< 1 Chronicles 3 >

1 Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Dafidi tí a bí fún un ní Hebroni. Àkọ́bí sì ni Amnoni ọmọ Ahinoamu ti Jesreeli; èkejì sì ni Daniẹli ọmọ Abigaili ará Karmeli;
E Estes foram os filhos de David, que lhe nasceram em Hebron: o primogenito, Amnon, de Ahinoam, a jizreelita; o segundo, Daniel, de Abigail, a carmelita;
2 ẹ̀kẹta sì ni Absalomu ọmọ Maaka ọmọbìnrin Talmai ọba Geṣuri bí fún un; ẹ̀kẹrin sì ni Adonijah ọmọ Haggiti;
O terceiro, Absalão, filho de Maaca, filha de Talmai, rei de Gesur; o quarto, Adonias, filho de Haggith;
3 ẹ̀karùnún ni Ṣefatia láti ọ̀dọ̀ Abitali; àti ẹ̀kẹfà, Itreamu, láti ọ̀dọ̀ Egla aya rẹ̀.
O quinto, Sephatias, d'Abital; o sexto, Ithream, de Egla, sua mulher.
4 Àwọn mẹ́fà wọ̀nyí ni a bí fún Dafidi ni Hebroni, níbi tí ó ti jẹ ọba fún ọdún méje àti oṣù mẹ́fà. Dafidi sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n.
Seis lhe nasceram em Hebron, porque ali reinou sete annos e seis mezes: e trinta e tres annos reinou em Jerusalem.
5 Wọ̀nyí ni ọmọ wẹ́wẹ́ tí a bí fún un ní Jerusalẹmu: Ṣimea, Ṣobabu, Natani àti Solomoni. Àwọn mẹ́rin wọ̀nyí sì ni a bí láti ọ̀dọ̀ Bati-Ṣua ọmọbìnrin Ammieli.
E estes lhe nasceram em Jerusalem: Simea, e Sobab, e Nathan, e Salomão: estes quatro lhe nasceram de Bath-sua, filha de Ammiel.
6 Ibhari sì wà pẹ̀lú, Eliṣama, Elifeleti,
Nasceram-lhe mais Ibehar, e Elisama, e Eliphelet,
7 Noga, Nefegi, Jafia,
E Nogath, e Nepheg, e Japhia,
8 Eliṣama, Eliada àti Elifeleti mẹ́sàn-án ni wọ́n.
E Elisama, e Eliad, e Eliphelet, nove.
9 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dafidi yàtọ̀ sí àwọn ọmọ tí àlè bí fún un. Tamari sì ni arábìnrin wọn.
Todos estes foram filhos de David, afóra os filhos das concubinas, e Tamar, irmã d'elles.
10 Ọmọ Solomoni ni Rehoboamu, Abijah ọmọ rẹ̀, Asa ọmọ rẹ̀, Jehoṣafati ọmọ rẹ̀,
E filho de Salomão foi Roboão; e seu filho Abias; e seu filho Asa; e seu filho Josaphat;
11 Jehoramu ọmọ rẹ̀, Ahasiah ọmọ rẹ̀, Joaṣi ọmọ rẹ̀,
E seu filho Jorão; e seu filho Achazias; e seu filho Joás;
12 Amasiah ọmọ rẹ̀, Asariah ọmọ rẹ̀, Jotamu ọmọ rẹ̀,
E seu filho Amasias; e seu filho Jotham;
13 Ahasi ọmọ rẹ̀, Hesekiah ọmọ rẹ̀, Manase ọmọ rẹ̀,
E seu filho Achaz; e seu filho Ezequias; e seu filho Manassés;
14 Amoni ọmọ rẹ̀, Josiah ọmọ rẹ̀.
E seu filho Amon; e seu filho Josias.
15 Àwọn ọmọ Josiah: àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni Johanani, èkejì ọmọ rẹ̀ ni Jehoiakimu, ẹ̀kẹta ọmọ rẹ̀ ni Sedekiah, ẹ̀kẹrin ọmọ rẹ̀ ni Ṣallumu.
E os filhos de Josias foram: o primogenito, Johanan; o segundo, Joaquim; o terceiro, Zedekias; o quarto, Sallum.
16 Àwọn ìran ọmọ Jehoiakimu: Jekoniah ọmọ rẹ̀, àti Sedekiah.
E os filhos de Joaquim: Jechonias, seu filho, e Zedekias, seu filho.
17 Àwọn ọmọ Jekoniah tí a mú ní ìgbèkùn: Ṣealitieli ọmọ rẹ̀ ọkùnrin,
E os filhos de Jechonias: Assir, e seu filho Sealthiel.
18 Malkiramu, Pedaiah, Ṣenasari, Jekamiah, Hoṣama àti Nedabiah.
Os filhos d'este foram: Malchiram, e Pedaia, e Senazzar, Jekamias, Hosama, e Nedabias.
19 Àwọn ọmọ Pedaiah: Serubbabeli àti Ṣimei. Àwọn ọmọ Serubbabeli: Meṣullamu àti Hananiah. Ṣelomiti ni arábìnrin wọn.
E os filhos de Pedaia: Zorobabel e Simei; e os filhos de Zorobabel: Messullam, e Hananias, e Selomith, sua irmã,
20 Àwọn márùn-ún mìíràn sì tún wà: Haṣuba, Oheli, Berekiah, Hasadiah àti Jusabhesedi.
E Hasuba, e Obel, e Berechias, e Hasadias, e Jusab-hesed, cinco.
21 Àwọn ọmọ Hananiah: Pelatiah àti Jeṣaiah, àti àwọn ọmọ Refaiah, ti Arnani, ti Obadiah àti ti Ṣekaniah.
E os filhos de Hananias: Pelatias e Jesaias: os filhos de Rephaias, os filhos d'Arnan, os filhos de Obadias, e os filhos de Secanias.
22 Àwọn ọmọ Ṣekaniah: Ṣemaiah àti àwọn ọmọ rẹ̀: Hattusi, Igali, Bariah, Neariah àti Ṣafati, mẹ́fà ni gbogbo wọn.
E os filhos de Secanias foram Semaias: e os filhos de Semaias: Hattus, e Igeal, e Bariah, e Nearias, e Saphat, seis.
23 Àwọn ọmọ Neariah: Elioenai; Hesekiah, àti Asrikamu, mẹ́ta ni gbogbo wọn.
E os filhos de Nearias: Elioenai, e Ezequias, e Azrikam, tres.
24 Àwọn ọmọ Elioenai: Hodafiah, Eliaṣibu, Pelaiah, Akkubu, Johanani, Delaiah àti Anani, méje sì ni gbogbo wọn.
E os filhos de Elioenai: Hodavias, e Eliasib, e Pelaias, e Akkub, e Johanan, e Delaias, e Anani, sete.

< 1 Chronicles 3 >