< 1 Chronicles 9 >

1 Gbogbo Israẹli ni a kọ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá nínú ìwé àwọn ọba Israẹli. Àwọn ènìyàn Juda ni a kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli nítorí àìṣòótọ́ wọn.
So all Israel were recorded by their genealogies, and, behold, they are written in the book of the Kings of Israel; but [the men of] Judah were carried away into exile to Babylon for their unfaithfulness.
2 Nísinsin yìí, àwọn tí ó kọ́kọ́ tún tẹ̀dó lórí ohun ìní wọn ní ìlú wọn ni díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa.
And the first inhabitants that [dwelt again] in their possessions in their cities, were the Israelites, the priests, the Levites, and the temple-servants.
3 Àwọn tí ó wá láti Juda láti Benjamini àti láti Efraimu àti Manase tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu jẹ́:
And in Jerusalem dwelt some of the children of Judah, and of the children of Benjamin, and of the children of Ephraim, and Menasseh.
4 Uttai ọmọ Ammihudu, ọmọ Omri, ọmọ Imri, ọmọ Bani, ìran ọmọ Peresi ọmọ Juda.
'Uthai the son of 'Ammihud, the son of 'Omri, the son of Imri, the son of Bani, of the children of Perez the son of Judah.
5 Àti nínú ará Ṣilo: Asaiah àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀.
And of the Shilonites: 'Assayah the first-born, and his sons.
6 Ní ti ará Sera: Jeueli. Àwọn ènìyàn láti Juda sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́wàá.
And of the sons of Zerach: Je'uel, and their brethren, six hundred and ninety.
7 Àti nínú àwọn ọmọ Benjamini ni: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Hodafiah; ọmọ Hasenuah;
And of the sons of Benjamin: Sallu the son of Meshullam, the son of Hodavyah, the son of Hassenuah,
8 Ibinaiah ọmọ Jerohamu; Ela ọmọ Ussi, ọmọ Mikri; àti Meṣullamu ọmọ Ṣefatia; ọmọ Reueli, ọmọ Ibinijah.
And Yibneyah the son of Jerocham, and Elah the son of 'Uzzi, the son of Michri, and Meshullam the son of Shephatyah, the son of Re'uel, the son of Yibniyah;
9 Àwọn ènìyàn láti Benjamini gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ ọ́ nínú ìran wọn nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó dín mẹ́rìnlélógójì. Gbogbo àwọn ọkùnrin yí jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé.
And their brethren, according to their generations, nine hundred and fifty and six. All these men were chiefs of the divisions of their family divisions.
10 Ní ti àwọn àlùfáà: Jedaiah; Jehoiaribi; Jakini;
And of the priests: Jeda'yah, and Jehoyarib, and Jachin.
11 Asariah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, olórí tí ó ń bojútó ilé Ọlọ́run;
And 'Azaryah the son of Chilkiyah, the son of Meshullam, the son of Zadok, the son of Merayoth, the son of Actitub, the ruler of the house of God.
12 Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah; àti Masai ọmọ Adieli, ọmọ Jahisera, ọmọ Meṣullamu ọmọ Meṣilemiti, ọmọ Immeri.
And 'Adayah the son of Jerocham, the son of Pashchur, the son of Malkiyah, and Ma'sai the son of 'Adiel, the son of Jachzerah, the son of Meshullam, the son of Meshillemith, the son of Immer:
13 Àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀sán ó dín méjì. Wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin, tí wọ́n lè dúró fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run.
And their brethren, chiefs of their family divisions, were one thousand and seven hundred and sixty, very able men for the work of the service of the house of God.
14 Ní ti àwọn ará Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ará Merari;
And of the Levites: Shema'yah the son of Chasshub, the son of 'Azrikam, the son of Chashabyah, of the sons of Merari;
15 Bakibakari, Hereṣi, Galali àti Mattaniah, ọmọ Mika, ọmọ Sikri, ọmọ Asafu;
And Bakbakkar, Cheresh, and Galal, and Matthanyah the son of Micha, the son of Zichri, the son of Assaph;
16 Obadiah ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni; àti Berekiah ọmọ Asa, ọmọ Elkana, tí ó ń gbé nínú àwọn ìlú àwọn ará Netofa.
And 'Obadiah the son of Shema'yah, the son of Galal, the son of Jeduthun; and Berechyah the son of Assa, the son of Elkanah, that dwelt in the villages of the Netophathites.
17 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà: Ṣallumu, Akkubu, Talmoni, Ahimani àti arákùnrin wọn, Ṣalumu olóyè wọn,
And the gatekeepers were Shallum, and 'Akkub, and Talmon, and Achiman, and their brethren, Shallum being the chief;
18 ti wà ní ipò ìdúró ní ẹnu-ọ̀nà ọba ní apá ìhà ìlà-oòrùn títí di àkókò yí. Wọ̀nyí ni àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí ó jẹ́ ti ìpàgọ́ àwọn ará Lefi.
And up to this time they are in the king's gate to the eastward: they are the gatekeepers for the camps of the children of Levi.
19 Ṣallumu ọmọ Kore ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora, àti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Láti ìdílé rẹ̀ (àwọn ará Korati) ni ó dúró fún ṣíṣọ́ ìloro ẹnu-ọ̀nà àgọ́ gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti ń dúró fún ṣíṣọ́ àbáwọlé ibùgbé Olúwa.
And Shallum the son of Kore, the son of Ebyassaph, the son of Korach, and his brethren, of the house of his father, the Korchites, being over the work of the service, were the watchmen at the threshold of the tabernacle: and their fathers, being over the camp of the Lord, were the watchmen at the entrance [thereof].
20 Ní ìgbà àkọ́kọ́ Finehasi ọmọ Eleasari jẹ́ olórí fún àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà, Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
And Phinehas the son of El'azar was the ruler over them in times past; [and] the Lord was with him.
21 Sekariah, ọmọ Meṣelemiah jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àbáwọlé sí àgọ́ ibi ìpàdé.
[And] Zechariah the son of Meshelemyah was gatekeeper at the entrance of the tabernacle of the congregation.
22 Gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, àwọn tí a yàn láti jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àwọn ìloro jẹ́ igba ó lé méjìlá. A ka àwọn wọ̀nyí nípa ìdílé ní ìletò wọn. Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ni a ti yàn sí ipò láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Samuẹli, aríran, nítorí òtítọ́ wọn.
All of these selected to be gatekeepers at the thresholds were two hundred and twelve. These were recorded according to their genealogy in their villages; [and they were] those [whom] David and Samuel the seer did ordain in their trust.
23 Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ni ó wà fún ṣíṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ilé tí a pè ní àgọ́.
Both they and their children had the oversight over the gates of the house of the Lord, [namely, ] the house of the tabernacle, as watches.
24 Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà wà ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin: ìlà-oòrùn, ìwọ̀-oòrùn àríwá àti gúúsù.
On four quarters were the gatekeepers, toward the east, the west, the north, and the south.
25 Àwọn arákùnrin wọn ní àwọn ìletò wọn ní láti wá ní àkókò dé àkókò láti pín iṣẹ́ ìsìn wọn fún àkókò ọjọ́ méje.
And their brethren, who were in their villages, had to come after every seven days from time to time in common with these.
26 Ṣùgbọ́n àwọn olórí alábojútó ẹnu-ọ̀nà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ni a yàn fún àwọn iyàrá àti àwọn àpótí ìṣúra ní ilé Ọlọ́run.
For in [their] trust were these four chief gatekeepers— these Levites, and they were [appointed] over the chambers and treasuries of the house of God.
27 Wọ́n á lo gbogbo òru ní dídúró yí ilé Ọlọ́run ká, nítorí wọ́n ní láti ṣọ́ ọ, wọ́n sì ní àṣẹ sí kọ́kọ́rọ́ fún ṣíṣí i ní àràárọ̀.
And they lodged round about the house of God; because upon them rested the duty of watching, and they had the supervision of the opening thereof each and every morning.
28 Díẹ̀ wà ní ìdí ohun èlò tí à ń lò fún ìsìn ilé Ọlọ́run; wọn a máa kà á nígbà tí wọ́n gbé e wọlé àti nígbà tí a kó wọn jáde.
And some of them had the charge of the vessels for the service; for by number did they bring them in, and by number did they carry them out.
29 Àwọn mìíràn ni a yàn láti bojútó ohun èlò àti gbogbo ohun èlò ilé tí a yà sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run, àti ìyẹ̀fun àti ọtí èso àjàrà àti òróró náà, tùràrí àti tùràrí olóòórùn dídùn.
Some of them also were appointed over the vessels, and over all the vessels of the sanctuary, and over the fine flour, and the wine, and the oil, and the frankincense, and the spices.
30 Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn àlùfáà ni ó ń bojútó pípò tùràrí olóòórùn dídùn papọ̀.
And some of the sons of the priests prepared the mixture of the spices.
31 Ará Lefi tí a sọ ní Mattitiah àkọ́bí ọmọkùnrin Ṣallumu ará Kora ni a yàn, tí ń ṣe alábojútó ohun tí a dín.
And Matthithyah, one of the Levites, who was the first-born of Shallum the Korchite, had the trust over the meat-offerings that were baked in the pans.
32 Àti nínú àwọn arákùnrin wọn, nínú àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣe ìtọ́jú àkàrà ìfihàn, láti máa pèsè rẹ̀ ní ọjọọjọ́ ìsinmi.
And others of their brethren, of the sons of the Kehathites, were over the orders of the shew-bread, to prepare it every sabbath.
33 Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Lefi dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì ṣe lára iṣẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ náà lọ́sàn, lóru.
But these the singers, the chiefs of the divisions of the Levites, remained in the chambers free of service; for day and night were they obliged to engage in that work.
34 Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Lefi, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
These are the chiefs of the divisions of the Levites, being the chiefs for their generations: these dwelt at Jerusalem.
35 Jeieli baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka,
And in Gib'on dwelt the father of Gib'on, Je'iel; and the name of his wife was Ma'achah;
36 pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀ jẹ́ Abdoni, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu.
And his first-born son was 'Abdon, then Zur, and Kish, and Ba'al, and Ner, and Nadab,
37 Gedori, Ahio, Sekariah àti Mikiloti.
And Gedor, and Achyo, and Zechariah, and Mikloth.
38 Mikiloti jẹ́ baba Ṣimeamu, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
And Mikloth begat Shimam. And they also dwelt alongside of their brethren at Jerusalem, with their brethren.
39 Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba a Saulu, àti Saulu baba a Jonatani, àti Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
And Ner begat Kish; and Kish begat Saul; and Saul begat Jehonathan, and Malki-shua', and Abinadab, and Eshba'al.
40 Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali, tí ó jẹ́ baba Mika.
And the son of Jehonathan was Merib-ba'al: and Merib-ba'al begat Michah.
41 Àwọn ọmọ Mika: Pitoni. Meleki, Tarea àti Ahasi.
And the sons of Michah were, Pithon, and Melech, and Thachrea'.
42 Ahasi jẹ́ baba Jada, Jada jẹ́ baba Alemeti, Asmafeti, Simri, sì Simri jẹ́ baba Mosa.
And Achaz begat Ja'rah; and Ja'rah begat 'Alemeth, 'Azmaveth, and Zimri; and Zimri begat Moza;
43 Mosa jẹ́ baba Binea; Refaiah jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
And Moza begat Bin'a; ! and Rephayah his son, El'assah his son, Azel his son.
44 Aseli ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli Ṣeariah, Obadiah àti Hanani, gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
And Azel had six sons, and these are their names, 'Azrikam, Bocheru, and Ishmael, and She'aryah, and 'Obadiah, and Chanan: these were the sons of Azel.

< 1 Chronicles 9 >