< 1 Chronicles 26 >

1 Àwọn ìpín tí àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà. Láti ìran Kora: Meṣelemiah ọmọ Kore, ọ̀kan lára àwọn ọmọ Asafu.
Na, ko nga wehenga o nga kaitiaki kuwaha; no nga Korohi ko Meheremia tama a Kore, no nga tama a Ahapa.
2 Meṣelemiah ní àwọn ọmọkùnrin: Sekariah àkọ́bí, Jediaeli ẹlẹ́ẹ̀kejì, Sebadiah ẹlẹ́ẹ̀kẹta, Jatnieli ẹlẹ́ẹ̀kẹrin,
Na, ko nga tama a Meheremia, ko Hakaraia te matamua, ko Teriaere te tuarua, ko Teparia te tuatoru, ko Iataniere te tuawha,
3 Elamu ẹlẹ́ẹ̀karùnún, Jehohanani ẹlẹ́ẹ̀kẹfà àti Elihoenai ẹlẹ́ẹ̀keje.
Ko Erama te tuarima, ko Iehohanana te tuaono, ko Erioenai te tuawhitu.
4 Obedi-Edomu ni àwọn ọmọkùnrin pẹ̀lú: Ṣemaiah àkọ́bí, Jehosabadi ẹlẹ́ẹ̀kejì, Joah ẹlẹ́ẹ̀kẹta, Sakari ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Netaneli ẹlẹ́ẹ̀karùnún,
A ko nga tama a Opereeroma; ko Hemaia te matamua, ko Iehotapara te tuarua, ko Ioaha te tuatoru, ko Hakara te tuawha, ko Netaneere te tuarima,
5 Ammieli ẹ̀kẹfà, Isakari èkeje àti Peulltai ẹ̀kẹjọ. (Nítorí tí Ọlọ́run ti bùkún Obedi-Edomu).
Ko Amiere te tuaono, ko Ihakara te tuawhitu, ko Peurutai te tuawaru; he mea manaaki hoki ia na Ihowa.
6 Ọmọ rẹ̀ Ṣemaiah ní àwọn ọmọkùnrin pẹ̀lú tí wọ́n jẹ́ olórí ní ìdílé baba a wọn nítorí wọ́n jẹ́ ọkùnrin tó lágbára.
A i whanau ano he tama ma tana tama ma Hemaia, he rangatira ratou mo te whare o to ratou papa: he marohirohi hoki ratou, he toa.
7 Àwọn ọmọ Ṣemaiah: Otni, Refaeli, Obedi àti Elsabadi; àwọn ìbátan rẹ̀ Elihu àti Samakiah jẹ́ ọkùnrin alágbára.
Ko nga tama a Hemaia; ko Otoni, ko Repaere, ko Opere, ko Eretapara; he marohirohi ano o ratou teina a Erihu raua ko Hemakia.
8 Gbogbo wọ̀nyí ní ìran ọmọ Obedi-Edomu; àwọn àti ọmọkùnrin àti ìbátan wọn jẹ́ alágbára ọkùnrin pẹ̀lú ipá láti ṣe ìsìn náà. Ìran Obedi-Edomu méjìlélọ́gọ́ta ni gbogbo rẹ̀.
Ko enei katoa o nga tama a Opereeroma, me a ratou tama, me o ratou teina he kaha ki te mahi, e ono tekau ma rua; na Opereeroma.
9 Meṣelemiah ní àwọn ọmọ àti àwọn ìbátan, tí ó jẹ́ alágbára méjìdínlógún ni gbogbo wọn.
Na he tama a Meheremia, he teina ano, he marohirohi, tekau ma waru.
10 Hosa ará Merari ní àwọn ọmọkùnrin: Ṣimri alákọ́kọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé kì i ṣe àkọ́bí, baba a rẹ̀ ti yàn an ní àkọ́kọ́.
He tama ano a Hoha o nga tama a Merari; ko Himiri te upoko; ahakoa ehara ia i te matamua, i meinga ia hei upoko e tona papa;
11 Hilkiah ẹlẹ́ẹ̀kejì, Tabaliah ẹ̀kẹta àti Sekariah ẹ̀kẹrin. Àwọn ọmọ àti ìbátan Hosa jẹ́ mẹ́tàlá ni gbogbo rẹ̀.
Ko Hirikia te tuarua, ko Teparia te tuatoru, ko Hakaraia te tuawha; ko nga tama katoa, me nga teina o Hoha, tekau ma toru.
12 Ìpín wọ̀nyí ti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà nípasẹ̀ olóyè ọkùnrin wọn, ní iṣẹ́ ìsìn fún jíjíṣẹ́ nínú ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìbátan wọn ti ṣe.
I roto i enei nga wehenga o nga kaitiaki kuwaha, ara i roto i nga tino tangata, he mahi tiaki pera i ta o ratou tuakana, he minita i roto i te whare o Ihowa.
13 Wọ́n ṣẹ́ kèké fún ẹnu-ọ̀nà kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ìdílé wọn bí ọ̀dọ́ àti arúgbó.
I maka rota ano ratou, te iti, te rahi, nga whare o o ratou matua, mo tenei kuwaha, mo tenei kuwaha.
14 Kèké fún ẹnu-ọ̀nà ilà oòrùn bọ́ sí ọ̀dọ̀ Ṣelemiah. Nígbà náà a dá kèké fún ọmọkùnrin rẹ̀ Sekariah, ọlọ́gbọ́n onímọ̀ràn, kèké fún ẹnu-ọ̀nà àríwá sì bọ́ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Na i taka te rota whaka te rawhiti ki a Heremia. Katahi ka maka te rota a tana tama a Hakaraia, he mohio ia ki te whakatakoto whakaaro, a ko te rota mo te raki i puta ake mana.
15 Kèké fún ẹnu-ọ̀nà ìhà gúúsù bọ́ sí ọ̀dọ̀ Obedi-Edomu, kèké fún ilé ìṣúra sì bọ́ sí ọ̀dọ̀ ọmọ rẹ̀.
Ki a Opereeroma ko te rota mo te tonga; a ki ana tama ko te whare taonga.
16 Kèké fún ẹnu-ọ̀nà ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Ṣaleketi ẹnu-ọ̀nà ní ọ̀nà apá òkè bọ́ sí ọ̀dọ̀ Ṣuppimu àti Hosa. Olùṣọ́ wà ní ẹ̀bá olùṣọ́.
Ki a Tupimi raua ko Hoha ko to te hauauru, me te kuwaha Harekete, i te huarahi e piki atu ai, tenei tiakanga i te ritenga mai o tenei tiakanga.
17 Àwọn ará Lefi mẹ́fà ní ó wà ní ọjọ́ kan ní ìhà ìlà-oòrùn, mẹ́rin ní ọjọ́ kan ní ìhà àríwá, mẹ́rin ní ọjọ́ kan ní ìhà gúúsù àti méjì ní ẹ̀ẹ̀kan ṣoṣo ní ilé ìṣúra.
Tokoono nga Riwaiti mo to te rawhiti, tokowha mo to te raki i tenei ra, i tenei ra, tokowha mo to te tonga i tenei ra, i tenei ra, a ki te whare taonga tokorua, tokorua.
18 Ní ti ilé ẹjọ́ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn, mẹ́rin sì wà ní ojú ọ̀nà àti méjì ní ilé ẹjọ́ fúnra rẹ̀.
I Parapara whaka te hauauru, tokowha ki te huarahi, tokorua ki Parapara.
19 Wọ̀nyí ni ìpín ti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí wọ́n jẹ́ àwọn ìran ọmọ Kora àti Merari.
Ko nga wehenga enei o nga kaitiaki kuwaha i roto i nga tama a Kore, i nga tama ano a Merari.
20 Láti inú àwọn ọmọ Lefi, Ahijah ni ó wà lórí ìṣúra ti ilé Ọlọ́run àti lórí ìṣúra nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a yà sí mímọ́.
Na o nga Riwaiti, ko Ahia ki nga taonga o te whare o Ihowa, ki nga taonga hoki kua oti te whakatapu.
21 Àwọn ìran ọmọ Laadani tí wọn jẹ́ ará Gerṣoni nípasẹ̀ Laadani àti tí wọn jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé tí ó jẹ́ ti Laadani ará Gerṣoni ni Jehieli.
Ko nga tama a Raarana; ko nga tama a nga Kerehoni na Raarana, ko nga upoko o nga whare o nga matua na Raarana Kerehoni; ko Tehieri.
22 Àwọn ọmọ Jehieli, Setamu àti arákùnrin rẹ̀ Joẹli. Wọ́n ṣalábojútó ilé ìṣúra ti ilé ìṣúra ti ilé Olúwa.
Ko nga tama a Tehieri; ko Tetama, ko tona teina ko Hoera, i a ratou nga taonga o te whare o Ihowa.
23 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ará Amramu, àwọn ará Isari, àwọn ará Hebroni àti àwọn ará Usieli.
No nga Amarami enei, ratou ko nga Itihari, ko nga Heperoni, ko nga Utieri.
24 Ṣubaeli, ìran ọmọ Gerṣomu ọmọ Mose jẹ́ olórí tí ó bojútó ilé ìṣúra.
Na ko Hepuere tama a Kerehoma tama a Mohi te rangatira mo nga taonga.
25 Àwọn ìbátan rẹ̀ nípasẹ̀ Elieseri: Rehabiah ọmọ rẹ̀, Jeṣaiah ọmọ rẹ̀, Joramu ọmọ rẹ̀, Sikri ọmọ rẹ̀, Ṣelomiti ọmọ rẹ̀.
Me ona teina: na Erietere, tana tama a Rehapia, tana tama a Ihaia, tana tama a Iorama, tana tama a Tikiri, tana tama a Heromoto.
26 Ṣelomiti àti àwọn ìbátan rẹ̀ jẹ́ alábojútó ilé ìṣúra fún àwọn ohun tí à ti yà sọ́tọ̀ nípa ọba Dafidi, nípasẹ̀ àwọn olórí àwọn ìdílé tí wọ́n jẹ́ alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti nípasẹ̀ alákòóso ọmọ-ogun mìíràn.
Ko tenei Heromoto ratou ko ona teina nga rangatira mo nga taonga katoa, mo nga mea i whakatapua, i whakatapua nei e Kingi Rawiri ratou ko nga upoko o nga whare o nga matua, ko nga rangatira o nga mano, o nga rau, ko nga rangatira ope.
27 Díẹ̀ nínú ìkógun tí wọ́n kó nínú ogun ni wọ́n yà sọ́tọ̀ fún títún ilé Olúwa ṣe.
Ko etahi o nga taonga parakete i riro parau mai, he mea whakatapu na ratou kia mau tonu ai te ora o te whare o Ihowa.
28 Pẹ̀lú gbogbo nǹkan tí a yà sọ́tọ̀ láti ọ̀dọ̀ Samuẹli aríran láti nípasẹ̀ Saulu ọmọ Kiṣi, Abneri ọmọ Neri àti Joabu ọmọ Seruiah gbogbo ohun tí a yà sọ́tọ̀ sì wà ní abẹ́ ìtọ́jú Ṣelomiti àti àwọn ìbátan rẹ̀.
Na, ko nga mea katoa i whakatapua e Hamuera matakite, e Haora tama a Kihi, e Apanere tama a Nere, e Ioapa tama a Teruia, e te hunga katoa ano i whakatapua ai tetahi mea, i raro era i te ringa o Heromoto ratou ko ona teina.
29 Láti ọ̀dọ̀ àwọn Isari: Kenaniah àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni a pín iṣẹ́ ìsìn fún kúrò ní apá ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí àwọn oníṣẹ́ àti àwọn adájọ́ lórí Israẹli.
O nga Itihari, ko Kenania ratou ko ana tama mo nga mahinga o waho ki a Iharaira, hei rangatira, hei kaiwhakawa.
30 Láti ọ̀dọ̀ àwọn Hebroni: Haṣabiah àti àwọn ìbátan rẹ̀ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ọkùnrin alágbára ní ó dúró ni Israẹli, ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani fún gbogbo iṣẹ́ Olúwa àti fún iṣẹ́ ọba.
O nga Heperoni, ko Hahapia ratou ko ona teina, he marohirohi, kotahi mano e whitu rau, hei rangatira i roto i te hunga o Iharaira i tenei taha o Horano whaka te hauauru, i nga minitatanga katoa ki a Ihowa, i nga mahi ano a te kingi.
31 Ní ti àwọn ará Hebroni, Jeriah jẹ́ olóyè wọn gẹ́gẹ́ bí ìwé ìrántí ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, ní ti ìdílé wọn. Ní ọdún kẹrin ìjọba Dafidi, a ṣe ìwádìí nínú ìwé ìrántí, àwọn ọkùnrin alágbára láàrín àwọn ará Hebroni ni a rí ní Jaseri ní Gileadi.
I roto i nga Heperoni ko Teriia te upoko, ara i roto i nga Heperoni, i runga ano i nga whakatupuranga o nga whare o nga matua. I te wha tekau o nga tau o te kingitanga o Rawiri i rapua ratou, a kua kitea etahi marohirohi i roto i a ratou, he toa, ki Iatere o Kireara.
32 Jeriah ní ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ìbátan, tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbára àti olórí àwọn ìdílé ọba Dafidi sì fi wọ́n ṣe àkóso lórí àwọn ará Reubeni àwọn ará Gadi àti ààbọ̀ ẹ̀yà ti Manase fún gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó jọ mọ́ ti Ọlọ́run àti fún ọ̀ràn ti ọba.
Me ona teina, he toa, e rua mano e whitu rau, he upoko no nga whare o nga matua, meinga ana ratou e Kingi Rawiri hei rangatira mo nga Reupeni, mo nga Kari, mo tetahi tanga o te iwi o Manahi, mo nga mea katoa a te Atua, mo nga mea ano a te kingi.

< 1 Chronicles 26 >