< 1 Chronicles 8 >

1 Benjamini jẹ́ baba: Bela àkọ́bí rẹ̀, Aṣbeli ọmọkùnrin ni ẹ̀ẹ̀kejì, Ahara ẹ̀ẹ̀kẹ́ta,
Or Benjamin engendra Bélah, qui fut son premier-né, Asbel le second, Achrah le troisième,
2 Noha ẹ̀ẹ̀kẹrin àti Rafa ẹ̀karùnún.
Noah le quatrième, et Rapha le cinquième.
3 Àwọn ọmọ Bela ni, Adari, Gera, Abihudi,
Et les enfants de Bélah furent, Addar, Guéra, Abihud.
4 Abiṣua, Naamani, Ahoa,
Abisuah, Nahaman, Ahoah,
5 Gera, Ṣefufani àti Huramu.
Guéra, Séphuphan, et Huram.
6 Wọ̀nyí ni àwọn ìran ọmọ Ehudu, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé tí ó ń gbé ní Geba tí a sì lé kúrò lọ sí Manahati:
Ce sont là les enfants d'Ehud. Ceux-là étaient chefs des pères des habitants de Guéba, qui furent transportés à Manahath.
7 Naamani Ahijah àti Gera, tí ó lé wọn kúrò ní ìlú, àti tí ó sì jẹ́ baba Ussa àti Ahihudu.
Et Nahaman, et Ahija, et Guéra, qui les transporta; [et] qui après engendra Huza et Ahihud.
8 A bí àwọn ọmọkùnrin fún Ṣaharaimu ní Moabu lẹ́yìn tí ó ti kọ àwọn ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀, Huṣimu àti Baara.
Or Saharajim, après les avoir renvoyés, eut des enfants au pays de Moab, de Husim, et de Bahara ses femmes.
9 Nípasẹ̀ ìyàwó rẹ̀ Hodeṣi ó ní Jobabu Sibia, Meṣa, Malkamu,
Et il engendra, de Hodés sa femme Jobab, Tsibia, Mesa, Malcam,
10 Jeusi, Sakia àti Mirma. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, olórí àwọn ìdílé.
Jehuts, Socja, et Mirma. Ce sont là ses enfants, chefs des pères.
11 Nípasẹ̀ Huṣimu ó ní Abitubu àti Elipali.
Mais de Husim il engendra Abitub, Elpahal.
12 Àwọn ọmọ Elipali: Eberi, Miṣamu, Ṣemedu (ẹni tí ó kọ́ Ono àti Lodi pẹ̀lú àwọn ìletò àyíká rẹ̀.)
Et les enfants d'Elpahal furent Héber, Misham, et Semed, qui bâtit Onò, et Lod, et les villes de son ressort.
13 Pẹ̀lú Beriah àti Ṣema, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé ti àwọn tí ó ń gbé ní Aijaloni àti àwọn tí ó lé àwọn olùgbé Gati kúrò.
Et Bériha et Sémah furent chefs des pères des habitants d'Ajalon; ils mirent en fuite les habitants de Gath.
14 Ahio, Ṣasaki, Jeremoti,
Et Ahio, Sasak, Jérémoth,
15 Sebadiah, Aradi, Ederi
Zébadia, Harad, Héder,
16 Mikaeli, Iṣifa àti Joha jẹ́ àwọn ọmọ Beriah.
Micaël, Jispa, et Joha, enfants de Bériha.
17 Sebadiah, Meṣullamu, Hiski, Heberi
Et Zébadia, Mesullam, Hiski, Héber,
18 Iṣimerai, Isiliahi àti Jobabu jẹ́ àwọn ọmọ Elipali.
Jisméraï, Jizlia, et Jobab, enfants d'Elpahal.
19 Jakimu, Sikri, Sabdi,
Et Jakim, Zicri, Zabdi,
20 Elienai, Siletai, Elieli,
Elihenaï, Tsillethaï, Eliël,
21 Adaiah, Beraiah àti Ṣimrati jẹ́ àwọn ọmọ, Ṣimei.
Hadaja, Beraja, et Simrath, enfants de Simhi.
22 Iṣipani Eberi, Elieli,
Et Jispan, Héber, Eliël,
23 Abdoni, Sikri, Hanani,
Habdon, Zicri, Hanan,
24 Hananiah, Elamu, Anitotijah,
Hananja, Hélam, Hantothija,
25 Ifediah àti Penueli jẹ́ àwọn ọmọ Ṣasaki.
Jiphdeja et Pénuël, enfants de Sasak.
26 Ṣamṣerai, Ṣeharaiah, Ataliah
Et Samseraï, Seharia, Hathalija,
27 Jareṣiah, Elijah àti Sikri jẹ́ àwọn ọmọ Jerohamu.
Jaharésia, Elija, et Zicri, enfants de Jéroham.
28 Gbogbo àwọn wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn ìdílé, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìran wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
Ce sont là les chefs des pères selon les générations qui furent chefs; et ils habitèrent à Jérusalem.
29 Jeieli, baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Ìyàwó o rẹ̀ a má jẹ́ Maaka,
Et le père de Gabaon habita à Gabaon, sa femme avait nom Mahaca.
30 àkọ́bí rẹ̀ a sì máa jẹ́ Abdoni wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu,
Et son fils premier-né fut Habdon, puis Tsur, Kis, Bahal, Nadab,
31 Gedori Ahio, Sekeri
Guédor, Ahio, et Zeker.
32 pẹ̀lú Mikiloti, tí ó jẹ́ baba Ṣimea. Wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
Et Mikloth engendra Siméa. Ils habitèrent aussi vis-à-vis de leurs frères à Jérusalem, avec leurs frères.
33 Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba Saulu àti Saulu baba Jonatani, Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
Et Ner engendra Kis, et Kis engendra Saül, et Saül engendra Jonathan, Malki-suah, Abinadab, et Esbahal.
34 Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali tí ó jẹ́ baba Mika.
Le fils de Jonathan fut Mérib-bahal; et Mérib-bahal engendra Mica.
35 Àwọn ọmọ Mika: Pitoni, Meleki, Tarea, àti Ahasi.
Et les enfants de Mica furent, Pithon, Mélec, Taréah, et Achaz.
36 Ahasi jẹ́ baba a Jeheada, Jeheada jẹ́ baba a Alemeti, Asmafeti àti Simri, Simri sì jẹ́ baba Mosa.
Et Achaz engendra Jéhohadda; et Jéhohadda engendra Halemeth, Hasmaveth, et Zimri; et Zimri engendra Motsa.
37 Mosa jẹ́ baba Binea; Rafa sì jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
Et Motsa engendra Binha, qui eut pour fils Rapha, qui eut pour fils Elhasa, qui eut pour fils Atsel.
38 Aseli ní ọmọ mẹ́fà pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli, Ṣeariah, Obadiah àti Hanani. Gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
Et Atsel eut six fils, dont les noms sont, Hazrikam, Bocru, Ismaël, Séharia, Hobadia, et Hanan; tous ceux-là furent enfants d'Atsel.
39 Àwọn ọmọ arákùnrin rẹ̀ Eseki: Ulamu àkọ́bí rẹ̀, Jeuṣi ọmọkùnrin ẹ̀ẹ̀kejì àti Elifeleti ẹ̀ẹ̀kẹ́ta.
Et les enfants de Hesek son frère furent, Ulam son premier-né, Jéhu le second, Eliphelet le troisième.
40 Àwọn ọmọ Ulamu jẹ́ ògboyà jagunjagun tí ó lè gbá orin mú. Wọ́n ní ọ̀pọ̀ ọmọkùnrin àti ọmọ ọmọkùnrin áàdọ́jọ ní gbogbo rẹ̀. Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ìran ọmọ Benjamini.
Et les enfants d'Ulam furent des hommes forts et vaillants, tirant bien de l'arc, et ils eurent beaucoup de fils et de petits-fils, jusqu'à cent cinquante; tous des enfants de Benjamin.

< 1 Chronicles 8 >