< 1 Chronicles 9 >

1 Gbogbo Israẹli ni a kọ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá nínú ìwé àwọn ọba Israẹli. Àwọn ènìyàn Juda ni a kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli nítorí àìṣòótọ́ wọn.
Tout Israël fut ainsi répertorié par généalogies, et voici qu'elles sont écrites dans le livre des rois d'Israël. Juda fut emmené captif à Babylone pour sa désobéissance.
2 Nísinsin yìí, àwọn tí ó kọ́kọ́ tún tẹ̀dó lórí ohun ìní wọn ní ìlú wọn ni díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa.
Or les premiers habitants qui vécurent dans leurs biens, dans leurs villes, furent Israël, les prêtres, les lévites et les serviteurs du temple.
3 Àwọn tí ó wá láti Juda láti Benjamini àti láti Efraimu àti Manase tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu jẹ́:
A Jérusalem, vivaient des fils de Juda, des fils de Benjamin, des fils d'Ephraïm et de Manassé:
4 Uttai ọmọ Ammihudu, ọmọ Omri, ọmọ Imri, ọmọ Bani, ìran ọmọ Peresi ọmọ Juda.
Uthaï, fils d'Ammihud, fils d'Omri, fils d'Imri, fils de Bani, des fils de Pérez, fils de Juda.
5 Àti nínú ará Ṣilo: Asaiah àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Des Silonites: Asaja, premier-né, et ses fils.
6 Ní ti ará Sera: Jeueli. Àwọn ènìyàn láti Juda sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́wàá.
Des fils de Zérach: Jeuel et ses frères, six cent quatre-vingt-dix.
7 Àti nínú àwọn ọmọ Benjamini ni: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Hodafiah; ọmọ Hasenuah;
Pour les fils de Benjamin: Sallu, fils de Meshullam, fils d'Hodavia, fils d'Hassenua;
8 Ibinaiah ọmọ Jerohamu; Ela ọmọ Ussi, ọmọ Mikri; àti Meṣullamu ọmọ Ṣefatia; ọmọ Reueli, ọmọ Ibinijah.
Ibnéja, fils de Jerocham; Éla, fils d'Uzzi, fils de Michri; Meshullam, fils de Shephatia, fils de Reuel, fils d'Ibnija;
9 Àwọn ènìyàn láti Benjamini gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ ọ́ nínú ìran wọn nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó dín mẹ́rìnlélógójì. Gbogbo àwọn ọkùnrin yí jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé.
et leurs frères, selon leurs générations, neuf cent cinquante-six. Tous ces hommes étaient chefs de famille, selon les maisons de leurs pères.
10 Ní ti àwọn àlùfáà: Jedaiah; Jehoiaribi; Jakini;
Parmi les sacrificateurs: Jedaja, Jehoïarib, Jachin,
11 Asariah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, olórí tí ó ń bojútó ilé Ọlọ́run;
et Azaria, fils de Hilkija, fils de Meshullam, fils de Tsadok, fils de Meraioth, fils d'Ahitub, chef de la maison de Dieu;
12 Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah; àti Masai ọmọ Adieli, ọmọ Jahisera, ọmọ Meṣullamu ọmọ Meṣilemiti, ọmọ Immeri.
et Adaja, fils de Jerocham, fils de Pashhur, fils de Malkija; et Maasaï, fils d'Adiel, fils de Jahzerah, fils de Meshullam, fils de Meshillemith, fils d'Immer;
13 Àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀sán ó dín méjì. Wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin, tí wọ́n lè dúró fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run.
et leurs frères, chefs des maisons de leurs pères, au nombre de mille sept cent soixante; ils étaient des hommes très capables pour l'œuvre du service de la maison de Dieu.
14 Ní ti àwọn ará Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ará Merari;
Parmi les Lévites: Schemaeja, fils de Hasshub, fils d'Azrikam, fils de Haschabia, d'entre les fils de Merari;
15 Bakibakari, Hereṣi, Galali àti Mattaniah, ọmọ Mika, ọmọ Sikri, ọmọ Asafu;
Bakbakkar, Heresh, Galal, Mattania, fils de Mica, fils de Zichri, fils d'Asaph;
16 Obadiah ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni; àti Berekiah ọmọ Asa, ọmọ Elkana, tí ó ń gbé nínú àwọn ìlú àwọn ará Netofa.
Abdias, fils de Shemaeja, fils de Galal, fils de Jeduthun, et Bérékia, fils d'Asa, fils d'Elkana, qui habitaient dans les villages des Nethophathiens.
17 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà: Ṣallumu, Akkubu, Talmoni, Ahimani àti arákùnrin wọn, Ṣalumu olóyè wọn,
Les gardiens de la porte: Shallum, Akkub, Talmon, Ahiman et leurs frères (Shallum était le chef),
18 ti wà ní ipò ìdúró ní ẹnu-ọ̀nà ọba ní apá ìhà ìlà-oòrùn títí di àkókò yí. Wọ̀nyí ni àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí ó jẹ́ ti ìpàgọ́ àwọn ará Lefi.
qui servaient auparavant à la porte du roi, à l'est. Ils étaient les gardiens du camp des fils de Lévi.
19 Ṣallumu ọmọ Kore ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora, àti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Láti ìdílé rẹ̀ (àwọn ará Korati) ni ó dúró fún ṣíṣọ́ ìloro ẹnu-ọ̀nà àgọ́ gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti ń dúró fún ṣíṣọ́ àbáwọlé ibùgbé Olúwa.
Shallum était le fils de Koré, fils d'Ebiasaph, fils de Koré, et ses frères, de la maison de son père, les Koréites, étaient chargés de l'exécution du service, gardiens des seuils du tabernacle. Leurs pères avaient été responsables du camp de l'Éternel et avaient gardé l'entrée.
20 Ní ìgbà àkọ́kọ́ Finehasi ọmọ Eleasari jẹ́ olórí fún àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà, Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
Phinées, fils d'Éléazar, était autrefois leur chef, et l'Éternel était avec lui.
21 Sekariah, ọmọ Meṣelemiah jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àbáwọlé sí àgọ́ ibi ìpàdé.
Zacharie, fils de Meshelemia, était gardien de l'entrée de la Tente de la Rencontre.
22 Gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, àwọn tí a yàn láti jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àwọn ìloro jẹ́ igba ó lé méjìlá. A ka àwọn wọ̀nyí nípa ìdílé ní ìletò wọn. Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ni a ti yàn sí ipò láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Samuẹli, aríran, nítorí òtítọ́ wọn.
Tous ceux qui avaient été choisis pour être gardiens des seuils étaient au nombre de deux cent douze. Ils étaient classés par généalogie dans leurs villages, et David et le voyant Samuel les avaient ordonnés à leur poste de confiance.
23 Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ni ó wà fún ṣíṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ilé tí a pè ní àgọ́.
Eux et leurs enfants avaient la surveillance des portes de la maison de l'Éternel, de la maison du tabernacle, en tant que gardiens.
24 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà wà ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin: ìlà-oòrùn, ìwọ̀-oòrùn àríwá àti gúúsù.
Les gardiens des portes étaient répartis sur les quatre côtés, à l'est, à l'ouest, au nord et au sud.
25 Àwọn arákùnrin wọn ní àwọn ìletò wọn ní láti wá ní àkókò dé àkókò láti pín iṣẹ́ ìsìn wọn fún àkókò ọjọ́ méje.
Leurs frères, dans leurs villages, devaient venir tous les sept jours, de temps en temps, pour être avec eux.
26 Ṣùgbọ́n àwọn olórí alábojútó ẹnu-ọ̀nà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ni a yàn fún àwọn iyàrá àti àwọn àpótí ìṣúra ní ilé Ọlọ́run.
Car les quatre principaux portiers, qui étaient des lévites, occupaient une fonction de confiance et étaient responsables des chambres et des trésors de la maison de Dieu.
27 Wọ́n á lo gbogbo òru ní dídúró yí ilé Ọlọ́run ká, nítorí wọ́n ní láti ṣọ́ ọ, wọ́n sì ní àṣẹ sí kọ́kọ́rọ́ fún ṣíṣí i ní àràárọ̀.
Ils restaient autour de la maison de Dieu, car c'était leur devoir, et c'était leur devoir de l'ouvrir matin par matin.
28 Díẹ̀ wà ní ìdí ohun èlò tí à ń lò fún ìsìn ilé Ọlọ́run; wọn a máa kà á nígbà tí wọ́n gbé e wọlé àti nígbà tí a kó wọn jáde.
Certains d'entre eux étaient chargés des ustensiles de service, car on les apportait en les comptant et on les retirait en les comptant.
29 Àwọn mìíràn ni a yàn láti bojútó ohun èlò àti gbogbo ohun èlò ilé tí a yà sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run, àti ìyẹ̀fun àti ọtí èso àjàrà àti òróró náà, tùràrí àti tùràrí olóòórùn dídùn.
Certains d'entre eux étaient aussi chargés des meubles et de tous les ustensiles du sanctuaire, de la farine fine, du vin, de l'huile, de l'encens et des aromates.
30 Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn àlùfáà ni ó ń bojútó pípò tùràrí olóòórùn dídùn papọ̀.
Quelques-uns des fils des prêtres préparaient le mélange des épices.
31 Ará Lefi tí a sọ ní Mattitiah àkọ́bí ọmọkùnrin Ṣallumu ará Kora ni a yàn, tí ń ṣe alábojútó ohun tí a dín.
Mattithia, l'un des Lévites, premier-né de Shallum, le Coréen, avait la charge des produits cuits dans les poêles.
32 Àti nínú àwọn arákùnrin wọn, nínú àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣe ìtọ́jú àkàrà ìfihàn, láti máa pèsè rẹ̀ ní ọjọọjọ́ ìsinmi.
Quelques-uns de leurs frères, parmi les fils des Kehathites, avaient la charge du pain de proposition, pour le préparer chaque sabbat.
33 Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Lefi dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì ṣe lára iṣẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ náà lọ́sàn, lóru.
Ce sont les chantres, chefs de famille des Lévites, qui habitaient dans les chambres et étaient libres de tout autre service, car ils étaient employés à leur travail jour et nuit.
34 Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Lefi, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Ce sont des chefs de famille de Lévites, de génération en génération, des chefs. Ils habitaient à Jérusalem.
35 Jeieli baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka,
Jeiel, père de Gabaon, dont la femme s'appelait Maaca, habitait à Gabaon.
36 pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀ jẹ́ Abdoni, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu.
Son fils premier-né était Abdon, puis Tsur, Kis, Baal, Ner, Nadab,
37 Gedori, Ahio, Sekariah àti Mikiloti.
Gedor, Ahio, Zacharie et Mikloth.
38 Mikiloti jẹ́ baba Ṣimeamu, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
Mikloth devint le père de Schimeam. Ils habitaient aussi à Jérusalem, près de leurs parents.
39 Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba a Saulu, àti Saulu baba a Jonatani, àti Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
Ner engendra Kish. Kis est devenu le père de Saül. Saül engendra Jonathan, Malkischua, Abinadab et Eschbaal.
40 Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali, tí ó jẹ́ baba Mika.
Le fils de Jonathan s'appelait Merib-Baal. Merib-Baal engendra Michée.
41 Àwọn ọmọ Mika: Pitoni. Meleki, Tarea àti Ahasi.
Fils de Michée: Pithon, Mélec, Tahréa et Achaz.
42 Ahasi jẹ́ baba Jada, Jada jẹ́ baba Alemeti, Asmafeti, Simri, sì Simri jẹ́ baba Mosa.
Achaz engendra Jarah. Jarah engendra Alemeth, Azmaveth et Zimri. Zimri engendra Moza.
43 Mosa jẹ́ baba Binea; Refaiah jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
Moza engendra Binea, son fils Rephaja, son fils Éléasa, et son fils Azel.
44 Aseli ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli Ṣeariah, Obadiah àti Hanani, gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
Azel eut six fils, dont les noms sont: Azrikam, Bocheru, Ismaël, Sheariah, Abdias et Hanan. Ce sont les fils d'Azel.

< 1 Chronicles 9 >