< 1 Chronicles 8 >

1 Benjamini jẹ́ baba: Bela àkọ́bí rẹ̀, Aṣbeli ọmọkùnrin ni ẹ̀ẹ̀kejì, Ahara ẹ̀ẹ̀kẹ́ta,
Ben-jamín engendró a Bale su primogénito, Asbel el segundo, Ahala el tercero,
2 Noha ẹ̀ẹ̀kẹrin àti Rafa ẹ̀karùnún.
Nohaa el cuarto, y Rafa el quinto.
3 Àwọn ọmọ Bela ni, Adari, Gera, Abihudi,
Y los hijos de Bale fueron Addar, Gera, Abiud,
4 Abiṣua, Naamani, Ahoa,
Abisué, Naamán, Ahoe,
5 Gera, Ṣefufani àti Huramu.
Ítem, Gera, Sefufán, y Huram.
6 Wọ̀nyí ni àwọn ìran ọmọ Ehudu, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé tí ó ń gbé ní Geba tí a sì lé kúrò lọ sí Manahati:
Y estos son los hijos de Ahod, y estos son las cabezas de padres que habitaron en Gabaa, y fueron trasportados a Manahat:
7 Naamani Ahijah àti Gera, tí ó lé wọn kúrò ní ìlú, àti tí ó sì jẹ́ baba Ussa àti Ahihudu.
Es a saber, Nahamán, Aquías, y Gera: este los trasportó, y engendró a Oza, y Ahihud.
8 A bí àwọn ọmọkùnrin fún Ṣaharaimu ní Moabu lẹ́yìn tí ó ti kọ àwọn ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀, Huṣimu àti Baara.
Y Saharaim engendró en la provincia de Moab, después que dejó a Husim y a Bara que eran sus mujeres.
9 Nípasẹ̀ ìyàwó rẹ̀ Hodeṣi ó ní Jobabu Sibia, Meṣa, Malkamu,
Y engendró de Codes su mujer a Jobab, Sebias, Mosa, Molcom,
10 Jeusi, Sakia àti Mirma. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, olórí àwọn ìdílé.
Jehús, Sequías, y Marma. Estos son sus hijos, cabezas de familias.
11 Nípasẹ̀ Huṣimu ó ní Abitubu àti Elipali.
Mas de Husim engendró a Abitob, y a Elfaal.
12 Àwọn ọmọ Elipali: Eberi, Miṣamu, Ṣemedu (ẹni tí ó kọ́ Ono àti Lodi pẹ̀lú àwọn ìletò àyíká rẹ̀.)
Y los hijos de Elfaal fueron Jeber, Misaam, y Samad, el cual edificó a Ono, y a Lot con sus aldeas:
13 Pẹ̀lú Beriah àti Ṣema, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé ti àwọn tí ó ń gbé ní Aijaloni àti àwọn tí ó lé àwọn olùgbé Gati kúrò.
Y Barias y Sama; estos fueron las cabezas de las familias de los moradores de Ajalón. Estos echaron a los moradores de Get.
14 Ahio, Ṣasaki, Jeremoti,
Ítem, Ahio, Sesac, Jerimot,
15 Sebadiah, Aradi, Ederi
Zabadías, Arod, Heder,
16 Mikaeli, Iṣifa àti Joha jẹ́ àwọn ọmọ Beriah.
Micael, Jespa, y Joa, hijos de Barias.
17 Sebadiah, Meṣullamu, Hiski, Heberi
Y Zabadías, Mosollam, Hezeci, Jeber,
18 Iṣimerai, Isiliahi àti Jobabu jẹ́ àwọn ọmọ Elipali.
Jesamari, Jezlia, y Jobab, hijos de Elfaal.
19 Jakimu, Sikri, Sabdi,
Y Jacim, Zecri, Zabdi,
20 Elienai, Siletai, Elieli,
Elioenai, Seletai, Eliel,
21 Adaiah, Beraiah àti Ṣimrati jẹ́ àwọn ọmọ, Ṣimei.
Adaias, Baraias, y Samarat, hijos de Semeí.
22 Iṣipani Eberi, Elieli,
Y Jefán, Jeber, Eliel,
23 Abdoni, Sikri, Hanani,
Abdón, Zecri, Hanán,
24 Hananiah, Elamu, Anitotijah,
Jananías, Helam, Anatotias,
25 Ifediah àti Penueli jẹ́ àwọn ọmọ Ṣasaki.
Jefdaias, y Fanuel, hijos de Sesac.
26 Ṣamṣerai, Ṣeharaiah, Ataliah
Y Samsari, Jahorias, Otolias,
27 Jareṣiah, Elijah àti Sikri jẹ́ àwọn ọmọ Jerohamu.
Jersias, Elijas, y Zecri, hijos de Jeroham.
28 Gbogbo àwọn wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn ìdílé, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìran wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Estos fueron príncipes de familias por sus linajes, capitanes, y habitaron en Jerusalem.
29 Jeieli, baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Ìyàwó o rẹ̀ a má jẹ́ Maaka,
Y en Gabaón habitaron Abigabaón, la mujer del cual se llamó Maaca;
30 àkọ́bí rẹ̀ a sì máa jẹ́ Abdoni wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu,
Y su hijo primogénito Abdón, y Sur, Cis, Baal, Nadab,
31 Gedori Ahio, Sekeri
Gedor, Ahio, y Zaquer.
32 pẹ̀lú Mikiloti, tí ó jẹ́ baba Ṣimea. Wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
Y Macellot engendró a Samaa, los cuales también habitaron en frente de sus hermanos en Jerusalem con sus hermanos.
33 Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba Saulu àti Saulu baba Jonatani, Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
Y Ner engendró a Cis, y Cis engendró a Saul, y Saul engendró a Jonatán, Melqui-sua, Abinadab, y Esbaal.
34 Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali tí ó jẹ́ baba Mika.
Hijo de Jonatán fue Meri-baal, Meri-baal engendró a Mica.
35 Àwọn ọmọ Mika: Pitoni, Meleki, Tarea, àti Ahasi.
Los hijos de Mica fueron Fitón, Melec, Taraa, y Ajaz.
36 Ahasi jẹ́ baba a Jeheada, Jeheada jẹ́ baba a Alemeti, Asmafeti àti Simri, Simri sì jẹ́ baba Mosa.
Y Ajaz engendró a Joada, y Joada engendró a Alamat, y a Azmot, y a Zamrí: y Zamrí engendró a Mosa:
37 Mosa jẹ́ baba Binea; Rafa sì jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
Y Mosa engendró a Banaa, hijo del cual fue Rafa, hijo del cual fue Elasa, cuyo hijo fue Asel.
38 Aseli ní ọmọ mẹ́fà pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli, Ṣeariah, Obadiah àti Hanani. Gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
Y los hijos de Asel fueron seis, cuyos nombres son Ezricam, Bocru, Ismael, Sarias, Abdías y Hanán: todos estos fueron hijos de Asel.
39 Àwọn ọmọ arákùnrin rẹ̀ Eseki: Ulamu àkọ́bí rẹ̀, Jeuṣi ọmọkùnrin ẹ̀ẹ̀kejì àti Elifeleti ẹ̀ẹ̀kẹ́ta.
Y los hijos de Esec su hermano fueron Ulam su primogénito, Jehús el segundo, Elifalet el tercero.
40 Àwọn ọmọ Ulamu jẹ́ ògboyà jagunjagun tí ó lè gbá orin mú. Wọ́n ní ọ̀pọ̀ ọmọkùnrin àti ọmọ ọmọkùnrin áàdọ́jọ ní gbogbo rẹ̀. Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ìran ọmọ Benjamini.
Y fueron los hijos de Ulam varones valientes en fuerzas, flecheros diestros, los cuales tuvieron muchos hijos y nietos, ciento y cincuenta. Todos estos fueron de los hijos de Ben-jamín.

< 1 Chronicles 8 >