< 1 Chronicles 27 >

1 Wọ̀nyí ni ìwé àkójọ orúkọ àwọn ọmọ Israẹli, àwọn olórí àwọn ìdílé, àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn ìjòyè wọn. Tí ó n sin ọba nínú gbogbo ohun tí ó kan ìpín àwọn ọmọ-ogun tí ó wà lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn ní oṣooṣù ní gbogbo ọdún. Ìpín kọ̀ọ̀kan jẹ́ ẹgbàá méjìlá ọkùnrin.
Et, pendant le cours de l'année, de mois en mois, une division de vingt- quatre mille hommes, prise parmi tous les fils d'Israël, chefs de familles, commandants de mille hommes, centeniers, scribes et serviteurs, était employée à exécuter les ordres du roi; chaque division était relevée à son tour.
2 Ní ti alákòóso lórí ìpín kìn-ín-ní fún oṣù kìn-ín-ní jẹ́ Jaṣobeamu ọmọ Sabdieli àwọn ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ní ó wà ní abẹ́ ìpín tirẹ̀.
A la tête de la première division employée le premier mois était Isboaz, fils de Zabdiel; il commandait vingt-quatre mille hommes.
3 Ó jẹ́ ìran ọmọ Peresi àti olóyè fún gbogbo àwọn ìjòyè ológun fún oṣù kìn-ín-ní.
Il était issu de Pharès, et comme chef de tous les chefs de l'armée, il commandait pendant le premier mois.
4 Alákòóso fún ìpín àwọn ọmọ-ogun fún oṣù kejì jẹ́ Dodai ará Ahohi; Mikloti jẹ́ olórí ìpín tirẹ̀. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
A la tête de la division du second mois était Dodia, fils d'Eccoc, et il y avait encore pour chef de cette division Maceloth; ils étaient chefs de vingt- quatre mille hommes.
5 Olórí àwọn ọmọ-ogun ẹlẹ́ẹ̀kẹta fún oṣù kẹta jẹ́ Benaiah ọmọ Jehoiada àlùfáà. Ó jẹ́ olóyè, àwọn ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ní ó wà ní ìpín tirẹ̀.
Banaïas, fils de Joad le prêtre, était le troisième chef, il commandait la division du troisième mois, pareillement vingt-quatre mille hommes.
6 Èyí ni Benaiah náà tí ó jẹ́ ọkùnrin ńlá láàrín àwọn ọgbọ̀n àti lórí àwọn ọgbọ̀n. Ọmọ rẹ̀ Amisabadi jẹ́ alákòóso lórí ìpín tirẹ̀.
Ce Banaïas était le plus vaillant des trente; il était à leur tête, et son fils Zabad commandait avec lui sa division.
7 Ẹlẹ́ẹ̀kẹrin fún oṣù kẹrin, jẹ́ Asaheli arákùnrin Joabu: ọmọ rẹ̀ Sebadiah jẹ́ arọ́pò rẹ̀. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
Le quatrième, celui du quatrième mois, était Asaël, frère de Joab, et son fils Zabadie; ses fils et ses frères partageaient son commandement sur vingt- quatre mille hommes.
8 Ẹ̀karùnún fún oṣù karùn-ún, jẹ́ olórí Ṣamhuti ará Israhi. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ní ó wà ní ìpín tirẹ̀.
Le cinquième chef, celui du cinquième mois, était Samaoth le Jezraïte; il commandait vingt-quatre mille hommes.
9 Ẹ̀kẹfà fún oṣù kẹfà jẹ́ Ira ọmọ Ikẹsi, ará Tekoi. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
Le sixième, celui du sixième mois, était Oduïas, fils d'Eccès de Thécoé; il commandait vingt-quatre mille hommes.
10 Èkeje fún oṣù keje jẹ́ Helesi ará Peloni, ará Efraimu. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni o wà ní ìpín rẹ̀.
Le septième, celui du septième mois, était Relies de Phallus, des fils d'Ephrahn; sa division comptait vingt-quatre mille hommes.
11 Ẹ̀kẹjọ fún oṣù kẹjọ jẹ́ Sibekai ará Huṣati, ará Sera ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
Le huitième, celui du huitième mois, était Sohochaï de Husathi, issu de Zara; il commandait vingt-quatre mille hommes.
12 Ẹ̀kẹsànán fún oṣù kẹsànán jẹ́. Abieseri ará Anatoti, ará Benjamini ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
Le neuvième, celui du neuvième mois, était Abiézer d'Anathoth, de la terre de Benjamin; il commandait vingt-quatre mille hommes.
13 Ẹ̀kẹwàá fún oṣù kẹwàá jẹ́ Maharai ará Netofa, ará Sera ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
Le dixième, celui du dixième mois, était Méhéra de Netophathi, issu de Zara; il commandait vingt-quatre mille hommes.
14 Ìkọkànlá fún oṣù kọkànlá jẹ́ Benaiah ará Piratoni ará Efraimu ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
Le onzième, celui du onzième mois, était Baillas de Pharathon, des fils d'Ephraïm; il commandait vingt-quatre mille hommes.
15 Èkejìlá fún oṣù kejìlá jẹ́ Heldai ará Netofa láti ìdílé Otnieli. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
Le douzième, celui du douzième mois, était Holdia de Netophathi, issu d'Othoniel; il commandait vingt-quatre mille hommes.
16 Àwọn ìjòyè lórí àwọn ẹ̀yà tí Israẹli: lórí àwọn ará Reubeni: Elieseri ọmọ Sikri; lórí àwọn ọmọ Simeoni: Ṣefatia ọmọ Maaka;
Et il y avait des chefs à la tête de claque tribu; celui de Ruben était Eliézer, fils de Zéchri; celui de Siméon, Saphatias, fils de Maacha.
17 lórí Lefi: Haṣabiah ọmọ Kemueli; lórí Aaroni: Sadoku;
Celui de Lévi, Asabias, fils de Camuel; Sadoc était chef de la famille d'Aaron.
18 lórí Juda: Elihu arákùnrin Dafidi; lórí Isakari: Omri ọmọ Mikaeli;
Le chef de Juda était Eliab, l'un des frères de David; celui d'Issachar Ambri, fils de Michel.
19 lórí Sebuluni: Iṣmaiah ọmọ Obadiah; lórí Naftali: Jerimoti ọmọ Asrieli;
Celui de Zabulon, Samain, fils d'Abdiu; celui de Nephthali: Jerimoth, fils d'Oziel.
20 lórí àwọn ará Efraimu: Hosea ọmọ Asasiah; lórí ààbọ̀ ẹ̀yà Manase: Joẹli ọmọ Pedaiah;
Celui d'Ephraïm, Osé, fils d'Oziu; celui de la demi-tribu de Manassé: Johel, fils de Phadaïa.
21 lórí ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ní Gileadi: Iddo ọmọ Sekariah; lórí Benjamini: Jaasieli ọmọ Abneri;
Celui de l'autre demi-tribu de Manassé, en Galaad, Jadaï, fils de Zadaïu; celui de Benjamin, Jasiel, fils d'Abner.
22 lórí Dani: Asareeli ọmọ Jerohamu. Wọ̀nyí ni àwọn ìjòyè lórí ẹ̀yà Israẹli.
Celui de Dan: Azariel, fils de Iroab; tels étaient les chefs de familles des tribus d'Israël.
23 Dafidi kò kọ iye àwọn ọkùnrin náà ní ogún ọdún sẹ́yìn tàbí dín nítorí Olúwa ti ṣe ìlérí láti ṣe Israẹli gẹ́gẹ́ bí iye ìràwọ̀ ojú ọ̀run.
Et David ne fit point le dénombrement de ceux de vingt ans et au-dessous, car le Seigneur lui avait dit qu'il multiplierait Israël comme les étoiles du ciel.
24 Joabu ọmọ Seruiah bẹ̀rẹ̀ sí ní kà wọ́n, ṣùgbọ́n kò parí kíkà wọ́n nítorí, ìbínú dé sórí àwọn Israẹli nípasẹ̀ kíka iye àti iye náà, a kò kọ ọ́ sínú ìwé ìtàn ayé ti ọba Dafidi.
Et Joab, fils de Sarvia, avait commencé le dénombrement du peuple, mais il ne l'acheva point; et ce dénombrement causa la colère qui éclata contre Israël, et le nombre que l'on avait trouvé fut supprimé du livre des faits et gestes du roi David.
25 Asmafeti ọmọ Adieli wà ní ìdí ilé ìṣúra ti ọba. Jonatani ọmọ Ussiah wà ní ìdí ilé ìṣúra ní iwájú agbègbè nínú àwọn ìlú, àwọn ìletò àti àwọn ilé ìṣọ́.
Asmoth, fils d'Adaël, fut trésorier du roi, et Jonathas, fils d'Ozia, trésorier de la contrée, des villes, des villages et des tours.
26 Esri ọmọ Kelubu wà ní ìdí àwọn òṣìṣẹ́ lórí pápá, tí wọ́n ń ko ilẹ̀ náà.
Esdri, fils d'Hélab, avait l'intendance des laboureurs et ouvriers travaillant à la terre.
27 Ṣimei ará Ramoti wà ní ìdí àwọn ọgbà àjàrà. Sabdi ará Sifmi wà ní ìdí mímú jáde ti èso àjàrà fún ọpọ́n ńlá tí a ń fi ọ̀tún èso àjàrà sí.
Semei de Rahel, celle des champs; Zabni, fils de Jephni, celle des vignes.
28 Baali-Hanani ará Gederi wà ní ìdí olifi àti àwọn igi sikamore ní apá ìhà ìwọ̀-oòrùn àwọn ní ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀. Joaṣi wà ní ìdí fífún ni ní òróró olifi.
Balanan le Gedorite, celle des oliviers et des figuiers des champs; Joas, celle de l'huile.
29 Ṣitrai ará Ṣaroni wà ní ìdí fífi ọwọ́ ẹran jẹ oko ní Ṣaroni. Ṣafati ọmọ Adlai wà ní ìdí àwọn ọ̀wọ́ ẹran ní àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀.
Satrai le Saronite, celle des bœufs qui paissaient en Saron; et Sophat, fils d'Abdi, celle des bœufs à l'étable.
30 Obili ará Iṣmaeli wà ní ìdí àwọn ìbákasẹ. Jehdeiah ará Meronoti wà ní ìdí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Abias, l'Ismaélite, celle des chameaux; Jadias de Merathon, celle des ânes.
31 Jasisi ará Hagari wà ní ìdí àwọn agbo ẹran. Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn oníṣẹ́ tí wọ́n wà ní ìdí ẹrù ọba Dafidi.
Jaziz l'Agarite, celle des brebis. Tels étaient tous les intendants des domaines du roi David.
32 Jonatani, arákùnrin Dafidi jẹ́ olùdámọ̀ràn, ọkùnrin onímọ̀ àti akọ̀wé. Jehieli ọmọ Hakmoni bojútó àwọn ọmọ ọba.
Jonathas, oncle paternel de David, était conseiller, homme intelligent; et Jehel, fils d'Achami, était avec les fils du roi.
33 Ahitofeli jẹ́ olùdámọ̀ràn ọba. Huṣai ará Arki jẹ́ ọ̀rẹ́ ọba.
Achitophel était conseiller du roi, et Chusi son principal favori.
34 (Jehoiada ọmọ Benaiah àti nípasẹ̀ Abiatari jẹ ọba rọ́pò Ahitofeli.) Joabu jẹ́ olórí ọmọ-ogun ọba.
Après lui venaient Achitophel, Joad, fils de Banaïas et Abiathar. Joab était le général en chef du roi.

< 1 Chronicles 27 >