< 1 Chronicles 28 >

1 Dafidi pe gbogbo àwọn oníṣẹ́ ti Israẹli láti péjọ ní Jerusalẹmu. Àwọn ìjòyè lórí àwọn ẹ̀yà, àwọn alákòóso ìpín nínú iṣẹ́ bí ọba, àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn oníṣẹ́ tí ó wà ní ìdí bíbojútó gbogbo àwọn ẹrù àti ohun ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú ààfin àwọn oníṣẹ́ ààfin, àwọn ọkùnrin alágbára àti gbogbo àwọn ògbójú jagunjagun lápapọ̀.
David je zbral vse Izraelove prince, prince rodov in poveljnike skupin, ki so služili kralju po skupini in poveljnike nad tisočimi, poveljnike nad stotimi in oskrbnike nad vsem imetjem in posestjo kralja in njegovih sinov, s častniki in z mogočnimi možmi in z vsemi hrabrimi možmi v Jeruzalem.
2 Ọba Dafidi dìde dúró ní ẹsẹ̀ rẹ̀, o sì wí pé, “Fetísílẹ̀ sí mi, ẹ̀yin ará mi àti ẹ̀yin ènìyàn mi. Èmi ní o ni lọ́kàn mi láti kọ́ ilé gẹ́gẹ́ bí ibi ìsinmi fún àpótí ẹ̀rí tí Olúwa fún àpótí ìtìsẹ̀ Ọlọ́run wa, èmi sì gbèrò láti kọ́ ọ.
Potem je kralj David stopil na svoja stopala in rekel: »Poslušajte me, moji bratje in moje ljudstvo: › Kar se mene tiče, sem imel v svojem srcu, da zgradim hišo počitka za skrinjo Gospodove zaveze in za pručko našega Boga in sem pripravil za gradnjo,
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ ilé fún orúkọ mi, nítorí ìwọ jẹ́ jagunjagun, ìwọ sì ti tàjẹ̀ sílẹ̀.’
toda Bog mi je rekel: ›Ne boš gradil hiše mojemu imenu, ker si bil bojevnik in si prelival kri.‹
4 “Síbẹ̀ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli yàn mí láti gbogbo ìdílé láti jẹ́ ọba lórí Israẹli, títí láé. Ó yan Juda gẹ́gẹ́ bí olórí, àti láti ilé Juda, ó yan ìdílé mi, àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ baba à mí, ó tẹ́ Ẹ lọ́rùn láti fi mí ṣe ọba lórí gbogbo Israẹli.
Vendar je Gospod, Izraelov Bog, mene izbral pred vso hišo mojega očeta, da bi bil na veke kralj nad Izraelom, kajti Juda je izbral, da bi bil vladar; in od Judove hiše, hišo mojega očeta; in med sinovi mojega očeta sem mu bil všeč, da me je postavil za kralja nad vsem Izraelom,
5 Nínú gbogbo àwọn ọmọ mi pẹ̀lú Olúwa ti fún mi ní púpọ̀, ó ti yan ọmọ mi Solomoni láti jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba ti Olúwa lórí Israẹli.
in izmed vseh mojih sinov (kajti Gospod mi je dal mnogo sinov), je izbral mojega sina Salomona, da sedi na prestolu Gospodovega kraljestva nad Izraelom.
6 Ó wí fún mi pé, Solomoni ọmọ rẹ ni ẹni tí yóò kọ́ ilé mi àti àwọn ààfin mi, nítorí tí èmi ti yàn án láti ṣe ọmọ mi èmi yóò sì jẹ́ baba a rẹ̀.
Rekel mi je: ›Tvoj sin Salomon bo zgradil mojo hišo in moje dvore, kajti izbral sem ga, da bo moj sin in jaz bom njegov oče.
7 Èmi yóò fi ìdí ìjọba rẹ̀ kalẹ̀ títí láé tí kò bá kọ̀ láti gbé àṣẹ àti òfin mi jáde, gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe é ní àsìkò yìí.
Poleg tega bom na veke utrdil njegovo kraljestvo, če bo stalno izpolnjeval moje zapovedi in moje sodbe, kakor ta dan.‹
8 “Bẹ́ẹ̀ ni, nísinsin yìí, èmi pàṣẹ fún ọ ní ojú gbogbo Israẹli àti ní ti ìpéjọpọ̀ tí Olúwa, àti ní etí ìgbọ́ Ọlọ́run wa. Ṣọ́ra kó o sì tẹ̀lé gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run rẹ kí ìwọ kí ó le jogún ilẹ̀ dáradára yìí, kí o sì mú un lọ síwájú gẹ́gẹ́ bí ogún rẹ fún àwọn ìran ọmọ rẹ títí láé.
Zdaj se torej pred očmi vsega Izraela, Gospodove skupnosti in v občinstvu našega Boga, držite in iščite vse zapovedi Gospoda, svojega Boga, da boste lahko posedli to dobro deželo in jo pustili za dediščino svojim otrokom za seboj na veke.
9 “Àti ìwọ, ọmọ mi Solomoni, rántí Ọlọ́run baba à rẹ, kí o sì sìn ín pẹ̀lú tọkàntọkàn pẹ̀lú ìfọkànsí pẹ̀lú ọkàn tí ó pé, nítorí Olúwa ṣàwárí gbogbo ọkàn ó sì mọ gbogbo èrò. Tí ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i; ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ títí láé.
Ti pa, moj sin Salomon, spoznaj Boga svojega očeta in mu služi s popolnim srcem in z voljnim umom, kajti Gospod preiskuje vsa srca in razume vse miselne zamisli. Če ga boš iskal, ga boš našel, toda če ga zapustiš, te bo on zavrgel na veke.
10 Gbèrò báyìí nítorí tí Olúwa ti yàn ọ́ láti kọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí ilé tí a yà sí mímọ́ fún Olúwa. Jẹ́ alágbára kí ó sì ṣe iṣẹ́ náà.”
Pazi torej, kajti Gospod te je izbral, da zgradiš hišo za svetišče. Bodi močan in to stôri.‹«
11 Nígbà náà ni Dafidi fi àpẹẹrẹ fún Solomoni ọmọ rẹ̀ ti ìloro àti ti ilé Olúwa náà, kíkọ́ ọ rẹ̀, àti ti ibi ìṣúra rẹ̀, àti ti iyàrá òkè rẹ̀, àti ti ìyẹ̀wù rẹ̀ àti ti ibùjókòó àánú.
Potem je David svojemu sinu Salomonu dal vzorec preddverja, njegovih hiš, njegovih zakladnic, njegovih gornjih sob, njegovih notranjih dvoran in kraja sedeža milosti,
12 Ó fún un ní àwọn ètò gbogbo èyí tí ẹ̀mí ti fi sí ọkàn rẹ̀ fún ti ààfin ilé Olúwa àti gbogbo yàrá tí ó yíká fún ìṣúra ilé Ọlọ́run àti fún ìṣúra fún ohun yíyà sọ́tọ̀.
vzorec vsega, kar je imel po duhu glede dvorov Gospodove hiše in vseh sob naokoli, zakladnic Božje hiše in zakladnic posvečenih stvari.
13 Ó fún un ní àwọn ìlànà fún ìpín ti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti fún gbogbo iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa àti fún gbogbo ohun èlò tí wọn ó lò nínú ìsìn rẹ̀.
Tudi za skupine duhovnikov in Lévijevcev in za vse delo službe Gospodove hiše in za vse posode službe v Gospodovi hiši.
14 Ó yàn ìwọ̀n wúrà fún gbogbo ohun èlò wúrà tí a ó lò níbi oríṣìí ìsìn, àti ìwọ̀n fàdákà fún gbogbo ohun èlò fàdákà tí a ó lò fún oríṣìí ìsìn,
Dal je zlata po teži za stvari iz zlata, za vse priprave vseh vrst službe; tudi srebra za vse priprave iz srebra po teži, za vse priprave vsake vrste službe.
15 ìwọ̀n wúrà fún ìdúró fìtílà àti fìtílà wọn, fún ìwọ̀n fún ọ̀kọ̀ọ̀kan ìdúró fìtílà àti fìtílà wọn; àti ìwọ̀n fàdákà ìdúró fìtílà fàdákà àti àwọn fìtílà rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìlò ti gbogbo ìdúró fìtílà.
Celo težo za svečnike iz zlata in za njihove svetilke iz zlata po teži za vsak svečnik in za njihove svetilke. In za svečnike iz srebra po teži, tako za svečnik in tudi za njihove svetilke, glede na uporabo vsakega svečnika.
16 Ìwọ̀n ti wúrà fun tábìlì, tábìlì fún àkàrà tí a yà sọ́tọ̀; ìwọ̀n fàdákà fún àwọn tábìlì fàdákà;
Po teži je dal zlata za mize hlebov navzočnosti za vsako mizo in podobno zlata za mize iz srebra.
17 ìwọ̀n kìkì wúrà fún àwọn àmúga ìjẹun, àwọn ìbùwọ́n ọpọ́n àti àwọn ìkòkò ìpọnmi; ìwọ̀n wúrà fún gbogbo àwopọ̀kọ́ fàdákà;
Tudi čistega zlata za kavlje za meso, skledice in čaše. Za zlate umivalnike je dal zlata po teži za vsak umivalnik; in podobno srebra, po teži za vsak umivalnik iz srebra;
18 àti ìwọ̀n ìdá wúrà fún pẹpẹ tùràrí ó fún un ní ètò fún kẹ̀kẹ́, ìyẹn ni pé àwọn ìdúró kérúbù wúrà tí wọ́n tan iye wọn ká, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí Olúwa.
Za kadilni oltar prečiščeno zlato po teži in zlata za vzorec bojnega voza kerubov, ki razprostirata svoje peruti in pokrivata skrinjo Gospodove zaveze.
19 “Gbogbo èyí,” ni Dafidi wí pé, “Èmi ní kíkọ sílẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa sórí mi, ó sì fún mí ní ìmọ̀ nínú gbogbo iṣẹ́ ètò yìí.”
»Vse to, « je rekel David, »mi je Gospod dal razumeti v pisanju po svoji roki nad menoj, torej vsa dela tega vzorca.«
20 Dafidi tún sọ fún Solomoni ọmọ rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára kí o sì gbóyà, kí o sì ṣe iṣẹ́ náà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí dààmú, nítorí Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run mi, wà pẹ̀lú rẹ. Òun kì yóò sì já ọ kule tàbí kọ ọ sílẹ̀ títí gbogbo iṣẹ́ fún ìsìn ní ti ilé Olúwa yóò fi parí.
David je rekel svojemu sinu Salomonu: »Bodi močan in odločnega poguma in stôri to. Ne boj se niti ne bodi zaprepaden, kajti Gospod Bog, celó moj Bog, bo s teboj. Ne bo te razočaral niti te ne bo zapustil, dokler ne dokončaš vsega dela za službo Gospodove hiše.
21 Ìpín àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ṣetán fún gbogbo iṣẹ́ ilé Olúwa. Gbogbo ọkùnrin tí ó ní ìfẹ́ sí i tí ó sì ní òye oríṣìíríṣìí iṣẹ́. Yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ náà. Àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn yóò gbọ́rọ̀ sí gbogbo àṣẹ rẹ.”
Glej, skupine duhovnikov in Lévijevcev, celo oni bodo s teboj za vso službo Božje hiše, in tam bo s teboj za vse vrste rokodelstva vsak voljan vešč mož, za vse vrste del. Tudi princi in vse ljudstvo bo popolno ob tvoji zapovedi.«

< 1 Chronicles 28 >