< 1 Chronicles 7 >

1 Àwọn ọmọ Isakari: Tola, Pua, Jaṣubu àti Ṣimroni, mẹ́rin ni gbogbo rẹ̀.
A synowie Isascharowi: Tola i Fua, Jasub, i Semram, czterej.
2 Àwọn ọmọ Tola: Ussi, Refaiah, Jehieli, Jamai, Ibsamu àti Samuẹli olórí àwọn ìdílé wọn. Ní àkókò ìjọba, Dafidi, àwọn ìran ọmọ Tola tò lẹ́sẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí àwọn ọkùnrin alágbára ní ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀ta.
A synowie Tolego: Uzy, i Rafajasz, i Jeryjel, i Jachamaj, i Jebsam, i Samuel; a cić byli książętami według domów ojców swych, którzy poszli z Tole, mężowie bardzo duży według narodów swych; poczet ich był za dni Dawodowych dwadzieścia i dwa tysiące i sześć set.
3 Àwọn ọmọ, Ussi: Israhiah. Àwọn ọmọ Israhiah: Mikaeli, Obadiah, Joẹli àti Iṣiah. Gbogbo àwọn márààrún sì jẹ́ olóyè.
A synowie Uzego: Izrahyjasz; a synowie Izrahyjaszowi: Michael i Obadyjasz, i Joel, Jesyjasz; pięć książąt wszystkich.
4 Gẹ́gẹ́ bí ìtàn ìdílé wọn láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n ní ọkùnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógójì tí ó ti ṣe tan fún ogun, nítorí wọ́n ní ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ àti ìyàwó.
A z nimi w narodach ich, według domów ojców ich, poczet mężów walecznych trzydzieści i sześć tysięcy; bo mieli wiele żon i synów.
5 Àwọn ìbátan tí ó jẹ́ alágbára akọni àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ti àwọn ìdílé Isakari, bí a ti tò ó lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínláàádọ́rin ni gbogbo rẹ̀.
A braci ich według wszystkich rodzajów Isascharowych, mężów dużych było ośmdziesiąt i siedm tysięcy, wszystkich policzonych.
6 Àwọn ọmọ mẹ́ta Benjamini: Bela, Bekeri àti Jediaeli.
Synowie Benjaminowi: Bela i Bechor, i Jedyjael, trzej.
7 Àwọn ọmọ Bela: Esboni, Ussi, Usieli, Jerimoti àti Iri, àwọn márààrún. Àwọn ni olórí ilé baba ńlá wọn, akọni alágbára ènìyàn. A sì ka iye wọn nípa ìran wọn sí ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ènìyàn.
Synowie zaś Belego: Esbon i Uzy, i Uzyjel, i Jerymot, i Iry; pięć książąt domów ojcowskich, mężów dużych; naliczono dwadzieścia i dwa tysiące, i trzydzieści i cztery.
8 Àwọn ọmọ Bekeri: Semirahi, Joaṣi, Elieseri, Elioenai, Omri, Jeremoti, Abijah, Anatoti àti Alemeti. Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ọmọ Bekeri.
A synowie Bechorowi; Zamirai i Joaz, i Eliezer, i Elienaj, i Amry, i Jerymot, i Abijasz, i Anatot, i Alamat; wszyscy ci synowie Bechorowi.
9 Ìtàn ìdílé wọn láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn tí a kọ lẹ́sẹẹsẹ jẹ́ ti àwọn olórí ìdílé àti ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà ogún ó lé nígba ọkùnrin alágbára.
A naliczono ich według rodzajów ich, książąt domów ojców ich, mężów udatnych dwadzieścia tysięcy i dwieście.
10 Ọmọ Jediaeli: Bilhani. Àwọn ọmọ Bilhani: Jeuṣi Benjamini, Ehudu, Kenaana, Setamu, Tarṣiṣi àti Ahiṣahari.
A synowie Jedyjaelowi: Bilan; a synowie Bilanowi: Jehus, i Banjamin, i Ehod, i Chanaan, i Zetan, i Tarsys, i Achysachar.
11 Gbogbo àwọn ọmọ Jediaeli jẹ́ olórí. Àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́tàdínlógún ó lé nígba akọni ọkùnrin ni ó ti ṣetán láti jáde lọ sí ogun.
Tych wszystkich synów Jadyjaelowych według książąt domów ojcowskich, mężów bardzo dużych siedmnaście tysięcy i dwieście, wychodzących na wojnę do bitwy;
12 Àti Ṣuppimu, àti Huppimu, àwọn ọmọ Iri, àti Huṣimu, àwọn ọmọ Aheri.
Oprócz Suppim i Ofim, synów w domu zrodzonych, i Husym, i synów w obcym kraju zrodzonych.
13 Àwọn ọmọ Naftali: Jasieli, Guni, Jeseri àti Ṣallumu—ọmọ rẹ̀ nípa Biliha.
A synowie Neftalimowi: Jachsel, i Guni, i Jesser, i Selem, synowie Bali.
14 Àwọn ìran ọmọ Manase: Asrieli jẹ́ ìran ọmọ rẹ̀ ní ipasẹ̀ àlè rẹ̀ ará Aramu ó bí Makiri baba Gileadi.
A synowie Manasesowi: Asryjel, którego mu urodziła Zona, (a założnica jego Syryjanka urodziła Machyra, ojca Galaadowego.
15 Makiri sì mú ìyàwó láti àárín àwọn ará Huppimu àti Ṣuppimu. Orúkọ arábìnrin rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka. Orúkọ ìran ọmọ mìíràn a máa jẹ́ Selofehadi, tí ó ní àwọn ọmọbìnrin nìkan ṣoṣo.
A Machyr wziął sobie za żonę siostrę Ofimową i Suppimową, której imię było Maacha; ) a imię drugiego Salfaad, i miał Salfaad córki.
16 Maaka, ìyàwó Makiri bí ọmọkùnrin kan. Ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Peresi. Ó sì pe arákùnrin rẹ̀ ní Ṣereṣi, àwọn ọmọ rẹ̀ sì ní Ulamu àti Rakemu.
A urodziła Maacha, żona Machyrowa, syna, i nazwała imię jego Fares; a imię brata jego Sares, a synowie jego Ulam i Rekiem.
17 Ọmọ Ulamu: Bedani. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gileadi ọmọ Makiri, ọmọ Manase.
A synowie Ulamowi Bedon. Cić są synowie Galaada, syna Machyrowego, syna Manasesowego.
18 Arábìnrin rẹ̀. Hamoleketi bí Iṣhodi, Abieseri àti Mahila.
A siostra jego Molechet urodzi×a Isoda, i Abiezera, i Machala.
19 Àwọn ọmọ Ṣemida sì jẹ́: Ahiani, Ṣekemu, Likki àti Aniamu.
A synowie Semidowi byli Ahyjan, i Sechem, i Likchy, i Anijam.
20 Àwọn ìran ọmọ Efraimu: Ṣutelahi, Beredi ọmọkùnrin rẹ̀, Tahati ọmọ rẹ̀, Eleadah ọmọ rẹ̀. Tahati ọmọ rẹ̀
A synowie Efraimowi: Sutala, i Bered syn jego, i Tachat syn jego, i Elada syn jego, i Tachat syn jego;
21 Sabadi ọmọ, rẹ̀, àti Ṣutelahi ọmọ rẹ̀. Eseri àti Eleadi ni a pa nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin bíbí ìbílẹ̀ Gati nígbà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ fi agbára mú ohun ọ̀sìn wọn
I Zabad syn jego, i Sutala syn jego, i Eser, i Elad. A pobili ich mężowie z Get, co się byli zrodzili w onej ziemi; albowiem byli wtargnęli, aby pobrali dobytki ich.
22 Efraimu baba wọn ṣọ̀fọ̀ fún wọn ní ọjọ́ púpọ̀, àwọn ìbátan rẹ̀ wá láti tù ú nínú.
Przetoż płakał Efraim, ojciec ich, przez wiele dni; i przyszli bracia jego, aby go cieszyli.
23 Nígbà náà, ó sùn pẹ̀lú, ìyàwó rẹ̀, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin kan. Ó sì sọ ọ́ ní Beriah nítorí òfò ti wà nínú ìdílé náà.
24 Ọmọbìnrin rẹ̀ sì jẹ́ Ṣerah, ẹni tí ó kọ́ ìsàlẹ̀ àti òkè Beti-Horoni àti Useni-Ṣerah pẹ̀lú.
Córkę też jego Seerę, która pobudowała Betoron niższe i wyższe, i Uzenzeera;
25 Refa jẹ́ ọmọ rẹ̀, Resefi ọmọ rẹ̀, Tela ọmọ rẹ̀, Tahani ọmọ rẹ̀,
I Refacha syna jego, i Resefa, i Telacha syna jego, i Techena syna jego;
26 Laadani ọmọ rẹ̀ Ammihudu ọmọ rẹ̀, Eliṣama ọmọ rẹ̀,
I Laadana syna jego, Ammiuda syna jego, Elisama syna jego;
27 Nuni ọmọ rẹ̀ àti Joṣua ọmọ rẹ̀.
Nuna syna jego, Jozuego syna jego.
28 Ilẹ̀ wọn àti ìfìdíkalẹ̀ wọn ni Beteli àti àwọn ìletò tí ó yíká, Narani lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, Geseri àti àwọn ìletò rẹ̀ lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Ṣekemu àti àwọn ìletò rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Ayahi àti àwọn ìletò.
A osiadłość ich i mieszkania ich, Betel i wsi jego; a na wschód słońca Naaran; a na zachód słońca Gazer i wsi jego, i Sychem i wsi jego, aż do Aza i wsi jego.
29 Lẹ́gbẹ̀ ìpínlẹ̀ ti Manase ni Beti-Ṣeani, Taanaki, Megido àti Dori lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìletò rẹ̀. Àwọn ìran ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli ń gbé nínú ìlú wọ̀nyí.
A podle miejsc synów Manasesowych: Betsan, i wsi jego, Tanach i wsi jego, Magieddon i wsi jego, Dor i wsi jego. W tych mieszkali synowie Józefowi, syna Izraelowego.
30 Àwọn ọmọ Aṣeri: Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn sì jẹ́ Sera.
Synowie Aserowi: Jemna i Jesua, Iswy i Beryja, i Sera, siostra ich.
31 Àwọn ọmọ Beriah: Heberi àti Malkieli, tí ó jẹ́ baba Barsafiti.
A synowie Beryjaszowi: Heber i Melchyjel; ten jest ojciec Birsawitów,
32 Heberi jẹ́ baba Jafileti, Ṣomeri àti Hotami àti ti arábìnrin wọn Ṣua.
A Heber spłodził Jafleta, i Somera, i Hotama, i Suę, siostrę ich.
33 Àwọn ọmọ Jafileti: Pasaki, Bimhali àti Asifati. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jafileti.
A synowie Jafletowi: Pasach i Bimhal i Aswat. Cić są synowie Jafletowi.
34 Àwọn ọmọ Ṣomeri: Ahi, Roga, Jahuba àti Aramu.
A synowie Somerowi: Ahy i Rohaga, Jechuba i Aram.
35 Àwọn ọmọ arákùnrin rẹ̀ Helemu Sofahi, Imina, Ṣeleṣi àti Amali.
A synowie Helema, brata jego: Sofach, Jemna, i Seles, i Amal.
36 Àwọn ọmọ Sofahi: Sua, Haniferi, Ṣuali, Beri, Imra.
Synowie Sofachowi: Suach, Harnefer, i Sual, i Bery, i Imra.
37 Beseri, Hodi, Ṣamma, Ṣilisa, Itrani àti Bera.
Beser, i Hod, i Sema, i Silsa, i Jetram, i Bera.
38 Àwọn ọmọ Jeteri: Jefunne, Pisifa àti Ara.
A synowie Jeterowi: Jefone, i Fispa, i Ara, i Ulla.
39 Àwọn ọmọ Ulla: Arah, Hannieli àti Resia.
A synowie Ullowi: Arach, i Haniel, i Rysyjasz.
40 Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ìran ọmọ Aṣeri—olórí ìdílé, àṣàyàn ọkùnrin, alágbára jagunjagun àti olórí nínú àwọn ìjòyè. Iye àwọn tí a kà yẹ fún ogun, gẹ́gẹ́ bí à ti ṣe kọ ọ́ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlá ọkùnrin.
Ci wszyscy są synowie Aserowi, książęta domów rodzajów swych, wybrani i duży mężowie, przedniejsi z książąt, którzy policzeni są na wojnę do bitwy; poczet tych mężów dwadzieścia i sześć tysięcy.

< 1 Chronicles 7 >