< 1 Chronicles 28 >

1 Dafidi pe gbogbo àwọn oníṣẹ́ ti Israẹli láti péjọ ní Jerusalẹmu. Àwọn ìjòyè lórí àwọn ẹ̀yà, àwọn alákòóso ìpín nínú iṣẹ́ bí ọba, àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn oníṣẹ́ tí ó wà ní ìdí bíbojútó gbogbo àwọn ẹrù àti ohun ọ̀sìn tí ó jẹ́ ti ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú ààfin àwọn oníṣẹ́ ààfin, àwọn ọkùnrin alágbára àti gbogbo àwọn ògbójú jagunjagun lápapọ̀.
And David assembled all the princes of Israel, the princes of the tribes, and the captains of the divisions that ministered to the king, and the captains of the thousands, and the captains of the hundreds, and the rulers of all the property and the cattle of the king and of his sons, with the court-servants, and the mighty men, and with all the valiant men of the army, unto Jerusalem.
2 Ọba Dafidi dìde dúró ní ẹsẹ̀ rẹ̀, o sì wí pé, “Fetísílẹ̀ sí mi, ẹ̀yin ará mi àti ẹ̀yin ènìyàn mi. Èmi ní o ni lọ́kàn mi láti kọ́ ilé gẹ́gẹ́ bí ibi ìsinmi fún àpótí ẹ̀rí tí Olúwa fún àpótí ìtìsẹ̀ Ọlọ́run wa, èmi sì gbèrò láti kọ́ ọ.
Then arose king David upon his feet, and said, Hear me, my brethren, and my people! I had in my heart to build a house of rest for the ark of the covenant of the Lord, and for the footstool of our God, and I had made preparations to build;
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún mi pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ ilé fún orúkọ mi, nítorí ìwọ jẹ́ jagunjagun, ìwọ sì ti tàjẹ̀ sílẹ̀.’
But God said unto me, Thou shalt not build a house unto my name; because thou art a man of war, and blood hast thou shed.
4 “Síbẹ̀ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli yàn mí láti gbogbo ìdílé láti jẹ́ ọba lórí Israẹli, títí láé. Ó yan Juda gẹ́gẹ́ bí olórí, àti láti ilé Juda, ó yan ìdílé mi, àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ baba à mí, ó tẹ́ Ẹ lọ́rùn láti fi mí ṣe ọba lórí gbogbo Israẹli.
Yet the Lord the God of Israel made choice of me out of all the house of my father to be king over Israel for ever; for of Judah had he made choice as ruler, and among the house of Judah, of the house of my father; and among the sons of my father had he pleasure in me to make [me] king over all Israel:
5 Nínú gbogbo àwọn ọmọ mi pẹ̀lú Olúwa ti fún mi ní púpọ̀, ó ti yan ọmọ mi Solomoni láti jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba ti Olúwa lórí Israẹli.
And of all my sons, —for the Lord hath given me many sons, — hath he made choice of Solomon my son, to sit upon the throne of the kingdom of the Lord over Israel.
6 Ó wí fún mi pé, Solomoni ọmọ rẹ ni ẹni tí yóò kọ́ ilé mi àti àwọn ààfin mi, nítorí tí èmi ti yàn án láti ṣe ọmọ mi èmi yóò sì jẹ́ baba a rẹ̀.
And he hath said unto me, Solomon thy son it is that shall build my house and my courts; for I have made choice of him to be as a son unto me, and I will be indeed to him as a father.
7 Èmi yóò fi ìdí ìjọba rẹ̀ kalẹ̀ títí láé tí kò bá kọ̀ láti gbé àṣẹ àti òfin mi jáde, gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe é ní àsìkò yìí.
Moreover, I will firmly establish his kingdom for everlasting, if he be strong to execute my commandments and my ordinances as it is this day.
8 “Bẹ́ẹ̀ ni, nísinsin yìí, èmi pàṣẹ fún ọ ní ojú gbogbo Israẹli àti ní ti ìpéjọpọ̀ tí Olúwa, àti ní etí ìgbọ́ Ọlọ́run wa. Ṣọ́ra kó o sì tẹ̀lé gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run rẹ kí ìwọ kí ó le jogún ilẹ̀ dáradára yìí, kí o sì mú un lọ síwájú gẹ́gẹ́ bí ogún rẹ fún àwọn ìran ọmọ rẹ títí láé.
And now before the eyes of all Israel, the congregation of the Lord, and in the hearing of our God, [I admonish you] observe and seek for all the commandments of the Lord your God: in order that ye may keep possession of this good land, and leave it for an inheritance unto your children after you forever.
9 “Àti ìwọ, ọmọ mi Solomoni, rántí Ọlọ́run baba à rẹ, kí o sì sìn ín pẹ̀lú tọkàntọkàn pẹ̀lú ìfọkànsí pẹ̀lú ọkàn tí ó pé, nítorí Olúwa ṣàwárí gbogbo ọkàn ó sì mọ gbogbo èrò. Tí ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i; ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ títí láé.
And thou, Solomon my son, know thou the God of thy father, and serve him with an entire heart and with a willing soul; for all hearts doth the Lord search, and every imagination of the thoughts doth he understand; if thou seek him, he will let himself be found by thee; but if thou forsake him, he will cast thee off for ever.
10 Gbèrò báyìí nítorí tí Olúwa ti yàn ọ́ láti kọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí ilé tí a yà sí mímọ́ fún Olúwa. Jẹ́ alágbára kí ó sì ṣe iṣẹ́ náà.”
See now that the Lord hath made choice of thee to build a house for the sanctuary: be strong and do it.
11 Nígbà náà ni Dafidi fi àpẹẹrẹ fún Solomoni ọmọ rẹ̀ ti ìloro àti ti ilé Olúwa náà, kíkọ́ ọ rẹ̀, àti ti ibi ìṣúra rẹ̀, àti ti iyàrá òkè rẹ̀, àti ti ìyẹ̀wù rẹ̀ àti ti ibùjókòó àánú.
Then gave David to Solomon his son the pattern of the porch, and of its apartments, and of its treasuries, and of upper chambers, and of its inner chambers, and of the place of the cover of the ark.
12 Ó fún un ní àwọn ètò gbogbo èyí tí ẹ̀mí ti fi sí ọkàn rẹ̀ fún ti ààfin ilé Olúwa àti gbogbo yàrá tí ó yíká fún ìṣúra ilé Ọlọ́run àti fún ìṣúra fún ohun yíyà sọ́tọ̀.
And the pattern of all that he had in his spirit, concerning the courts of the house of the Lord, and concerning all the chambers round about, concerning the treasuries of the house of God, and concerning the treasuries of the holy things:
13 Ó fún un ní àwọn ìlànà fún ìpín ti àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àti fún gbogbo iṣẹ́ ìsìn nínú ilé Olúwa àti fún gbogbo ohun èlò tí wọn ó lò nínú ìsìn rẹ̀.
Also concerning the divisions of the priests and the Levites, and concerning all the work of the service of the house of the Lord, and concerning all the vessels of service of the house of the Lord;
14 Ó yàn ìwọ̀n wúrà fún gbogbo ohun èlò wúrà tí a ó lò níbi oríṣìí ìsìn, àti ìwọ̀n fàdákà fún gbogbo ohun èlò fàdákà tí a ó lò fún oríṣìí ìsìn,
Concerning the golden vessels, after the weight of the gold, for all the vessels of all manner of service; concerning all the vessels of silver after the weight, for all the vessels of every kind of service;
15 ìwọ̀n wúrà fún ìdúró fìtílà àti fìtílà wọn, fún ìwọ̀n fún ọ̀kọ̀ọ̀kan ìdúró fìtílà àti fìtílà wọn; àti ìwọ̀n fàdákà ìdúró fìtílà fàdákà àti àwọn fìtílà rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìlò ti gbogbo ìdúró fìtílà.
Also the weight for the candlesticks of gold, and for their lamps of gold, after the weight for every candlestick, and for its lamps; and concerning the candlesticks of silver after the weight, for the candlestick, and for its lamps, according to the use of every candlestick;
16 Ìwọ̀n ti wúrà fun tábìlì, tábìlì fún àkàrà tí a yà sọ́tọ̀; ìwọ̀n fàdákà fún àwọn tábìlì fàdákà;
And the gold after the weight for the tables of the rows of shewbread, for every table; and the silver for the tables of silver;
17 ìwọ̀n kìkì wúrà fún àwọn àmúga ìjẹun, àwọn ìbùwọ́n ọpọ́n àti àwọn ìkòkò ìpọnmi; ìwọ̀n wúrà fún gbogbo àwopọ̀kọ́ fàdákà;
Also [concerning] the forks, and the bowls, and the supporters of pure gold; and concerning the golden cups after the weight for every cup; and concerning the silver cups after the weight for every cup;
18 àti ìwọ̀n ìdá wúrà fún pẹpẹ tùràrí ó fún un ní ètò fún kẹ̀kẹ́, ìyẹn ni pé àwọn ìdúró kérúbù wúrà tí wọ́n tan iye wọn ká, wọ́n sì bo àpótí ẹ̀rí Olúwa.
And concerning the altar of incense the refined gold after the weight; and concerning the pattern of the chariot of the golden cherubim, which spread out [their wings], and over the ark of the covenant of the Lord.
19 “Gbogbo èyí,” ni Dafidi wí pé, “Èmi ní kíkọ sílẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa sórí mi, ó sì fún mí ní ìmọ̀ nínú gbogbo iṣẹ́ ètò yìí.”
All [this, said David, ] was put in writing from the hand of the Lord, who gave me instruction [respecting] all the works of the pattern.
20 Dafidi tún sọ fún Solomoni ọmọ rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára kí o sì gbóyà, kí o sì ṣe iṣẹ́ náà. Má ṣe bẹ̀rù tàbí dààmú, nítorí Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run mi, wà pẹ̀lú rẹ. Òun kì yóò sì já ọ kule tàbí kọ ọ sílẹ̀ títí gbogbo iṣẹ́ fún ìsìn ní ti ilé Olúwa yóò fi parí.
And David said to Solomon his son, Be strong, and of good courage, and do [the work]; fear not, and be not dismayed; for the Lord God, [yea, ] my God is with thee: he will not fail thee, nor forsake thee, until thou have finished all the work for the service of the house of the Lord.
21 Ìpín àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ṣetán fún gbogbo iṣẹ́ ilé Olúwa. Gbogbo ọkùnrin tí ó ní ìfẹ́ sí i tí ó sì ní òye oríṣìíríṣìí iṣẹ́. Yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nínú iṣẹ́ náà. Àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn ènìyàn yóò gbọ́rọ̀ sí gbogbo àṣẹ rẹ.”
And, behold, the divisions of the priests and the Levites are there for all the service of the house of God; and with thee are in all manner of workmanship all kinds of men distinguished in wisdom, for every manner of service; and the princes and all the people are ready [to obey] all thy words.

< 1 Chronicles 28 >