< 1 Chronicles 4 >

1 Àwọn ọmọ Juda: Peresi, Hesroni, Karmi, Huri àti Ṣobali.
Sons of Judah: Perez, Hezron, and Carmi, and Hur, and Shobal.
2 Reaiah ọmọ Ṣobali ni baba Jahati, àti Jahati baba Ahumai àti Lahadi. Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀yà ará Sorati.
And Reaiah son of Shobal begot Jahath, and Jahath begot Ahumai and Lahad; these [are] families of the Zorathite.
3 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Etamu: Jesreeli, Iṣima, Idbaṣi, orúkọ arábìnrin wọn sì ni Haseleponi
And these [are] of the father of Etam: Jezreel, and Ishma, and Idbash; and the name of their sister [is] Hazzelelponi;
4 Penueli sì ni baba Gedori, àti Eseri baba Huṣa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata àti baba Bẹtilẹhẹmu.
and Penuel [is] father of Gedor, and Ezer father of Hushah. These [are] sons of Hur, firstborn of Ephratah, father of Beth-Lehem.
5 Aṣihuri baba Tekoa sì ní aya méjì, Hela àti Naara.
And to Ashhur father of Tekoa were two wives, Helah and Naarah;
6 Naara sì bí Ahussamu, Heferi Temeni àti Haaṣtari. Àwọn wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Naara.
and Naarah bears to him Ahuzzam, and Hepher, and Temeni, and Haahashtari: these [are] sons of Naarah.
7 Àwọn ọmọ Hela: Sereti Sohari, Etani,
And sons of Helah: Zereth, and Zohar, and Ethnan.
8 àti Kosi ẹni tí ó jẹ́ baba Anubu àti Sobeba àti ti àwọn ẹ̀yà Aharheli ọmọ Harumu.
And Coz begot Anub, and Zobebah, and the families of Aharhel son of Harum.
9 Jabesi sì ní ọlá ju àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin lọ. Ìyá rẹ̀ sì sọ ọ́ ní Jabesi wí pé, “Mo bí i nínú ìpọ́njú.”
And Jabez is honored above his brothers, and his mother called his name Jabez, saying, “Because I have brought forth with grief.”
10 Jabesi sì kígbe sókè sí Ọlọ́run Israẹli wí pé, “Háà, Ìwọ yóò bùkún fún mi, ìwọ yóò sì mú agbègbè mi tóbi! Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó wà pẹ̀lú mi kí o sì pa mi mọ́ kúrò nínú ibi; kí èmi kí ó le ní ìdáǹdè kúrò nínú ìrora.” Ọlọ́run sì gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ rẹ̀.
And Jabez calls to the God of Israel, saying, “If blessing You bless me, then You have made my border great, and Your hand has been with me, and You have kept [me] from evil—not to grieve me”; and God brings in that which he asked.
11 Kelubu arákùnrin Ṣuha, sì jẹ́ baba Mehiri, ẹni tí ó jẹ́ baba Eṣtoni.
And Chelub brother of Shuah begot Mehir; he [is] father of Eshton.
12 Eṣtoni sì jẹ́ baba Beti-Rafa, Pasea àti Tehina ti baba ìlú Nahaṣi. Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin Reka.
And Eshton begot Beth-Rapha, and Paseah, and Tehinnah father of Ir-Nahash; these [are] men of Rechah.
13 Àwọn ọmọ Kenasi: Otnieli àti Seraiah. Àwọn ọmọ Otnieli: Hatati àti Meonotai.
And sons of Kenaz: Othniel and Seraiah; and sons of Othniel: Hathath.
14 Meonotai sì ni baba Ofira. Seraiah sì jẹ́ baba Joabu, baba Geharaṣinu. A pè báyìí nítorí àwọn ènìyàn àwọn oníṣọ̀nà ní ìwọ̀n.
And Meonothai begot Ophrah, and Seraiah begot Joab father of the Valley of the Craftsmen, for they were craftsmen.
15 Àwọn ọmọ Kalebu ọmọ Jefunne: Iru, Ela, àti Naamu. Àwọn ọmọ Ela: Kenasi.
And sons of Caleb son of Jephunneh: Iru, Elah, and Naam; and sons of Elah: even Kenaz.
16 Àwọn ọmọ Jehaleeli: Sifi, àti Sifa, Tiria àti Asareeli.
And sons of Jehaleleel: Ziph and Ziphah, Tiria, and Asareel.
17 Àwọn ọmọ Esra: Jeteri, Meredi, Eferi àti Jaloni. Ọ̀kan lára àwọn aya Meredi sì bí Miriamu, Ṣammai àti Iṣba baba Eṣitemoa.
And sons of Ezra: Jether, and Mered, and Epher, and Jalon. And she bears Miriam, and Shammai, and Ishbah father of Eshtemoa.
18 Aya rẹ̀ láti ẹ̀yà Juda sì bí Jaredi baba Gedori, àti Heberi baba Soko àti Jekutieli baba Sanoa. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọbìnrin Farao Bitia, ẹni ti Meredi ti fẹ́.
And his wife Jehudijah bore Jered father of Gedor, and Heber father of Socho, and Jekuthiel father of Zanoah. And these [are] sons of Bithiah daughter of Pharaoh, whom Mered took,
19 Àwọn ọmọ aya Hodiah arábìnrin Nahamu, baba Keila ará Garimu, àti Eṣitemoa àwọn ará Maakati.
and sons of the wife of Hodiah sister of Nahom: Abi-Keilah the Garmite, and Eshtemoa the Maachathite.
20 Àwọn ọmọ Ṣimoni: Amnoni, Rina, Beni-Hanani àti Tiloni. Àwọn ọmọ Iṣi: Soheti àti Beni-Soheti.
And sons of Shimon: Amnon, and Rinnah, Ben-Hanon, and Tilon; and sons of Ishi: Zoheth, and Ben-Zoheth.
21 Àwọn ọmọ Ṣela ọmọ Juda: Eri baba Leka, Lada baba Meraṣa àti àwọn ìdílé ilé àwọn tí ń hun aṣọ oníṣẹ́ ní Beti-Aṣibea.
Sons of Shelah son of Judah: Er father of Lecah, and Laadah father of Mareshah, and the families of the house of the service of fine linen, of the house of Ashbea;
22 Jokimu, ọkùnrin Koseba, àti Joaṣi àti Sarafi, olórí ní Moabu àti Jaṣubi Lehemu. (Àkọsílẹ̀ yìí sì wà láti ìgbà àtijọ́.)
and Jokim, and the men of Chozeba, and Joash, and Saraph, who ruled over Moab and Jashubi-Lehem; and these things [are] ancient.
23 Àwọn sì ni amọ̀kòkò tí ń gbé ní Netaimu àti Gedera; wọ́n sì dúró níbẹ̀ wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ fún ọba.
They [are] the potters and inhabitants of Netaim and Gedera; they dwelt there with the king in his work.
24 Àwọn ọmọ Simeoni: Nemueli, Jamini, Jaribi, Sera àti Saulu;
Sons of Simeon: Nemuel, and Jamin, Jarib, Zerah, Shaul;
25 Ṣallumu sì jẹ́ ọmọ Saulu, Mibsamu ọmọ rẹ̀ Miṣima ọmọ rẹ̀.
Shallum his son, Mibsam his son, Mishma his son.
26 Àwọn ọmọ Miṣima: Hamueli ọmọ rẹ̀ Sakkuri ọmọ rẹ̀ àti Ṣimei ọmọ rẹ̀.
And sons of Mishma: Hammuel his son, Zacchur his son, Shimei his son.
27 Ṣimei sì ní ọmọkùnrin mẹ́rìndínlógún àti ọmọbìnrin mẹ́fà, ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin kò ní ọmọ púpọ̀; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìdílé wọn kò sì pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn Juda.
And to Shimei [are] sixteen sons and six daughters, and to his brothers there are not many sons, and none of their families have multiplied as much as the sons of Judah.
28 Wọ́n sì ń gbé ní Beerṣeba, Molada, Hasari-Ṣuali,
And they dwell in Beer-Sheba, and Moladah, and Hazar-Shaul,
29 àti ní Biliha, àti ní Esemu, àti ní Toladi,
and in Bilhah, and in Ezem, and in Tolad,
30 Betueli, Horma, Siklagi,
and in Bethuel, and in Hormah, and in Ziklag,
31 Beti-Markaboti Hormah; Hasari Susimu, Beti-Biri àti Ṣaraimi. Àwọn wọ̀nyí ni ìlú wọn títí di ìgbà ọba Dafidi,
and in Beth-Marcaboth, and in Hazar-Susim, and in Beth-Birei, and in Shaarim; these [are] their cities until the reigning of David.
32 agbègbè ìlú wọn ni Etamu, Aini, Rimoni, Tokeni, Aṣani àwọn ìlú márùn-ún,
And their villages [are] Etam, and Ain, Rimmon, and Tochen, and Ashan—five cities,
33 àti gbogbo ìletò wọn, tí ó wà yí ìlú náà ká, dé Baali. Àwọn wọ̀nyí ni ibùgbé wọn. Àti ìtàn ìdílé wọ́n.
and all their villages that [are] around these cities to Ba‘al; these [are] their dwellings, and they have their genealogy:
34 Meṣobabu àti Jamleki, Josa ọmọ Amasiah,
even Meshobab, and Jamlech, and Joshah son of Amaziah,
35 Joẹli, Jehu ọmọ Josibiah, ọmọ Seraiah, ọmọ Asieli,
and Joel, and Jehu son of Josibiah, son of Seraiah, son of Asiel,
36 àti pẹ̀lú Elioenai, Jaakoba, Jeṣohaiah, Asaiah, Adieli, Jesimieli, Benaiah,
and Elioenai, and Jaakobah, and Jeshohaiah, and Asaiah, and Adiel, and Jesimiel, and Benaiah,
37 àti Sisa ọmọ Ṣifi ọmọ Alloni, ọmọ Jedaiah, ọmọ Ṣimri ọmọ Ṣemaiah.
and Ziza son of Shiphi, son of Allon, son of Jedaiah, son of Shimri, son of Shemaiah.
38 Àwọn ọkùnrin tí a dárúkọ lókè yìí àwọn ni ìjòyè ìdílé wọn. Àwọn ìdílé sì pọ̀ sí i gidigidi,
These who are coming in by name [are] princes in their families, and the house of their fathers has broken forth into a multitude;
39 wọ́n sì lọ sí ojú ọ̀nà Gedori. Lọ títí dé ìlà-oòrùn àfonífojì láti wá koríko fún àwọn agbo ẹran wọn.
and they go to the entrance of Gedor, to the east of the valley, to seek pasture for their flock,
40 Wọ́n sì rí koríko tútù tí ó dára ilẹ̀ náà gbòòrò ó sì ní àlàáfíà ó sì gbé jẹ́. Àwọn ọmọ Hamu ni ó ti ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.
and they find pasture, fat and good, and the land broad of sides, and quiet, and safe, for those dwelling there before are of Ham.
41 Àwọn ọkùnrin tí a kọ orúkọ rẹ̀ sókè, dé ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Wọ́n sì kọlu àwọn ará Hamu ní àgọ́ wọn àti pẹ̀lú àwọn ará Mehuni tí a rí níbẹ̀ tí ó sì pa wọ́n run pátápátá títí di òní yìí. Wọ́n sì ń gbé ní ipò wọn, nítorí pé koríko ń bẹ níbẹ̀ fún agbo ẹran wọn.
And these who are written by name come in the days of Hezekiah king of Judah, and strike their tents, and the habitations that have been found there, and devote them to destruction to this day, and dwell in their stead, because pasture for their flock [is] there.
42 Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ará Simeoni, lábẹ́ ìdarí pẹ̀lú Pelatiah, Neariah, Refaiah àti Usieli, àwọn ọmọ Iṣi, gbógun sí àwọn òkè ìlú ti Seiri.
And of them, of the sons of Simeon, five hundred men have gone to Mount Seir, and Pelatiah, and Neariah, and Rephaiah, and Uzziel, sons of Ishi, at their head,
43 Wọ́n sì pa àwọn ará Amaleki tí ó kù, àwọn tí ó ti sálà, wọ́n sì ti ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.
and they strike the remnant of those escaped of Amalek, and dwell there to this day.

< 1 Chronicles 4 >