< 1 Chronicles 9 >
1 Gbogbo Israẹli ni a kọ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá nínú ìwé àwọn ọba Israẹli. Àwọn ènìyàn Juda ni a kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli nítorí àìṣòótọ́ wọn.
Voilà tout Israël et son dénombrement, et ceux qui furent inscrits au livre des Rois d'Israël et de Juda, après qu'ils eurent été transportés à Babylone à cause de tous leurs péchés,
2 Nísinsin yìí, àwọn tí ó kọ́kọ́ tún tẹ̀dó lórí ohun ìní wọn ní ìlú wọn ni díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa.
Et ceux qui les premiers revinrent en leurs possessions et dans les villes d'Israël, prêtres, lévites et autres à qui cela fut permis.
3 Àwọn tí ó wá láti Juda láti Benjamini àti láti Efraimu àti Manase tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu jẹ́:
Jérusalem fut repeuplée par des fils de Juda, des fils de Benjamin, des fils d'Ephraïm et des fils de Manassé.
4 Uttai ọmọ Ammihudu, ọmọ Omri, ọmọ Imri, ọmọ Bani, ìran ọmọ Peresi ọmọ Juda.
Il y eut parmi eux: Nothi, fils de Samiud, fils d'Amri, fils d'Ambraïm, fils de Buni, issus des fils de Pharès, fils de Juda,
5 Àti nínú ará Ṣilo: Asaiah àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Et de la famille de Seléni Asaie premier-né, et ses fils,
6 Ní ti ará Sera: Jeueli. Àwọn ènìyàn láti Juda sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́wàá.
Issus de Zara; puis, Jehel et leurs frères au nombre de six cent quatre- vingt-dix.
7 Àti nínú àwọn ọmọ Benjamini ni: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Hodafiah; ọmọ Hasenuah;
Et des fils de Benjamin: Salem, fils de Mosollam, fils d'Odes, fils d'Asinu.
8 Ibinaiah ọmọ Jerohamu; Ela ọmọ Ussi, ọmọ Mikri; àti Meṣullamu ọmọ Ṣefatia; ọmọ Reueli, ọmọ Ibinijah.
Et Jemnaa, fils de Jéroboam et Elo ceux-ci étaient issus d'Ozi, fils de Machir), et Mosollam, fils de Saphatia, fils de Raguel, fils de Jemnaï,
9 Àwọn ènìyàn láti Benjamini gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ ọ́ nínú ìran wọn nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó dín mẹ́rìnlélógójì. Gbogbo àwọn ọkùnrin yí jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé.
Et leurs frères, selon leur naissance, au nombre de neuf cent cinquante- six, tous chefs de familles dans leur tribu.
10 Ní ti àwọn àlùfáà: Jedaiah; Jehoiaribi; Jakini;
Et parmi les prêtres: Jodaé, et Joarim, et Jachin;
11 Asariah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, olórí tí ó ń bojútó ilé Ọlọ́run;
Et Azarias, fils d'Helcias, fils de Mosollam, fils de Sadoc, fils de Maraïoth, fils d'Achitob, grand prêtre du temple du Seigneur.
12 Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah; àti Masai ọmọ Adieli, ọmọ Jahisera, ọmọ Meṣullamu ọmọ Meṣilemiti, ọmọ Immeri.
Et Adaie, fils d'Ira, fils de Phaschor, fils de Melchia, et Maasaïa, fils d'Adiel, fils d'Ezira, fils de Mosollam, fils de Maselmoth, fils d'Emmer;
13 Àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀sán ó dín méjì. Wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin, tí wọ́n lè dúró fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run.
Et leurs frères, chefs de familles dans leur tribu, au nombre de dix-sept cent soixante, hommes vaillants et forts employés au temple de Dieu.
14 Ní ti àwọn ará Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ará Merari;
Et des lévites: Saulaie, fils d'Asob, fils d'Ezricam, fils d'Asahia, des fils de Mérari.
15 Bakibakari, Hereṣi, Galali àti Mattaniah, ọmọ Mika, ọmọ Sikri, ọmọ Asafu;
Et Bacbacar, Arès, Galaal et Matthanias, fils de Micha, fils de Zéchri, fils d'Asaph.
16 Obadiah ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni; àti Berekiah ọmọ Asa, ọmọ Elkana, tí ó ń gbé nínú àwọn ìlú àwọn ará Netofa.
Et Abdias, fils de Samias, fils de Galaal, fils d'Idithun, et Barachie, fils d'Ossa, fils d'Elcana, qui demeurait dans les bourgs de Notephati.
17 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà: Ṣallumu, Akkubu, Talmoni, Ahimani àti arákùnrin wọn, Ṣalumu olóyè wọn,
Les portiers étaient: Salom, Acum, Telmon et Diman, et ses frères; Salom était leur chef.
18 ti wà ní ipò ìdúró ní ẹnu-ọ̀nà ọba ní apá ìhà ìlà-oòrùn títí di àkókò yí. Wọ̀nyí ni àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí ó jẹ́ ti ìpàgọ́ àwọn ará Lefi.
Et jusqu'à ce jour, le chef est attaché à la porte royale du côté de l'orient; les portes sont les mêmes que celles des camps des fils de Lévi.
19 Ṣallumu ọmọ Kore ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora, àti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Láti ìdílé rẹ̀ (àwọn ará Korati) ni ó dúró fún ṣíṣọ́ ìloro ẹnu-ọ̀nà àgọ́ gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti ń dúró fún ṣíṣọ́ àbáwọlé ibùgbé Olúwa.
Or, Sellum était fils de Coré, fils d'Abiasaph, fils de Coré, et ses frères les Coréites, entre autres services dans le temple, gardaient le tabernacle; et leurs pères dans les camps du Seigneur en avaient gardé l'entrée.
20 Ní ìgbà àkọ́kọ́ Finehasi ọmọ Eleasari jẹ́ olórí fún àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà, Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Et Phinéès, fils d'Eléazar, avait été leur chef devant le Seigneur, et après lui ceux ci-dessus nommés.
21 Sekariah, ọmọ Meṣelemiah jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àbáwọlé sí àgọ́ ibi ìpàdé.
Zacharie, fils de Mosollam, gardait la porte du tabernacle du témoignage.
22 Gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, àwọn tí a yàn láti jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àwọn ìloro jẹ́ igba ó lé méjìlá. A ka àwọn wọ̀nyí nípa ìdílé ní ìletò wọn. Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ni a ti yàn sí ipò láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Samuẹli, aríran, nítorí òtítọ́ wọn.
Tous ceux qu'on avait choisis pour garder les portes du temple étaient au nombre de deux cent douze; ils étaient dénombrés selon leurs résidences; David et Samuel le voyant les avaient institués, s'en remettant à leur foi.
23 Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ni ó wà fún ṣíṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ilé tí a pè ní àgọ́.
Et eux et leurs fils gardaient les portes du temple, et, dans le temple, le tabernacle.
24 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà wà ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin: ìlà-oòrùn, ìwọ̀-oòrùn àríwá àti gúúsù.
Les portes regardaient les quatre vents du côté de l'orient, de la mer, de Borée et de Notos.
25 Àwọn arákùnrin wọn ní àwọn ìletò wọn ní láti wá ní àkókò dé àkókò láti pín iṣẹ́ ìsìn wọn fún àkókò ọjọ́ méje.
Et leurs frères demeuraient dans leurs résidences, et en partaient pour qu'ils fussent relevés de sept en sept jours, à partir du jour du sabbat.
26 Ṣùgbọ́n àwọn olórí alábojútó ẹnu-ọ̀nà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ni a yàn fún àwọn iyàrá àti àwọn àpótí ìṣúra ní ilé Ọlọ́run.
A quatre chefs étaient confiés les gardiens des portes, et les lévites veillaient à ce quel nul ne s'introduisît furtivement dans les chambres, ni dans le trésor du temple du Seigneur.
27 Wọ́n á lo gbogbo òru ní dídúró yí ilé Ọlọ́run ká, nítorí wọ́n ní láti ṣọ́ ọ, wọ́n sì ní àṣẹ sí kọ́kọ́rọ́ fún ṣíṣí i ní àràárọ̀.
Car la garde leur en était remise, et ils en avaient les clefs, et chaque matin dès l'aurore ils ouvraient les portes du lieu saint;
28 Díẹ̀ wà ní ìdí ohun èlò tí à ń lò fún ìsìn ilé Ọlọ́run; wọn a máa kà á nígbà tí wọ́n gbé e wọlé àti nígbà tí a kó wọn jáde.
Et quelques-uns des leurs étaient chargés du service des vases, qu'on ne déplaçait pas sans qu'ils les eussent comptés.
29 Àwọn mìíràn ni a yàn láti bojútó ohun èlò àti gbogbo ohun èlò ilé tí a yà sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run, àti ìyẹ̀fun àti ọtí èso àjàrà àti òróró náà, tùràrí àti tùràrí olóòórùn dídùn.
Et d'autres avaient la surveillance des provisions destinées aux choses saintes: de la fleur de farine, du vin, de l'huile, de, l'encens, des aromates.
30 Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn àlùfáà ni ó ń bojútó pípò tùràrí olóòórùn dídùn papọ̀.
Et ceux qui préparaient les parfums et les aromates étaient pris parmi les fils des prêtres.
31 Ará Lefi tí a sọ ní Mattitiah àkọ́bí ọmọkùnrin Ṣallumu ará Kora ni a yàn, tí ń ṣe alábojútó ohun tí a dín.
Et Matthathias, issu de Lévi, fils premier-né de Salom le Coréite, avait la surveillance de tout ce qui se préparait après les sacrifices dans la poêle à frire du grand prêtre.
32 Àti nínú àwọn arákùnrin wọn, nínú àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣe ìtọ́jú àkàrà ìfihàn, láti máa pèsè rẹ̀ ní ọjọọjọ́ ìsinmi.
Et Banaïas, issu de ses frères, de la maison de Caath, était chargé des pains de proposition que l'on consacrait de sabbat en sabbat.
33 Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Lefi dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì ṣe lára iṣẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ náà lọ́sàn, lóru.
Et les chefs des chantres-harpistes, de la famille des lévites, étaient désignés chaque jour, car jour et nuit ils étaient employés;
34 Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Lefi, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Et les chefs distribués par familles demeuraient à Jérusalem.
35 Jeieli baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka,
Or, Jehel avait habité Gabaon, qu'il avait fondée; et sa femme se nommait Moocha.
36 pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀ jẹ́ Abdoni, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu.
Noms de ses fils: Abdon, premier-né; puis, Sur, Cis, Baal, Ner et Nadab,
37 Gedori, Ahio, Sekariah àti Mikiloti.
Gedur et son frère, et Zachur et Maceloth.
38 Mikiloti jẹ́ baba Ṣimeamu, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
Et Maceloth engendra Samaa, et ceux-ci demeurèrent à Jérusalem au milieu de leurs frères.
39 Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba a Saulu, àti Saulu baba a Jonatani, àti Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
Et Ner engendra Cis, et Cis engendra Saül, et Saül engendra Jonathas, et Melchisué, et Aminadab et Asabal.
40 Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali, tí ó jẹ́ baba Mika.
Et Jonathas engendra Meribaal, et Meribaal engendra Micha.
41 Àwọn ọmọ Mika: Pitoni. Meleki, Tarea àti Ahasi.
Fils de Micha: Phithon, Malach et Tharach.
42 Ahasi jẹ́ baba Jada, Jada jẹ́ baba Alemeti, Asmafeti, Simri, sì Simri jẹ́ baba Mosa.
Et Achaz engendra Juda, et Juda engendra Galemeth, Gazmoth et Zambri, et Zambri engendra Massa;
43 Mosa jẹ́ baba Binea; Refaiah jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
Et Massa engendra Baana, et Raphaïe son fils, et Elasa son fils, et Esel son fils.
44 Aseli ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli Ṣeariah, Obadiah àti Hanani, gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
Et Esel eut six fils, et voici leurs noms: Ezricam, le premier-né; puis, Ismaël, Saraïa, Abdias, Anan et Asa; voilà les fils d'Esel.