< 1 Chronicles 6 >

1 Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Die Kinder Levis waren: Gerson, Kahath und Merari.
2 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni, àti Usieli.
Die Kinder aber Kahaths waren: Amram, Jizhar, Hebron und Usiel.
3 Àwọn ọmọ Amramu: Aaroni, Mose àti Miriamu. Àwọn ọmọkùnrin Aaroni: Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Die Kinder Amrams waren: Aaron, Mose und Mirjam. Die Kinder Aaron waren Nadab, Abihu, Eleasar und Ithamar.
4 Eleasari jẹ́ baba Finehasi, Finehasi baba Abiṣua
Eleasar zeugte Pinehas. Pinehas zeugte Abisua.
5 Abiṣua baba Bukki, Bukki baba Ussi,
Abisua zeugte Bukki. Bukki zeugte Usi.
6 Ussi baba Serahiah, Serahiah baba Meraioti,
Usi zeugte Serahja. Serahja zeugte Merajoth.
7 Meraioti baba Amariah, Amariah baba Ahitubu
Merajoth zeugte Amarja. Amarja zeugte Ahitob.
8 Ahitubu baba Sadoku, Sadoku baba Ahimasi,
Ahitob zeugte Zadok. Zadok zeugte Ahimaaz.
9 Ahimasi baba Asariah, Asariah baba Johanani,
Ahimaaz zeugte Asarja. Asarja zeugte Johanan.
10 Johanani baba Asariah. (Òhun ni ó sìn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà nínú ilé Olúwa tí Solomoni kọ́ sí Jerusalẹmu).
Johanan zeugte Asarja, den, der Priester war in dem Hause, das Salomo baute zu Jerusalem.
11 Asariah baba Amariah Amariah baba Ahitubu
Asarja zeugte Amarja. Amarja zeugte Ahitob.
12 Ahitubu baba Sadoku. Sadoku baba Ṣallumu,
Ahitob zeugte Zadok. Zadok zeugte Sallum.
13 Ṣallumu baba Hilkiah, Hilkiah baba Asariah,
Sallum zeugte Hilkia. Hilkia zeugte Asarja.
14 Asariah baba Seraiah, pẹ̀lú Seraiah baba Josadaki.
Asarja zeugte Seraja. Seraja zeugte Jozadak.
15 A kó Josadaki lẹ́rú nígbà tí Olúwa lé Juda àti Jerusalẹmu kúrò ní ìlú nípasẹ̀ Nebukadnessari.
Jozadak aber ward mit weggeführt, da der HERR Juda und Jerusalem durch Nebukadnezar ließ gefangen wegführen.
16 Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
So sind nun die Kinder Levis diese: Gerson, Kahath, Merari.
17 Wọ̀nyí ni àwọn orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
So heißen aber die Kinder Gersons: Libni und Simei.
18 Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
Aber die Kinder Kahaths heißen: Amram, Jizhar, Hebron und Usiel.
19 Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ará Lefi tí a kọ ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí baba wọn.
Die Kinder Meraris heißen: Maheli und Musi. Das sind die Geschlechter der Leviten nach ihren Vaterhäusern.
20 Ti Gerṣoni: Libni ọmọkùnrin rẹ̀, Jahati. Ọmọkùnrin rẹ̀, Simma ọmọkùnrin rẹ̀,
Gerson Sohn war Libni; des Sohn war Jahath; des Sohn war Simma;
21 Joah ọmọkùnrin rẹ̀, Iddo ọmọkùnrin rẹ̀, Sera ọmọkùnrin rẹ̀ àti Jeaterai ọmọkùnrin rẹ̀.
des Sohn war Joah; des Sohn war Iddo; des Sohn war Serah; des Sohn war Jeathrai.
22 Àwọn ìran ọmọ Kohati: Amminadabu ọmọkùnrin rẹ̀, Kora ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
Kahaths Sohn aber war Aminadab; des Sohn war Korah; des Sohn war Assir;
23 Elkana ọmọkùnrin rẹ̀, Ebiasafi ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
des Sohn war Elkana; des Sohn war Abiasaph; des Sohn war Assir;
24 Tahati ọmọkùnrin rẹ̀, Urieli ọmọkùnrin rẹ̀, Ussiah ọmọkùnrin rẹ̀ àti Saulu ọmọkùnrin rẹ̀.
des Sohn war Thahat; des Sohn war Uriel; des Sohn war Usia; des Sohn war Saul.
25 Àwọn ìran ọmọ Elkana: Amasai, Ahimoti
Die Kinder Elkanas waren: Amasai und Ahimoth;
26 Elkana ọmọ rẹ̀, Sofai ọmọ rẹ̀ Nahati ọmọ rẹ̀,
des Sohn war Elkana; des Sohn war Elkana von Zoph; des Sohn war Nahath;
27 Eliabu ọmọ rẹ̀, Jerohamu ọmọ rẹ̀, Elkana ọmọ rẹ̀ àti Samuẹli ọmọ rẹ̀.
des Sohn war Eliab; des Sohn war Jeroham; des Sohn war Elkana.
28 Àwọn ọmọ Samuẹli: Joẹli àkọ́bí àti Abijah ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì.
Und die Kinder Samuels waren: der Erstgeborene Vasni und Abia.
29 Àwọn ìran ọmọ Merari: Mahili, Libni ọmọ rẹ̀. Ṣimei ọmọ rẹ̀, Ussa ọmọ rẹ̀.
Meraris Sohn war Maheli; des Sohn war Libni; des Sohn war Simei; des Sohn war Usa;
30 Ṣimea ọmọ rẹ̀, Haggiah ọmọ rẹ̀ àti Asaiah ọmọ rẹ̀.
des Sohn war Simea; des Sohn war Haggia; des Sohn war Asaja.
31 Èyí ní àwọn ọkùnrin Dafidi tí a fi sí ìdí orin nínú ilé Olúwa lẹ́yìn tí àpótí ẹ̀rí ti wá láti sinmi níbẹ̀.
Dies sind aber, die David bestellte, zu singen im Hause des HERRN, als die Lade des Bundes zur Ruhe gekommen war;
32 Wọ́n jíṣẹ́ pẹ̀lú orin níwájú àgọ́ ìpàdé títí tí Solomoni fi kọ́ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu. Wọ́n ṣe iṣẹ́ ìsìn wọn ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà tí a fi lélẹ̀ fún wọn.
und sie dienten vor der Wohnung der Hütte des Stifts mit Singen, bis daß Salomo das Haus des HERRN baute zu Jerusalem, und standen nach ihrer Weise in ihrem Amt.
33 Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ó sìn pẹ̀lú ọmọ wọn. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ará Kohati: Hemani olùkọrin, ọmọ Joẹli, ọmọ Samuẹli,
Und dies sind sie, die da standen, und ihre Kinder: Von den Kindern Kahaths war Heman, der Sänger, der Sohn Joels, des Sohnes Samuel;
34 ọmọ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elieli, ọmọ Toha,
des Sohnes Elkanas, des Sohnes Jerohams, des Sohnes Eliels, des Sohnes Thoahs,
35 ọmọ Sufu, ọmọ Elkana, ọmọ Mahati, ọmọ Amasai,
des Sohnes Zuphs, des Sohnes Elkanas, des Sohnes Mahaths, des Sohnes Amasais,
36 ọmọ Elkana, ọmọ Joẹli, ọmọ Asariah, ọmọ Sefaniah,
des Sohnes Elkanas, des Sohnes Joels, des Sohnes Asarjas, des Sohnes Zephanjas,
37 ọmọ Tahati, ọmọ Asiri, ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora,
des Sohnes Thahaths, des Sohnes Assirs, des Sohnes Abiasaphs, des Sohnes Korahs,
38 ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli;
des Sohnes Jizhars, des Sohnes Kahaths, des Sohnes Levis, des Sohnes Israels.
39 Hemani sì darapọ̀ mọ́ Asafu, ẹni tí o sìn ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀: Asafu ọmọ Berekiah, ọmọ Ṣimea,
Und sein Bruder Asaph stand zu seiner Rechten. Und er, der Asaph, war ein Sohn Berechjas, des Sohnes Simeas,
40 ọmọ Mikaeli, ọmọ Baaseiah, ọmọ Malkiah
des Sohnes Michaels, des Sohnes Baesejas, des Sohnes Malchias,
41 ọmọ Etini, ọmọ Sera, ọmọ Adaiah,
des Sohnes Athnis, des Sohnes Serahs, des Sohnes Adajas,
42 ọmọ Etani, ọmọ Simma, ọmọ Ṣimei,
des Sohnes Ethans, des Sohnes Simmas, des Sohnes Simeis,
43 ọmọ Jahati, ọmọ Gerṣoni, ọmọ Lefi;
des Sohnes Jahats, des Sohnes Gersons, des Sohnes Levis.
44 láti ìbákẹ́gbẹ́ wọn, àwọn ará Merari wà ní ọwọ́ òsì rẹ̀: Etani ọmọ Kiṣi, ọmọ Abdi, ọmọ Malluki,
Ihre Brüder aber, die Kinder Meraris, standen zur Linken: nämlich Ethan, der Sohn Kusis, des Sohnes Abdis, des Sohnes Malluchs,
45 ọmọ Haṣabiah, ọmọ Amasiah, ọmọ Hilkiah,
des Sohnes Hasabjas, des Sohnes Amazjas, des Sohnes Hilkias,
46 ọmọ Amisi, ọmọ Bani, ọmọ Ṣemeri,
des Sohnes Amzis, des Sohnes Banis, des Sohnes Semers,
47 ọmọ Mahili, ọmọ Muṣi, ọmọ Merari, ọmọ Lefi.
des Sohnes Mahelis, des Sohnes Musis, des Sohnes Meraris, des Sohnes Levis.
48 Àwọn Lefi ẹgbẹ́ wọn ni wọn yan àwọn iṣẹ́ yòókù ti àgọ́ fún, èyí tí í ṣe ilé Ọlọ́run.
Ihre Brüder aber, die Leviten, waren gegeben zu allerlei Amt an der Wohnung des Hauses Gottes.
49 Ṣùgbọ́n Aaroni àti àwọn ìran ọmọ rẹ̀ jẹ́ àwọn tí ó gbé ọrẹ kalẹ̀ lórí pẹpẹ ẹbọ sísun àti lórí pẹpẹ tùràrí ní ìbátan pẹ̀lú gbogbo ohun tí a ṣe ní Ibi Mímọ́ Jùlọ. Ṣíṣe ètùtù fún Israẹli, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run ti pàṣẹ.
Aaron aber und seine Söhne waren im Amt, anzuzünden auf dem Brandopferaltar und auf dem Räucheraltar und zu allem Geschäft im Allerheiligsten und zu versöhnen Israel, wie Mose, der Knecht Gottes, geboten hatte.
50 Wọ̀nyí ni àwọn ìránṣẹ́ Aaroni: Eleasari ọmọ rẹ̀, Finehasi ọmọ rẹ̀, Abiṣua ọmọ rẹ̀,
Dies sind aber die Kinder Aarons: Eleasar, sein Sohn: des Sohn war Pinehas; des Sohn war Abisua;
51 Bukki ọmọ rẹ̀, Ussi ọmọ rẹ̀, Serahiah ọmọ rẹ̀,
des Sohn war Bukki, des Sohn war Usi; des Sohn war Serahja;
52 Meraioti ọmọ rẹ̀, Amariah ọmọ rẹ̀, Ahitubu ọmọ rẹ̀,
des Sohn war Merajoth; des Sohn war Amarja; des Sohn war Ahitob;
53 Sadoku ọmọ rẹ̀ àti Ahimasi ọmọ rẹ̀.
des Sohn war Zadok; des Sohn war Ahimaaz.
54 Wọ̀nyí ni ibùgbé wọn tí a pín fún wọn gẹ́gẹ́ bí agbègbè wọn (tí a fi lé àwọn ìran ọmọ Aaroni lọ́wọ́ tí ó wá láti ẹ̀yà Kohati, nítorí kèké alákọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
Und dies ist ihre Wohnung und Sitz in ihren Grenzen, nämlich der Kinder Aaron, des Geschlechts der Kahathiter; denn das Los fiel ihnen zu,
55 A fún wọn ní Hebroni ní Juda pẹ̀lú àyíká pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
und sie gaben ihnen Hebron im Lande Juda und desselben Vorstädte umher.
56 Ṣùgbọ́n àwọn pápá àti ìletò tí ó yí ìlú ńlá náà ká ni a fi fún Kalebu ọmọ Jefunne.
Aber das Feld der Stadt und ihre Dörfer gaben sie Kaleb, dem Sohn Jephunnes.
57 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìran ọmọ Aaroni ni a fún ní Hebroni (ìlú ti ààbò), àti Libina, Jattiri, Eṣitemoa,
So gaben sie nun den Kinder Aaron die Freistädte Hebron und Libna samt ihren Vorstädten, Jatthir und Esthemoa mit ihren Vorstädten.
58 Hileni, Debiri,
Hilen, Debir,
59 Aṣani, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
Asan und Beth-Semes mit ihren Vorstädten;
60 Àti láti inú ẹ̀yà Benjamini, a fún wọn ní Gibeoni, Geba, Alemeti àti Anatoti lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn. Àwọn ìlú wọ̀nyí, tí a pín láàrín àwọn ẹ̀yà Kohati jẹ́ mẹ́tàlá ní gbogbo rẹ̀.
und aus dem Stamm Benjamin: Geba, Alemeth und Anathoth mit ihren Vorstädten, daß aller Städte in ihren Geschlechtern waren dreizehn.
61 Ìyókù àwọn ìran ọmọ Kohati ní a pín ìlú mẹ́wàá fún láti àwọn ìdílé ní ti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase.
Aber den Kindern Kahaths nach ihren Geschlechtern wurden durch Los aus dem Stamm Ephraim, aus dem Stamm Dan und aus dem halben Stamm Manasse zehn Städte.
62 Àwọn ìran ọmọ Gerṣoni, sí ìdílé ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ẹ̀yà àwọn ẹ̀yà Isakari, Aṣeri àti Naftali, àti láti apá ẹ̀yà Manase tí ó wà ní Baṣani.
Den Kindern Gerson nach ihren Geschlechtern wurden aus dem Stamm Isaschar und aus dem Stamm Asser und aus dem Stamm Naphthali und aus dem Stamm Manasse in Basan dreizehn Städte.
63 Sebuluni àwọn ìran ọmọ Merari, ìdílé sí ìdílé, ní a pín ìlú méjìlá fún láti ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
Den Kindern Merari nach ihren Geschlechtern wurden durch das Los aus dem Stamm Ruben und aus dem Stamm Gad und aus dem Stamm Sebulon zwölf Städte.
64 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli fún àwọn ará Lefi ní ìlú wọ̀nyí pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Und die Kinder Israel gaben den Leviten die Städte mit ihren Vorstädten,
65 Láti ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini ni a pín ìlú tí a ti dárúkọ wọn sẹ́yìn fún.
nämlich durchs Los aus dem Stamm der Kinder Juda und aus dem Stamm der Kinder Simeon und aus dem Stamm der Kinder Benjamin die Städte, die sie mit Namen bestimmten.
66 Lára àwọn ìdílé Kohati ni a fún ní ìlú láti ẹ̀yà Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìlú agbègbè wọn.
Aber den Geschlechtern der Kinder Kahath wurden Städte ihres Gebietes aus dem Stamm Ephraim.
67 Ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, a fún wọn ní Ṣekemu (ìlú ńlá ti ààbò), àti Geseri
So gaben sie nun ihnen, dem Geschlecht der andern Kinder Kahath, die Freistädte: Sichem auf dem Gebirge Ephraim, Geser,
68 Jokimeamu, Beti-Horoni.
Jokmeam, Beth-Horon,
69 Aijaloni àti Gati-Rimoni lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Ajalon und Gath-Rimmon mit ihren Vorstädten.
70 Pẹ̀lú láti apá ààbọ̀ ẹ̀yà Manase àwọn ọmọ Israẹli fún Aneri àti Bileamu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn, fún ìyókù àwọn ìdílé Kohati.
Dazu aus dem halben Stamm Manasse: Aner und Bileam mit ihren Vorstädten.
71 Àwọn ará Gerṣoni gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ààbọ̀ ẹ̀yà ti Manase wọ́n gba Golani ní Baṣani àti pẹ̀lú Aṣtarotu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù wọn.
Aber den Kindern Gerson gaben sie aus dem Geschlecht des halben Stammes Manasse: Golan in Basan und Astharoth mit ihren Vorstädten.
72 Láti ẹ̀yà Isakari wọ́n gba Kedeṣi, Daberati
Aus dem Stamm Isaschar: Kedes, Dabrath,
73 Ramoti àti Anenu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Ramoth und Anem mit ihren Vorstädten.
74 Láti ẹ̀yà Aṣeri wọ́n gba Maṣali, Abdoni,
Aus dem Stamm Asser: Masal, Abdon,
75 Hukoki àti Rehobu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Hukok und Rehob mit ihren Vorstädten.
76 Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Naftali wọ́n gba Kedeṣi ní Galili, Hammoni àti Kiriataimu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
Aus dem Stamm Naphthali: Kedes in Galiläa, Hammon und Kirjathaim mit ihren Vorstädten.
77 Àwọn ará Merari (ìyókù àwọn ará Lefi) gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ẹ̀yà Sebuluni wọ́n gba Jokneamu, Karta, Rimoni àti Tabori, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Den andern Kindern Merari gaben sie aus dem Stamm Sebulon: Rimmono und Thabor mit ihren Vorstädten;
78 Láti ẹ̀yà Reubeni rékọjá Jordani ìlà-oòrùn Jeriko wọ́n gba Beseri nínú aginjù Jahisa,
und jenseit des Jordans gegenüber Jericho, gegen der Sonne Aufgang am Jordan, aus dem Stamm Ruben: Bezer in der Wüste, Jahza,
79 Kedemoti àti Mefaati, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Kedemoth und Mephaat mit ihren Vorstädten.
80 Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Gadi wọ́n gba Ramoti ní Gileadi Mahanaimu,
Aus dem Stamm Gad: Ramoth in Gilead, Mahanaim,
81 Heṣboni àti Jaseri lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Hesbon und Jaser mit ihren Vorstädten.

< 1 Chronicles 6 >