< 1 Chronicles 9 >

1 Gbogbo Israẹli ni a kọ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá nínú ìwé àwọn ọba Israẹli. Àwọn ènìyàn Juda ni a kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli nítorí àìṣòótọ́ wọn.
Et tous ceux d’Israël furent enregistrés par généalogies; et voici, ils sont inscrits dans le livre des rois d’Israël. Et Juda fut transporté à Babylone à cause de ses péchés.
2 Nísinsin yìí, àwọn tí ó kọ́kọ́ tún tẹ̀dó lórí ohun ìní wọn ní ìlú wọn ni díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa.
Et les premiers habitants qui étaient dans leurs possessions, dans leurs villes, étaient Israël, les sacrificateurs, les lévites, et les Nethiniens.
3 Àwọn tí ó wá láti Juda láti Benjamini àti láti Efraimu àti Manase tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu jẹ́:
Et à Jérusalem habitèrent des fils de Juda, et des fils de Benjamin, et des fils d’Éphraïm et de Manassé:
4 Uttai ọmọ Ammihudu, ọmọ Omri, ọmọ Imri, ọmọ Bani, ìran ọmọ Peresi ọmọ Juda.
Uthaï, fils d’Ammihud, fils d’Omri, fils d’Imri, fils de Bani, des fils de Pérets, fils de Juda.
5 Àti nínú ará Ṣilo: Asaiah àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Et des Shilonites: Asçaïa, le premier-né, et ses fils.
6 Ní ti ará Sera: Jeueli. Àwọn ènìyàn láti Juda sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́wàá.
Et des fils de Zérakh: Jehuel, et ses frères, 690.
7 Àti nínú àwọn ọmọ Benjamini ni: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Hodafiah; ọmọ Hasenuah;
Et des fils de Benjamin: Sallu, fils de Meshullam, fils d’Hodavia, fils d’Hassenua;
8 Ibinaiah ọmọ Jerohamu; Ela ọmọ Ussi, ọmọ Mikri; àti Meṣullamu ọmọ Ṣefatia; ọmọ Reueli, ọmọ Ibinijah.
et Jibneïa, fils de Jerokham; et Éla, fils d’Uzzi, fils de Micri; et Meshullam, fils de Shephatia, fils de Rehuel, fils de Jibnija;
9 Àwọn ènìyàn láti Benjamini gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ ọ́ nínú ìran wọn nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó dín mẹ́rìnlélógójì. Gbogbo àwọn ọkùnrin yí jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé.
et leurs frères, selon leurs générations, 956. Tous ces hommes-là étaient chefs des pères de leurs maisons de pères.
10 Ní ti àwọn àlùfáà: Jedaiah; Jehoiaribi; Jakini;
Et des sacrificateurs: Jedahia, et Joïarib, et Jakin;
11 Asariah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, olórí tí ó ń bojútó ilé Ọlọ́run;
et Azaria, fils de Hilkija, fils de Meshullam, fils de Tsadok, fils de Meraïoth, fils d’Akhitub, prince de la maison de Dieu;
12 Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah; àti Masai ọmọ Adieli, ọmọ Jahisera, ọmọ Meṣullamu ọmọ Meṣilemiti, ọmọ Immeri.
et Adaïa, fils de Jerokham, fils de Pashkhur, fils de Malkija; et Mahçaï, fils d’Adiel, fils de Jakhzéra, fils de Meshullam, fils de Meshillémith, fils d’Immer;
13 Àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀sán ó dín méjì. Wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin, tí wọ́n lè dúró fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run.
et leurs frères, chefs de leurs maisons de pères, 1 760 hommes forts et vaillants, pour l’œuvre du service de la maison de Dieu.
14 Ní ti àwọn ará Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ará Merari;
Et des lévites: Shemahia, fils de Hashub, fils d’Azrikam, fils de Hashabia, des fils de Merari;
15 Bakibakari, Hereṣi, Galali àti Mattaniah, ọmọ Mika, ọmọ Sikri, ọmọ Asafu;
et Bakbakkar, Héresh, et Galal; et Matthania, fils de Michée, fils de Zicri, fils d’Asaph;
16 Obadiah ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni; àti Berekiah ọmọ Asa, ọmọ Elkana, tí ó ń gbé nínú àwọn ìlú àwọn ará Netofa.
et Abdias, fils de Shemahia, fils de Galal, fils de Jeduthun; et Bérékia, fils d’Asa, fils d’Elkana, qui habitait dans les villages des Netophathites.
17 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà: Ṣallumu, Akkubu, Talmoni, Ahimani àti arákùnrin wọn, Ṣalumu olóyè wọn,
Et les portiers: Shallum, et Akkub, et Talmon, et Akhiman, et leurs frères; Shallum était le chef.
18 ti wà ní ipò ìdúró ní ẹnu-ọ̀nà ọba ní apá ìhà ìlà-oòrùn títí di àkókò yí. Wọ̀nyí ni àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí ó jẹ́ ti ìpàgọ́ àwọn ará Lefi.
Et [ils sont] jusqu’à maintenant à la porte du roi, au levant; ils étaient les portiers des camps des fils de Lévi.
19 Ṣallumu ọmọ Kore ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora, àti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Láti ìdílé rẹ̀ (àwọn ará Korati) ni ó dúró fún ṣíṣọ́ ìloro ẹnu-ọ̀nà àgọ́ gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti ń dúró fún ṣíṣọ́ àbáwọlé ibùgbé Olúwa.
Et Shallum, fils de Koré, fils d’Ébiasaph, fils de Coré, et ses frères, les Corites, de la maison de son père, étaient [préposés] sur l’œuvre du service, gardant les seuils de la tente: et leurs pères avaient été [préposés] sur le camp de l’Éternel, gardant l’entrée;
20 Ní ìgbà àkọ́kọ́ Finehasi ọmọ Eleasari jẹ́ olórí fún àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà, Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
et Phinées, fils d’Éléazar, fut autrefois prince sur eux: l’Éternel était avec lui.
21 Sekariah, ọmọ Meṣelemiah jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àbáwọlé sí àgọ́ ibi ìpàdé.
Zacharie, fils de Meshélémia, était portier à l’entrée de la tente d’assignation.
22 Gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, àwọn tí a yàn láti jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àwọn ìloro jẹ́ igba ó lé méjìlá. A ka àwọn wọ̀nyí nípa ìdílé ní ìletò wọn. Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ni a ti yàn sí ipò láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Samuẹli, aríran, nítorí òtítọ́ wọn.
Tous ceux-là, choisis pour portiers des seuils, étaient 212; ils furent enregistrés par généalogies dans leurs villages; David et Samuel, le voyant, les avaient établis dans leur charge.
23 Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ni ó wà fún ṣíṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ilé tí a pè ní àgọ́.
Et eux, et leurs fils, étaient [établis] aux portes de la maison de l’Éternel, de la maison de la tente, pour y faire la garde.
24 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà wà ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin: ìlà-oòrùn, ìwọ̀-oòrùn àríwá àti gúúsù.
Les portiers étaient vers les quatre vents, à l’orient, à l’occident, au nord, et au midi.
25 Àwọn arákùnrin wọn ní àwọn ìletò wọn ní láti wá ní àkókò dé àkókò láti pín iṣẹ́ ìsìn wọn fún àkókò ọjọ́ méje.
Et leurs frères, dans leurs villages, devaient venir de sept jours en sept jours, d’un terme à l’autre, auprès d’eux;
26 Ṣùgbọ́n àwọn olórí alábojútó ẹnu-ọ̀nà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ni a yàn fún àwọn iyàrá àti àwọn àpótí ìṣúra ní ilé Ọlọ́run.
car, dans leur charge, ces quatre furent les principaux portiers: ils étaient Lévites; et ils étaient [préposés] sur les chambres et sur les trésors de la maison de Dieu,
27 Wọ́n á lo gbogbo òru ní dídúró yí ilé Ọlọ́run ká, nítorí wọ́n ní láti ṣọ́ ọ, wọ́n sì ní àṣẹ sí kọ́kọ́rọ́ fún ṣíṣí i ní àràárọ̀.
et ils se tenaient la nuit autour de la maison de Dieu, car la garde leur en appartenait, et ils en avaient la clé, [pour ouvrir] chaque matin.
28 Díẹ̀ wà ní ìdí ohun èlò tí à ń lò fún ìsìn ilé Ọlọ́run; wọn a máa kà á nígbà tí wọ́n gbé e wọlé àti nígbà tí a kó wọn jáde.
Il y en avait aussi quelques-uns d’entre eux [qui étaient préposés] sur les ustensiles du service; car ils les rentraient en les comptant, et ils les sortaient en les comptant.
29 Àwọn mìíràn ni a yàn láti bojútó ohun èlò àti gbogbo ohun èlò ilé tí a yà sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run, àti ìyẹ̀fun àti ọtí èso àjàrà àti òróró náà, tùràrí àti tùràrí olóòórùn dídùn.
Et il y en avait qui étaient préposés sur les vases, et sur tous les ustensiles du lieu saint, et sur la fleur de farine, et sur le vin, et sur l’huile, et sur l’encens, et sur les aromates.
30 Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn àlùfáà ni ó ń bojútó pípò tùràrí olóòórùn dídùn papọ̀.
Et c’étaient des fils des sacrificateurs qui composaient les parfums avec les aromates.
31 Ará Lefi tí a sọ ní Mattitiah àkọ́bí ọmọkùnrin Ṣallumu ará Kora ni a yàn, tí ń ṣe alábojútó ohun tí a dín.
Et Matthithia, d’entre les Lévites, premier-né de Shallum, le Corite, avait la charge de l’ouvrage des [gâteaux] cuits sur la plaque;
32 Àti nínú àwọn arákùnrin wọn, nínú àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣe ìtọ́jú àkàrà ìfihàn, láti máa pèsè rẹ̀ ní ọjọọjọ́ ìsinmi.
et des fils des Kehathites, d’entre leurs frères, [étaient chargés] des pains à placer en rangées, pour les apprêter chaque sabbat.
33 Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Lefi dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì ṣe lára iṣẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ náà lọ́sàn, lóru.
Et ce sont là les chantres, chefs des pères des Lévites, qui étaient dans les chambres, étant exempts d’autres fonctions, parce que, jour et nuit, ils étaient à l’œuvre.
34 Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Lefi, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Ce sont les chefs des pères des Lévites, selon leurs générations, des chefs; ceux-là habitèrent à Jérusalem.
35 Jeieli baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka,
Et à Gabaon habita le père de Gabaon, Jehiel; et le nom de sa femme était Maaca.
36 pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀ jẹ́ Abdoni, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu.
Et son fils premier-né: Abdon; et Tsur, et Kis, et Baal, et Ner, et Nadab,
37 Gedori, Ahio, Sekariah àti Mikiloti.
et Guedor, et Akhio, et Zacharie, et Mikloth.
38 Mikiloti jẹ́ baba Ṣimeamu, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
Et Mikloth engendra Shimeam. Et eux aussi habitèrent à côté de leurs frères à Jérusalem, avec leurs frères.
39 Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba a Saulu, àti Saulu baba a Jonatani, àti Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
– Et Ner engendra Kis; et Kis engendra Saül; et Saül engendra Jonathan, et Malki-Shua, et Abinadab, et Eshbaal.
40 Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali, tí ó jẹ́ baba Mika.
– Et le fils de Jonathan fut Merib-Baal; et Merib-Baal engendra Michée.
41 Àwọn ọmọ Mika: Pitoni. Meleki, Tarea àti Ahasi.
Et les fils de Michée: Pithon, et Mélec, et Thakhréa.
42 Ahasi jẹ́ baba Jada, Jada jẹ́ baba Alemeti, Asmafeti, Simri, sì Simri jẹ́ baba Mosa.
– Et Achaz engendra Jahra; et Jahra engendra Alémeth, et Azmaveth, et Zimri. Et Zimri engendra Motsa;
43 Mosa jẹ́ baba Binea; Refaiah jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
et Motsa engendra Binha: et Rephaïa, son fils; Elhasça, son fils; Atsel, son fils.
44 Aseli ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli Ṣeariah, Obadiah àti Hanani, gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
Et Atsel eut six fils, et ce sont ici leurs noms: Azrikam, Bocru, et Ismaël, et Shearia, et Abdias, et Hanan; ce furent là les fils d’Atsel.

< 1 Chronicles 9 >