọn àlùfáà: Jedaiah; Jehoiaribi; Jakini;
Af Presterna, Jedaja, Jojarib, Jachin;
11 Asariah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, olórí tí ó ń bojútó ilé Ọlọ́run;
Och Asaria, Hilkia son, Mesullams sons, Zadoks sons, Merajoths sons, Ahitobs sons, en Förste i Guds hus;
12 Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah; àti Masai ọmọ Adieli, ọmọ Jahisera, ọmọ Meṣullamu ọmọ Meṣilemiti, ọmọ Immeri.
Och Adaja, Jerohams son, Pashurs sons, Malchia sons; och Masai, Adiels son, Jahsera sons, Mesullams sons, Mesillemiths sons, Immers sons;
13 Àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀sán ó dín méjì. Wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin, tí wọ́n lè dúró fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run.
Dertill deras bröder höfvitsmän i deras fäders huse, tusende sjuhundrad och sextio starke män, till att beställa hvad ämbetet tillhörde i Guds hus.
14 Ní ti àwọn ará Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ará Merari;
Men af Leviterna, af Merari barnom, Semaja, Hasubs son, Asrikams sons, Hasabia sons,
15 Bakibakari, Hereṣi, Galali àti Mattaniah, ọmọ Mika, ọmọ Sikri, ọmọ Asafu;
Och Bakbakkar, den timbermannen, och Galal; och Matthania, Micha son, Sichri sons, Assaphs sons,
16 Obadiah ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni; àti Berekiah ọmọ Asa, ọmọ Elkana, tí ó ń gbé nínú àwọn ìlú àwọn ará Netofa.
Och Obadja, Semaja son, Galals sons, Jeduthuns sons, och Berechia, Asa son, Elkana sons, den som uti de Netophathiters byar bodde.
17 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà: Ṣallumu, Akkubu, Talmoni, Ahimani àti arákùnrin wọn, Ṣalumu olóyè wọn,
Dörravaktarena voro: Sallum, Akkub, Talmon, Ahiman, med deras bröder; och Sallum, öfversten.
18 ti wà ní ipò ìdúró ní ẹnu-ọ̀nà ọba ní apá ìhà ìlà-oòrùn títí di àkókò yí. Wọ̀nyí ni àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí ó jẹ́ ti ìpàgọ́ àwọn ará Lefi.
Ty härtill hade vaktat för Konungsporten östantill Levi barn, i lägre,
19 Ṣallumu ọmọ Kore ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora, àti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Láti ìdílé rẹ̀ (àwọn ará Korati) ni ó dúró fún ṣíṣọ́ ìloro ẹnu-ọ̀nà àgọ́ gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti ń dúró fún ṣíṣọ́ àbáwọlé ibùgbé Olúwa.
Sallum, Kore son, Ebiasaphs sons, Korahs sons, och hans bröder utu hans faders hus, de Korhiter, vid ämbetets sysslo, att de vaktade vid tabernaklets dörrar, och deras fader i Herrans lägre, att de skulle vakta på ingången.
20 Ní ìgbà àkọ́kọ́ Finehasi ọmọ Eleasari jẹ́ olórí fún àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà, Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Men Pinehas, Eleazars son, var Försten öfver dem, derföre att Herren hade tillförene varit med honom.
21 Sekariah, ọmọ Meṣelemiah jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àbáwọlé sí àgọ́ ibi ìpàdé.
Zacharia, Meselemia son, var väktare vid vittnesbördsens tabernakels dörr.
22 Gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, àwọn tí a yàn láti jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àwọn ìloro jẹ́ igba ó lé méjìlá. A ka àwọn wọ̀nyí nípa ìdílé ní ìletò wọn. Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ni a ti yàn sí ipò láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Samuẹli, aríran, nítorí òtítọ́ wọn.
Alle desse voro utvalde till väktare vid dörrarna, tuhundrad och tolf. De voro räknade i deras byar. Och David och Samuel Siaren stiktade dem genom deras tro;
23 Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ni ó wà fún ṣíṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ilé tí a pè ní àgọ́.
Att de och deras barn skulle taga vara på Herrans hus, nämliga på tabernaklets hus, att de det vakta skulle.
24 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà wà ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin: ìlà-oòrùn, ìwọ̀-oòrùn àríwá àti gúúsù.
De samme dörravaktare voro ställde på fyra sidor, östan, vestan, norr, söder.
25 Àwọn arákùnrin wọn ní àwọn ìletò wọn ní láti wá ní àkókò dé àkókò láti pín iṣẹ́ ìsìn wọn fún àkókò ọjọ́ méje.
Men deras bröder voro i sina byar, så att de ju inkommo på sjunde dagen, till att alltid vara när dem.
26 Ṣùgbọ́n àwọn olórí alábojútó ẹnu-ọ̀nà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ni a yàn fún àwọn iyàrá àti àwọn àpótí ìṣúra ní ilé Ọlọ́run.
Förty Leviterna voro dessom fyra öfversta dörravaktaromen betrodde, och de voro öfver kistorna och skatten i Guds hus;
27 Wọ́n á lo gbogbo òru ní dídúró yí ilé Ọlọ́run ká, nítorí wọ́n ní láti ṣọ́ ọ, wọ́n sì ní àṣẹ sí kọ́kọ́rọ́ fún ṣíṣí i ní àràárọ̀.
Och blefvo de öfver nattena omkring Guds hus; ty dem hörde vakten till, att de skulle upplåta hvar morgon.
28 Díẹ̀ wà ní ìdí ohun èlò tí à ń lò fún ìsìn ilé Ọlọ́run; wọn a máa kà á nígbà tí wọ́n gbé e wọlé àti nígbà tí a kó wọn jáde.
Och somlige af dem voro öfver ämbetstygen; förty de båro dem tald ut och in.
29 Àwọn mìíràn ni a yàn láti bojútó ohun èlò àti gbogbo ohun èlò ilé tí a yà sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run, àti ìyẹ̀fun àti ọtí èso àjàrà àti òróró náà, tùràrí àti tùràrí olóòórùn dídùn.
Och somlige af dem voro beställde öfver kärilen, och öfver all helig redskap; öfver semlomjöl, öfver vin, öfver oljo, öfver rökelse, öfver rökverk.
30 Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn àlùfáà ni ó ń bojútó pípò tùràrí olóòórùn dídùn papọ̀.
Men Presternas barn gjorde somlige rökverk.
31 Ará Lefi tí a sọ ní Mattitiah àkọ́bí ọmọkùnrin Ṣallumu ará Kora ni a yàn, tí ń ṣe alábojútó ohun tí a dín.
Mattithia utaf Leviterna, dem första Sallums sone, den Korhitens, voro betrodda pannorna.
32 Àti nínú àwọn arákùnrin wọn, nínú àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣe ìtọ́jú àkàrà ìfihàn, láti máa pèsè rẹ̀ ní ọjọọjọ́ ìsinmi.
Utaf de Kehathiter deras bröder, voro till att bereda skådobröden, så att de tillredde dem på hvar Sabbathsdag.
33 Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Lefi dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì ṣe lára iṣẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ náà lọ́sàn, lóru.
Desse äro de sångare, höfvitsmän ibland Leviternas fäder, öfver kistorna skickade; förty dag och natt voro de der öfver i sysslomen.
34 Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Lefi, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Desse äro höfvitsmän förfäderna ibland Leviterna uti deras ätter; och bodde i Jerusalem.
35 Jeieli baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka,
I Gibeon bodde Jegiel, Gibeons fader; hans hustru het Maacha;
36 pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀ jẹ́ Abdoni, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu.
Och hans förste son Abdon, Zur, Kis, Baal, Ner, Nadab,
37 Gedori, Ahio, Sekariah àti Mikiloti.
Gedor, Ahio, Zacharia, Mikloth.
38 Mikiloti jẹ́ baba Ṣimeamu, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
Men Mikloth födde Simeam; de bodde också omkring deras bröder i Jerusalem, ibland sina bröder.
39 Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba a Saulu, àti Saulu baba a Jonatani, àti Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
Ner födde Kis. Kis födde Saul. Saul födde Jonathan, MalchiSua, AbiNadab, Esbaal.
40 Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali, tí ó jẹ́ baba Mika.
Jonathans son var Meribaal; Meribaal födde Micha.
41 Àwọn ọmọ Mika: Pitoni. Meleki, Tarea àti Ahasi.
Micha barn voro: Pithon, Melech och Thahrea.
42 Ahasi jẹ́ baba Jada, Jada jẹ́ baba Alemeti, Asmafeti, Simri, sì Simri jẹ́ baba Mosa.
Ahas födde Jaera. Jaera födde Alemeth, Asmaveth och Simri. Simri födde Moza.
43 Mosa jẹ́ baba Binea; Refaiah jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
Moza födde Binea. Hans son var Rephaja, Hans son var Eleasa. Hans son var Azel.
44 Aseli ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli Ṣeariah, Obadiah àti Hanani, gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
Azel hade sex söner; de heto: Asrikam, Bochru, Ismael, Searia, Obadja, Hanan. Desse äro Azels barn.

< 1 Chronicles 9 >