< 1 Chronicles 6 >

1 Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Die Söhne Levis waren: Gerson, Kehath und Merari;
2 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni, àti Usieli.
und die Söhne Kehaths: Amram, Jizhar, Hebron und Ussiel.
3 Àwọn ọmọ Amramu: Aaroni, Mose àti Miriamu. Àwọn ọmọkùnrin Aaroni: Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Und die Söhne Amrams: Aaron und Mose, und (ihre Schwester) Mirjam. Und die Söhne Aarons: Nadab und Abihu, Eleasar und Ithamar.
4 Eleasari jẹ́ baba Finehasi, Finehasi baba Abiṣua
Eleasar zeugte Pinehas, Pinehas zeugte Abisua,
5 Abiṣua baba Bukki, Bukki baba Ussi,
Abisua zeugte Bukki, Bukki zeugte Ussi,
6 Ussi baba Serahiah, Serahiah baba Meraioti,
Ussi zeugte Serahja, Serahja zeugte Merajoth,
7 Meraioti baba Amariah, Amariah baba Ahitubu
Merajoth zeugte Amarja, Amarja zeugte Ahitub,
8 Ahitubu baba Sadoku, Sadoku baba Ahimasi,
Ahitub zeugte Zadok, Zadok zeugte Ahimaaz,
9 Ahimasi baba Asariah, Asariah baba Johanani,
Ahimaaz zeugte Asarja, Asarja zeugte Johanan,
10 Johanani baba Asariah. (Òhun ni ó sìn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà nínú ilé Olúwa tí Solomoni kọ́ sí Jerusalẹmu).
Johanan zeugte Asarja – das ist derselbe, der den Priesterdienst versah in dem Tempel, den Salomo in Jerusalem erbaut hatte –;
11 Asariah baba Amariah Amariah baba Ahitubu
Asarja zeugte Amarja, Amarja zeugte Ahitub,
12 Ahitubu baba Sadoku. Sadoku baba Ṣallumu,
Ahitub zeugte Zadok, Zadok zeugte Sallum,
13 Ṣallumu baba Hilkiah, Hilkiah baba Asariah,
Sallum zeugte Hilkia, Hilkia zeugte Asarja,
14 Asariah baba Seraiah, pẹ̀lú Seraiah baba Josadaki.
Asarja zeugte Seraja, Seraja zeugte Jozadak;
15 A kó Josadaki lẹ́rú nígbà tí Olúwa lé Juda àti Jerusalẹmu kúrò ní ìlú nípasẹ̀ Nebukadnessari.
Jozadak aber zog mit, als der HERR die Bewohner von Juda und Jerusalem durch Nebukadnezar in die Gefangenschaft führen ließ.
16 Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Die Söhne Levis waren: Gersom, Kehath und Merari.
17 Wọ̀nyí ni àwọn orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
Dies aber sind die Namen der Söhne Gersoms: Libni und Simei.
18 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
Und die Söhne Kehaths waren: Amram, Jizhar, Hebron und Ussiel.
19 Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ará Lefi tí a kọ ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí baba wọn.
Die Söhne Meraris waren: Mahli und Musi. – Dies aber sind die Geschlechter der Leviten nach ihren Familienvätern:
20 Ti Gerṣoni: Libni ọmọkùnrin rẹ̀, Jahati. Ọmọkùnrin rẹ̀, Simma ọmọkùnrin rẹ̀,
Von Gersom stammten: sein Sohn Libni, dessen Sohn Jahath, dessen Sohn Simma,
21 Joah ọmọkùnrin rẹ̀, Iddo ọmọkùnrin rẹ̀, Sera ọmọkùnrin rẹ̀ àti Jeaterai ọmọkùnrin rẹ̀.
dessen Sohn Joah, dessen Sohn Iddo, dessen Sohn Serah, dessen Sohn Jeathrai. –
22 Àwọn ìran ọmọ Kohati: Amminadabu ọmọkùnrin rẹ̀, Kora ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
Die Söhne Kehaths waren: sein Sohn Amminadab, dessen Sohn Korah, dessen Sohn Assir,
23 Elkana ọmọkùnrin rẹ̀, Ebiasafi ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
dessen Sohn Elkana, dessen Sohn Ebjasaph, dessen Sohn Assir,
24 Tahati ọmọkùnrin rẹ̀, Urieli ọmọkùnrin rẹ̀, Ussiah ọmọkùnrin rẹ̀ àti Saulu ọmọkùnrin rẹ̀.
dessen Sohn Thahath, dessen Sohn Uriel, dessen Sohn Ussia, dessen Sohn Saul.
25 Àwọn ìran ọmọ Elkana: Amasai, Ahimoti
Und die Söhne Elkanas waren: Amasai und Ahimoth;
26 Elkana ọmọ rẹ̀, Sofai ọmọ rẹ̀ Nahati ọmọ rẹ̀,
dessen Sohn war Elkana, dessen Sohn Zophai, dessen Sohn Nahath,
27 Eliabu ọmọ rẹ̀, Jerohamu ọmọ rẹ̀, Elkana ọmọ rẹ̀ àti Samuẹli ọmọ rẹ̀.
dessen Sohn Eliab, dessen Sohn Jeroham, dessen Sohn Elkana (dessen Sohn Samuel).
28 Àwọn ọmọ Samuẹli: Joẹli àkọ́bí àti Abijah ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì.
Und die Söhne Samuels waren: der Erstgeborene Joel und der zweite Abia. –
29 Àwọn ìran ọmọ Merari: Mahili, Libni ọmọ rẹ̀. Ṣimei ọmọ rẹ̀, Ussa ọmọ rẹ̀.
Die Söhne Meraris waren: Mahli, dessen Sohn Libni, dessen Sohn Simei, dessen Sohn Ussa,
30 Ṣimea ọmọ rẹ̀, Haggiah ọmọ rẹ̀ àti Asaiah ọmọ rẹ̀.
dessen Sohn Simea, dessen Sohn Haggia, dessen Sohn Asaja.
31 Èyí ní àwọn ọkùnrin Dafidi tí a fi sí ìdí orin nínú ilé Olúwa lẹ́yìn tí àpótí ẹ̀rí ti wá láti sinmi níbẹ̀.
Die folgenden sind es, die David zur Leitung des Gesangs im Tempel des HERRN bestellte, nachdem die Lade dort einen festen Platz gefunden hatte;
32 Wọ́n jíṣẹ́ pẹ̀lú orin níwájú àgọ́ ìpàdé títí tí Solomoni fi kọ́ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu. Wọ́n ṣe iṣẹ́ ìsìn wọn ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà tí a fi lélẹ̀ fún wọn.
sie dienten aber als Sänger vor der Wohnung des Offenbarungszeltes, bis Salomo den Tempel des HERRN in Jerusalem erbaut hatte, und verrichteten ihr Amt nach den ihnen erteilten Weisungen.
33 Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ó sìn pẹ̀lú ọmọ wọn. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ará Kohati: Hemani olùkọrin, ọmọ Joẹli, ọmọ Samuẹli,
Die folgenden sind es, die das Amt versahen, und ihre Nachkommen: Von den zu den Kehathiten Gehörigen: Heman, der Sänger, der Sohn Joels, des Sohnes Samuels,
34 ọmọ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elieli, ọmọ Toha,
des Sohnes Elkanas, des Sohnes Jerohams, des Sohnes Eliels, des Sohnes Thoahs,
35 ọmọ Sufu, ọmọ Elkana, ọmọ Mahati, ọmọ Amasai,
des Sohnes Zuphs, des Sohnes Elkanas, des Sohnes Mahaths, des Sohnes Amasais,
36 ọmọ Elkana, ọmọ Joẹli, ọmọ Asariah, ọmọ Sefaniah,
des Sohnes Elkanas, des Sohnes Joels, des Sohnes Asarjas, des Sohnes Zephanjas,
37 ọmọ Tahati, ọmọ Asiri, ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora,
des Sohnes Thahaths, des Sohnes Assirs, des Sohnes Ebjasaphs, des Sohnes Korahs,
38 ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli;
des Sohnes Jizhars, des Sohnes Kehaths, des Sohnes Levis, des Sohnes Israels.
39 Hemani sì darapọ̀ mọ́ Asafu, ẹni tí o sìn ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀: Asafu ọmọ Berekiah, ọmọ Ṣimea,
Und sein Geschlechtsgenosse war Asaph, der ihm zur Rechten stand: Asaph, der Sohn Berechjas, des Sohnes Simeas,
40 ọmọ Mikaeli, ọmọ Baaseiah, ọmọ Malkiah
des Sohnes Michaels, des Sohnes Baasejas, des Sohnes Malkias,
41 ọmọ Etini, ọmọ Sera, ọmọ Adaiah,
des Sohnes Ethnis, des Sohnes Serahs, des Sohnes Adajas,
42 ọmọ Etani, ọmọ Simma, ọmọ Ṣimei,
des Sohnes Ethans, des Sohnes Simmas, des Sohnes Simeis,
43 ọmọ Jahati, ọmọ Gerṣoni, ọmọ Lefi;
des Sohnes Jahaths, des Sohnes Gersoms, des Sohnes Levis.
44 láti ìbákẹ́gbẹ́ wọn, àwọn ará Merari wà ní ọwọ́ òsì rẹ̀: Etani ọmọ Kiṣi, ọmọ Abdi, ọmọ Malluki,
Und von den Nachkommen Meraris, ihren Geschlechtsgenossen, stand zur Linken: Ethan, der Sohn Kisis, des Sohnes Abdis, des Sohnes Malluchs,
45 ọmọ Haṣabiah, ọmọ Amasiah, ọmọ Hilkiah,
des Sohnes Hasabjas, des Sohnes Amazjas, des Sohnes Hilkias,
46 ọmọ Amisi, ọmọ Bani, ọmọ Ṣemeri,
des Sohnes Amzis, des Sohnes Banis, des Sohnes Semers,
47 ọmọ Mahili, ọmọ Muṣi, ọmọ Merari, ọmọ Lefi.
des Sohnes Mahlis, des Sohnes Musis, des Sohnes Meraris, des Sohnes Levis.
48 Àwọn Lefi ẹgbẹ́ wọn ni wọn yan àwọn iṣẹ́ yòókù ti àgọ́ fún, èyí tí í ṣe ilé Ọlọ́run.
Ihre Geschlechtsgenossen aber, die übrigen Leviten, waren für den gesamten Dienst an der Wohnung des Tempels Gottes bestellt;
49 Ṣùgbọ́n Aaroni àti àwọn ìran ọmọ rẹ̀ jẹ́ àwọn tí ó gbé ọrẹ kalẹ̀ lórí pẹpẹ ẹbọ sísun àti lórí pẹpẹ tùràrí ní ìbátan pẹ̀lú gbogbo ohun tí a ṣe ní Ibi Mímọ́ Jùlọ. Ṣíṣe ètùtù fún Israẹli, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run ti pàṣẹ.
und zwar versahen Aaron und seine Nachkommen den Opferdienst auf dem Brandopferaltar und auf dem Räucheraltar und den gesamten Dienst am Allerheiligsten und was zur Versöhnung Israels diente, ganz so, wie Mose, der Knecht Gottes, geboten hatte.
50 Wọ̀nyí ni àwọn ìránṣẹ́ Aaroni: Eleasari ọmọ rẹ̀, Finehasi ọmọ rẹ̀, Abiṣua ọmọ rẹ̀,
Dies waren aber die Nachkommen Aarons: sein Sohn Eleasar, dessen Sohn Pinehas, dessen Sohn Abisua,
51 Bukki ọmọ rẹ̀, Ussi ọmọ rẹ̀, Serahiah ọmọ rẹ̀,
dessen Sohn Bukki, dessen Sohn Ussi, dessen Sohn Serahja,
52 Meraioti ọmọ rẹ̀, Amariah ọmọ rẹ̀, Ahitubu ọmọ rẹ̀,
dessen Sohn Merajoth, dessen Sohn Amarja, dessen Sohn Ahitub,
53 Sadoku ọmọ rẹ̀ àti Ahimasi ọmọ rẹ̀.
dessen Sohn Zadok, dessen Sohn Ahimaaz.
54 Wọ̀nyí ni ibùgbé wọn tí a pín fún wọn gẹ́gẹ́ bí agbègbè wọn (tí a fi lé àwọn ìran ọmọ Aaroni lọ́wọ́ tí ó wá láti ẹ̀yà Kohati, nítorí kèké alákọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
Folgendes aber sind ihre Wohnsitze nach ihren Niederlassungen in ihrem Gebiet: Den Nachkommen Aarons von dem Geschlecht der Kehathiten – denn auf sie war das erste Los gefallen –,
55 A fún wọn ní Hebroni ní Juda pẹ̀lú àyíká pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
ihnen gab man Hebron im Lande Juda samt den zugehörigen Weidetriften rings um sie her;
56 Ṣùgbọ́n àwọn pápá àti ìletò tí ó yí ìlú ńlá náà ká ni a fi fún Kalebu ọmọ Jefunne.
die zur Stadt gehörigen Felder aber und die zugehörigen Dörfer übergab man Kaleb, dem Sohne Jephunnes.
57 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìran ọmọ Aaroni ni a fún ní Hebroni (ìlú ti ààbò), àti Libina, Jattiri, Eṣitemoa,
Weiter übergab man den Nachkommen Aarons die Zufluchtstadt Hebron sowie Libna samt den zugehörigen Weidetriften, ferner Jatthir und Esthemoa samt den zugehörigen Weidetriften,
58 Hileni, Debiri,
Holon samt den zugehörigen Weidetriften, Debir samt den zugehörigen Weidetriften,
59 Aṣani, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
Asan samt den zugehörigen Weidetriften und Beth-Semes samt den zugehörigen Weidetriften.
60 Àti láti inú ẹ̀yà Benjamini, a fún wọn ní Gibeoni, Geba, Alemeti àti Anatoti lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn. Àwọn ìlú wọ̀nyí, tí a pín láàrín àwọn ẹ̀yà Kohati jẹ́ mẹ́tàlá ní gbogbo rẹ̀.
Weiter vom Stamme Benjamin: Geba und Allemeth samt den zugehörigen Weidetriften und Anathoth samt den zugehörigen Weidetriften. Die Gesamtzahl ihrer Städte betrug dreizehn nach ihren Familien. –
61 Ìyókù àwọn ìran ọmọ Kohati ní a pín ìlú mẹ́wàá fún láti àwọn ìdílé ní ti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase.
Die übrigen Nachkommen Kehaths aber erhielten nach ihren Geschlechtern vom Stamme Ephraim und vom Stamme Dan und vom halben Stamm Manasse durchs Los zehn Städte.
62 Àwọn ìran ọmọ Gerṣoni, sí ìdílé ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ẹ̀yà àwọn ẹ̀yà Isakari, Aṣeri àti Naftali, àti láti apá ẹ̀yà Manase tí ó wà ní Baṣani.
Die Nachkommen Gersoms erhielten nach ihren Geschlechtern vom Stamme Issaschar, vom Stamme Asser, vom Stamme Naphthali und vom halben Stamm Manasse in Basan dreizehn Städte. –
63 Sebuluni àwọn ìran ọmọ Merari, ìdílé sí ìdílé, ní a pín ìlú méjìlá fún láti ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
Die Nachkommen Meraris erhielten nach ihren Geschlechtern vom Stamme Ruben, vom Stamme Gad und vom Stamme Sebulon durchs Los zwölf Städte.
64 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli fún àwọn ará Lefi ní ìlú wọ̀nyí pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
So übergaben die Israeliten den Leviten die Städte samt den zugehörigen Weidetriften;
65 Láti ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini ni a pín ìlú tí a ti dárúkọ wọn sẹ́yìn fún.
und zwar übergaben sie durchs Los jene namentlich angeführten Städte aus den Stämmen Juda, Simeon und Benjamin.
66 Lára àwọn ìdílé Kohati ni a fún ní ìlú láti ẹ̀yà Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìlú agbègbè wọn.
Was dann die übrigen Geschlechter der Nachkommen Kahaths anbetrifft, so erhielten sie die Städte, die ihnen durchs Los zufielen, vom Stamme Ephraim abgetreten;
67 Ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, a fún wọn ní Ṣekemu (ìlú ńlá ti ààbò), àti Geseri
und zwar übergab man ihnen die Zufluchtstadt Sichem samt den zugehörigen Weidetriften auf dem Gebirge Ephraim; ferner Geser samt den zugehörigen Weidetriften,
68 Jokimeamu, Beti-Horoni.
Jokmeam samt den zugehörigen Weidetriften, Beth-Horon samt den zugehörigen Weidetriften,
69 Aijaloni àti Gati-Rimoni lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Ajjalon samt den zugehörigen Weidetriften und Gath-Rimmon samt den zugehörigen Weidetriften;
70 Pẹ̀lú láti apá ààbọ̀ ẹ̀yà Manase àwọn ọmọ Israẹli fún Aneri àti Bileamu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn, fún ìyókù àwọn ìdílé Kohati.
dazu vom halben Stamm Manasse: Aner samt den zugehörigen Weidetriften und Jibleam samt den zugehörigen Weidetriften – diese übergab man den Familien der übrigen Nachkommen Kahaths.
71 Àwọn ará Gerṣoni gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ààbọ̀ ẹ̀yà ti Manase wọ́n gba Golani ní Baṣani àti pẹ̀lú Aṣtarotu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù wọn.
Die Nachkommen Gersoms erhielten nach ihren Geschlechtern vom halben Stamm Manasse: Golan in Basan samt den zugehörigen Weidetriften und Astharoth samt den zugehörigen Weidetriften;
72 Láti ẹ̀yà Isakari wọ́n gba Kedeṣi, Daberati
ferner vom Stamme Issaschar: Kedes samt den zugehörigen Weidetriften, Daberath samt den zugehörigen Weidetriften,
73 Ramoti àti Anenu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Ramoth samt den zugehörigen Weidetriften und Anem samt den zugehörigen Weidetriften;
74 Láti ẹ̀yà Aṣeri wọ́n gba Maṣali, Abdoni,
dazu vom Stamme Asser: Masal samt den zugehörigen Weidetriften, Abdon samt den zugehörigen Weidetriften,
75 Hukoki àti Rehobu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Hukok samt den zugehörigen Weidetriften und Rehob samt den zugehörigen Weidetriften;
76 Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Naftali wọ́n gba Kedeṣi ní Galili, Hammoni àti Kiriataimu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
ferner vom Stamme Naphthali: Kedes in Galiläa samt den zugehörigen Weidetriften, Hammot samt den zugehörigen Weidetriften und Kirjathaim samt den zugehörigen Weidetriften.
77 Àwọn ará Merari (ìyókù àwọn ará Lefi) gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ẹ̀yà Sebuluni wọ́n gba Jokneamu, Karta, Rimoni àti Tabori, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Die übrigen Nachkommen Meraris erhielten vom Stamme Sebulon: Rimmon samt den zugehörigen Weidetriften und Thabor samt den zugehörigen Weidetriften;
78 Láti ẹ̀yà Reubeni rékọjá Jordani ìlà-oòrùn Jeriko wọ́n gba Beseri nínú aginjù Jahisa,
und jenseits des Jordans gegenüber von Jericho, östlich vom Jordan, erhielten sie vom Stamme Ruben: Bezer in der Steppe samt den zugehörigen Weidetriften, Jahza samt den zugehörigen Weidetriften,
79 Kedemoti àti Mefaati, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Kedemoth samt den zugehörigen Weidetriften und Mephaath samt den zugehörigen Weidetriften;
80 Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Gadi wọ́n gba Ramoti ní Gileadi Mahanaimu,
ferner vom Stamme Gad: Ramoth in Gilead samt den zugehörigen Weidetriften, Mahanaim samt den zugehörigen Weidetriften;
81 Heṣboni àti Jaseri lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Hesbon samt den zugehörigen Weidetriften und Jaser samt den zugehörigen Weidetriften.

< 1 Chronicles 6 >