< 1 Chronicles 29 >

1 Nígbà náà, ọba Dafidi sọ fún gbogbo àpéjọ pé, “Ọmọ mi Solomoni, èyí tí Ọlọ́run ti yàn, sì kéré ó sì jẹ́ aláìmòye. Iṣẹ́ náà tóbi, nítorí ìkọ́lé bí ti ààfin kì í ṣe fún ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa Ọlọ́run.
Then King David said to all the people who had gathered there, “My son Solomon, the one whom God has chosen [to be the next king], is young and does not have much experience. This work [of building the temple] is great/important, because this glorious building will not be to [honor] people, but to honor Yahweh our God.
2 Pẹ̀lú gbogbo ìrànlọ́wọ́ mi èmi ti pèsè fún ilé Ọlọ́run mi wúrà fún iṣẹ́ wúrà, fàdákà fún ti fàdákà, idẹ fún ti idẹ, irin fún ti irin àti igi fún ti igi àti òkúta oníyebíye fún títọ́ rẹ̀, òkúta lóríṣìíríṣìí, àwọ̀ àti oríṣìíríṣìí ẹ̀yà òkúta àti òkúta dáradára kan gbogbo wọ̀nyí ní iye púpọ̀.
From all the things that I possess, I have provided [what will be needed] to [build] the temple of my God—the gold for the things to be made of gold, the silver for the things to be made of silver, bronze for the things to be made of bronze, iron for the things to be made of iron, wood for the things to be made of wood, and large amounts of onyx and turquoise and other valuable stones of various colors, and marble and all kinds of valuable stones.
3 Yàtọ̀ fún èyí, nínú ìfọkànsìn mi sí ilé Ọlọ́run mi, èmí fi ìṣúra mi tìkára mi ti wúrà àti fàdákà fún ilé Ọlọ́run mi. Jù gbogbo rẹ̀ lọ, èmi ti pèsè fún ilé mímọ́ ti Olúwa yìí,
In addition to all these things that I have given for the temple, I am giving treasures of gold and silver, because I very much desire that this holy temple for my God be built.
4 ẹgbẹ̀rún mẹ́ta tálẹ́ǹtì wúrà, ti wúrà Ofiri àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin tálẹ́ǹtì fàdákà dídára, fún bíbo àwọn ògiri ilé náà.
I am giving 110 tons of gold from Ophir and 260 tons of refined silver to cover the walls of the buildings,
5 Fún iṣẹ́ wúrà àti fàdákà náà, àti fún oríṣìí iṣẹ́ ti ó yẹ ní ṣíṣe nípasẹ̀ àwọn tí ó ní òye oríṣìíríṣìí iṣẹ́. Nísinsin yìí, ta ni ó ní ìfẹ́ sí yíya ará rẹ̀ sọ́tọ̀ lónìí sí Olúwa?”
for making the other items of gold and silver, and for the other work to be done by the craftsmen. So now, [I ask you], are there others willing to show [by contributing other gifts for the building of the temple] [EUP] that they have dedicated themselves to Yahweh?”
6 Nígbà náà àwọn aṣáájú àwọn ìdílé, àwọn ìjòyè àwọn ẹ̀yà Israẹli, àwọn alákòóso ẹgbẹgbẹ̀wàá àti alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn oníṣẹ́ tí ó wà ní ìdí iṣẹ́ ọba ní ìfẹ́ sí i.
Then the leaders of the families/clans, the leaders of the tribes of Israel, the commanders of 1,000 soldiers and the commanders of 100 soldiers, and the officials who supervised the work that the king wanted done, gave gifts (willingly/because they wanted to give them).
7 Wọ́n fi sílẹ̀ fún iṣẹ́ lórí ilé Ọlọ́run, ẹgbẹ̀rún márùn-ún tálẹ́ǹtì àti ẹgbẹ̀rin mẹ́wàá wúrà, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá tálẹ́ǹtì fàdákà, ẹgbàá mẹ́sàn tálẹ́ǹtì idẹ àti ọgọ́rin ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì irin.
For the work at the temple they gave 190 tons and (185 pounds/84 kg.) of gold, 375 tons of silver, 675 tons of bronze, and 3,750 tons of iron.
8 Ẹnikẹ́ni tí ó ní òkúta iyebíye fi wọn sí ilé ìṣúra ilé Olúwa ní abẹ́ ìtọ́jú Jehieli ará Gerṣoni.
And any people who owned valuable stones gave them to be put in the storeroom of the temple. Jehiel, a descendant of Gershon, was appointed to be in charge of them.
9 Àwọn ènìyàn láyọ̀ nínú ìṣesí àtọkànwá fi sílẹ̀ àwọn olórí wọn, nítorí tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ọ̀fẹ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn sí Olúwa. Dafidi ọba pẹ̀lú yọ̀ gidigidi.
The people were happy to see that their leaders wanted to give those things, because [they knew that] their leaders were happy and enthusiastic to give those things to Yahweh. And King David also was very happy.
10 Dafidi yin Olúwa níwájú gbogbo àwọn tí ó péjọ, wí pé, “Ìyìn ni fún Ọ, Olúwa, Ọlọ́run baba a wa Israẹli, láé àti láéláé.
Then, while all the people there were listening, David prayed, saying, “We praise you, Yahweh, the God whom our ancestor Jacob worshiped. We will praise you forever!
11 Tìrẹ Olúwa ni títóbi àti agbára pẹ̀lú ìyìn àti ọláńlá àti dídán, nítorí tí gbogbo nǹkan ní ọ̀run àti ayé jẹ́ tìrẹ. Tìrẹ Olúwa ni ìjọba; a gbé ọ ga gẹ́gẹ́ bí orí lórí ohun gbogbo.
You alone are great and powerful; only you are truly glorious and majestic and wonderful. [And that is true] because everything in heaven and on the earth is yours. You are the king of all the people in this world; you are the ruler of everything.
12 Ọlá àti ọ̀wọ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Rẹ; ìwọ ni alákòóso gbogbo nǹkan. Ní ọwọ́ rẹ ni ipá àti agbára wà láti gbéga àti láti fi agbára fún ohun gbogbo.
Because you are very powerful [DOU], you are able to cause anyone to be great and strong.
13 Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, àwa fi ọpẹ́ fún Ọ, a sì fi ìyìn fún orúkọ rẹ̀ tí ó lógo.
So now, our God, we thank you, and we praise you [MTY] for being very great.
14 “Ṣùgbọ́n ta ni èmi, àti ta ni àwọn ènìyàn mi, tí a fi lè ṣe ìrànlọ́wọ́ tinútinú bí irú èyí? Gbogbo nǹkan wá láti ọ̀dọ̀ rẹ ní ti wá, àwa sì ti fífún ọ láti ara ohun tí ó wá láti ọwọ́ rẹ.
But my people and I are not really able to give anything to you, because everything [that we have] comes from you, and what we have given to you are only the things that we have received from you [MTY].
15 Àwa jẹ́ àjèjì àti àlejò ní ojú rẹ gẹ́gẹ́ bí baba ńlá a wa, àwọn ọjọ́ wa lórí ilẹ̀ ayé rí bí òjìji láìsí ìrètí.
[In this land] we are like [MET] foreigners and strangers, like our ancestors were. Our time here on this earth is like [SIM] a shadow [that disappears quickly]; [we know that there is] nothing [that] can enable us [to escape dying].
16 Olúwa Ọlọ́run wa tí fi gbogbo púpọ̀ yìí tí àwa ti pèsè fún kíkọ́ ilé Olúwa fun orúkọ, mímọ́ rẹ̀, ó wá láti ọwọ́ ọ̀ rẹ, gbogbo rẹ̀ sì jẹ́ tirẹ̀.
Yahweh our God, we have gathered all these things to use in building your [MTY] temple, but all of it really belongs to you, and you have given it to us [MTY].
17 Èmi mọ̀ Ọlọ́run mi, wí pé ìwọ̀ dán ọkàn wò, ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn pẹ̀lú òtítọ́ inú. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti fi sílẹ̀ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́ pẹ̀lú òtítọ́. Nísinsin yìí èmi ti rí i pẹ̀lú ayọ̀ bí àwọn ènìyàn yìí tí ó wà níbí ti fi fún ọ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́.
My God, I know that you test us people, and you are pleased if you find out that we do what is right. All these things I have given to you because I wanted to. And now I have seen that your people have also joyfully and generously given things to you.
18 Olúwa Ọlọ́run àwọn baba a wa Abrahamu, Isaaki àti Israẹli pa ìfẹ́ yìí mọ́ nínú ọkàn àwọn ènìyàn rẹ títí láé pẹ̀lú pípa ọkàn mọ́ lóòtítọ́ sí ọ.
Yahweh, the God whom our ancestors Abraham, Isaac, and Jacob worshiped, I desire/hope that your people will continue to desire [to do things like this] forever, and that they will always be loyal to you.
19 Àti fún ọmọ mi Solomoni ní ìfọkànsìn tòótọ́ láti pa àṣẹ rẹ mọ́ àwọn ohun tí ó nílò àti òfin àti láti ṣe ohun gbogbo láti kọ́ ààfin bí ti ọba fún èyí tí mo ti pèsè.”
And now, please enable my son Solomon to faithfully and sincerely [DOU] obey your commands and laws and decrees [DOU] and to do everything that is needed to build this beautiful building for which I have provided [all these things].”
20 Dafidi sì sọ fún gbogbo ìjọ ènìyàn pé, “Nísinsin yìí, ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín.” Gbogbo ènìyàn sì fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì tẹ orí wọn ba, wọ́n wólẹ̀ fún Olúwa àti ọba.
Then David said to all the people who were gathered there, “Praise Yahweh our God!” So they all praised Yahweh the God whom their ancestors ([also worshiped/belonged to]). They prostrated themselves on the ground in front of Yahweh and in front of the king.
21 Ni ọjọ́ kejì, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì rú ẹbọ sísun sí i: ẹgbẹ̀rún kan akọ màlúù, ẹgbẹ̀rin kan àgbò, àti ẹgbẹ̀rin kan akọ ọ̀dọ́-àgùntàn. Lápapọ̀ pẹ̀lú ọrẹ mímu àti àwọn ẹbọ mìíràn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún gbogbo Israẹli.
The next day the people offered sacrifices to Yahweh. They presented many animals to be completely burned [on the altar]: 1,000 bulls, 1,000 rams, 1,000 male sheep, plus offerings of wine, and many other sacrifices on behalf of all [the people of] Israel.
22 Wọ́n jẹ wọ́n sì mu pẹ̀lú ayọ̀ kíkún ní iwájú Olúwa ní ọjọ́ náà. Nígbà náà wọ́n yan Solomoni ọmọ Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba lẹ́ẹ̀kejì wọ́n fi àmì òróró yàn án níwájú Olúwa láti ṣe olórí àti Sadoku láti ṣe àlùfáà.
On that day the people were joyful and ate and drank while Yahweh was watching. Then for the second time they declared that Solomon was now the king. While Yahweh was watching, they anointed him [with olive oil] to be the king, and they anointed Zadok to be the Supreme Priest.
23 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Olúwa gẹ́gẹ́ bí ọba ní ipò baba a rẹ̀ Dafidi. O ṣe àṣeyọrí, gbogbo Israẹli sì gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
So Solomon sat on the throne [because Yahweh wanted him to be] the king to succeed his father David. [During the following years] Solomon prospered, and all the Israeli people obeyed him.
24 Gbogbo àwọn ìjòyè àti àwọn ọkùnrin alágbára, pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ọba Dafidi tẹrí ara wọn ba fún ọba Solomoni.
King David’s other sons and all the officers and mighty warriors accepted Solomon as their king, and they solemnly promised to obey him.
25 Olúwa gbé Solomoni ga púpọ̀ ní ojú gbogbo Israẹli, ó sì kẹ́ ẹ ní ìkẹ́ ọláńlá, ní irú èyí tí a kò kẹ́ ọba kankan ṣáájú rẹ̀ tí ó jẹ lórí Israẹli.
Yahweh caused Solomon to be highly respected by all the Israeli people, and they honored him very much. No king of Israel was honored as much as Solomon was.
26 Dafidi ọmọ Jese jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli.
Jesse’s son David was the king who ruled all of Israel.
27 Ó jẹ ọba lórí Israẹli fún ogójì ọdún; ọdún méje ni ó jẹ ọba ní Hebroni, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu.
He ruled for 40 years: Seven years in Hebron [city] and 33 years in Jerusalem.
28 Òun sì darúgbó, ó sì kú ikú rere, ó gbádùn ẹ̀mí gígùn, ọlá àti ọrọ̀. Solomoni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
He became an old man who was very rich and greatly honored by all the people. Then he died, and his son Solomon became the king [of Israel].
29 Ní ti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba ọba Dafidi, láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin, a kọ wọ́n sínú ìwé ìrántí ti Samuẹli aríran, ìwé ìrántí ti Natani wòlíì àti ìwé ìrántí ti Gadi aríran,
A record of all the things that King David did while he ruled, from the beginning to the end, was put on scrolls written by the prophets Samuel, Nathan, and Gad.
30 lápapọ̀, pẹ̀lú gbogbo ìjọba àti agbára rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìgbà tí ó kọjá lórí rẹ̀, àti lórí Israẹli, àti lórí gbogbo àwọn ìjọba gbogbo ilẹ̀ náà.
They told about his powerful rule [HEN], and all the things that happened to him and to the people of Israel and in the nearby kingdoms [while he was ruling Israel].

< 1 Chronicles 29 >