< 1 Chronicles 29 >

1 Nígbà náà, ọba Dafidi sọ fún gbogbo àpéjọ pé, “Ọmọ mi Solomoni, èyí tí Ọlọ́run ti yàn, sì kéré ó sì jẹ́ aláìmòye. Iṣẹ́ náà tóbi, nítorí ìkọ́lé bí ti ààfin kì í ṣe fún ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa Ọlọ́run.
UDavida inkosi wasesithi ebandleni lonke: USolomoni indodana yami, yena yedwa uNkulunkulu amkhethileyo, usengumfana ubuthakathaka, lomsebenzi mkhulu; ngoba isigodlo kayisiso somuntu, kodwa ngeseNkosi uNkulunkulu.
2 Pẹ̀lú gbogbo ìrànlọ́wọ́ mi èmi ti pèsè fún ilé Ọlọ́run mi wúrà fún iṣẹ́ wúrà, fàdákà fún ti fàdákà, idẹ fún ti idẹ, irin fún ti irin àti igi fún ti igi àti òkúta oníyebíye fún títọ́ rẹ̀, òkúta lóríṣìíríṣìí, àwọ̀ àti oríṣìíríṣìí ẹ̀yà òkúta àti òkúta dáradára kan gbogbo wọ̀nyí ní iye púpọ̀.
Ngakho ngiyilungisele indlu kaNkulunkulu wami ngamandla ami wonke, igolide lokwegolide, lesiliva lokwesiliva, lethusi lokwethusi, insimbi lokwensimbi, lezigodo lokwezigodo, amatshe e-onikse lawokubekwa, amatshe akhazimulayo lalemibala, lenhlobo zonke zamatshe aligugu, lamatshe e-alibasta ngobunengi.
3 Yàtọ̀ fún èyí, nínú ìfọkànsìn mi sí ilé Ọlọ́run mi, èmí fi ìṣúra mi tìkára mi ti wúrà àti fàdákà fún ilé Ọlọ́run mi. Jù gbogbo rẹ̀ lọ, èmi ti pèsè fún ilé mímọ́ ti Olúwa yìí,
Laphezu kwakho, ngenxa yokuthanda kwami indlu kaNkulunkulu wami, nganikela indlu kaNkulunkulu wami inotho yegolide leyesiliva, engilakho, phezu kwakho konke engikulungisele indlu yendawo engcwele,
4 ẹgbẹ̀rún mẹ́ta tálẹ́ǹtì wúrà, ti wúrà Ofiri àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin tálẹ́ǹtì fàdákà dídára, fún bíbo àwọn ògiri ilé náà.
amathalenta egolide azinkulungwane ezintathu egolideni leOfiri, lamathalenta esiliva elicwengekileyo azinkulungwane eziyisikhombisa, ukuhuqa imiduli yezindlu.
5 Fún iṣẹ́ wúrà àti fàdákà náà, àti fún oríṣìí iṣẹ́ ti ó yẹ ní ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn tí ó ní òye oríṣìíríṣìí iṣẹ́. Nísinsin yìí, ta ni ó ní ìfẹ́ sí yíya ará rẹ̀ sọ́tọ̀ lónìí sí Olúwa?”
Igolide kusenzelwa okwegolide, lesiliva kusenzelwa okwesiliva, langawo wonke umsebenzi ngesandla sezingcitshi. Ngubani-ke ovumayo ukuzehlukanisela iNkosi lamuhla?
6 Nígbà náà àwọn aṣáájú àwọn ìdílé, àwọn ìjòyè àwọn ẹ̀yà Israẹli, àwọn alákòóso ẹgbẹgbẹ̀wàá àti alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn oníṣẹ́ tí ó wà ní ìdí iṣẹ́ ọba ní ìfẹ́ sí i.
Inhloko zaboyise zasezinikela ngesihle, lezinduna zezizwe zakoIsrayeli, labaphathi bezinkulungwane labamakhulu, labaphathi bomsebenzi wenkosi.
7 Wọ́n fi sílẹ̀ fún iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run, ẹgbẹ̀rún márùn-ún tálẹ́ǹtì àti ẹgbẹ̀rin mẹ́wàá wúrà, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá tálẹ́ǹtì fàdákà, ẹgbàá mẹ́sàn tálẹ́ǹtì idẹ àti ọgọ́rin ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì irin.
Basebenikela emsebenzini wendlu kaNkulunkulu amathalenta azinkulungwane ezinhlanu egolide, lenhlamvu ezizinkulungwane ezilitshumi, lamathalenta esiliva azinkulungwane ezilitshumi, lamathalenta ethusi azinkulungwane ezilitshumi lesificaminwembili, lamathalenta ensimbi azinkulungwane ezilikhulu.
8 Ẹnikẹ́ni tí ó ní òkúta iyebíye fi wọn sí ilé ìṣúra ilé Olúwa ní abẹ́ ìtọ́jú Jehieli ará Gerṣoni.
Lalabo okwatholwa kibo amatshe aligugu bawanika indlu yokuligugu yendlu yeNkosi ngaphansi kwesandla sikaJehiyeli umGerishoni.
9 Àwọn ènìyàn láyọ̀ nínú ìṣesí àtọkànwá fi sílẹ̀ àwọn olórí wọn, nítorí tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ọ̀fẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn sí Olúwa. Dafidi ọba pẹ̀lú yọ̀ gidigidi.
Basebethokoza abantu ngokunikela kwabo ngesihle, ngoba ngenhliziyo epheleleyo babenikele ngothando kuNkulunkulu; loDavida inkosi laye wathokoza ngentokozo enkulu.
10 Dafidi yin Olúwa níwájú gbogbo àwọn tí ó péjọ, wí pé, “Ìyìn ni fún Ọ, Olúwa, Ọlọ́run baba a wa Israẹli, láé àti láéláé.
UDavida waseyibusisa iNkosi phambi kwamehlo ebandla lonke; uDavida wathi: Kawubusiswe wena Nkosi Nkulunkulu kaIsrayeli ubaba, kusukela ephakadeni kuze kube sephakadeni.
11 Tìrẹ Olúwa ni títóbi àti agbára pẹ̀lú ìyìn àti ọláńlá àti dídán, nítorí tí gbogbo nǹkan ní ọ̀run àti ayé jẹ́ tìrẹ. Tìrẹ Olúwa ni ìjọba; a gbé ọ ga gẹ́gẹ́ bí orí lórí ohun gbogbo.
Kungokwakho, Nkosi, ubukhulu lamandla lodumo lokunqoba lobukhosi; ngoba konke okusemazulwini lokusemhlabeni kungokwakho; umbuso ungowakho, Nkosi; wena uziphakamisile waba yinhloko phezu kwakho konke.
12 Ọlá àti ọ̀wọ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Rẹ; ìwọ ni alákòóso gbogbo nǹkan. Ní ọwọ́ rẹ ni ipá àti agbára wà láti gbéga àti láti fi agbára fún ohun gbogbo.
Lenotho lodumo kuvela phambi kwakho, wena-ke ubusa phezu kwakho konke; lesandleni sakho kukhona ukuqina lamandla, lesandleni sakho kukhona ukukhulisa lokupha amandla kubo bonke.
13 Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, àwa fi ọpẹ́ fún Ọ, a sì fi ìyìn fún orúkọ rẹ̀ tí ó lógo.
Ngakho-ke Nkulunkulu wethu, siyakubonga, silidumise ibizo lakho elilodumo.
14 “Ṣùgbọ́n ta ni èmi, àti ta ni àwọn ènìyàn mi, tí a fi lè ṣe ìrànlọ́wọ́ tinútinú bí irú èyí? Gbogbo nǹkan wá láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ti wá, àwa sì ti fífún ọ láti ara ohun tí ó wá láti ọwọ́ rẹ.
Ngoba mina-ke ngingubani, labantu bami bangobani, ukuthi sithole amandla okunika ngothando ngokunje? Ngoba konke kuvela kuwe, sinikele kuwe okuvela esandleni sakho.
15 Àwa jẹ́ àjèjì àti àlejò ní ojú rẹ gẹ́gẹ́ bí baba ńlá a wa, àwọn ọjọ́ wa lórí ilẹ̀ ayé rí bí òjìji láìsí ìrètí.
Ngoba singabemzini phambi kwakho labahlala njengabezizwe njengabo bonke obaba; insuku zethu emhlabeni zinjengesithunzi, njalo kalikho ithemba.
16 Olúwa Ọlọ́run wa tí fi gbogbo púpọ̀ yìí tí àwa ti pèsè fún kíkọ́ ilé Olúwa fun orúkọ, mímọ́ rẹ̀, ó wá láti ọwọ́ ọ̀ rẹ, gbogbo rẹ̀ sì jẹ́ tirẹ̀.
Nkosi Nkulunkulu wethu, konke lokhu okunengi, esikulungisele ukwakhela wena indlu, kusenzelwa ibizo lakho elingcwele, kuvela esandleni sakho, njalo konke kungokwakho.
17 Èmi mọ̀ Ọlọ́run mi, wí pé ìwọ̀ dán ọkàn wò, ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn pẹ̀lú òtítọ́ inú. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti fi sílẹ̀ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́ pẹ̀lú òtítọ́. Nísinsin yìí èmi ti rí i pẹ̀lú ayọ̀ bí àwọn ènìyàn yìí tí ó wà níbí ti fi fún ọ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́.
Ngiyazi-ke, Nkulunkulu wami, ukuthi wena uhlola inhliziyo, uyabuthanda ubuqotho. Mina, ebuqothweni benhliziyo yami nginikele ngesihle zonke lezizinto; khathesi sengibonile ngentokozo abantu bakho abatholakala lapha ukuthi banikela kuwe ngesihle.
18 Olúwa Ọlọ́run àwọn baba a wa Abrahamu, Isaaki àti Israẹli pa ìfẹ́ yìí mọ́ nínú ọkàn àwọn ènìyàn rẹ títí láé pẹ̀lú pípa ọkàn mọ́ lóòtítọ́ sí ọ.
Nkosi, Nkulunkulu kaAbrahama, uIsaka, loIsrayeli, obaba, gcina lokho laphakade ekuzindleni kweminakano yenhliziyo yabantu bakho, ulungise inhliziyo yabo kuwe.
19 Àti fún ọmọ mi Solomoni ní ìfọkànsìn tòótọ́ láti pa àṣẹ rẹ mọ́ àwọn ohun tí ó nílò àti òfin àti láti ṣe ohun gbogbo láti kọ́ ààfin bí ti ọba fún èyí tí mo ti pèsè.”
Njalo unike uSolomoni indodana yami inhliziyo epheleleyo ukugcina imilayo yakho, ubufakazi bakho, lezimiso zakho, lokwenza konke, lokwakha isigodlo engisilungiseleleyo.
20 Dafidi sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn pé, “Nísinsin yìí, ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín.” Gbogbo ènìyàn sì fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì tẹ orí wọn ba, wọ́n wólẹ̀ fún Olúwa àti ọba.
UDavida wasesithi kulo lonke ibandla: Khathesi busisani iNkosi uNkulunkulu wenu. Ibandla lonke laselibusisa iNkosi, uNkulunkulu waboyise; bakhothama bamkhonza uJehova, lenkosi.
21 Ni ọjọ́ kejì, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì rú ẹbọ sísun sí i: ẹgbẹ̀rún kan akọ màlúù, ẹgbẹ̀rin kan àgbò, àti ẹgbẹ̀rin kan akọ ọ̀dọ́-àgùntàn. Lápapọ̀ pẹ̀lú ọrẹ mímu àti àwọn ẹbọ mìíràn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún gbogbo Israẹli.
Basebehlabela imihlatshelo eNkosini, banikela iminikelo yokutshiswa eNkosini, ngokusa kwalolosuku, amajongosi azinkulungwane, izinqama eziyinkulungwane, amawundlu ayinkulungwane, kanye leminikelo yabo yokunathwayo, lemihlatshelo ngobunengi kusenzelwa uIsrayeli wonke.
22 Wọ́n jẹ wọ́n sì mu pẹ̀lú ayọ̀ kíkún ní iwájú Olúwa ní ọjọ́ náà. Nígbà náà wọ́n yan Solomoni ọmọ Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba lẹ́ẹ̀kejì wọ́n fi àmì òróró yàn án níwájú Olúwa láti ṣe olórí àti Sadoku láti ṣe àlùfáà.
Basebesidla banatha phambi kweNkosi ngalolosuku ngentokozo enkulu. Basebembeka okwesibili uSolomoni indodana kaDavida ukuthi abe yinkosi, bamgcobela iNkosi waba ngumkhokheli, loZadoki waba ngumpristi.
23 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọba ní ipò baba a rẹ̀ Dafidi. O ṣe àṣeyọrí, gbogbo Israẹli sì gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
USolomoni wasehlala esihlalweni sobukhosi sikaJehova njengenkosi esikhundleni sikaDavida uyise, waphumelela; loIsrayeli wonke wamlalela.
24 Gbogbo àwọn ìjòyè àti àwọn ọkùnrin alágbára, pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọba Dafidi tẹrí ara wọn ba fún ọba Solomoni.
Lazo zonke izinduna lamaqhawe kanye lawo wonke amadodana enkosi uDavida bazehlisela ngaphansi kukaSolomoni inkosi.
25 Olúwa gbé Solomoni ga púpọ̀ ní ojú gbogbo Israẹli, ó sì kẹ́ ẹ ní ìkẹ́ ọláńlá, ní irú èyí tí a kò kẹ́ ọba kankan ṣáájú rẹ̀ tí ó jẹ lórí Israẹli.
INkosi yasimphakamisa uSolomoni kakhulu phambi kwamehlo kaIsrayeli wonke, yamnika ubukhosi bombuso obungazanga bube khona lakuyiphi inkosi ngaphambi kwakhe koIsrayeli.
26 Dafidi ọmọ Jese jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli.
Ngokunjalo uDavida indodana kaJese wayebuse phezu kukaIsrayeli wonke.
27 Ó jẹ ọba lórí Israẹli fún ogójì ọdún; ọdún méje ni ó jẹ ọba ní Hebroni, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu.
Njalo insuku abusa ngazo phezu kukaIsrayeli zaziyiminyaka engamatshumi amane; eHebroni wabusa iminyaka eyisikhombisa, leJerusalema wabusa iminyaka engamatshumi amathathu lantathu.
28 Òun sì darúgbó, ó sì kú ikú rere, ó gbádùn ẹ̀mí gígùn, ọlá àti ọrọ̀. Solomoni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Wasesifa eseluphele kuhle, enele ngezinsuku, inotho lodumo; uSolomoni indodana yakhe wasebusa esikhundleni sakhe.
29 Ní ti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba ọba Dafidi, láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin, a kọ wọ́n sínú ìwé ìrántí ti Samuẹli aríran, ìwé ìrántí ti Natani wòlíì àti ìwé ìrántí ti Gadi aríran,
Njalo izindaba zikaDavida inkosi, ezokuqala lezokucina, khangela, zibhaliwe egwalweni lwezindaba zikaSamuweli umboni legwalweni lwezindaba zikaNathani umprofethi legwalweni lwezindaba zikaGadi umboni,
30 lápapọ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti agbára rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìgbà tí ó kọjá lórí rẹ̀, àti lórí Israẹli, àti lórí gbogbo àwọn ìjọba gbogbo ilẹ̀ náà.
kanye lakho konke ukubusa kwakhe lamandla akhe, lezikhathi ezedlula phezu kwakhe laphezu kukaIsrayeli laphezu kwayo yonke imibuso yamazwe.

< 1 Chronicles 29 >