< 1 Chronicles 26 >

1 Àwọn ìpín tí àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà. Láti ìran Kora: Meṣelemiah ọmọ Kore, ọ̀kan lára àwọn ọmọ Asafu.
Ceux à qui les portes furent distribuées, étaient les fils de Coré, Mosellamia, de la famille d'Asaph.
2 Meṣelemiah ní àwọn ọmọkùnrin: Sekariah àkọ́bí, Jediaeli ẹlẹ́ẹ̀kejì, Sebadiah ẹlẹ́ẹ̀kẹta, Jatnieli ẹlẹ́ẹ̀kẹrin,
Et les fils de Mosellamia: Zacharie le premier-né, Jadiel le second, Zabadie le troisième, Jénuel le quatrième,
3 Elamu ẹlẹ́ẹ̀karùnún, Jehohanani ẹlẹ́ẹ̀kẹfà àti Elihoenai ẹlẹ́ẹ̀keje.
Jolam le cinquième, Jonathan le sixième, Elionai le septième, Abdedom le huitième.
4 Obedi-Edomu ni àwọn ọmọkùnrin pẹ̀lú: Ṣemaiah àkọ́bí, Jehosabadi ẹlẹ́ẹ̀kejì, Joah ẹlẹ́ẹ̀kẹta, Sakari ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Netaneli ẹlẹ́ẹ̀karùnún,
Et les fils d'Abdedom: Samaias le premier-né, Jozabath le second, Joath le troisième, Sachar le quatrième, Nathanaél le cinquième,
5 Ammieli ẹ̀kẹfà, Isakari èkeje àti Peulltai ẹ̀kẹjọ. (Nítorí tí Ọlọ́run ti bùkún Obedi-Edomu).
Amiel le sixième, Issachar le septième, Phelathi le huitième; car Dieu l'avait béni.
6 Ọmọ rẹ̀ Ṣemaiah ní àwọn ọmọkùnrin pẹ̀lú tí wọ́n jẹ́ olórí ní ìdílé baba a wọn nítorí wọ́n jẹ́ ọkùnrin tó lágbára.
Et à son premier fils Samaïas, des fils naquirent, et furent chefs dans leur famille, parce qu'ils étaient forts
7 Àwọn ọmọ Ṣemaiah: Otni, Refaeli, Obedi àti Elsabadi; àwọn ìbátan rẹ̀ Elihu àti Samakiah jẹ́ ọkùnrin alágbára.
Fils de Samaï: Otbni, Raphaël, Obed, Elzabath, Achiud, tous hommes forts, Elia, Sabachias et Isbacom.
8 Gbogbo wọ̀nyí ní ìran ọmọ Obedi-Edomu; àwọn àti ọmọkùnrin àti ìbátan wọn jẹ́ alágbára ọkùnrin pẹ̀lú ipá láti ṣe ìsìn náà. Ìran Obedi-Edomu méjìlélọ́gọ́ta ni gbogbo rẹ̀.
Tous issus d'Abdedom; eux, et leurs fils et leurs frères, remplissant avec énergie leurs fonctions, au nombre de soixante-deux, issus d'Abdedom.
9 Meṣelemiah ní àwọn ọmọ àti àwọn ìbátan, tí ó jẹ́ alágbára méjìdínlógún ni gbogbo wọn.
Mosellemia avait dix-huit fils et frères, tous hommes forts.
10 Hosa ará Merari ní àwọn ọmọkùnrin: Ṣimri alákọ́kọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé kì i ṣe àkọ́bí, baba a rẹ̀ ti yàn an ní àkọ́kọ́.
Et les fils d'Osa, issu de Mérari, et qui n'était pas le premier-né, commandaient ce service; son père lui donna le commandement de la deuxième division.
11 Hilkiah ẹlẹ́ẹ̀kejì, Tabaliah ẹ̀kẹta àti Sekariah ẹ̀kẹrin. Àwọn ọmọ àti ìbátan Hosa jẹ́ mẹ́tàlá ni gbogbo rẹ̀.
Helcias venait après lui, Tablé était le troisième, Zacharie le quatrième; les fils et les frères d'Osa étaient en tout: treize.
12 Ìpín wọ̀nyí ti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà nípasẹ̀ olóyè ọkùnrin wọn, ní iṣẹ́ ìsìn fún jíjíṣẹ́ nínú ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìbátan wọn ti ṣe.
C'est entre eux que furent partagées les portes; chefs énergiques, servant avec autant de zèle que leurs frères, employés dans l'intérieur du temple.
13 Wọ́n ṣẹ́ kèké fún ẹnu-ọ̀nà kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ìdílé wọn bí ọ̀dọ́ àti arúgbó.
Et ils tirèrent au sort les portes où ils devaient être placés, après qu'on les eut classés, selon leur plus ou moins de force, par familles paternelles.
14 Kèké fún ẹnu-ọ̀nà ilà oòrùn bọ́ sí ọ̀dọ̀ Ṣelemiah. Nígbà náà a dá kèké fún ọmọkùnrin rẹ̀ Sekariah, ọlọ́gbọ́n onímọ̀ràn, kèké fún ẹnu-ọ̀nà àríwá sì bọ́ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Le sort désigna, pour la porte orientale, Sélémie et Zacharie; ensuite, les fils de Soaz, issu de Melchia, agitèrent les sorts, et celui de la porte du nord sortit.
15 Kèké fún ẹnu-ọ̀nà ìhà gúúsù bọ́ sí ọ̀dọ̀ Obedi-Edomu, kèké fún ilé ìṣúra sì bọ́ sí ọ̀dọ̀ ọmọ rẹ̀.
Abdedom eut la porte du midi, en face de la maison d'Esephim.
16 Kèké fún ẹnu-ọ̀nà ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Ṣaleketi ẹnu-ọ̀nà ní ọ̀nà apá òkè bọ́ sí ọ̀dọ̀ Ṣuppimu àti Hosa. Olùṣọ́ wà ní ẹ̀bá olùṣọ́.
Osa eut la seconde porte du côté de l'orient, après celle qui mène au vestibule des degrés; un garde vis-à-vis l'autre garde.
17 Àwọn ará Lefi mẹ́fà ní ó wà ní ọjọ́ kan ní ìhà ìlà-oòrùn, mẹ́rin ní ọjọ́ kan ní ìhà àríwá, mẹ́rin ní ọjọ́ kan ní ìhà gúúsù àti méjì ní ẹ̀ẹ̀kan ṣoṣo ní ilé ìṣúra.
Il y avait chaque jour six hommes à la porte orientale, quatre à celle du nord, quatre à celle du midi et deux à Esephim,
18 Ní ti ilé ẹjọ́ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn, mẹ́rin sì wà ní ojú ọ̀nà àti méjì ní ilé ẹjọ́ fúnra rẹ̀.
Pour la relève, du côté du couchant quatre et deux à l'entrée du chemin.
19 Wọ̀nyí ni ìpín ti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí wọ́n jẹ́ àwọn ìran ọmọ Kora àti Merari.
Les portes étaient ainsi distribuées entre les fils dé Coré et ceux de Mérari.
20 Láti inú àwọn ọmọ Lefi, Ahijah ni ó wà lórí ìṣúra ti ilé Ọlọ́run àti lórí ìṣúra nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a yà sí mímọ́.
Et des lévites, leurs frères, gardaient le trésor de la demeure du Seigneur et le trésor des consécrations.
21 Àwọn ìran ọmọ Laadani tí wọn jẹ́ ará Gerṣoni nípasẹ̀ Laadani àti tí wọn jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé tí ó jẹ́ ti Laadani ará Gerṣoni ni Jehieli.
Ceux-là étaient fils de Ladan; ils étaient issus des fils de Gerson; les chefs des familles provenaient de Ladan, le fils de Ladan le Gersonite était Jehiel.
22 Àwọn ọmọ Jehieli, Setamu àti arákùnrin rẹ̀ Joẹli. Wọ́n ṣalábojútó ilé ìṣúra ti ilé ìṣúra ti ilé Olúwa.
Zethom et Johel, son frère, fils de Jehiel, étaient intendants du trésor de la demeure du Seigneur,
23 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ará Amramu, àwọn ará Isari, àwọn ará Hebroni àti àwọn ará Usieli.
Avec les familles d'Amram, d'Issaar, d'Hébron et d'Oziel.
24 Ṣubaeli, ìran ọmọ Gerṣomu ọmọ Mose jẹ́ olórí tí ó bojútó ilé ìṣúra.
Subael, issu de Gersam, fils de Moïse, était aussi intendant des trésors.
25 Àwọn ìbátan rẹ̀ nípasẹ̀ Elieseri: Rehabiah ọmọ rẹ̀, Jeṣaiah ọmọ rẹ̀, Joramu ọmọ rẹ̀, Sikri ọmọ rẹ̀, Ṣelomiti ọmọ rẹ̀.
Or, Eliézer, l'un de ses proches, eut pour fils Rabias, de qui descendirent: Josias, Joram, Zéchri et Salomoth.
26 Ṣelomiti àti àwọn ìbátan rẹ̀ jẹ́ alábojútó ilé ìṣúra fún àwọn ohun tí à ti yà sọ́tọ̀ nípa ọba Dafidi, nípasẹ̀ àwọn olórí àwọn ìdílé tí wọ́n jẹ́ alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún àti nípasẹ̀ alákòóso ọmọ-ogun mìíràn.
Ce Salomoth et ses frères eurent l'intendance de tous les trésors saints, que consacrèrent le roi David et les chefs de familles paternelles, commandants de mille hommes, ou centeniers, ou princes de l'armée;
27 Díẹ̀ nínú ìkógun tí wọ́n kó nínú ogun ni wọ́n yà sọ́tọ̀ fún títún ilé Olúwa ṣe.
C'étaient les choses qu'ils avaient enlevées des villes prises sur l'ennemi, et consacrées pour subvenir aux frais de construction du temple de Dieu.
28 Pẹ̀lú gbogbo nǹkan tí a yà sọ́tọ̀ láti ọ̀dọ̀ Samuẹli aríran láti nípasẹ̀ Saulu ọmọ Kiṣi, Abneri ọmọ Neri àti Joabu ọmọ Seruiah gbogbo ohun tí a yà sọ́tọ̀ sì wà ní abẹ́ ìtọ́jú Ṣelomiti àti àwọn ìbátan rẹ̀.
Ainsi, tout ce qu'avait consacré Samuel le prophète; Saül, fils de Cis; Abner, fils de Ner; Joab, fils de Servie, fut confié à Salomoth et à ses frères.
29 Láti ọ̀dọ̀ àwọn Isari: Kenaniah àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni a pín iṣẹ́ ìsìn fún kúrò ní apá ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí àwọn oníṣẹ́ àti àwọn adájọ́ lórí Israẹli.
Honnias, issu d'Isaar, et ses fils, furent chargés de fonctions extérieures en Israël; ils étaient scribes et juges.
30 Láti ọ̀dọ̀ àwọn Hebroni: Haṣabiah àti àwọn ìbátan rẹ̀ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ọkùnrin alágbára ní ó dúró ni Israẹli, ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani fún gbogbo iṣẹ́ Olúwa àti fún iṣẹ́ ọba.
Asubias, issu d'Hébron, et ses frères, hommes forts, au nombre de dix- sept cents, avaient la surveillance d'Israël, sur la rive occidentale du Jourdain, pour tout ce qui concernait le service du Seigneur et le gouvernement du roi.
31 Ní ti àwọn ará Hebroni, Jeriah jẹ́ olóyè wọn gẹ́gẹ́ bí ìwé ìrántí ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, ní ti ìdílé wọn. Ní ọdún kẹrin ìjọba Dafidi, a ṣe ìwádìí nínú ìwé ìrántí, àwọn ọkùnrin alágbára láàrín àwọn ará Hebroni ni a rí ní Jaseri ní Gileadi.
Urie était le chef de la postérité d'Hébron, par familles paternelles; or, la quarantième année du règne de David, elle fut recensée en Jazer-Galaad, et Urie fut reconnu vaillant.
32 Jeriah ní ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ìbátan, tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbára àti olórí àwọn ìdílé ọba Dafidi sì fi wọ́n ṣe àkóso lórí àwọn ará Reubeni àwọn ará Gadi àti ààbọ̀ ẹ̀yà ti Manase fún gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó jọ mọ́ ti Ọlọ́run àti fún ọ̀ràn ti ọba.
Ses frères, les chefs de famille, au nombre de deux mille sept cents, étaient aussi des hommes forts; le roi les institua intendants de Ruben, de Gad et de la demi-tribu de Manassé, pour tout ce qui concernait les commandements du Seigneur et les ordres du roi.

< 1 Chronicles 26 >