< 1 Chronicles 9 >

1 Gbogbo Israẹli ni a kọ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá nínú ìwé àwọn ọba Israẹli. Àwọn ènìyàn Juda ni a kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli nítorí àìṣòótọ́ wọn.
And, all Israel, registered themselves, and lo! they are written, in the Book of the Kings of Israel, and, Judah, was carried away captive to Babylon, for their faithlessness.
2 Nísinsin yìí, àwọn tí ó kọ́kọ́ tún tẹ̀dó lórí ohun ìní wọn ní ìlú wọn ni díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa.
Now, the first inhabitants, who were in their possessions, in their cities, were Israel, the priests, the Levites, and the Nethinim.
3 Àwọn tí ó wá láti Juda láti Benjamini àti láti Efraimu àti Manase tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu jẹ́:
And, in Jerusalem, there dwelt, of the sons of Judah, and of the sons of Benjamin, —and of the sons of Ephraim, and Manasseh:
4 Uttai ọmọ Ammihudu, ọmọ Omri, ọmọ Imri, ọmọ Bani, ìran ọmọ Peresi ọmọ Juda.
Uthai son of Ammihud, son of Omri, son of Imri, son of Bani, of the sons of Perez, son of Judah.
5 Àti nínú ará Ṣilo: Asaiah àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀.
And, of the Shilonites, Asaiah the firstborn, and his sons.
6 Ní ti ará Sera: Jeueli. Àwọn ènìyàn láti Juda sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́wàá.
And, of the sons of Zerah, Jeuel, —and their brethren, six hundred and ninety.
7 Àti nínú àwọn ọmọ Benjamini ni: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Hodafiah; ọmọ Hasenuah;
And, of the sons of Benjamin, Sallu, son of Meshullam, son of Hodaviah, son of Hassenuah;
8 Ibinaiah ọmọ Jerohamu; Ela ọmọ Ussi, ọmọ Mikri; àti Meṣullamu ọmọ Ṣefatia; ọmọ Reueli, ọmọ Ibinijah.
and Ibneiah, son of Jeroham, and Elah, son of Uzzi, son of Michri, —and Meshullam, son of Shephatiah, son of Reuel, son of Ibnijah;
9 Àwọn ènìyàn láti Benjamini gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ ọ́ nínú ìran wọn nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó dín mẹ́rìnlélógójì. Gbogbo àwọn ọkùnrin yí jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé.
and their brethren, by their generations, nine hundred and fifty-six, —all these men, were ancestral chiefs, to their ancestral house.
10 Ní ti àwọn àlùfáà: Jedaiah; Jehoiaribi; Jakini;
And, of the priests, Jedaiah, and Jehoiarib, and Jachin, —
11 Asariah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, olórí tí ó ń bojútó ilé Ọlọ́run;
and Azariah son of Hilkiah, son of Meshullam, son of Zadok, son of Meraioth, son of Ahitub, chief ruler of the house of God;
12 Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah; àti Masai ọmọ Adieli, ọmọ Jahisera, ọmọ Meṣullamu ọmọ Meṣilemiti, ọmọ Immeri.
and Adaiah, son of Jeroham, son of Pashhur, son of Malchijah, —and Maasai son of Adiel, son of Jahzerah, son of Meshullam, son of Meshillemith, son of Immer;
13 Àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀sán ó dín méjì. Wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin, tí wọ́n lè dúró fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run.
and their brethren, chief men of their ancestral house, a thousand and seven hundred and sixty, —able men, for the business of the service of the house of God.
14 Ní ti àwọn ará Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ará Merari;
And, of the Levites, Shemaiah, son of Hasshub, son of Azrikam, son of Hashabiah, of the sons of Merari;
15 Bakibakari, Hereṣi, Galali àti Mattaniah, ọmọ Mika, ọmọ Sikri, ọmọ Asafu;
and Bakbakkar, Heresh, and Galal, —and Mattaniah, son of Mica, son of Zichri, son of Asaph;
16 Obadiah ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni; àti Berekiah ọmọ Asa, ọmọ Elkana, tí ó ń gbé nínú àwọn ìlú àwọn ará Netofa.
and Obadiah, son of Shemaiah, son of Galal, son of Jeduthun, —and Berechiah son of Asa, son of Elkanah, who dwelt in the villages of the Netophathites.
17 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà: Ṣallumu, Akkubu, Talmoni, Ahimani àti arákùnrin wọn, Ṣalumu olóyè wọn,
And, the keepers of the gates, were Shallum, and Akkub, and Talmon, and Ahiman, —and their brethren—Shallum the chief;
18 ti wà ní ipò ìdúró ní ẹnu-ọ̀nà ọba ní apá ìhà ìlà-oòrùn títí di àkókò yí. Wọ̀nyí ni àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí ó jẹ́ ti ìpàgọ́ àwọn ará Lefi.
and, hitherto, they were in the gate of the king, eastward, —the same, were the keepers of the gate, for the camps of the sons of Levi.
19 Ṣallumu ọmọ Kore ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora, àti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Láti ìdílé rẹ̀ (àwọn ará Korati) ni ó dúró fún ṣíṣọ́ ìloro ẹnu-ọ̀nà àgọ́ gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti ń dúró fún ṣíṣọ́ àbáwọlé ibùgbé Olúwa.
And, Shallum, son of Kore, son of Ebiasaph, son of Korah and his brethren of his ancestral house—the Korahites, were over the business of the service, watchers at the vestibule of the tent, —and, their fathers, had been over the camp of Yahweh, watchers at the entrance.
20 Ní ìgbà àkọ́kọ́ Finehasi ọmọ Eleasari jẹ́ olórí fún àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà, Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
And, Phinehas son of Eleazar, was, chief ruler, over them aforetime, Yahweh, being with him.
21 Sekariah, ọmọ Meṣelemiah jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àbáwọlé sí àgọ́ ibi ìpàdé.
Zechariah son of Meshelemiah, was door-keeper at the entrance of the tent of meeting.
22 Gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, àwọn tí a yàn láti jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àwọn ìloro jẹ́ igba ó lé méjìlá. A ka àwọn wọ̀nyí nípa ìdílé ní ìletò wọn. Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ni a ti yàn sí ipò láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Samuẹli, aríran, nítorí òtítọ́ wọn.
All those who were chosen for door-keepers in the vestibule, were two hundred and twelve, —the same, in their villages, had registered themselves, the same, did David and Samuel the seer establish in their trust.
23 Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ni ó wà fún ṣíṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ilé tí a pè ní àgọ́.
So, they and their sons, were over the gates of the house of Yahweh, of the house of the tent, by watches.
24 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà wà ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin: ìlà-oòrùn, ìwọ̀-oòrùn àríwá àti gúúsù.
Towards the four winds, were the keepers of the gates, —eastward, westward, northward, and southward.
25 Àwọn arákùnrin wọn ní àwọn ìletò wọn ní láti wá ní àkókò dé àkókò láti pín iṣẹ́ ìsìn wọn fún àkókò ọjọ́ méje.
And, their brethren in their villages, had to come in, every seven days, from time to time, along with these.
26 Ṣùgbọ́n àwọn olórí alábojútó ẹnu-ọ̀nà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ni a yàn fún àwọn iyàrá àti àwọn àpótí ìṣúra ní ilé Ọlọ́run.
For, in trust, were four mighty men of the keepers of the gates, the same, were Levites, —and they were over the chambers, and over the treasuries of the house of God.
27 Wọ́n á lo gbogbo òru ní dídúró yí ilé Ọlọ́run ká, nítorí wọ́n ní láti ṣọ́ ọ, wọ́n sì ní àṣẹ sí kọ́kọ́rọ́ fún ṣíṣí i ní àràárọ̀.
And, round about the house of God, used they to lodge, —for, upon them, was the charge, and they were over the setting open, morning by morning.
28 Díẹ̀ wà ní ìdí ohun èlò tí à ń lò fún ìsìn ilé Ọlọ́run; wọn a máa kà á nígbà tí wọ́n gbé e wọlé àti nígbà tí a kó wọn jáde.
And, some from among them, were over the utensils of the service, —for, by number, used they to bring them in, and, by number, used they to take them forth.
29 Àwọn mìíràn ni a yàn láti bojútó ohun èlò àti gbogbo ohun èlò ilé tí a yà sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run, àti ìyẹ̀fun àti ọtí èso àjàrà àti òróró náà, tùràrí àti tùràrí olóòórùn dídùn.
And, some from among them, were appointed over the utensils, yea over all the vessels of the holy place, —and over the fine meal, and the wine, and the oil, and the frankincense, and the spices.
30 Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn àlùfáà ni ó ń bojútó pípò tùràrí olóòórùn dídùn papọ̀.
And, some from among the sons of the priests, were compounders of perfumes, with the spices.
31 Ará Lefi tí a sọ ní Mattitiah àkọ́bí ọmọkùnrin Ṣallumu ará Kora ni a yàn, tí ń ṣe alábojútó ohun tí a dín.
And, Mattithiah, from among the Levites, —the same, was the firstborn of Shallum the Korahite—was in trust over the making of the flat cakes.
32 Àti nínú àwọn arákùnrin wọn, nínú àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣe ìtọ́jú àkàrà ìfihàn, láti máa pèsè rẹ̀ ní ọjọọjọ́ ìsinmi.
And, some from among the Kohathites, of their brethren, were over the Bread that was set in Array, —to place it sabbath by sabbath.
33 Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Lefi dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì ṣe lára iṣẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ náà lọ́sàn, lóru.
These, also were the singers, ancestral chiefs of the Levites, in the chambers, free, —for, by day and by night, was there [a charge] upon them, in the business.
34 Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Lefi, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
These, were the ancestral chiefs, of the Levites, by their generations, chief men, —these, dwelt in Jerusalem.
35 Jeieli baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka,
And, in Gibeon, dwelt the father of Gibeon, Jeiel, —the name of whose wife, was Maacah:
36 pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀ jẹ́ Abdoni, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu.
and, his firstborn son, Abdon, —and Zur, and Kish, and Baal and Ner, and Nadab;
37 Gedori, Ahio, Sekariah àti Mikiloti.
and Gedor, and Ahio, and Zechariah, and Mikloh.
38 Mikiloti jẹ́ baba Ṣimeamu, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
And, Mikloth, begat Shimeam—and, they also, over against their brethren, did dwell in Jerusalem, along with their brethren.
39 Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba a Saulu, àti Saulu baba a Jonatani, àti Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
And, Ner, begat Kith, and, Kish, begat Saul, —and, Saul, begat Jonathan, and Malchishua, and Abinadab, and Eshbaal;
40 Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali, tí ó jẹ́ baba Mika.
and, the son of Jonathan, was Merib-baal, —and, Merib-baal, begat Micah;
41 Àwọn ọmọ Mika: Pitoni. Meleki, Tarea àti Ahasi.
and, the sons of Micah, were Pithon, and Melech, and Tahrea [and Ahaz];
42 Ahasi jẹ́ baba Jada, Jada jẹ́ baba Alemeti, Asmafeti, Simri, sì Simri jẹ́ baba Mosa.
and, Ahaz, begat Jarah, and, Jarah begat Alemeth, and Azmaveth, and Zimri, —and Zimri, begat Moza;
43 Mosa jẹ́ baba Binea; Refaiah jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
and, Moza, begat Binea, —and Raphaiah his son, Eleasah his son, Azel his son;
44 Aseli ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli Ṣeariah, Obadiah àti Hanani, gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
and, Azel, had six sons, and these are their names—Azrikam, [his firstborn], and Ishmael, and Sheariah and Obadiah, and Hanan, [and Asah]. These, were the sons of Azel.

< 1 Chronicles 9 >