< 1 Chronicles 6 >
1 Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Hijos de Leví: Gersón, Coat y Merari.
2 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni, àti Usieli.
Hijos de Coat: Amram, Izhar, Hebrón y Uziel.
3 Àwọn ọmọ Amramu: Aaroni, Mose àti Miriamu. Àwọn ọmọkùnrin Aaroni: Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Hijos de Amram: Aarón, Moisés y Miriam. Hijos de Aarón: Nadab, Abiú, Eleazar e Itamar.
4 Eleasari jẹ́ baba Finehasi, Finehasi baba Abiṣua
Eleazar engendró a Finees. Finees engendró a Abisúa.
5 Abiṣua baba Bukki, Bukki baba Ussi,
Abisúa engendró a Buqui. Buqui engendró a Uzi.
6 Ussi baba Serahiah, Serahiah baba Meraioti,
Uzi engendró a Zeraías. Zeraías engendró a Meraiot.
7 Meraioti baba Amariah, Amariah baba Ahitubu
Meraiot engendró a Amarías. Amarías engendró a Ahitob.
8 Ahitubu baba Sadoku, Sadoku baba Ahimasi,
Ahitob engendró a Sadoc. Sadoc engendró a Ahimaas.
9 Ahimasi baba Asariah, Asariah baba Johanani,
Ahimaas engendró a Azarías. Azarías engendró a Johanán.
10 Johanani baba Asariah. (Òhun ni ó sìn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà nínú ilé Olúwa tí Solomoni kọ́ sí Jerusalẹmu).
Johanán engendró a Azarías, quien tuvo el sacerdocio en la Casa que Salomón edificó en Jerusalén.
11 Asariah baba Amariah Amariah baba Ahitubu
Azarías engendró a Amarías. Amarías engendró a Ahitob.
12 Ahitubu baba Sadoku. Sadoku baba Ṣallumu,
Ahitob engendró a Sadoc. Sadoc engendró a Salum.
13 Ṣallumu baba Hilkiah, Hilkiah baba Asariah,
Salum engendró a Hilcías. Hilcías engendró a Azarías.
14 Asariah baba Seraiah, pẹ̀lú Seraiah baba Josadaki.
Azarías engendró a Seraías. Y Seraías engendró a Josadac.
15 A kó Josadaki lẹ́rú nígbà tí Olúwa lé Juda àti Jerusalẹmu kúrò ní ìlú nípasẹ̀ Nebukadnessari.
Josadac fue llevado cautivo cuando Yavé deportó a Judá y a Jerusalén por medio de Nabucodonosor.
16 Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Hijos de Leví: Gersón, Coat y Merari.
17 Wọ̀nyí ni àwọn orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
Éstos son los nombres de los hijos de Gersón: Libni y Simei.
18 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
Hijos de Coat: Amram, Izhar, Hebrón y Uziel.
19 Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ará Lefi tí a kọ ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí baba wọn.
Hijos de Merari: Mahli y Musi. Éstas son las familias de Leví según sus descendencias:
20 Ti Gerṣoni: Libni ọmọkùnrin rẹ̀, Jahati. Ọmọkùnrin rẹ̀, Simma ọmọkùnrin rẹ̀,
Hijos de Gersón: Libni, Jahat, Zima,
21 Joah ọmọkùnrin rẹ̀, Iddo ọmọkùnrin rẹ̀, Sera ọmọkùnrin rẹ̀ àti Jeaterai ọmọkùnrin rẹ̀.
Joa, Iddo, Zera y Jeatrai.
22 Àwọn ìran ọmọ Kohati: Amminadabu ọmọkùnrin rẹ̀, Kora ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
Los hijos de Coat: Aminadab, Coré, Asir,
23 Elkana ọmọkùnrin rẹ̀, Ebiasafi ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
Elcana, Ebiasaf, Asir,
24 Tahati ọmọkùnrin rẹ̀, Urieli ọmọkùnrin rẹ̀, Ussiah ọmọkùnrin rẹ̀ àti Saulu ọmọkùnrin rẹ̀.
Tahat, Uriel, Uzías, Saúl,
25 Àwọn ìran ọmọ Elkana: Amasai, Ahimoti
Elcana, Amasai, Ahimot,
26 Elkana ọmọ rẹ̀, Sofai ọmọ rẹ̀ Nahati ọmọ rẹ̀,
Elcana, Zofai, Nahat,
27 Eliabu ọmọ rẹ̀, Jerohamu ọmọ rẹ̀, Elkana ọmọ rẹ̀ àti Samuẹli ọmọ rẹ̀.
Eliab, Jeroham y Elcana.
28 Àwọn ọmọ Samuẹli: Joẹli àkọ́bí àti Abijah ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì.
Hijos de Samuel fueron: Joel el primogénito, y Abías el segundo.
29 Àwọn ìran ọmọ Merari: Mahili, Libni ọmọ rẹ̀. Ṣimei ọmọ rẹ̀, Ussa ọmọ rẹ̀.
Los hijos de Merari fueron: Mahli, Libni, Simei, Uza,
30 Ṣimea ọmọ rẹ̀, Haggiah ọmọ rẹ̀ àti Asaiah ọmọ rẹ̀.
Simea, Haguía, Asaías.
31 Èyí ní àwọn ọkùnrin Dafidi tí a fi sí ìdí orin nínú ilé Olúwa lẹ́yìn tí àpótí ẹ̀rí ti wá láti sinmi níbẹ̀.
Éstos son los que David estableció para el servicio del canto en la Casa de Yavé desde cuando el Arca reposó allí,
32 Wọ́n jíṣẹ́ pẹ̀lú orin níwájú àgọ́ ìpàdé títí tí Solomoni fi kọ́ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu. Wọ́n ṣe iṣẹ́ ìsìn wọn ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà tí a fi lélẹ̀ fún wọn.
quienes servían en el canto delante de la tienda del Tabernáculo de Reunión, hasta que Salomón edificó la Casa de Yavé en Jerusalén. Después estuvieron en su ministerio según su costumbre.
33 Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ó sìn pẹ̀lú ọmọ wọn. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ará Kohati: Hemani olùkọrin, ọmọ Joẹli, ọmọ Samuẹli,
Éstos y sus hijos eran los que ejercían su servicio. De los hijos de Coat: el cantor Hemán, hijo de Joel, hijo de Samuel,
34 ọmọ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elieli, ọmọ Toha,
hijo de Elcana, hijo de Jeroham, hijo de Eliel, hijo de Toa,
35 ọmọ Sufu, ọmọ Elkana, ọmọ Mahati, ọmọ Amasai,
hijo de Zuf, hijo de Elcana, hijo de Mahat, hijo de Amasai,
36 ọmọ Elkana, ọmọ Joẹli, ọmọ Asariah, ọmọ Sefaniah,
hijo de Elcana, hijo de Joel, hijo de Azarías, hijo de Sofonías,
37 ọmọ Tahati, ọmọ Asiri, ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora,
hijo de Tahat, hijo de Asir, hijo de Ebiasaf, hijo de Coré,
38 ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli;
hijo de Izhar, hijo de Coat, hijo de Leví, hijo de Israel,
39 Hemani sì darapọ̀ mọ́ Asafu, ẹni tí o sìn ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀: Asafu ọmọ Berekiah, ọmọ Ṣimea,
su hermano Asaf, el cual estaba a su mano derecha, Asaf, hijo de Berequías, hijo de Simea,
40 ọmọ Mikaeli, ọmọ Baaseiah, ọmọ Malkiah
hijo de Micael, hijo de Baasías, hijo de Malquías,
41 ọmọ Etini, ọmọ Sera, ọmọ Adaiah,
hijo de Etni, hijo de Zera, hijo de Adaía,
42 ọmọ Etani, ọmọ Simma, ọmọ Ṣimei,
hijo de Etán, hijo de Zima, hijo de Simei,
43 ọmọ Jahati, ọmọ Gerṣoni, ọmọ Lefi;
hijo de Jahat, hijo de Gersón, hijo de Leví.
44 láti ìbákẹ́gbẹ́ wọn, àwọn ará Merari wà ní ọwọ́ òsì rẹ̀: Etani ọmọ Kiṣi, ọmọ Abdi, ọmọ Malluki,
Los hijos de Merari, sus hermanos, estaban a la izquierda: Etán, hijo de Quisi, hijo de Abdi, hijo de Maluc,
45 ọmọ Haṣabiah, ọmọ Amasiah, ọmọ Hilkiah,
hijo de Hasabías, hijo de Amasías, hijo de Hilcías,
46 ọmọ Amisi, ọmọ Bani, ọmọ Ṣemeri,
hijo de Amsi, hijo de Bani, hijo de Semer,
47 ọmọ Mahili, ọmọ Muṣi, ọmọ Merari, ọmọ Lefi.
hijo de Mahli, hijo de Musi, hijo de Merari, hijo de Leví.
48 Àwọn Lefi ẹgbẹ́ wọn ni wọn yan àwọn iṣẹ́ yòókù ti àgọ́ fún, èyí tí í ṣe ilé Ọlọ́run.
Sus hermanos levitas fueron asignados a todo el ministerio del Tabernáculo de la Casa de ʼElohim.
49 Ṣùgbọ́n Aaroni àti àwọn ìran ọmọ rẹ̀ jẹ́ àwọn tí ó gbé ọrẹ kalẹ̀ lórí pẹpẹ ẹbọ sísun àti lórí pẹpẹ tùràrí ní ìbátan pẹ̀lú gbogbo ohun tí a ṣe ní Ibi Mímọ́ Jùlọ. Ṣíṣe ètùtù fún Israẹli, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run ti pàṣẹ.
Pero Aarón y sus hijos ofrecían sacrificios sobre el altar del holocausto y del incienso, ministraban en toda la obra del Lugar Santísimo y hacían los sacrificios que apaciguan por Israel según todo lo que mandó Moisés esclavo de ʼElohim.
50 Wọ̀nyí ni àwọn ìránṣẹ́ Aaroni: Eleasari ọmọ rẹ̀, Finehasi ọmọ rẹ̀, Abiṣua ọmọ rẹ̀,
Estos son los hijos de Aarón: Finees, Abisúa,
51 Bukki ọmọ rẹ̀, Ussi ọmọ rẹ̀, Serahiah ọmọ rẹ̀,
Buqui, Uzi, Zeraías,
52 Meraioti ọmọ rẹ̀, Amariah ọmọ rẹ̀, Ahitubu ọmọ rẹ̀,
Meraiot, Amarías, Ahitob,
53 Sadoku ọmọ rẹ̀ àti Ahimasi ọmọ rẹ̀.
Sadoc, Ahimaas.
54 Wọ̀nyí ni ibùgbé wọn tí a pín fún wọn gẹ́gẹ́ bí agbègbè wọn (tí a fi lé àwọn ìran ọmọ Aaroni lọ́wọ́ tí ó wá láti ẹ̀yà Kohati, nítorí kèké alákọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
Éstos son los lugares de residencia según sus campamentos en su territorio. A los hijos de Aarón de la familia de los coatitas, porque a ellos les tocó la primera suerte,
55 A fún wọn ní Hebroni ní Juda pẹ̀lú àyíká pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
les dieron Hebrón, en tierra de Judá, y sus campos de alrededor.
56 Ṣùgbọ́n àwọn pápá àti ìletò tí ó yí ìlú ńlá náà ká ni a fi fún Kalebu ọmọ Jefunne.
Pero el territorio de la ciudad y sus aldeas se dieron a Caleb, hijo de Jefone.
57 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìran ọmọ Aaroni ni a fún ní Hebroni (ìlú ti ààbò), àti Libina, Jattiri, Eṣitemoa,
De Judá dieron Hebrón, la ciudad de refugio, a los hijos de Aarón. Además [dieron ciudades] con sus campos de alrededor: Libna, Jatir, Estemoa,
59 Aṣani, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
Asán y Bet-semes.
60 Àti láti inú ẹ̀yà Benjamini, a fún wọn ní Gibeoni, Geba, Alemeti àti Anatoti lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn. Àwọn ìlú wọ̀nyí, tí a pín láàrín àwọn ẹ̀yà Kohati jẹ́ mẹ́tàlá ní gbogbo rẹ̀.
De la tribu de Benjamín [dieron ciudades] con sus campos de alrededor: Geba, Alemet y Anatot. Todas sus ciudades fueron 13, repartidas por sus familias.
61 Ìyókù àwọn ìran ọmọ Kohati ní a pín ìlú mẹ́wàá fún láti àwọn ìdílé ní ti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase.
A los hijos de Coat que quedaron les dieron por sorteo diez ciudades de la media tribu de Manasés.
62 Àwọn ìran ọmọ Gerṣoni, sí ìdílé ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ẹ̀yà àwọn ẹ̀yà Isakari, Aṣeri àti Naftali, àti láti apá ẹ̀yà Manase tí ó wà ní Baṣani.
A los hijos de Gersón, por sus familias, fueron dadas de las tribus de Isacar, Aser, Neftalí y Manasés en Basán, 13 ciudades.
63 Sebuluni àwọn ìran ọmọ Merari, ìdílé sí ìdílé, ní a pín ìlú méjìlá fún láti ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
A los hijos de Merari, por sus familias, les dieron 12 ciudades por sorteo de las tribus de Rubén, Gad y Zabulón.
64 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli fún àwọn ará Lefi ní ìlú wọ̀nyí pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Así los hijos de Israel dieron a los levitas las ciudades con sus campos de alrededor.
65 Láti ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini ni a pín ìlú tí a ti dárúkọ wọn sẹ́yìn fún.
De las tribus de los hijos de Judá, Simeón y Benjamín, dieron por sorteo las ciudades que llamaron por sus nombres.
66 Lára àwọn ìdílé Kohati ni a fún ní ìlú láti ẹ̀yà Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìlú agbègbè wọn.
De la tribu de Efraín dieron ciudades con sus campos de alrededor a las familias de los hijos de Coat,
67 Ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, a fún wọn ní Ṣekemu (ìlú ńlá ti ààbò), àti Geseri
y las siguientes ciudades de refugio con sus campos de alrededor: Siquem en la región montañosa de Efraín, Gezer,
68 Jokimeamu, Beti-Horoni.
Jocmeam, Bet-horón,
69 Aijaloni àti Gati-Rimoni lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Ajalón y Gat-rimón.
70 Pẹ̀lú láti apá ààbọ̀ ẹ̀yà Manase àwọn ọmọ Israẹli fún Aneri àti Bileamu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn, fún ìyókù àwọn ìdílé Kohati.
De la media tribu de Manasés [dieron ciudades] con sus campos de alrededor: Aner y Bileam, para los que quedaron de las familias de los hijos de Coat.
71 Àwọn ará Gerṣoni gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ààbọ̀ ẹ̀yà ti Manase wọ́n gba Golani ní Baṣani àti pẹ̀lú Aṣtarotu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù wọn.
De la familia de la media tribu de Manasés dieron [ciudades] con sus campos de alrededor a los hijos de Gersón: Golán en Basán y Astarot.
72 Láti ẹ̀yà Isakari wọ́n gba Kedeṣi, Daberati
De la tribu de Isacar [dieron ciudades] con sus campos de alrededor: Cedes, Daberat,
73 Ramoti àti Anenu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Ramot y Anem.
74 Láti ẹ̀yà Aṣeri wọ́n gba Maṣali, Abdoni,
De la tribu de Aser [dieron ciudades] con sus campos de alrededor: Masal, Abdón,
75 Hukoki àti Rehobu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Hucoc y Rehob.
76 Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Naftali wọ́n gba Kedeṣi ní Galili, Hammoni àti Kiriataimu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
De la tribu de Neftalí [dieron ciudades] con sus campos de alrededor: Cedes, en Galilea, Hamón y Quiriataim.
77 Àwọn ará Merari (ìyókù àwọn ará Lefi) gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ẹ̀yà Sebuluni wọ́n gba Jokneamu, Karta, Rimoni àti Tabori, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
A los hijos de Merari que quedaron de la tribu de Zabulón dieron [ciudades] con sus campos de alrededor: Rimón y Tabor.
78 Láti ẹ̀yà Reubeni rékọjá Jordani ìlà-oòrùn Jeriko wọ́n gba Beseri nínú aginjù Jahisa,
De la tribu de Rubén, dieron [ciudades] con sus campos de alrededor al otro lado del Jordán, frente a Jericó, al oriente del Jordán: Beser, en la región despoblada, Jaza,
79 Kedemoti àti Mefaati, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Cademot y Mefaat.
80 Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Gadi wọ́n gba Ramoti ní Gileadi Mahanaimu,
Y de la tribu de Gad [dieron ciudades] con sus campos de alrededor: Ramot de Galaad, Mahanaim,
81 Heṣboni àti Jaseri lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Hesbón y Jazer.