< 1 Chronicles 5 >

1 Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí Israẹli. (Nítorí òun ni àkọ́bí; ṣùgbọ́n, bí ó ti ṣe pé ó ba ibùsùn baba rẹ̀ jẹ́, a fi ogún ìbí rẹ̀ fún àwọn ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli: a kì yóò sì ka ìtàn ìdílé náà gẹ́gẹ́ bí ipò ìbí.
Reuben was the oldest son of Jacob. Therefore, he should have received the special rights/privileges that belonged to firstborn sons. But he had sex with his father’s slave wife, so [his father] gave the rights if a firstborn son to the sons of Reubers younger brother Joseph. And in the family records, Reuben is not mentioned first, like the firstborn sons always are.
2 Nítorí Juda borí àwọn arákùnrin rẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni aláṣẹ ti ń jáde wá; ṣùgbọ́n ogún ìbí jẹ́ ti Josẹfu),
Although Judah became more influential than his brothers, and a ruler of the tribe descended from him, Joseph’s family received the rights that belonged to firstborn sons.
3 àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku àti Pallu, Hesroni àti Karmi.
But Reuben was Jacob’s oldest son. Reuben’s sons were Hanoch, Pallu, Hezron, and Carmi.
4 Àwọn ọmọ Joẹli: Ṣemaiah ọmọ rẹ̀, Gogu ọmọ rẹ̀, Ṣimei ọmọ rẹ̀.
[Another descendant of Reuben was Joel]. Joel’s son was Shemaiah. Shemaiah’s son was Gog. Gog’s son was Shimei.
5 Mika ọmọ rẹ̀, Reaiah ọmọ rẹ̀, Baali ọmọ rẹ̀.
Shimei’s son was Micah. Micah’s son was Reaiah. Reaiah’s son was Baal.
6 Beera ọmọ rẹ̀, tí Tiglat-Pileseri ọba Asiria kó ní ìgbèkùn lọ. Ìjòyè àwọn ọmọ Reubeni ni Beera jẹ́.
Baal’s son was Beerah. Beerah was a leader of the tribe/descendants of Reuben. But Tiglath-Pileser the king of Assyria captured him and took him to Assyria.
7 Àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn: Jeieli àti Sekariah ni olórí,
The names of these clans are listed here according to what is written in their family records. The first [name written was] Jeiel. Then Zechariah,
8 àti Bela ọmọ Asasi ọmọ Ṣema, ọmọ Joẹli. Wọ́n tí ń gbé Aroeri àní títí dé Nebo àti Baali-Meoni.
and then Bela. Bela was the son of Azaz, and Azaz was the son of Shema, and Shema was the son of Joel. Reuben’s clan was very large. Some of them lived near Aroer [city] as far [north] as Nebo [town] and Baal-Meon [city].
9 Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àtiwọ aginjù láti odò Eufurate; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ sí i ní ilẹ̀ Gileadi.
Some of them lived further east, as far as the edge of the desert [south of] the Euphrates River. [They went there] because they had a huge amount of cattle, [with the result that there was not enough pastureland for them] in [the] Gilead [region].
10 Àti ní ọjọ́ Saulu, wọ́n bá àwọn ọmọ Hagari jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gileadi.
When Saul was king [of Israel], Bela’s clan fought against the descendants of Hagar and defeated them. After that, Bela’s clan lived in the tents that the descendants of Hagar had lived in previously, in all the area east of [the] Gilead [region].
11 Àti àwọn ọmọ Gadi ń gbé lékè wọn, ní ilẹ̀ Baṣani títí dé Saleka:
The tribe of Gad lived near the tribe of Reuben; they lived in [the] Bashan [region], all the way [east] to Salecah [town].
12 Joẹli jẹ́ olórí, Ṣafamu ìran ọmọ Janai, àti Ṣafati ni Baṣani.
Joel was their chief; Shapham was his assistant; other leaders were Janai and Shaphat.
13 Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní: Mikaeli, Meṣullamu Ṣeba, Jorai, Jaka, Sia àti Eberi méje.
Other members of the tribe belonged to seven clans, whose leaders were Michael, Meshullam, Sheba, Jorai, Jacan, Zia, and Eber.
14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Abihaili, ọmọ Huri, ọmọ Jeroa, ọmọ Gileadi, ọmọ Mikaeli, ọmọ Jeṣiṣai, ọmọ Jado, ọmọ Busi.
They were descendants of Abihail. Abihail was Huri’s son. Huri was Jaroah’s son. Jaroah was Gilead’s son. Gilead was Michael’s son. Michael was Jeshishai’s son. Jeshishai was Jahdo’s son. Jahdo was the son of Buz.
15 Ahi, ọmọ Adbeeli, ọmọ Guni, olórí ilé àwọn baba wọn.
Ahi was Abdiel’s son. Abdiel was Guni’s son. Ahi was the leader of their clan.
16 Wọ́n sì ń gbé Gileadi ní Baṣani àti nínú àwọn ìlú rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbèríko Ṣaroni, ní agbègbè wọn.
The descendants of Gad lived in the towns in Gilead and Bashan regions, and on all the pastureland on [the] Sharon [plain].
17 Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn ìdílé, ní ọjọ́ Jotamu ọba Juda, àti ní ọjọ́ Jeroboamu ọba Israẹli.
All of those names were written in the records of the clans of Gad during the time that Jotham was the king of Judah and Jeroboam was the king of Israel.
18 Àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé asà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹgbẹ̀rìnlélógún dín ogójì ènìyàn, tí ó jáde lọ sí ogún náà.
There were 44,760 soldiers from the tribes of Reuben and Gad and [the eastern] half of the tribe of Manasseh. They all carried shields and swords and bows [and arrows]. They [were all trained to] fight well in battles.
19 Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hagari jagun, pẹ̀lú Jeturi, àti Nafiṣi àti Nadabu.
They attacked the descendants of Hagar and the people of Jetur, Naphish, and Nodab [cities].
20 Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hagari lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí tiwọn ké pe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
The men from those three tribes prayed to God during the battles, requesting him to help them. So he helped them, because they trusted in him. He enabled them to defeat [IDM] the descendants of Hagar and all those who were helping them.
21 Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ìbákasẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùn-ún, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì, àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn-ún.
They took the animals that belonged to the descendants of Hagar: They took 50,000 camels, 250,000 sheep, and 2,000 donkeys. They also captured 100,000 people.
22 Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbèkùn.
But many descendants of Hagar were killed because God helped the people of the tribes of Reuben, Gad, and Manasseh. After that, those three tribes lived in that area until [the army of] Babylonia [captured them and] took them away to Babylon.
23 Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Baṣani títí dé Baali-Hermoni, àti Seniri àti títí dé òkè Hermoni.
There were many people who belonged to the eastern half of the tribe of Manasseh. They lived in [the] Bashan [region east of the Jordan River], as far [north] as Baal-Hermon, Senir, and Hermon Mountain.
24 Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Eferi, Iṣi, Elieli, Asrieli, Jeremiah, Hodafiah àti Jahdieli àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn.
Their clan leaders were Epher, Ishi, Eliel, Azriel, Jeremiah, Hodaviah, and Jahdiel. They were all strong, brave, and famous soldiers, and leaders of their clans.
25 Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì ṣe àgbèrè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn.
But they sinned against God, the one whom their ancestors had worshiped. They began to worship the gods/idols that the people of that region had worshiped, the people whom God had enabled them to destroy!
26 Nítorí náà Ọlọ́run Israẹli ru ẹ̀mí Pulu ọba Asiria sókè (èyí ni Tiglat-Pileseri ọba Asiria), ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase lọ sí ìgbèkùn. Ó sì kó wọn wá sí Hala, àti Habori, àti Harani, àti sí etí odò Gosani; títí dí òní yìí.
So the God whom the Israelis [worshiped] caused Pul, the king of Assyria, to conquer those tribes. Pul’s other name was Tiglath-Pileser. His [army] captured the people of the tribes of Reuben, Gad, and the eastern half of the tribe of Manasseh, and took them to [various places in Assyria]: Halah, Habor, Hara and near the Gozan River. [They have lived in those places from that time] to the present time.

< 1 Chronicles 5 >