< 1 Chronicles 9 >
1 Gbogbo Israẹli ni a kọ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá nínú ìwé àwọn ọba Israẹli. Àwọn ènìyàn Juda ni a kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli nítorí àìṣòótọ́ wọn.
Tak wszyscy Izraelici byli spisani w rodowodach, a oto zostały one zapisane w księdze królów Izraela i Judy, [a] ci zostali uprowadzeni do Babilonu z powodu swego przestępstwa.
2 Nísinsin yìí, àwọn tí ó kọ́kọ́ tún tẹ̀dó lórí ohun ìní wọn ní ìlú wọn ni díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa.
Pierwszymi mieszkańcami, którzy weszli do swych posiadłości w swoich miastach, byli Izraelici, kapłani, Lewici i Netinici.
3 Àwọn tí ó wá láti Juda láti Benjamini àti láti Efraimu àti Manase tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu jẹ́:
W Jerozolimie mieszkali spośród synów Judy, Beniamina, Efraima i Manassesa:
4 Uttai ọmọ Ammihudu, ọmọ Omri, ọmọ Imri, ọmọ Bani, ìran ọmọ Peresi ọmọ Juda.
Utaj, syn Ammihuda, syna Omriego, syna Imriego, syna Baniego, z synów Peresa, syna Judy.
5 Àti nínú ará Ṣilo: Asaiah àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Z Szilonitów: pierworodny Asajasz i jego synowie.
6 Ní ti ará Sera: Jeueli. Àwọn ènìyàn láti Juda sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́wàá.
Z synów Zeracha: Jeuel i ich braci, sześciuset dziewięćdziesięciu.
7 Àti nínú àwọn ọmọ Benjamini ni: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Hodafiah; ọmọ Hasenuah;
Z synów Beniamina: Sallu, syn Meszullama, syna Hodawiasza, syna Hassenuy;
8 Ibinaiah ọmọ Jerohamu; Ela ọmọ Ussi, ọmọ Mikri; àti Meṣullamu ọmọ Ṣefatia; ọmọ Reueli, ọmọ Ibinijah.
I Jibnejasz, syn Jerochama, Ela, syn Uzziego, syna Mikriego, i Meszullam, syn Szefatiasza, syna Reuela, syna Jibniasza.
9 Àwọn ènìyàn láti Benjamini gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ ọ́ nínú ìran wọn nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó dín mẹ́rìnlélógójì. Gbogbo àwọn ọkùnrin yí jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé.
Ich braci według rodowodów [było] dziewięćset pięćdziesięciu sześciu. Ci wszyscy [byli] naczelnikami rodów według domów swoich ojców.
10 Ní ti àwọn àlùfáà: Jedaiah; Jehoiaribi; Jakini;
Z kapłanów: Jedajasz, Jehojarib, Jakin;
11 Asariah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, olórí tí ó ń bojútó ilé Ọlọ́run;
I Azariasz, syn Chilkiasza, syna Meszullama, syna Sadoka, syna Merajota, syna Achituba, przełożonego domu Bożego;
12 Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah; àti Masai ọmọ Adieli, ọmọ Jahisera, ọmọ Meṣullamu ọmọ Meṣilemiti, ọmọ Immeri.
I Adajasz, syn Jerochama, syna Paszchura, syna Malkiasza, i Maasaj, syn Adiela, syna Jachzery, syna Meszullama, syna Meszillemita, syna Immera;
13 Àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀sán ó dín méjì. Wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin, tí wọ́n lè dúró fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run.
Ich braci, naczelników swoich rodów, [było] tysiąc siedmiuset sześćdziesięciu, ludzi zdolnych do pełnienia służby w domu Bożym.
14 Ní ti àwọn ará Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ará Merari;
A z Lewitów: Szemejasz, syn Chaszuba, syna Azrikama, syna Chaszabiasza, z synów Merariego;
15 Bakibakari, Hereṣi, Galali àti Mattaniah, ọmọ Mika, ọmọ Sikri, ọmọ Asafu;
I Bakbakar, Cheresz, Galal, Mattaniasz, syn Micheasza, syna Zikriego, syna Asafa;
16 Obadiah ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni; àti Berekiah ọmọ Asa, ọmọ Elkana, tí ó ń gbé nínú àwọn ìlú àwọn ará Netofa.
I Obadiasz, syn Szemajasza, syna Galala, syna Jedutuna, i Berechiasz, syn Asy, syna Elkany, który mieszkał we wsiach Netofatytów.
17 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà: Ṣallumu, Akkubu, Talmoni, Ahimani àti arákùnrin wọn, Ṣalumu olóyè wọn,
A odźwierni: Szallum, Akkub, Talmon, Achiman i ich bracia. Szallum [był ich] zwierzchnikiem;
18 ti wà ní ipò ìdúró ní ẹnu-ọ̀nà ọba ní apá ìhà ìlà-oòrùn títí di àkókò yí. Wọ̀nyí ni àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí ó jẹ́ ti ìpàgọ́ àwọn ará Lefi.
[Który] aż dotąd [stawał] przy bramie królewskiej od wschodu. Ci byli odźwiernymi w obozach synów Lewiego.
19 Ṣallumu ọmọ Kore ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora, àti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Láti ìdílé rẹ̀ (àwọn ará Korati) ni ó dúró fún ṣíṣọ́ ìloro ẹnu-ọ̀nà àgọ́ gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti ń dúró fún ṣíṣọ́ àbáwọlé ibùgbé Olúwa.
Szallum, syn Korego, syna Ebiazafa, syna Koracha, i jego bracia z domu jego ojca, Korachici, pełnili służbę, [byli] stróżami progów namiotu, a ich ojcowie byli stróżami wejścia do obozu PANA.
20 Ní ìgbà àkọ́kọ́ Finehasi ọmọ Eleasari jẹ́ olórí fún àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà, Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Pinchas, syn Eleazara, był niegdyś zwierzchnikiem nad nimi, a PAN był z nim.
21 Sekariah, ọmọ Meṣelemiah jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àbáwọlé sí àgọ́ ibi ìpàdé.
Zachariasz, syn Meszelemiasza, [był] odźwiernym przy wejściu do Namiotu Zgromadzenia.
22 Gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, àwọn tí a yàn láti jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àwọn ìloro jẹ́ igba ó lé méjìlá. A ka àwọn wọ̀nyí nípa ìdílé ní ìletò wọn. Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ni a ti yàn sí ipò láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Samuẹli, aríran, nítorí òtítọ́ wọn.
Wszystkich wybranych na odźwiernych przy bramach było dwustu dwunastu. Byli oni policzeni według ich rodowodu w swoich osiedlach, a ustanowił ich Dawid i Samuel, widzący.
23 Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ni ó wà fún ṣíṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ilé tí a pè ní àgọ́.
Oni więc i ich synowie [czuwali] nad bramami domu PANA, w domu namiotu, jako stróże.
24 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà wà ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin: ìlà-oòrùn, ìwọ̀-oòrùn àríwá àti gúúsù.
Odźwierni znajdowali się z czterech stron: od wschodu, od zachodu, od północy i od południa.
25 Àwọn arákùnrin wọn ní àwọn ìletò wọn ní láti wá ní àkókò dé àkókò láti pín iṣẹ́ ìsìn wọn fún àkókò ọjọ́ méje.
Ich bracia zaś, [mieszkający] w swoich osiedlach, przychodzili co siódmy dzień, w swoich porach, aby [być] z nimi.
26 Ṣùgbọ́n àwọn olórí alábojútó ẹnu-ọ̀nà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ni a yàn fún àwọn iyàrá àti àwọn àpótí ìṣúra ní ilé Ọlọ́run.
Czterej bowiem naczelni odźwierni pełnili stałą służbę. [Byli] to Lewici [odpowiedzialni] za komnaty i skarbiec domu Bożego;
27 Wọ́n á lo gbogbo òru ní dídúró yí ilé Ọlọ́run ká, nítorí wọ́n ní láti ṣọ́ ọ, wọ́n sì ní àṣẹ sí kọ́kọ́rọ́ fún ṣíṣí i ní àràárọ̀.
I nocowali dokoła domu Bożego, gdyż do nich należała straż i obowiązek otwierania [go] każdego ranka.
28 Díẹ̀ wà ní ìdí ohun èlò tí à ń lò fún ìsìn ilé Ọlọ́run; wọn a máa kà á nígbà tí wọ́n gbé e wọlé àti nígbà tí a kó wọn jáde.
[Niektórzy] z nich mieli pieczę nad naczyniami do służby, by je wnosić i wynosić w tej samej liczbie.
29 Àwọn mìíràn ni a yàn láti bojútó ohun èlò àti gbogbo ohun èlò ilé tí a yà sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run, àti ìyẹ̀fun àti ọtí èso àjàrà àti òróró náà, tùràrí àti tùràrí olóòórùn dídùn.
[Inni] spośród nich byli ustanowieni [do opieki] nad naczyniami i przyborami Miejsca Najświętszego – nad mąką pszenną, winem, oliwą, kadzidłem i wonnościami.
30 Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn àlùfáà ni ó ń bojútó pípò tùràrí olóòórùn dídùn papọ̀.
A niektórzy z synów kapłanów sporządzali olejki z wonności.
31 Ará Lefi tí a sọ ní Mattitiah àkọ́bí ọmọkùnrin Ṣallumu ará Kora ni a yàn, tí ń ṣe alábojútó ohun tí a dín.
Mattitiasz, spośród Lewitów, pierworodny Szalluma Korachity, był przełożonym nad tym, co przygotowane w patelniach.
32 Àti nínú àwọn arákùnrin wọn, nínú àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣe ìtọ́jú àkàrà ìfihàn, láti máa pèsè rẹ̀ ní ọjọọjọ́ ìsinmi.
[Niektórzy] ich bracia spośród synów Kehata [byli] ustanowieni [do opieki] nad chlebami pokładnymi, aby [je] przygotowywać w każdy szabat.
33 Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Lefi dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì ṣe lára iṣẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ náà lọ́sàn, lóru.
Ci [byli] śpiewakami, naczelnikami rodów Lewitów, którzy mieszkają w komnatach; byli wolni od innych zajęć, gdyż we dnie i w nocy zajmowali się tą służbą.
34 Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Lefi, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Byli oni naczelnikami rodów Lewitów, naczelnikami według swoich rodowodów, a mieszkali w Jerozolimie.
35 Jeieli baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka,
W Gibeonie mieszkał Jejel, ojciec Gibeona, a jego żona miała na imię Maaka;
36 pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀ jẹ́ Abdoni, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu.
A jego synem pierworodnym był Abdon, a następni to: Sur, Kisz, Baal, Neer, Nadab;
37 Gedori, Ahio, Sekariah àti Mikiloti.
I Gedor, Achio, Zachariasz, i Miklot.
38 Mikiloti jẹ́ baba Ṣimeamu, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
A Miklot spłodził Szimmeama. Tamci również mieszkali ze swoimi braćmi w Jerozolimie naprzeciw swoich braci.
39 Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba a Saulu, àti Saulu baba a Jonatani, àti Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
Neer spłodził Kisza, a Kisz spłodził Saula, a Saul spłodził Jonatana, Malkiszuę, Abinadaba i Eszbaala.
40 Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali, tí ó jẹ́ baba Mika.
Synem Jonatana [był] Meribbaal, a Meribbaal spłodził Micheasza.
41 Àwọn ọmọ Mika: Pitoni. Meleki, Tarea àti Ahasi.
Synowie zaś Micheasza to: Piton, Melek, Tarea i [Achaz].
42 Ahasi jẹ́ baba Jada, Jada jẹ́ baba Alemeti, Asmafeti, Simri, sì Simri jẹ́ baba Mosa.
Achaz spłodził Jarę, a Jara spłodził Alemeta, Azmaweta i Zimriego, a Zimri spłodził Mosę.
43 Mosa jẹ́ baba Binea; Refaiah jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
Mosa spłodził Bineę, a jego synem [był] Rafa, jego synem [był] Elasa, jego synem [był] Asel.
44 Aseli ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli Ṣeariah, Obadiah àti Hanani, gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
Asel miał sześciu synów, a oto ich imiona: Azrikam, Bokru, Izmael, Szeariasz, Obadiasz i Chanan. Ci [byli] synami Asela.