< 1 Chronicles 4 >

1 Àwọn ọmọ Juda: Peresi, Hesroni, Karmi, Huri àti Ṣobali.
Descendants de Juda: Héçron, Karmi, Hour et Chobal.
2 Reaiah ọmọ Ṣobali ni baba Jahati, àti Jahati baba Ahumai àti Lahadi. Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀yà ará Sorati.
Reaïa, fils de Chobal, engendra Yahat; celui-ci, Ahoumaï et Lahad. Telles étaient les familles des Çoratiens.
3 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Etamu: Jesreeli, Iṣima, Idbaṣi, orúkọ arábìnrin wọn sì ni Haseleponi
Ceux-ci fondèrent Etham, Jezreël, Yichma et Yidbach; leur sœur s’appelait Hacelélponi.
4 Penueli sì ni baba Gedori, àti Eseri baba Huṣa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata àti baba Bẹtilẹhẹmu.
Penouêl fut le père de Ghedor, Ezer, de Houcha. Tels furent les descendants de Hour, le premier-né d’Ephrata, le père de Bethléem.
5 Aṣihuri baba Tekoa sì ní aya méjì, Hela àti Naara.
Achhour, père de Tekoa, eut deux femmes: Hélea et Naara.
6 Naara sì bí Ahussamu, Heferi Temeni àti Haaṣtari. Àwọn wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Naara.
Naara lui enfanta Ahouzzam, Héfer, Tèmeni et l’Ahachtarien. Tels furent les fils de Naara.
7 Àwọn ọmọ Hela: Sereti Sohari, Etani,
Ceux de Hélea furent: Céreth, Çohar et Etnân.
8 àti Kosi ẹni tí ó jẹ́ baba Anubu àti Sobeba àti ti àwọn ẹ̀yà Aharheli ọmọ Harumu.
Koç engendra Anoub, Haçobêba, et les familles d’Aharhêl, fils de Haroum…
9 Jabesi sì ní ọlá ju àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin lọ. Ìyá rẹ̀ sì sọ ọ́ ní Jabesi wí pé, “Mo bí i nínú ìpọ́njú.”
Yabêç était le plus considéré de ses frères. C’Était sa mère qui lui avait donné le nom de Yabêç, en disant: "Certes, j’ai enfanté avec douleur."
10 Jabesi sì kígbe sókè sí Ọlọ́run Israẹli wí pé, “Háà, Ìwọ yóò bùkún fún mi, ìwọ yóò sì mú agbègbè mi tóbi! Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà pẹ̀lú mi kí o sì pa mi mọ́ kúrò nínú ibi; kí èmi kí ó le ní ìdáǹdè kúrò nínú ìrora.” Ọlọ́run sì gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ rẹ̀.
Yabêç adressa au Dieu d’Israël cette supplique: "Si tu daignes me bénir, accroître mon territoire, et que ta main soit avec moi, que tu me gardes du mal pour m’éviter la douleur…" Et Dieu lui accorda ce qu’il avait demandé.
11 Kelubu arákùnrin Ṣuha, sì jẹ́ baba Mehiri, ẹni tí ó jẹ́ baba Eṣtoni.
Keloub, frère de Chouha, engendra Mehir, qui fut le père d’Echtôn.
12 Eṣtoni sì jẹ́ baba Beti-Rafa, Pasea àti Tehina ti baba ìlú Nahaṣi. Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin Reka.
Echtôn engendra Beth-Rafa, Passéêah et Tehinna, le père de la ville de Nahach. C’Étaient là les gens de Rêkha.
13 Àwọn ọmọ Kenasi: Otnieli àti Seraiah. Àwọn ọmọ Otnieli: Hatati àti Meonotai.
Kenaz eut pour fils Othoniel et Seraïa. Les fils d’Othoniel furent Hatath…
14 Meonotai sì ni baba Ofira. Seraiah sì jẹ́ baba Joabu, baba Geharaṣinu. A pè báyìí nítorí àwọn ènìyàn àwọn oníṣọ̀nà ní ìwọ̀n.
Meonotaï engendra Ofra, et Seraïa Joab, le père de la "Vallée des Artisans", car c’étaient des artisans.
15 Àwọn ọmọ Kalebu ọmọ Jefunne: Iru, Ela, àti Naamu. Àwọn ọmọ Ela: Kenasi.
Les fils de Caleb, fils de Yefounné, furent: Irou, Ela et Naam; les fils d’Ela… et Kenaz.
16 Àwọn ọmọ Jehaleeli: Sifi, àti Sifa, Tiria àti Asareeli.
Les fils de Yehallèlêl: Zif, Zifa, Tiria et Assarêl.
17 Àwọn ọmọ Esra: Jeteri, Meredi, Eferi àti Jaloni. Ọ̀kan lára àwọn aya Meredi sì bí Miriamu, Ṣammai àti Iṣba baba Eṣitemoa.
Le s fils d’Ezra: Yeter, Méred, Efer et Yalôn. Et elle conçut et enfanta Miriam, Chammaï et Yichbah, père d’Echtemoa.
18 Aya rẹ̀ láti ẹ̀yà Juda sì bí Jaredi baba Gedori, àti Heberi baba Soko àti Jekutieli baba Sanoa. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọbìnrin Farao Bitia, ẹni ti Meredi ti fẹ́.
Sa femme, la Judéenne, enfanta Yéred, père de Ghedor, Héber, père de Sokho, Yekoutiël, père de Zanoah. Ceux-là, furent les enfants de Bitia, fille de Pharaon, qu’avait épousée Méred.
19 Àwọn ọmọ aya Hodiah arábìnrin Nahamu, baba Keila ará Garimu, àti Eṣitemoa àwọn ará Maakati.
Les fils de la femme de Hodia, sœur de Naham, furent le "père" de Keïla, le Garmien, et d’Echtemoa, le Maakhatien.
20 Àwọn ọmọ Ṣimoni: Amnoni, Rina, Beni-Hanani àti Tiloni. Àwọn ọmọ Iṣi: Soheti àti Beni-Soheti.
Les fils de Chimôn furent Amnôn et Rinna, Ben-Hanân et Tilôn; les fils de Yichi: Zohêth et Ben-Zohéth.
21 Àwọn ọmọ Ṣela ọmọ Juda: Eri baba Leka, Lada baba Meraṣa àti àwọn ìdílé ilé àwọn tí ń hun aṣọ oníṣẹ́ ní Beti-Aṣibea.
Les fils de Chêla, fils de Juda, furent Er, "père" de Lêkha, Lada, "père" de Marêcha, et les familles de la maison du travail de byssus, de la maison d’Achbêa;
22 Jokimu, ọkùnrin Koseba, àti Joaṣi àti Sarafi, olórí ní Moabu àti Jaṣubi Lehemu. (Àkọsílẹ̀ yìí sì wà láti ìgbà àtijọ́.)
en outre, Yokim, les gens de Kozêba, Yoach et Saraf, qui dominèrent sur Moab, et Yachoubi-Léhem. Ce sont là choses anciennes.
23 Àwọn sì ni amọ̀kòkò tí ń gbé ní Netaimu àti Gedera; wọ́n sì dúró níbẹ̀ wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ fún ọba.
C’Étaient les potiers et les habitants des plantations et des parcs. Ils y demeuraient pour être plus près du roi en vue de son service.
24 Àwọn ọmọ Simeoni: Nemueli, Jamini, Jaribi, Sera àti Saulu;
Les fils de Siméon furent: Nemouêl, Yamîn, Yarib, Zérah, Chaoul.
25 Ṣallumu sì jẹ́ ọmọ Saulu, Mibsamu ọmọ rẹ̀ Miṣima ọmọ rẹ̀.
Celui-ci eut pour fils Challoum, celui-ci Mibsam, celui-ci Michma.
26 Àwọn ọmọ Miṣima: Hamueli ọmọ rẹ̀ Sakkuri ọmọ rẹ̀ àti Ṣimei ọmọ rẹ̀.
Les descendants de Michma furent Hammouêl, qui eut pour fils Zakkour, celui-ci Chimeï.
27 Ṣimei sì ní ọmọkùnrin mẹ́rìndínlógún àti ọmọbìnrin mẹ́fà, ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin kò ní ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìdílé wọn kò sì pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn Juda.
Chimeï eut seize fils et six filles, tandis que ses frères n’eurent pas beaucoup d’enfants; toutes leurs familles n’atteignirent pas le nombre des descendants de Juda.
28 Wọ́n sì ń gbé ní Beerṣeba, Molada, Hasari-Ṣuali,
Ils habitèrent Bersabée, Molada, Haçar-Choual,
29 àti ní Biliha, àti ní Esemu, àti ní Toladi,
Bilha, Ecem, Tolad,
30 Betueli, Horma, Siklagi,
Betouêl, Horma, Ciklag,
31 Beti-Markaboti Hormah; Hasari Susimu, Beti-Biri àti Ṣaraimi. Àwọn wọ̀nyí ni ìlú wọn títí di ìgbà ọba Dafidi,
Beth-Marcabot, Haçar-Soussim, Beth-Bireï et Chaaraïm. Telles furent leurs villes jusqu’à l’avènement de David.
32 agbègbè ìlú wọn ni Etamu, Aini, Rimoni, Tokeni, Aṣani àwọn ìlú márùn-ún,
Ils eurent pour dépendances Etam, Ayîn, Rimmôn, Tokhén et Achàn, soit cinq villes,
33 àti gbogbo ìletò wọn, tí ó wà yí ìlú náà ká, dé Baali. Àwọn wọ̀nyí ni ibùgbé wọn. Àti ìtàn ìdílé wọ́n.
et toutes les campagnes, aux environs de ces villes, jusqu’à Baal. Telles furent leurs résidences et leur filiation par familles.
34 Meṣobabu àti Jamleki, Josa ọmọ Amasiah,
Quand à Mechobab, Yamlêkh, Yocha, fils d’Amacia,
35 Joẹli, Jehu ọmọ Josibiah, ọmọ Seraiah, ọmọ Asieli,
Joël, Yêhou, fils de Yochibia, fils de Seraïa, fils d’Assiël,
36 àti pẹ̀lú Elioenai, Jaakoba, Jeṣohaiah, Asaiah, Adieli, Jesimieli, Benaiah,
Elyoênaï, Yaakoba, Yechohaïa, Assaïa, Adiêl, Yessimiêl, Benaïa,
37 àti Sisa ọmọ Ṣifi ọmọ Alloni, ọmọ Jedaiah, ọmọ Ṣimri ọmọ Ṣemaiah.
et Ziza, fils de Chifeï, fils d’Allôn, fils de Yedaïa, fils de Chimri, fils de Chemaïa,
38 Àwọn ọkùnrin tí a dárúkọ lókè yìí àwọn ni ìjòyè ìdílé wọn. Àwọn ìdílé sì pọ̀ sí i gidigidi,
ceux-là, qui sont désignés nominativement, et qui étaient princes dans leurs familles, leurs lignées paternelles débordèrent beaucoup
39 wọ́n sì lọ sí ojú ọ̀nà Gedori. Lọ títí dé ìlà-oòrùn àfonífojì láti wá koríko fún àwọn agbo ẹran wọn.
et allèrent jusqu’à l’entrée de Ghedor, à l’est de la vallée, afin d’y chercher des pâturages pour leurs troupeaux.
40 Wọ́n sì rí koríko tútù tí ó dára ilẹ̀ náà gbòòrò ó sì ní àlàáfíà ó sì gbé jẹ́. Àwọn ọmọ Hamu ni ó ti ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.
Ils y trouvèrent des pâturages gras et bons et un pays vaste, tranquille et pacifique, car ceux qui y habitaient auparavant étaient des descendants de Cham.
41 Àwọn ọkùnrin tí a kọ orúkọ rẹ̀ sókè, dé ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Wọ́n sì kọlu àwọn ará Hamu ní àgọ́ wọn àti pẹ̀lú àwọn ará Mehuni tí a rí níbẹ̀ tí ó sì pa wọ́n run pátápátá títí di òní yìí. Wọ́n sì ń gbé ní ipò wọn, nítorí pé koríko ń bẹ níbẹ̀ fún agbo ẹran wọn.
Ceux donc qui ont été désignés par leurs noms vinrent à l’époque d’Ezéchias, roi de Juda; ils détruisirent leurs tentes et les habitations qui s’y trouvaient et ils les vouèrent à l’interdit, ce qui se voit encore aujourd’hui; puis ils s’y établirent à leur place, car ils avaient là des pâturages pour leurs troupeaux.
42 Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ará Simeoni, lábẹ́ ìdarí pẹ̀lú Pelatiah, Neariah, Refaiah àti Usieli, àwọn ọmọ Iṣi, gbógun sí àwọn òkè ìlú ti Seiri.
D’Entre eux, c’est-à-dire des descendants de Siméon, cinq cents hommes allèrent se fixer sur la montagne de Séïr. Ils avaient à leur tête Pelatia, Nearia, Refaïa et Ouzziël, fils de Yicheï.
43 Wọ́n sì pa àwọn ará Amaleki tí ó kù, àwọn tí ó ti sálà, wọ́n sì ti ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.
Ils exterminèrent le reste des survivants d’Amalec, et ils habitent là encore aujourd’hui.

< 1 Chronicles 4 >