< 1 Chronicles 24 >

1 Àwọn wọ̀nyí sì ni pínpín àwọn ọmọ Aaroni. Àwọn ọmọ Aaroni ni Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Et les fils d'Aaron étaient: Nadab, Abiud, Eléazar et Ithamar.
2 Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu kú kí ó tó di wí pé baba wọn kú, wọn kò sì ní àwọn ọmọ; bẹ́ẹ̀ ni Eleasari àti Itamari sì ṣe gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
Or, Nadab et Abiud moururent sous les yeux de leur père, et ils n'avaient point de fils; Eléazar et Ithamar, fils d'Aaron, eurent donc le sacerdoce.
3 Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Sadoku ọmọ Eleasari àti Ahimeleki ọmọ Itamari, Dafidi sì yà wọ́n nípa nínú ìpín fún ìyàsọ́tọ̀ àwọn iṣẹ́ ìsìn wọn.
Et David distingua les fils d'Eléazar, de qui descendait Sadoc, des fils d'Ithamar, de qui était issu Achimélech, selon leur recensement, et leurs services, et leurs familles paternelles.
4 A rí ọ̀pọ̀ àwọn olórí lára àwọn ọmọ Eleasari ju lára àwọn ọmọ Itamari lọ, wọ́n sì pín wọn lẹ́sẹ lẹ́sẹ: mẹ́rìndínlógún olórí láti ìdílé ọmọ Eleasari ìran wọn àti olórí méjọ ìdílé láti ara àwọn ọmọ Itamari.
Et il se trouva, parmi ces hommes forts, plus de chefs des fils d'Eléazar que des fils d'Ithamar, et David mit les premiers à la tête de seize familles, les seconds à la tête de huit familles seulement.
5 Wọ́n sì pín wọn láìṣègbè nípa yíya ìpín, nítorí àwọn olórí ibi mímọ́ àti àwọn olórí ilé Ọlọ́run wà láàrín àwọn ọmọ méjèèjì Eleasari àti Itamari.
Et il leur distribua leurs services par le sort; car, parmi les uns comme parmi les autres, il y avait des chefs des choses saintes, et des chefs du Seigneur.
6 Ṣemaiah ọmọ Netaneli, akọ̀wé ọ̀kan lára àwọn ọmọ Lefi sì kọ orúkọ wọn níwájú ọba àti àwọn ìjòyè: Sadoku àlùfáà, Ahimeleki ọmọ Abiatari àti olórí ìdílé àwọn àlùfáà tí a mú láti ọ̀dọ̀ Eleasari àti ọ̀kan láti ọ̀dọ̀ Itamari.
Et le scribe Samaïas, fils de Nathanakl de la tribu de Lévi, écrivit la liste en présence du roi et des chefs, aidé de Sadoc le prêtre, et d'Abimélech, fils d'Abiathar, et des chefs des familles paternelles des prêtres et des lévites, inscrivant tour à tour un nom provenant d'Eléazar, un nom provenant d'Ithamar.
7 Ìpín èkínní jáde sí Jehoiaribu, èkejì sí Jedaiah,
Le sort désigna en premier lieu Joarim; le second fut Jedia,
8 ẹlẹ́ẹ̀kẹta sì ni Harimu, ẹ̀kẹrin sì ní Seorimu,
Le troisième Harib, le quatrième Séorim,
9 ẹ̀karùnún sì ni Malkiah, ẹlẹ́ẹ̀kẹfà sì ni Mijamini,
Le cinquième Melchias, le sixième Meïamin,
10 èkeje sì ni Hakosi, ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ sí ni Abijah,
Le septième Cos, le huitième Abias,
11 ẹ̀kẹsànán sì ni Jeṣua, ẹ̀kẹwàá sì ni Ṣekaniah,
Le neuvième Jésua, le dixième Sechénias,
12 ẹ̀kọkànlá sì ni Eliaṣibu, ẹlẹ́ẹ̀kẹjìlá sì ni Jakimu,
Le onzième Eliabi, le douzième Jacim,
13 ẹ̀kẹtàlá sì ni Hupa, ẹlẹ́ẹ̀kẹrìnlá sì ni Jeṣebeabu,
Le treizième Opha, le quatorzième Jezbaal,
14 ẹ̀kẹdógún sì ni Bilgah, ẹ̀kẹrìndínlógún sì ni Immeri,
Le quinzième Belga, le seizième Hemmer,
15 ẹ̀kẹtàdínlógún sì ni Hesiri, èkejìdínlógún sì ni Hafisesi,
Le dix-septième Hézin, le dix-huitième Aphésé,
16 ẹ̀kọkàndínlógún sì ni Petahiah, ogún sì ni Jeheskeli,
Le dix-neuvième Phetaïe, le vingtième Ezecel,
17 ẹ̀kọkànlélógún sì ni Jakini, ẹ̀kẹrìnlélógún sì ni Gamuli,
Le vingt et unième Achim, le vingt-deuxième Gamul,
18 ẹ̀kẹtàlélógún sì ni Delaiah, ẹ̀kẹrìnlélógún sì ni Maasiah.
Le vingt-troisième Abdallé, le vingt-quatrième Maasé.
19 Àwọn wọ̀nyí ni a yàn fún iṣẹ́ ìsìn nígbà tí wọ́n wọ ilé Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìlànà àti àṣẹ tí a ti fi fún wọn láti ọwọ́ baba ńlá wọn Aaroni gẹ́gẹ́ bí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tí pàṣẹ fun un.
Tel fut leur recensement, selon leurs services, pour pénétrer dans le tabernacle du Seigneur, d'après le règlement d'Aaron, leur père, tel que le Seigneur l'avait prescrit.
20 Ìyókù àwọn ọmọ Lefi. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Amramu: Ṣubaeli láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ṣubaeli; Jehdeiah.
Voici le reste des fils de Lévi: Fils d'Amram: Sobael. Fils de Sobael: Jedia.
21 Àti gẹ́gẹ́ bí Rehabiah, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Rehabiah, Iṣiah sì ni alákọ́kọ́.
Le chef des fils de Raabia:
22 Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Isari: Ṣelomiti; láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ṣelomoti: Jahati.
Salomoth, fils de Isaar; Jath, des fils de Salomoth.
23 Àwọn ọmọ Hebroni: Jeriah alákọ́kọ́, Amariah ẹlẹ́ẹ̀kejì, Jahasieli ẹlẹ́ẹ̀kẹta àti Jekameamu ẹlẹ́ẹ̀kẹrin.
Les fils d'Ecdiu: Amadias le second, Jaziel le troisième, Jecmoam le quatrième.
24 Àwọn ọmọ Usieli: Mika; nínú àwọn ọmọ Mika: Ṣamiri.
Des fils d'Oziel: Micha. Des fils de Micha: Samer.
25 Àwọn arákùnrin Mika: Iṣi; nínú àwọn ọmọ Iṣiah: Sekariah.
Le frère de Micha: Isia. Fils de Micha: Zacharie.
26 Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Àwọn ọmọ Jaasiah: Beno.
Les descendants des fils de Mérari: Mooli et Musi. Les fils d'Ozia.
27 Àwọn ọmọ Merari. Láti Jaasiah: Beno, Ṣohamu, Sakkuri àti Ibri.
Fils de Mérari: Joram, et Sacchur, et Abaï.
28 Láti Mahili: Eleasari, ẹni tí kò ni àwọn ọmọ.
Mooli avait eu encore Eléazar et Ithamar; mais Eléazar était mort sans laisser de fils.
29 Láti Kiṣi. Àwọn ọmọ Kiṣi: Jerahmeeli.
Jeraméel, issu des fils de Cis,
30 Àti àwọn ọmọ Muṣi: Mahili, Ederi àti Jerimoti. Èyí ni àwọn ọmọ Lefi, gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
Et Mooli, Eder et Jerimoth, issus de Musi. Tels étaient les fils des lévites par familles paternelles.
31 Wọ́n sì ṣé kèké gẹ́gẹ́ bí àwọn arákùnrin wọn àwọn ọmọ Aaroni ṣe ṣẹ́, níwájú ọba Dafidi àti Sadoku, Ahimeleki, àti olórí ìdílé àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ìdílé àgbàgbà arákùnrin wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀ lórí àwọn arákùnrin wọn kéékèèké.
Et ils tirèrent au sort, comme leurs frères les fils d'Aaron, en présence du roi, de Sadoc, d'Achimélech, et des chefs de familles des prêtres et des lévites; aussi bien les plus anciens chefs de familles que leurs frères les plus jeunes.

< 1 Chronicles 24 >